< 2 Chronicles 17 >
1 Jehoṣafati ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀ ó sì mú ara rẹ̀ lágbára sí lórí Israẹli.
Then Jehoshaphat, his son, reigned in his place. And he grew strong against Israel.
2 Ó sì fi ogun sínú gbogbo ìlú olódi Juda ó sì kó ẹgbẹ́ ológun ní Juda àti nínú ìlú Efraimu tí Asa baba rẹ̀ ti gbà.
And he appointed numbers of soldiers in all the cities of Judah that had been fortified with walls. And he placed garrisons in the land of Judah, and in the cities of Ephraim that his father Asa had seized.
3 Olúwa sì wà pẹ̀lú Jehoṣafati nítorí, ní ọdún àkọ́kọ́ rẹ̀, ó rìn ní ọ̀nà ti baba rẹ̀ Dafidi ti rìn, kò sì fi ọ̀ràn lọ Baali.
And the Lord was with Jehoshaphat, because he walked in the first ways of his father, David. And he did not trust in the Baals,
4 Ṣùgbọ́n ó wá Ọlọ́run baba rẹ̀ kiri ó sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ̀ ju iṣẹ́ Israẹli.
but in the God of his father. And he advanced in his precepts, and not according to the sins of Israel.
5 Olúwa sì fi ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ lábẹ́ àkóso rẹ̀, gbogbo Juda sì mú ẹ̀bùn wá fún Jehoṣafati, bẹ́ẹ̀ ni ó sì ní ọrọ̀ àti ọlá lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
And the Lord confirmed the kingdom in his hand. And all of Judah gave gifts to Jehoshaphat. And innumerable riches were brought to him, and much glory.
6 Ọkàn rẹ̀ sì gbé sókè si ọ̀nà Olúwa, pẹ̀lúpẹ̀lú, ó sì mú ibi gíga wọn àti ère òrìṣà Aṣerah kúrò ní Juda.
And when his heart had taken courage because of the ways of the Lord, he now also took away the high places and the sacred groves from Judah.
7 Ní ọdún kẹta ìjọba rẹ̀, ó rán àwọn ìjòyè rẹ̀ Bene-Haili, Obadiah, Sekariah, Netaneli, Mikaiah láti máa kọ́ ni nínú ìlú Juda.
Then, in the third year of his reign, he sent Benhail, and Obadiah, and Zechariah, and Nethanel, and Micaiah, from among his leaders, so that they might teach in the cites of Judah.
8 Wọ́n sì ní díẹ̀ lára àwọn ọmọ Lefi, àní Ṣemaiah, Netaniah, Sebadiah, Asaheli, Ṣemiramotu, Jehonatani, Adonijah, Tobijah àti Tobu-Adonijah àti àwọn àlùfáà Eliṣama àti Jehoramu.
And with them were the Levites Shemaiah and Nethaniah and Zebadiah, and also Asahel and Shemiramoth and Jehonathan, and the Levites Adonijah and Tobijah and Tobadonijah. And with them were the priests Elishama and Jehoram.
9 Wọ́n ń kọ́ ni ní agbègbè Juda, wọ́n mú ìwé òfin Olúwa wọ́n sì rìn yíká gbogbo àwọn ìlú Juda wọ́n sì ń kọ́ àwọn ènìyàn.
And they were teaching the people in Judah, having with them the book of the law of the Lord. And they were traveling through all the cities of Judah, and were instructing the people.
10 Ìbẹ̀rù Olúwa bà lórí gbogbo ìjọba ilẹ̀ tí ó yí Juda ká, dé bi pé wọn kò bá Jehoṣafati jagun.
And so, the fear of the Lord fell upon all the kingdoms of the lands which were around Judah. And they did not dare to make war against Jehoshaphat.
11 Lára àwọn ará Filistini, mú ẹ̀bùn fàdákà gẹ́gẹ́ bí owó ọba wá fún Jehoṣafati, àwọn ará Arabia sì mú ọ̀wọ́ ẹran wá fún un, ẹgbàarindín ní ọ̀ọ́dúnrún àgbò àti ẹgbàarindín ní ọ̀ọ́dúnrún òbúkọ.
Moreover, the Philistines carried gifts to Jehoshaphat, and a tribute in silver. Also, the Arabians brought cattle: seven thousand seven hundred rams, and the same number of he-goats.
12 Jehoṣafati sì ń di alágbára nínú agbára sí i, ó sì kọ́ ilé olódi àti ilé ìṣúra púpọ̀ ní Juda
Therefore, Jehoshaphat increased and was magnified, even on high. And in Judah, he built houses in the likeness of towers, and walled cities.
13 Ó sì ní ìṣúra ní ìlú Juda. Ó sì tún ní àwọn alágbára jagunjagun akọni ọkùnrin ní Jerusalẹmu.
And he prepared many works in the cities of Judah. Also, there were men experienced in warfare in Jerusalem,
14 Iye wọn gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn nìwọ̀nyí. Láti Juda, àwọn olórí ìpín kan ti ẹgbẹ̀rún: Adina olórí, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún alágbára akọni ọkùnrin.
and this is the number of them, by each of the houses and families. In Judah, the leader of the army was Adnah, the commander; and with him were three hundred thousand very experienced men.
15 Èkejì, Jehohanani olórí, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlá ọkùnrin;
After him, Jehohanan was the leader; and with him were two hundred eighty thousand.
16 àtẹ̀lé Amasiah ọmọ Sikri, ẹni tí ó fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ Olúwa pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́wàá.
Also after him, there was Amasiah, the son of Zichri, who was consecrated to the Lord; and with him were two hundred thousand strong men.
17 Láti ọ̀dọ̀ Benjamini: Eliada, alágbára akọni ọkùnrin pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́wàá àwọn jagunjagun ọkùnrin pẹ̀lú ọrun àti àpáta ìhámọ́ra;
Following him, there was Eliada, who was experienced in battle; and with him were two hundred thousand, holding bow and shield.
18 àtẹ̀lé Jehosabadi, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án jagunjagun ọkùnrin múra sílẹ̀ fún ogun.
Then too, after him, there was Jehozabad; and with him were one hundred eighty thousand lightly-armed soldiers.
19 Wọ̀nyí ni àwọn ọkùnrin tí ń dúró níwájú ọba, ní àyíká àwọn ẹni tí ó fi sínú ìlú olódi ní àyíká gbogbo Juda.
All these were at the hand of the king, aside from the others, whom he had positioned in the walled cities, in all of Judah.