< 2 Chronicles 17 >

1 Jehoṣafati ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀ ó sì mú ara rẹ̀ lágbára sí lórí Israẹli.
Uralkodék pedig ő helyette az ő fia, Jósafát, és megerősíté magát Izráel ellen.
2 Ó sì fi ogun sínú gbogbo ìlú olódi Juda ó sì kó ẹgbẹ́ ológun ní Juda àti nínú ìlú Efraimu tí Asa baba rẹ̀ ti gbà.
És sereget helyezett Júda minden erős városaiba, és őrségeket helyezett Júda országába és Efraim városaiba, a melyeket az ő atyja, Asa meghódított vala.
3 Olúwa sì wà pẹ̀lú Jehoṣafati nítorí, ní ọdún àkọ́kọ́ rẹ̀, ó rìn ní ọ̀nà ti baba rẹ̀ Dafidi ti rìn, kò sì fi ọ̀ràn lọ Baali.
És az Úr Jósafáttal vala, mivel az ő atyjának Dávidnak előbbi útain jára, és nem kére segítséget a bálványoktól,
4 Ṣùgbọ́n ó wá Ọlọ́run baba rẹ̀ kiri ó sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ̀ ju iṣẹ́ Israẹli.
Hanem az ő atyjának Istenét kereste, és az ő parancsolatiban járt vala, és nem Izráelnek cselekedetei szerint.
5 Olúwa sì fi ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ lábẹ́ àkóso rẹ̀, gbogbo Juda sì mú ẹ̀bùn wá fún Jehoṣafati, bẹ́ẹ̀ ni ó sì ní ọrọ̀ àti ọlá lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Azért az Úr megerősíté a királyságot az ő kezében, és az egész Júda ada Jósafátnak ajándékot, s gazdagsága és dicsősége igen nagy volt.
6 Ọkàn rẹ̀ sì gbé sókè si ọ̀nà Olúwa, pẹ̀lúpẹ̀lú, ó sì mú ibi gíga wọn àti ère òrìṣà Aṣerah kúrò ní Juda.
És az ő szíve felemelkedett az Úr útjain, és még jobban kiirtá Júdából a magaslatokat és az Aserákat.
7 Ní ọdún kẹta ìjọba rẹ̀, ó rán àwọn ìjòyè rẹ̀ Bene-Haili, Obadiah, Sekariah, Netaneli, Mikaiah láti máa kọ́ ni nínú ìlú Juda.
Királyságának harmadik esztendejében elküldé az ő vezérei közül Benhailát, Obádiást, Zakariást, Nétanéelt és Mikáját, hogy tanítsanak a Júda városaiban,
8 Wọ́n sì ní díẹ̀ lára àwọn ọmọ Lefi, àní Ṣemaiah, Netaniah, Sebadiah, Asaheli, Ṣemiramotu, Jehonatani, Adonijah, Tobijah àti Tobu-Adonijah àti àwọn àlùfáà Eliṣama àti Jehoramu.
És velök Lévitákat: Semája, Nétánia, Zebádia, Asáel, Semirámót, Jónatán, Adónia, Tóbiás és Tóbadónia Lévitákat, és velök Elisáma és Jórám papokat.
9 Wọ́n ń kọ́ ni ní agbègbè Juda, wọ́n mú ìwé òfin Olúwa wọ́n sì rìn yíká gbogbo àwọn ìlú Juda wọ́n sì ń kọ́ àwọn ènìyàn.
Tanítának azért Júdában, és az Úr törvényének könyve velök vala, mikor jártak vala Júda városaiban, tanítván a népet.
10 Ìbẹ̀rù Olúwa bà lórí gbogbo ìjọba ilẹ̀ tí ó yí Juda ká, dé bi pé wọn kò bá Jehoṣafati jagun.
Ezért az Úr igen megrettenté a földnek minden országait, a melyek Júda körül valának, annyira, hogy nem merének Jósafát ellen hadakozni.
11 Lára àwọn ará Filistini, mú ẹ̀bùn fàdákà gẹ́gẹ́ bí owó ọba wá fún Jehoṣafati, àwọn ará Arabia sì mú ọ̀wọ́ ẹran wá fún un, ẹgbàarindín ní ọ̀ọ́dúnrún àgbò àti ẹgbàarindín ní ọ̀ọ́dúnrún òbúkọ.
A Filiszteusoktól is hoznak vala Jósafátnak ajándékot és adópénzt; az Arábiabeliek is hoznak néki nyájakat, hétezerhétszáz kost és hétezerhétszáz bakot.
12 Jehoṣafati sì ń di alágbára nínú agbára sí i, ó sì kọ́ ilé olódi àti ilé ìṣúra púpọ̀ ní Juda
És Jósafát mindig nagyobb és hatalmasabb lőn, és építe Júdában kastélyokat és tárházakat.
13 Ó sì ní ìṣúra ní ìlú Juda. Ó sì tún ní àwọn alágbára jagunjagun akọni ọkùnrin ní Jerusalẹmu.
És sok munkája vala néki Júda városaiban, és erős hadakozó férfiakból álló serege volt Jeruzsálemben.
14 Iye wọn gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn nìwọ̀nyí. Láti Juda, àwọn olórí ìpín kan ti ẹgbẹ̀rún: Adina olórí, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún alágbára akọni ọkùnrin.
Ez pedig azoknak száma nemzetségeik szerint: Júdában az ezredesek: Adna, a fővezér, és vele háromszázezer harczos.
15 Èkejì, Jehohanani olórí, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlá ọkùnrin;
Mellette Johanán volt a vezér, és vele kétszáznyolczvanezer ember.
16 àtẹ̀lé Amasiah ọmọ Sikri, ẹni tí ó fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ Olúwa pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́wàá.
Mellette Amásia, a Zikri fia, a ki magát szabadakaratjából az Úrnak kötelezte vala; és ő vele kétszázezer harczos.
17 Láti ọ̀dọ̀ Benjamini: Eliada, alágbára akọni ọkùnrin pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́wàá àwọn jagunjagun ọkùnrin pẹ̀lú ọrun àti àpáta ìhámọ́ra;
A Benjámin nemzetségéből vitéz harczos vala Eljada, és vele a kézívesek és paizsosok kétszázezeren.
18 àtẹ̀lé Jehosabadi, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án jagunjagun ọkùnrin múra sílẹ̀ fún ogun.
Mellette Józabád, és vele száznyolczvanezeren harczra felszerelve.
19 Wọ̀nyí ni àwọn ọkùnrin tí ń dúró níwájú ọba, ní àyíká àwọn ẹni tí ó fi sínú ìlú olódi ní àyíká gbogbo Juda.
Ezek szolgálnak vala a királynak azokon kivül, a kiket a király egész Júdában a megerősített városokba helyezett.

< 2 Chronicles 17 >