< 2 Chronicles 18 >

1 Nísinsin yìí Jehoṣafati sì ní ọrọ̀ àti ọlá púpọ̀, ó sì dá àna pẹ̀lú Ahabu nípa fífẹ́ ọmọ rẹ̀.
Jehosaphat loe paroeai angraenghaih hoi pakoehhaih ah oh; anih loe zu lakhaih rang hoiah Ahab hoi angdaehhaih to sak.
2 Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, ó sọ̀kalẹ̀ láti lọ bá Ahabu lálejò ní Samaria. Ahabu sì pa àgùntàn àti màlúù púpọ̀ fún àti àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ó sì rọ̀ ọ́ láti dojú ìjà kọ Ramoti Gileadi.
Saning nazetto maw oh pacoengah, Ahab khae paqaih hanah Samaria ah a caeh tathuk. Ahab mah Jehosaphat hoi anih ih kaminawk hanah, paroeai tuu hoi maitawnawk to boh pae moe, anih hoi nawnto Ramoth-Gilead tuk hanah pacae.
3 Ahabu ọba Israẹli sì béèrè lọ́wọ́ ọba Jehoṣafati, ọba Juda pé, “Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi sí Ramoti Gileadi?” Jehoṣafati sì dá a lóhùn pé, “Èmi wà gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe wà, àti àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn rẹ àwa yóò pẹ̀lú rẹ nínú ogun náà”.
Israel siangpahrang Ahab mah Judah siangpahrang Jehosaphat khaeah, Ramoth-Gilead to nang tuk haih han maw? tiah a naa. Jehosaphat mah kai doeh nang ni; Kai ih kaminawk doeh nang ih kami ah ni oh o; nang hoi nawnto misa kang tuk pae o han, tiah a naa.
4 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati náà sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
Jehosaphat mah Israel siangpahrang khaeah, Vaihniah Angraeng khaeah lokdueng hmaloe ah, tiah a naa.
5 Bẹ́ẹ̀ ọba Israẹli kó àwọn wòlíì papọ̀, irinwó ọkùnrin ó sì bi wọ́n pé, “Kí àwa kí lọ sí ogun Ramoti Gileadi tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ?” Wọ́n dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Ọlọ́run yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
To pongah Israel siangpahrang mah, tahmaa cumvai palito kawk moe, nihcae khaeah, Ramoth-Gilead tuk hanah a caeh o han maw, a caeh o mak ai? tiah a naa. Nihcae mah, Caeh oh, Sithaw mah to vangpui to na ban ah paek tih, tiah a naa o.
6 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ṣé kò ha sí wòlíì Olúwa níbí ẹni tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
Toe Jehosaphat mah, lok a dueng o hanah, hae ah Angraeng ih tahmaa mi doeh om ai maw? tiah a naa.
7 Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan wà síbẹ̀ lọ́dọ̀ ẹni tí àwa ìbá tún béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n èmi kórìíra rẹ̀ nítorí kò jẹ́ sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun rere kan nípa mi ṣùgbọ́n bí kò ṣe ohun búburú, ní gbogbo ìgbà òun náà ni Mikaiah ọmọ Imla.” Jehoṣafati sì dá lóhùn pé, “Ọba kò gbọdọ̀ sọ bẹ́ẹ̀.”
Israel siangpahrang mah Jehosaphat khaeah, Aicae mah lokdueng hanah Angraeng ih kami maeto oh vop, toe anih loe kai kawng kahoih vaito doeh thui ai, ka sethaih khue to a thuih pongah, anih to ka hnukma; anih loe Imlah capa Mikaiah, tiah a naa. To naah Jehosaphat mah, Siangpahrang loe to tiah lok apaeh han om ai, tiah a naa.
8 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pe ọ̀kan lára àwọn ìjòyè ó sì wí pé, “Ẹ mú Mikaiah ọmọ Imla kí ó yára wá.”
