< 2 Chronicles 18 >

1 Nísinsin yìí Jehoṣafati sì ní ọrọ̀ àti ọlá púpọ̀, ó sì dá àna pẹ̀lú Ahabu nípa fífẹ́ ọmọ rẹ̀.
Therfor Josaphat was riche and ful noble, and bi affynyte, `ethir alie, he was ioyned to Achab.
2 Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, ó sọ̀kalẹ̀ láti lọ bá Ahabu lálejò ní Samaria. Ahabu sì pa àgùntàn àti màlúù púpọ̀ fún àti àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ó sì rọ̀ ọ́ láti dojú ìjà kọ Ramoti Gileadi.
And aftir yeeris he cam doun to hym in to Samarie; at whos comyng Achab killide ful many wetheris and oxis, and to the puple that cam with hym; and he counseilide hym to stie in to Ramoth of Galaad.
3 Ahabu ọba Israẹli sì béèrè lọ́wọ́ ọba Jehoṣafati, ọba Juda pé, “Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi sí Ramoti Gileadi?” Jehoṣafati sì dá a lóhùn pé, “Èmi wà gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe wà, àti àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn rẹ àwa yóò pẹ̀lú rẹ nínú ogun náà”.
And Achab, the kyng of Israel, seide to Josaphat, kyng of Juda, Come thou with me in to Ramoth of Galaad. To whom he answeride, As and Y am, thou art; as thi puple, so and my puple; and we schulen be with thee in batel.
4 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati náà sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
And Josaphat seide to the kyng of Israel, Y biseche, counsele thou in present tyme the word of the Lord.
5 Bẹ́ẹ̀ ọba Israẹli kó àwọn wòlíì papọ̀, irinwó ọkùnrin ó sì bi wọ́n pé, “Kí àwa kí lọ sí ogun Ramoti Gileadi tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ?” Wọ́n dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Ọlọ́run yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Therfor the kyng of Israel gaderide togidere foure hundrid `men of prophetis, and seide to hem, Owen we to go in to Ramath of Galaad for to fiyte, ethir `take reste? And thei seiden, Stie ye, and God schal bitake in the hond of the king.
6 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ṣé kò ha sí wòlíì Olúwa níbí ẹni tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
And Josaphat seide, Whether no profete of the Lord is here, that we `axe also of hym?
7 Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan wà síbẹ̀ lọ́dọ̀ ẹni tí àwa ìbá tún béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n èmi kórìíra rẹ̀ nítorí kò jẹ́ sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun rere kan nípa mi ṣùgbọ́n bí kò ṣe ohun búburú, ní gbogbo ìgbà òun náà ni Mikaiah ọmọ Imla.” Jehoṣafati sì dá lóhùn pé, “Ọba kò gbọdọ̀ sọ bẹ́ẹ̀.”
And the kyng of Israel seide to Josaphat, O man is, of whom we `moun axe the wille of the Lord, but and Y hate hym, for he prophecieth not good, but yuel to me in al tyme; sothely it is Mychee, the sone of Jebla. And Josaphat seide to hym, Kyng, speke thou not in this maner.
8 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pe ọ̀kan lára àwọn ìjòyè ó sì wí pé, “Ẹ mú Mikaiah ọmọ Imla kí ó yára wá.”
Therfor the kyng of Israel clepide oon of the geldyngis, and seide to hym, Clepe thou soone Mychee, the sone of Jebla.
9 Wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn, ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda wọ́n jókòó sórí ìtẹ́ wọ́n ní ìta ẹnu-bodè Samaria, pẹ̀lú gbogbo àwọn wòlíì tí ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.
Forsothe the kyng of Israel and Josaphat, the kyng of Juda, saten euer eithir in his seete, and weren clothid in kyngis aray; forsothe thei saten in the cornfloor, `ether large hows, bisidis the yate of Samarie; and alle the prophetis profesieden bifor hem.
10 Nísinsin yìí Sedekiah ọmọ Kenaana sì ti ṣe ìwo irin, ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Pẹ̀lú èyí ìwọ yóò kan àwọn ará Siria títí ìwọ ó fi pa wọ́n run.’”
Forsothe Sedechie, the sone of Cananee, made to hym yrone hornes, and seide, The Lord seith these thingis, With these thou schalt wyndewe Sirie, til thou al to-brake it.
