< 2 Chronicles 17 >
1 Jehoṣafati ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀ ó sì mú ara rẹ̀ lágbára sí lórí Israẹli.
Nandimbe aze nifehe t’Iehosafate anadahi’ey, le nihafatratse am’ Israele.
2 Ó sì fi ogun sínú gbogbo ìlú olódi Juda ó sì kó ẹgbẹ́ ológun ní Juda àti nínú ìlú Efraimu tí Asa baba rẹ̀ ti gbà.
Nampipoha’e lahindefoñe iaby o rova-fatrats’ Iehodao naho nampijadoña’e firimboñañe an-tane Iehoda ao vaho amo rova’ i Efraime rinambe’ i Asa rae’eo.
3 Olúwa sì wà pẹ̀lú Jehoṣafati nítorí, ní ọdún àkọ́kọ́ rẹ̀, ó rìn ní ọ̀nà ti baba rẹ̀ Dafidi ti rìn, kò sì fi ọ̀ràn lọ Baali.
Nindre am’ Iehosafate t’Iehovà, amy te nañaveloe’e o sata’ i Davide rae’e valoha’eo, le tsy pinai’e o Baaleo;
4 Ṣùgbọ́n ó wá Ọlọ́run baba rẹ̀ kiri ó sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ̀ ju iṣẹ́ Israẹli.
nitsoeha’e t’i Andrianañaharen-drae’e, nañaveloe’e o lili’eo vaho tsy nanoe’e o sata’ Israeleo.
5 Olúwa sì fi ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ lábẹ́ àkóso rẹ̀, gbogbo Juda sì mú ẹ̀bùn wá fún Jehoṣafati, bẹ́ẹ̀ ni ó sì ní ọrọ̀ àti ọlá lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Aa le najado’ Iehovà am-pità’e i fifeheañey; le ninday ravoravo am’ Iehosafate t’Iehoda iaby ie nanam-bara naho engeñe ra’elahy.
6 Ọkàn rẹ̀ sì gbé sókè si ọ̀nà Olúwa, pẹ̀lúpẹ̀lú, ó sì mú ibi gíga wọn àti ère òrìṣà Aṣerah kúrò ní Juda.
Le naonjoñe amo sata’ Iehovào ty arofo’e; mbore nafaha’e boake Iehoda ao o tambohoo naho o Aserào.
7 Ní ọdún kẹta ìjọba rẹ̀, ó rán àwọn ìjòyè rẹ̀ Bene-Haili, Obadiah, Sekariah, Netaneli, Mikaiah láti máa kọ́ ni nínú ìlú Juda.
Ie tan-taom-paha-telo’ i fifehea’ey, le nirahe’e o roandria’eo, i Benekaile naho i Obadia naho i Zekarià naho i Netanele vaho i Mikaià hañoke amo rova Iehodao.
8 Wọ́n sì ní díẹ̀ lára àwọn ọmọ Lefi, àní Ṣemaiah, Netaniah, Sebadiah, Asaheli, Ṣemiramotu, Jehonatani, Adonijah, Tobijah àti Tobu-Adonijah àti àwọn àlùfáà Eliṣama àti Jehoramu.
Nindre am’ iereo o nte-Levio; i Semaià naho i Netanià naho i Zebadià naho i Asahele naho i Semiramote naho Iehonatane naho i Adoniià naho i Tobiià vaho i Tobadonià, nte-Levy; nitraok’ am’ iereo t’i Elisamà naho Iehorame mpisoroñe,
9 Wọ́n ń kọ́ ni ní agbègbè Juda, wọ́n mú ìwé òfin Olúwa wọ́n sì rìn yíká gbogbo àwọn ìlú Juda wọ́n sì ń kọ́ àwọn ènìyàn.
nañanatse e Iehodà ao, le am’ iereo ty boke’ i Hà’ Iehovà; nitsitsihe’ iereo o rova’ Iehodà iabio, nañoke ondatio.
10 Ìbẹ̀rù Olúwa bà lórí gbogbo ìjọba ilẹ̀ tí ó yí Juda ká, dé bi pé wọn kò bá Jehoṣafati jagun.
Nivotrak’ amo fonga fifeheañe naho tane mañohoke am’ Iehodao ty firevendreveñañe Iehovà vaho tsy eo ty nialy am’ Iehosafate.
11 Lára àwọn ará Filistini, mú ẹ̀bùn fàdákà gẹ́gẹ́ bí owó ọba wá fún Jehoṣafati, àwọn ará Arabia sì mú ọ̀wọ́ ẹran wá fún un, ẹgbàarindín ní ọ̀ọ́dúnrún àgbò àti ẹgbàarindín ní ọ̀ọ́dúnrún òbúkọ.
Nandesa’ ty ila’ o nte-Pelistio ravoravo naho haba am-bolafoty; ninday hare o nte-Arabeo: añondrilahy fito-arivo-tsi-fitonjato naho oselahy fito-arivo-tsi-fitonjato.
12 Jehoṣafati sì ń di alágbára nínú agbára sí i, ó sì kọ́ ilé olódi àti ilé ìṣúra púpọ̀ ní Juda
Nitoabotse avao ty enge’ Iehosafate; le namboare’e e Iehoda ao ty rova fatratse naho rovam-pañajàñe.
13 Ó sì ní ìṣúra ní ìlú Juda. Ó sì tún ní àwọn alágbára jagunjagun akọni ọkùnrin ní Jerusalẹmu.
Nimaro ty tolon-draha’e amo rova’ Iehodao vaho inao o lahindefoñe, fanalolahy maozatse e Ierosalaimeo.
14 Iye wọn gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn nìwọ̀nyí. Láti Juda, àwọn olórí ìpín kan ti ẹgbẹ̀rún: Adina olórí, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún alágbára akọni ọkùnrin.
Le zao ty famoliliañe iareo ty aman’ anjomban-droae’e: am’ Iehoda, o mpifelek’ arivoo: i Adnà mpiaolo, reketse fanalolahy mahasibeke telo-hetse;
15 Èkejì, Jehohanani olórí, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlá ọkùnrin;
nanonjohy aze t’Iehohanane mpiaolo reketse roe-hetse-tsi-valo-ale;
16 àtẹ̀lé Amasiah ọmọ Sikri, ẹni tí ó fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ Olúwa pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́wàá.
nañorik’ aze t’i Amasià, ana’ i Zikrý, mpanolo-batañe ho am’ Iehovà, fanalolahy maozatse roe-hetse ty tama’e;
17 Láti ọ̀dọ̀ Benjamini: Eliada, alágbára akọni ọkùnrin pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́wàá àwọn jagunjagun ọkùnrin pẹ̀lú ọrun àti àpáta ìhámọ́ra;
le amy Beniamine, i Eliada, lahindefo maozatse nahasibeke, reketse mpitàm-pale naho fikalandefoñe roe-hetse;
18 àtẹ̀lé Jehosabadi, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án jagunjagun ọkùnrin múra sílẹ̀ fún ogun.
le añ’ila’e t’Iehozabade reketse rai-hetse-tsi-valo-ale veka’e hialy.
19 Wọ̀nyí ni àwọn ọkùnrin tí ń dúró níwájú ọba, ní àyíká àwọn ẹni tí ó fi sínú ìlú olódi ní àyíká gbogbo Juda.
Irezay ro nitoroñe i mpanjakay mandikoatse o napo’e amo rova fatratse nanitsike Iehodào iabio.