To pongah Israel siangpahrang mah angmah ih angraeng maeto kawk moe, Imlah capa Mikaiah to karangah kawk ah, tiah lokpaek.
9 Wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn, ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda wọ́n jókòó sórí ìtẹ́ wọ́n ní ìta ẹnu-bodè Samaria, pẹ̀lú gbogbo àwọn wòlíì tí ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.
Israel siangpahrang hoi Judah siangpahrang Jehosaphat loe, siangpahrang khukbuen to angkhuk hoi moe, Samaria vangpui akunhaih khongkha taeng ih, kakong ahmuen ah angraeng tangkhang nuiah anghnut hoi; to naah tahmaanawk boih mah nihnik hmaa ah lokthuih pae o.
10 Nísinsin yìí Sedekiah ọmọ Kenaana sì ti ṣe ìwo irin, ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Pẹ̀lú èyí ìwọ yóò kan àwọn ará Siria títí ìwọ ó fi pa wọ́n run.’”
Kenaanah capa Zedekiah mah sum hoi sak ih taki to lak moe, Angraeng mah, Syria prae nam rosak ai karoek to, hae taki hoiah na daeng tih, tiah a thuih, tiah a naa.
11 Gbogbo àwọn wòlíì tí ó kù ni wọn ń sọtẹ́lẹ̀ ní àkókò kan náà. Wọ́n sì wí pé, “Dojúkọ Ramoti Gileadi ìwọ yóò sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Kalah tahmaanawk boih mah doeh to tiah thuih o toeng; Ramoth-Gilead to tuh ah, na pazawk tih; Angraeng mah siangpahrang ban ah paek tih, tiah a naa o.
12 Ìránṣẹ́ tí ó ti lọ pe Mikaiah sì wí fún un pé, “Ẹ wò ó, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin kan àti òmíràn wòlíì fi ẹnu kan sọ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ kí ó dàbí ọ̀kan nínú tiwọn, kí o sì sọ rere.”
Mikaiah khaeah kacaeh laicaeh mah anih khaeah, Khenah, siangpahrang mah pazawk tih hmang, tiah tahmaanawk boih mah kanghmong lok to thuih o; nihcae mah thuih ih lok baktih toengah lok to thui ah, tahngai kahoih ah lok na thuih nahaeloe hoi tih, tiah a naa.
13 Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pe, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa ń bẹ láààyè, èmi yóò sọ ohun tí Ọlọ́run mi sọ.”
Toe Mikaiah mah, Angraeng loe hing pongah, ka Sithaw mah thuih ih lok khue ni ka thuih han, tiah a naa.
14 Nígbà tí ó dé, ọba béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, “Mikaiah, ṣe kí àwa ki ó lọ sí ogun ti Ramoti Gileadi, tàbí kí àwa kí ó fàsẹ́yìn?” Ó sì dáhùn pé, “Ẹ dojúkọ wọ́n kí ẹ sì ṣẹ́gun, nítorí a ó fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”
Anih siangpahrang hmaa ah phak naah, siangpahrang mah anih khaeah, Mikaiah, Ramoth-Gilead tuk hanah a caeh o han maw, a caeh o mak ai? tiah lok a dueng. Anih mah, Caeh oh loe, pazawk oh; nihcae to na ban ah paek tih, tiah a naa.
15 Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi ó fi ọ́ búra láti sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe ọ̀rọ̀ òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
Siangpahrang mah anih khaeah, Kamsoem lok khue ai ah loe, Angraeng ih ahmin hoiah kai khaeah kamsoem ai lok to thui hmah, tiah vai nazetto maw lokkamhaih kang saksak boeh? tiah a naa.
16 Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’”
Mikaiah mah, Toepkung tawn ai mae nuiah kamhet tuu caa baktiah kamhet phang Israel kaminawk to ka hnuk; Angraeng mah, Hae kaminawk loe angraeng tawn o ai pongah, kaminawk loe angmacae im ah amlaem o boih nasoe, tiah thuih, tiah a naa.
