< 2 Chronicles 18 >

1 Nísinsin yìí Jehoṣafati sì ní ọrọ̀ àti ọlá púpọ̀, ó sì dá àna pẹ̀lú Ahabu nípa fífẹ́ ọmọ rẹ̀.
Jehoshaphat te a cungkuem ah khuehtawn neh thangpomnah a om hatah Ahab te a masae nah.
2 Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, ó sọ̀kalẹ̀ láti lọ bá Ahabu lálejò ní Samaria. Ahabu sì pa àgùntàn àti màlúù púpọ̀ fún àti àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ó sì rọ̀ ọ́ láti dojú ìjà kọ Ramoti Gileadi.
Kum a thok vaengah tah Samaria kah Ahab taengla suntla tih anih ham neh a taengkah pilnam ham khaw Ahab loh boiva neh saelhung te a cungkuem la a ngawn pah. Te vaengah anih te Ramothgilead paan hamla a vueh.
3 Ahabu ọba Israẹli sì béèrè lọ́wọ́ ọba Jehoṣafati, ọba Juda pé, “Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi sí Ramoti Gileadi?” Jehoṣafati sì dá a lóhùn pé, “Èmi wà gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe wà, àti àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn rẹ àwa yóò pẹ̀lú rẹ nínú ogun náà”.
Te phoeiah Israel manghai Ahab loh Judah manghai Jehoshaphat te, “Kai taengah Ramothgilead la na lo aya?” a ti nah. Te dongah anih te, “Kai khaw nang banghui, na pilnam khaw ka pilnam ni. Caemtloek dongah khaw nang taengah ka om ni,” a ti nah.
4 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati náà sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
Tedae Jehoshaphat loh Israel manghai taengah, “BOEIPA ol te a khohnin bangla toem laeh,” a ti nah.
5 Bẹ́ẹ̀ ọba Israẹli kó àwọn wòlíì papọ̀, irinwó ọkùnrin ó sì bi wọ́n pé, “Kí àwa kí lọ sí ogun Ramoti Gileadi tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ?” Wọ́n dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Ọlọ́run yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Te vaengah Israel manghai loh tonghma rhoek te hlang ya li a coi tih amih te, “Ramothgilead ah caemtloek la na lo aya? Ka paa mai aya?” a ti nah. Te dongah, “Cet sih, Pathen loh manghai kut ah m'paek bitni,” a ti na uh.
6 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ṣé kò ha sí wòlíì Olúwa níbí ẹni tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
Tedae Jehoshaphat loh, “Amah te n'toem uh ham khaw BOEIPA kah tonghma om pueng pawt nim he,” a ti nah.
7 Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan wà síbẹ̀ lọ́dọ̀ ẹni tí àwa ìbá tún béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n èmi kórìíra rẹ̀ nítorí kò jẹ́ sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun rere kan nípa mi ṣùgbọ́n bí kò ṣe ohun búburú, ní gbogbo ìgbà òun náà ni Mikaiah ọmọ Imla.” Jehoṣafati sì dá lóhùn pé, “Ọba kò gbọdọ̀ sọ bẹ́ẹ̀.”
Israel manghai loh Jehoshaphat taengah, “Anih lamloh BOEIPA dawt sak ham hlang pakhat om pueng dae anih te ka thiinah. Anih te kai ham tah a then la a tonghma moenih. A hnin takuem ah thae mai. Anih te Imlah capa Mikhaiah ni,” a ti nah. Te vaengah Jehoshaphat loh, “Te te manghai kah a thui koi moenih,” a ti nah.
8 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pe ọ̀kan lára àwọn ìjòyè ó sì wí pé, “Ẹ mú Mikaiah ọmọ Imla kí ó yára wá.”
Te dongah Israel manghai loh imkhoem pakhat te a khue tih, “Imlah capa Mikhaiah tlek han khue,” a ti nah.
9 Wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn, ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda wọ́n jókòó sórí ìtẹ́ wọ́n ní ìta ẹnu-bodè Samaria, pẹ̀lú gbogbo àwọn wòlíì tí ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.
Israel manghai neh Judah manghai Jehoshaphat tah a ngolkhoel dongah ngol rhoi tih himbai a bai rhoi. Te vaengah Samaria vongka thohka kah cangtilhmuen ah ngol uh tih tonghma boeih te amih mikhmuh ah tonghma uh.
10 Nísinsin yìí Sedekiah ọmọ Kenaana sì ti ṣe ìwo irin, ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Pẹ̀lú èyí ìwọ yóò kan àwọn ará Siria títí ìwọ ó fi pa wọ́n run.’”
Te vaengah Kenaanah capa Zedekiah loh amah ham thi ki a saii tih, “BOEIPA loh he ni a thui. He nen he amih a khah hil Aram te na thoeh bitni,” a ti nah.