11 Gbogbo àwọn wòlíì tí ó kù ni wọn ń sọtẹ́lẹ̀ ní àkókò kan náà. Wọ́n sì wí pé, “Dojúkọ Ramoti Gileadi ìwọ yóò sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
And alle prophetis profesieden in lijk maner, and seiden, Stie thou in to Ramoth of Galaad, and thou schalt haue prosperite; and the Lord schal bitake hem in to the hondis of the kyng.
12 Ìránṣẹ́ tí ó ti lọ pe Mikaiah sì wí fún un pé, “Ẹ wò ó, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin kan àti òmíràn wòlíì fi ẹnu kan sọ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ kí ó dàbí ọ̀kan nínú tiwọn, kí o sì sọ rere.”
Forsothe the messanger, that yede to clepe Mychee, seide to hym, Lo! the wordis of alle prophetis tellen with o mouth goodis to the kyng; therfor, Y preye thee, that thi word disente not fro hem, and that thou speke prosperitees.
13 Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pe, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa ń bẹ láààyè, èmi yóò sọ ohun tí Ọlọ́run mi sọ.”
To whom Mychee answeride, The Lord lyueth, for what euer thingis my Lord spekith to me, Y schal speke these thingis. Therfor he cam to the kyng.
14 Nígbà tí ó dé, ọba béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, “Mikaiah, ṣe kí àwa ki ó lọ sí ogun ti Ramoti Gileadi, tàbí kí àwa kí ó fàsẹ́yìn?” Ó sì dáhùn pé, “Ẹ dojúkọ wọ́n kí ẹ sì ṣẹ́gun, nítorí a ó fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”
To whom the kyng seide, Mychee, owen we go in to Ramoth of Galaad to fiyte, ether take reste? To whom he answeride, Stie ye, for alle prosperitees schulen come, and enemyes schulen be bitakun in to youre hondis.
15 Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi ó fi ọ́ búra láti sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe ọ̀rọ̀ òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
And the kyng seide, Eft and eft Y charge thee, that thou speke not to me no but that that is soth in the name of the Lord.
16 Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’”
And he seide, Y siy al Israel scaterid in the hillis, as scheep with out scheepherde. And the Lord seide, These men han not lordis; ech man turne ayen in to his hows in pees.
17 Ọba Israẹli wí fún Jehoṣafati pé, “Ṣe èmi kò sọ fún ọ wí pé òun kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kankan nípa mi rí, ṣùgbọ́n búburú nìkan?”
The kyng of Israel seide to Josaphat, Whether Y seide not to thee, that he profesiede not ony good to me, but tho thingis that ben yuele?
18 Mikaiah tẹ̀síwájú pé, “Nítorí náà, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ gbogbo ogun ọ̀run sì dúró lápá ọ̀tún àti lápá òsì.
And therfor Mychee seide, Here ye the word of the Lord. Y siy the Lord sittynge in his trone, and al the oost of heuene stondynge nyy him at the riytside and `leftside.
19 Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu ọba Israẹli lọ sí Ramoti Gileadi kí ó sì lọ kú ikú rẹ̀ níbẹ̀?’ “Èkínní sì sọ tìhín, òmíràn sì sọ tọ̀hún.
And the Lord seide, Who schal disseyue Achab, the kyng of Israel, that he stie, and falle doun in Ramoth of Galaad? And whanne oon seide in this maner, and another seide in another maner, a spirit cam forth,
20 Ní ìparí, ni ẹ̀mí kan wá síwájú, ó dúró níwájú Olúwa ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’ “‘Nípa ọ̀nà wo?’ Olúwa béèrè.
and stood bifor the Lord, and seide, Y schal disseyue hym. To whom the Lord seide, `Wherynne, therfor schalt thou disseyue?
21 “‘Èmi yóò lọ láti lọ di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì.’ “‘Ìwọ yóò sì borí nínú ìtànjẹ rẹ̀ báyìí,’ ni Olúwa wí. ‘Lọ kí ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
And he answeride, Y schal go out, and Y schal be a `fals spirit in the mouth of alle hise profetis. And the Lord seide, Thou schalt disseyue, and thou schalt haue the maystri; go thou out, and do so.
22 “Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu àwọn wòlíì rẹ. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
Now therfor, lo! the Lord hath youe a spirit of leesyng in the mouth of alle thi prophetis, and the Lord spak yuels of thee.