17 Ọba Israẹli wí fún Jehoṣafati pé, “Ṣe èmi kò sọ fún ọ wí pé òun kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kankan nípa mi rí, ṣùgbọ́n búburú nìkan?”
Israel siangpahrang mah Jehosaphat khaeah, Kai kawng kahoih vaito doeh thui ai; kasae ngai ni a thuih, tiah kang thuih boeh na ai maw? tiah a naa.
18 Mikaiah tẹ̀síwájú pé, “Nítorí náà, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ gbogbo ogun ọ̀run sì dúró lápá ọ̀tún àti lápá òsì.
Mikaiah mah, To pongah Angraeng ih lok hae tahngai ah; Anih loe angmah ih angraeng tangkhang nuiah anghnut, anih ih banqoi bantang bangah anghnu van kaminawk to ka hnuk, tiah a thuih pae let.
19 Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu ọba Israẹli lọ sí Ramoti Gileadi kí ó sì lọ kú ikú rẹ̀ níbẹ̀?’ “Èkínní sì sọ tìhín, òmíràn sì sọ tọ̀hún.
Angraeng mah, Israel siangpahrang Ahab mah Ramah-Gilead to tuk moe, sung hanah mi mah maw zoek thai tih? tiah a thuih. To naah maeto mah hmuen maeto kawng to thuih moe, kalah maeto mah kalah hmuen maeto kawng to thuih.
20 Ní ìparí, ni ẹ̀mí kan wá síwájú, ó dúró níwájú Olúwa ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’ “‘Nípa ọ̀nà wo?’ Olúwa béèrè.
To nathuem ah muithla maeto angzoh, Angraeng hmaa ah angdoet moe, Anih to kai mah ka zoek han, tiah a naa. Angraeng mah anih khaeah, Kawbangmaw na zoek han loe? tiah dueng naah,
21 “‘Èmi yóò lọ láti lọ di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì.’ “‘Ìwọ yóò sì borí nínú ìtànjẹ rẹ̀ báyìí,’ ni Olúwa wí. ‘Lọ kí ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
anih mah, Ka caeh moe, siangpahrang ih tahmaanawk pakha ah amsawnlok kathui muithla baktiah ka oh pae han, tiah a naa. Angraeng mah, Nang mah na zoek thai tih; caeh loe, na thuih ih lok baktih toengah sah ah, tiah a naa.
22 “Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu àwọn wòlíì rẹ. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
To pongah khenah, Angraeng mah vaihi amsawnlok kathui muithla to hae tahmaanawk ih pakha ah suek pae boeh; Angraeng mah nang amro thai hanah lokthuih boeh, tiah a naa.
23 Nígbà náà Sedekiah ọmọ Kenaana lọ sókè ó sì gbá Mikaiah ní ojú. Ó sì béèrè pé, “Ní ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà kọjá lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
To pacoengah Kenaanah capa Zedekiah mah, caeh moe, Mikaiah to mikhmai ah tabaeng; Angraeng ih Muithla mah nang khae lokthuih hanah, naa bang ih loklam hoiah maw kai khae hoiah tacawt? tiah a naa.
24 Mikaiah sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò ṣe ìwádìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sá pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”
Mikaiah mah, Khenah, anghawk hanah imthung ah na caeh niah na panoek tih, tiah a naa.
25 Ọba Israẹli pa á láṣẹ pé, “Mú Mikaiah kí o sì ran padà sí Amoni olórí ìlú àti sí Joaṣi ọmọ ọba,
Israel siangpahrang mah, Mikaiah to la oh loe, vangpui ukkung, Amon hoi siangpahrang capa Joash khaeah thak oh, tiah a naa.
26 Ó sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí ọba sọ, ẹ fi ènìyàn yìí sínú túbú kí ẹ má sì ṣe fún un ní ohunkóhun ṣùgbọ́n àkàrà àti omi títí tí èmi yóò fi dé ní àlàáfíà.’”
