< 2 Chronicles 17 >

1 Jehoṣafati ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀ ó sì mú ara rẹ̀ lágbára sí lórí Israẹli.
Et Josaphat, son fils, devint roi en sa place,
2 Ó sì fi ogun sínú gbogbo ìlú olódi Juda ó sì kó ẹgbẹ́ ológun ní Juda àti nínú ìlú Efraimu tí Asa baba rẹ̀ ti gbà.
et il se fortifia contre Israël. Et il mit des troupes dans toutes les villes de Juda, qui étaient places fortes, et mit des garnisons dans le pays de Juda et dans les villes d'Ephraïm conquises par Asa, son père.
3 Olúwa sì wà pẹ̀lú Jehoṣafati nítorí, ní ọdún àkọ́kọ́ rẹ̀, ó rìn ní ọ̀nà ti baba rẹ̀ Dafidi ti rìn, kò sì fi ọ̀ràn lọ Baali.
Et l'Éternel fut avec Josaphat, car il marcha sur les premiers errements de David, son père, et ne chercha pas les Baals,
4 Ṣùgbọ́n ó wá Ọlọ́run baba rẹ̀ kiri ó sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ̀ ju iṣẹ́ Israẹli.
mais ce fut le Dieu de son père qu'il chercha et dont il suivit les commandements et non point l'exemple d'Israël.
5 Olúwa sì fi ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ lábẹ́ àkóso rẹ̀, gbogbo Juda sì mú ẹ̀bùn wá fún Jehoṣafati, bẹ́ẹ̀ ni ó sì ní ọrọ̀ àti ọlá lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Et l'Éternel affermit la royauté dans sa main, et tout Juda faisait des présents à Josaphat, et il eut richesse et gloire en abondance.
6 Ọkàn rẹ̀ sì gbé sókè si ọ̀nà Olúwa, pẹ̀lúpẹ̀lú, ó sì mú ibi gíga wọn àti ère òrìṣà Aṣerah kúrò ní Juda.
Et son courage s'éleva comme il suivait les voies de l'Éternel, et de plus il fit disparaître de Juda les tertres et les Aschères.
7 Ní ọdún kẹta ìjọba rẹ̀, ó rán àwọn ìjòyè rẹ̀ Bene-Haili, Obadiah, Sekariah, Netaneli, Mikaiah láti máa kọ́ ni nínú ìlú Juda.
Et la troisième année de son règne il délégua ses Chefs Ben-Haïl et Obadia et Zacharie et Nethaneël et Michée pour enseigner dans les villes de Juda,
8 Wọ́n sì ní díẹ̀ lára àwọn ọmọ Lefi, àní Ṣemaiah, Netaniah, Sebadiah, Asaheli, Ṣemiramotu, Jehonatani, Adonijah, Tobijah àti Tobu-Adonijah àti àwọn àlùfáà Eliṣama àti Jehoramu.
et avec eux les Lévites Semaïa et Nethania et Zebadia et Asahel et Semiramoth et Jonathan et Adonia et Tobie et Tob-Adonia, Lévites, et avec eux Elisama et Joram, Prêtres.
9 Wọ́n ń kọ́ ni ní agbègbè Juda, wọ́n mú ìwé òfin Olúwa wọ́n sì rìn yíká gbogbo àwọn ìlú Juda wọ́n sì ń kọ́ àwọn ènìyàn.
Et ils enseignèrent en Juda, munis du Livre de la Loi de l'Éternel, et ils firent le tour de toutes les villes de Juda et enseignèrent parmi le peuple.
10 Ìbẹ̀rù Olúwa bà lórí gbogbo ìjọba ilẹ̀ tí ó yí Juda ká, dé bi pé wọn kò bá Jehoṣafati jagun.
Et la terreur de l'Éternel pesa sur tous les royaumes des pays environnant Juda, de telle sorte qu'ils ne s'attaquèrent point à Josaphat.
11 Lára àwọn ará Filistini, mú ẹ̀bùn fàdákà gẹ́gẹ́ bí owó ọba wá fún Jehoṣafati, àwọn ará Arabia sì mú ọ̀wọ́ ẹran wá fún un, ẹgbàarindín ní ọ̀ọ́dúnrún àgbò àti ẹgbàarindín ní ọ̀ọ́dúnrún òbúkọ.
Et il y eut des Philistins qui apportaient à Josaphat des présents et de l'argent en masse; les Arabes aussi lui amenèrent du menu bétail, sept mille sept cents béliers et sept mille sept cents boucs.
12 Jehoṣafati sì ń di alágbára nínú agbára sí i, ó sì kọ́ ilé olódi àti ilé ìṣúra púpọ̀ ní Juda
Et Josaphat allait grandissant jusqu'au plus haut point, et il construisit en Juda des châteaux et des villes avec magasins,
13 Ó sì ní ìṣúra ní ìlú Juda. Ó sì tún ní àwọn alágbára jagunjagun akọni ọkùnrin ní Jerusalẹmu.
et il faisait faire des travaux considérables dans les villes de Juda, et il avait des gens de guerre, vaillants soldats, à Jérusalem.
14 Iye wọn gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn nìwọ̀nyí. Láti Juda, àwọn olórí ìpín kan ti ẹgbẹ̀rún: Adina olórí, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún alágbára akọni ọkùnrin.
Et voici leur rôle selon leurs maisons patriarcales. En Juda étaient chefs de milliers Adna, le chef, ayant avec lui trois cent mille vaillants soldats,
15 Èkejì, Jehohanani olórí, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlá ọkùnrin;
et à côté de lui Jochanan, le chef avec ses deux cent quatre-vingt mille hommes,
16 àtẹ̀lé Amasiah ọmọ Sikri, ẹni tí ó fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ Olúwa pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́wàá.
et à côté de lui Amasia, fils de Zichri, volontaire de l'Éternel, avec ses deux cent mille vaillants soldats.
17 Láti ọ̀dọ̀ Benjamini: Eliada, alágbára akọni ọkùnrin pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́wàá àwọn jagunjagun ọkùnrin pẹ̀lú ọrun àti àpáta ìhámọ́ra;
Et de Benjamin: le vaillant Eliada et avec lui deux cent mille hommes armés de l'arc et du bouclier,
18 àtẹ̀lé Jehosabadi, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án jagunjagun ọkùnrin múra sílẹ̀ fún ogun.
et à côté de lui Jozabad, et avec lui cent quatre-vingt mille hommes équipés pour le combat.
19 Wọ̀nyí ni àwọn ọkùnrin tí ń dúró níwájú ọba, ní àyíká àwọn ẹni tí ó fi sínú ìlú olódi ní àyíká gbogbo Juda.
Tels étaient ceux qui étaient au service du roi, non compris ceux que le roi avait placés dans les villes fortes dans tout Juda.

< 2 Chronicles 17 >