11 Gbogbo àwọn wòlíì tí ó kù ni wọn ń sọtẹ́lẹ̀ ní àkókò kan náà. Wọ́n sì wí pé, “Dojúkọ Ramoti Gileadi ìwọ yóò sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Tonghma boeih khaw tonghma uh tangloeng tih, “Ramothgilead te paan lamtah thaihtak laeh, BOEIPA loh manghai kut ah m'paek bitni,” a ti uh.
12 Ìránṣẹ́ tí ó ti lọ pe Mikaiah sì wí fún un pé, “Ẹ wò ó, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin kan àti òmíràn wòlíì fi ẹnu kan sọ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ kí ó dàbí ọ̀kan nínú tiwọn, kí o sì sọ rere.”
Mikhaiah te khue hamla aka cet puencawn long tah anih te a uen tih, “Tonghma rhoek kah ol tah olka pakhat la a om ke manghai ham khaw then ne. Te dongah nang ol khaw amih neh pakhat la om pawn saeh lamtah a then mah thui,” a ti nah.
13 Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pe, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa ń bẹ láààyè, èmi yóò sọ ohun tí Ọlọ́run mi sọ.”
Tedae Mikhaiah loh, “BOEIPA kah hingnah dongah kai kah Pathen amah loh a thui bueng te ni ka thui eh,” a ti nah.
14 Nígbà tí ó dé, ọba béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, “Mikaiah, ṣe kí àwa ki ó lọ sí ogun ti Ramoti Gileadi, tàbí kí àwa kí ó fàsẹ́yìn?” Ó sì dáhùn pé, “Ẹ dojúkọ wọ́n kí ẹ sì ṣẹ́gun, nítorí a ó fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”
Manghai taeng a pha vaengah manghai loh anih te, “Maikah, Ramothgilead te caemtloek la ka cet aya? Ka paa uh aya?” a ti nah. Te vaengah, “Cet uh lamtah thaihtak uh, nangmih kut ah m'paek uh hatko,” a ti nah.
15 Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi ó fi ọ́ búra láti sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe ọ̀rọ̀ òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
Tedae manghai loh anih te, “BOEIPA ming neh oltak bueng phoeiah kai taengah a tloe thui boeh tila nang te kai loh voei meyet hil nim kan toemngam ve,” a ti nah.
16 Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’”
Te vaengah, “Israel boeih te tlang ah boiva bangla a taekyak te ka hmuh, amih aka dawn ham khaw om pawh. Te dongah BOEIPA loh, ‘He rhoek he boei a om moenih, hlang he ngaimongnah neh amah im la mael uh saeh,’ a ti,” a ti nah.
17 Ọba Israẹli wí fún Jehoṣafati pé, “Ṣe èmi kò sọ fún ọ wí pé òun kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kankan nípa mi rí, ṣùgbọ́n búburú nìkan?”
Israel manghai loh Jehoshaphat te, “Nang taengah ka thui moenih a? Kai soah a thae lam bueng ni, a then la a tonghma tlaih moenih,” a ti nah.
18 Mikaiah tẹ̀síwájú pé, “Nítorí náà, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ gbogbo ogun ọ̀run sì dúró lápá ọ̀tún àti lápá òsì.
Te vaengah, “Te dongah BOEIPA ol he hnatun uh. A ngolkhoel dongah aka ngol BOEIPA te ka hmuh. Vaan caempuei boeih khaw amah kah banvoei bantang ah pai uh.
19 Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu ọba Israẹli lọ sí Ramoti Gileadi kí ó sì lọ kú ikú rẹ̀ níbẹ̀?’ “Èkínní sì sọ tìhín, òmíràn sì sọ tọ̀hún.
BOEIPA loh, ‘U long nim Israel manghai Ahab te a cuek lah ve? Te dongah cet lah vetih Ramothgilead ah cungku mako,’ a ti. Te vaengah tah, ‘He long khaw he coeng ni,’ a ti tih te long khaw, ‘Te coeng ni,’ a ti,” a ti nah.
20 Ní ìparí, ni ẹ̀mí kan wá síwájú, ó dúró níwájú Olúwa ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’ “‘Nípa ọ̀nà wo?’ Olúwa béèrè.
Tedae mueihla ha pawk vaengah tah BOEIPA mikhmuh ah pai tih, “Kamah loh anih te ka cuek eh,” a ti nah. Te vaengah BOEIPA loh anih te ni, “Me nen lae,” a ti nah.
21 “‘Èmi yóò lọ láti lọ di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì.’ “‘Ìwọ yóò sì borí nínú ìtànjẹ rẹ̀ báyìí,’ ni Olúwa wí. ‘Lọ kí ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
Te vaengah, “Ka cet vetih a tonghma rhoek boeih kah a ka khuiah laithae mueihla la ka om ni,” a ti nah. Te daengah, “Cuek lamtah coeng bal bitni, cet lamtah saii tangloeng laeh,” a ti nah.
22 “Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu àwọn wòlíì rẹ. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
Te dongah, “BOEIPA nang kah tonghma rhoek he a ka ah laithae mueihla a khueh pah coeng he. Te phoeiah BOEIPA loh nang hamla boethae a thui coeng,” a ti nah.