Siangpahrang mah, Hae kami hae thongim pakhrah oh, kamong ah kam laem let ai karoek to pacaekthlaek hanah, takaw hoi tui khue ai ah loe, tidoeh paek o hmah, tiah a thuih, tiah thuih paeh, tiah lok a paek.
27 Mikaiah sì wí pe, “Tí ìwọ bá padà ní àlàáfíà, Olúwa kò sọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.” Nígbà náà, ó sì fi kún un pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn!”
Mikaiah mah, Kamongah nam laem o let tangtang nahaeloe, Angraeng mah kai khaeah lokthui ai ah ni om tih. Kaminawk boih, ka lok hae panoek oh, tiah a naa.
28 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda lọ sókè ní Ramoti Gileadi.
To pongah Israel siangpahrang hoi Judah siangpahrang Jehosaphat loe Ramoth-Gilead ah caeh hoi tahang.
29 Ọba Israẹli sọ fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ rẹ̀ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
Israel siangpahrang mah Jehosaphat khaeah, Kai loe kami kalah ah angsak moe, misa ka tuk han; toe nang loe siangpahrang khukbuen to angkhuk ah loe, om ah, tiah a naa. To pongah Israel siangpahrang loe kami kalah baktiah angsak moe, misatuk hanah nawnto a caeh hoi.
30 Nísinsin yìí ọba Siria ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ tí ó wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ má ṣe jà pẹ̀lú ẹnìkankan, èwe tàbí àgbà àyàfi ọba Israẹli.”
To naah Syria siangpahrang mah, Angmah ih hrangleeng angthueng hoi misatuh angraeng khaeah, Israel siangpahrang khue ai ah loe, kathoeng doeh kalen doeh kalah kaminawk to tuh o hmah, tiah a naa.
31 Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rí Jehoṣafati, wọ́n rò wí pé, “Èyí ní ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yípadà láti bá a jà. Ṣùgbọ́n Jehoṣafati kégbe sókè, Olúwa sì ràn án lọ́wọ́. Ọlọ́run sì lé wọn kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀,
Hrangleeng hoi misatuh angraengnawk mah, Jehosaphat to hnuk o naah, Anih loe Israel siangpahrang mue, tiah poek o. To pongah anih tuk hanah takui o; toe Jehosaphat hang naah, Angraeng mah anih to abomh, Sithaw mah to kaminawk to loklam kalah bangah caehsak king.
32 Ó sì ṣe, nígbà tí olórí kẹ̀kẹ́ rí i wí pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì dáwọ́ lílé rẹ̀ dúró.
Hrangleeng hoi misatuh angraengnawk mah anih loe Israel siangpahrang na ai ni, tiah panoek o naah, anih to patom ai ah amlaem o let.
33 Ṣùgbọ́n ẹnìkan fa ọrun rẹ̀ láì pète, ó sì bá ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin, ọba sì sọ fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ padà, kí o sì wà mí jáde kúrò lójú ìjà. Nítorí èmi ti gbọgbẹ́.”
Kami maeto loe palaa to aphongh moe, a kah rumram, to naah Israel siangpahrang ih sum aphaw salakah cop; to naah anih mah angmah ih hrangleeng mongh kami khaeah, Kai loe ahmaa ka caak boeh pongah, angqoi ah loe misa angtukhaih ahmuen hoiah kai amlaem haih lai ah, tiah a naa.
34 Ní ọjọ́ pípẹ́, ìjà náà sì ń pọ̀ sí i, ọba Israẹli dúró nínú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ kọjú sí àwọn ará Siria títí ó fi di àṣálẹ́. Lẹ́yìn náà ní àkókò ìwọ oòrùn, ó sì kú.
To na niah paroeai misa angtuk o; Israel siangpahrang loe hrangleeng nuiah angthueng moe, duembang khoek to Syria kaminawk to tuk; anih loe niduem tom naah duek.

< 2 Chronicles 18 >