23 Nígbà náà Sedekiah ọmọ Kenaana lọ sókè ó sì gbá Mikaiah ní ojú. Ó sì béèrè pé, “Ní ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà kọjá lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
Forsothe Sedechie, the sone of Chananee, neiyide, and smoot `the cheke of Mychee, and seide, Bi what weye passide the Spirit of the Lord fro me to speke to thee?
24 Mikaiah sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò ṣe ìwádìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sá pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”
And Mychee seide, Thou thi silf schalt se in that dai, whanne thou schalt entre fro closet in to closet, that thou be hid.
25 Ọba Israẹli pa á láṣẹ pé, “Mú Mikaiah kí o sì ran padà sí Amoni olórí ìlú àti sí Joaṣi ọmọ ọba,
Sotheli the kyng of Israel comaundide, seiynge, Take ye Mychee, and lede ye hym to Amon, prince of the citee, and to Joas, the sone of Amalech;
26 Ó sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí ọba sọ, ẹ fi ènìyàn yìí sínú túbú kí ẹ má sì ṣe fún un ní ohunkóhun ṣùgbọ́n àkàrà àti omi títí tí èmi yóò fi dé ní àlàáfíà.’”
and ye schulen seie, The kyng seith these thingis, Sende ye this man in to prisoun, and yyue ye to hym a litil of breed, and a litil of watir, til Y turne ayen in pees.
27 Mikaiah sì wí pe, “Tí ìwọ bá padà ní àlàáfíà, Olúwa kò sọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.” Nígbà náà, ó sì fi kún un pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn!”
And Mychee seide, If thou turnest ayen in pees, the Lord spak not in me. And he seide, Alle `puplis here ye.
28 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda lọ sókè ní Ramoti Gileadi.
Therfor the kyng of Israel, and Josaphat, the kyng of Juda, stieden in to Ramoth of Galaad.
29 Ọba Israẹli sọ fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ rẹ̀ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
And the kyng of Israel seide to Josaphat, Y schal chaunge clothing, and so Y schal go to fiyte; but be thou clothid in thi clothis. Therfor whanne the kyng of Israel hadde chaungid clothing, he cam to batel.
30 Nísinsin yìí ọba Siria ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ tí ó wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ má ṣe jà pẹ̀lú ẹnìkankan, èwe tàbí àgbà àyàfi ọba Israẹli.”
Forsothe the kyng of Sirie comaundide to the duykis of his multitude of knyytis, and seide, Fiyte ye not ayens the leeste, nether ayens the mooste; no but ayens the kyng aloone of Israel.
31 Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rí Jehoṣafati, wọ́n rò wí pé, “Èyí ní ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yípadà láti bá a jà. Ṣùgbọ́n Jehoṣafati kégbe sókè, Olúwa sì ràn án lọ́wọ́. Ọlọ́run sì lé wọn kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀,
Therfor whanne the princes of the multitude of knyytis hadden seyn Josaphat, thei seiden, This is the kyng of Israel; and thei cumpassiden hym, and fouyten. And he criede to the Lord; and the Lord helpide hym, and turnede hem awey fro hym.
32 Ó sì ṣe, nígbà tí olórí kẹ̀kẹ́ rí i wí pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì dáwọ́ lílé rẹ̀ dúró.
Sotheli whanne the duykis of the multitude of knyytis hadden herd, that it was not the kyng of Israel, thei leften hym.
33 Ṣùgbọ́n ẹnìkan fa ọrun rẹ̀ láì pète, ó sì bá ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin, ọba sì sọ fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ padà, kí o sì wà mí jáde kúrò lójú ìjà. Nítorí èmi ti gbọgbẹ́.”
Forsothe it bifelde, that oon of the puple schette an arewe in to vncerteyn, and smoot the kyng of Israel bitwixe the necke and the schuldris. And he seide to his charietere, Turne thin hond, and lede me out of the scheltrun; for Y am woundid.
34 Ní ọjọ́ pípẹ́, ìjà náà sì ń pọ̀ sí i, ọba Israẹli dúró nínú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ kọjú sí àwọn ará Siria títí ó fi di àṣálẹ́. Lẹ́yìn náà ní àkókò ìwọ oòrùn, ó sì kú.
And the batel was endid in that dai. Certis the kyng of Israel stood in his chare ayens men of Sirye `til to euentid, and he diede, whanne the sunne yede doun.

< 2 Chronicles 18 >