23 Nígbà náà Sedekiah ọmọ Kenaana lọ sókè ó sì gbá Mikaiah ní ojú. Ó sì béèrè pé, “Ní ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà kọjá lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
Te vaengah Kenaanah capa Zedekiah te thoeih tih Mikhaiah te a kam ah a thoek. Te phoeiah, “Nang aka voek ham BOEIPA mueihla te kai taeng lamloh mekah longpuei lam a caeh he,” a ti nah.
24 Mikaiah sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò ṣe ìwádìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sá pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”
Mikhaiah loh, “Thuh uh hamla imkhui kah imkhui la na caeh vaengkah khohnin ah namah loh hmu ne,” a ti nah.
25 Ọba Israẹli pa á láṣẹ pé, “Mú Mikaiah kí o sì ran padà sí Amoni olórí ìlú àti sí Joaṣi ọmọ ọba,
Israel manghai loh, “Mikhaiah te khuen uh, anih te khopuei mangpa Amon taeng neh manghai capa Joash taengla khuen uh,” a ti.
26 Ó sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí ọba sọ, ẹ fi ènìyàn yìí sínú túbú kí ẹ má sì ṣe fún un ní ohunkóhun ṣùgbọ́n àkàrà àti omi títí tí èmi yóò fi dé ní àlàáfíà.’”
Te vaengah, “Manghai loh he ni a thui, anih he thong im ah khueh uh, anih te sading la ka mael hil nennah buh neh nennah tui mah cah uh,” a ti nah.
27 Mikaiah sì wí pe, “Tí ìwọ bá padà ní àlàáfíà, Olúwa kò sọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.” Nígbà náà, ó sì fi kún un pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn!”
Tedae Mikhaiah loh, “Sading la na mael la na mael atah BOEIPA loh kai dongah thui pawt mako,” a ti nah. Te phoeiah, “Te boeih te pilnam loh ya saeh,” a ti nah.
28 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda lọ sókè ní Ramoti Gileadi.
Te dongah Israel manghai neh Judah manghai Jehoshaphat tah Ramothgilead la cet rhoi.
29 Ọba Israẹli sọ fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ rẹ̀ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
Tedae Israel manghai loh Jehoshaphat te, “Caemtloek la kun vaengah ka thohai uh mai eh. Tedae nang tah na himbai bai,” a ti nah. Te dongah Israel manghai te thohai uh tih caemtloek la cet.
30 Nísinsin yìí ọba Siria ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ tí ó wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ má ṣe jà pẹ̀lú ẹnìkankan, èwe tàbí àgbà àyàfi ọba Israẹli.”
Aram manghai long khaw amah taengkah leng mangpa rhoek te a uen tih, “Israel manghai amah bueng phoeiah tah a yit a len khaw tloek uh boeh,” a ti nah.
31 Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rí Jehoṣafati, wọ́n rò wí pé, “Èyí ní ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yípadà láti bá a jà. Ṣùgbọ́n Jehoṣafati kégbe sókè, Olúwa sì ràn án lọ́wọ́. Ọlọ́run sì lé wọn kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀,
Leng mangpa rhoek loh Jehoshaphat te a hmuh uh tih amih loh, “Te te Israel manghai,” a ti uh. Te dongah anih te tloek hamla a vael uh dae Jehoshaphat la pang. BOEIPA loh anih te a bom tih amih te khaw Pathen amah lamloh puk a va sak.
32 Ó sì ṣe, nígbà tí olórí kẹ̀kẹ́ rí i wí pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì dáwọ́ lílé rẹ̀ dúró.
Leng mangpa rhoek loh a hmuh vaengah Israel manghai te a om pah pawt tih anih hnuk lamloh mael uh.
33 Ṣùgbọ́n ẹnìkan fa ọrun rẹ̀ láì pète, ó sì bá ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin, ọba sì sọ fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ padà, kí o sì wà mí jáde kúrò lójú ìjà. Nítorí èmi ti gbọgbẹ́.”
Tedae hlang pakhat loh a thincaknah neh lii te a phuk hatah Israel manghai te rhuhcong laklo neh caempho laklo ah a kah. Te dongah lengboei te, “Na kut, na kut te hooi laeh. Ka tlo coeng tih caem khui lamloh kai n'khuen laeh,” a ti nah.
34 Ní ọjọ́ pípẹ́, ìjà náà sì ń pọ̀ sí i, ọba Israẹli dúró nínú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ kọjú sí àwọn ará Siria títí ó fi di àṣálẹ́. Lẹ́yìn náà ní àkókò ìwọ oòrùn, ó sì kú.
Te vaengah caemtloek te hnin at puet puh mai. Tedae Israel manghai tah sut om tih Aram dan kah leng khuiah hlaem duela pai. Tedae khomik a khum tue vaengah duek.

< 2 Chronicles 18 >