< 2 Chronicles 16 >

1 Ní ọdún kẹrìndínlógójì ìjọba Asa, Baaṣa ọba Israẹli gòkè wá sí Juda ó sì kọlu Rama, láti ma bá a jẹ́ kí ẹnikẹ́ni lè jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba Juda lọ.
I Asas trettiosjätte regeringsår drog Baesa, Israels konung, upp mot Juda och begynte befästa Rama, för att hindra att någon komme vare sig från eller till Asa, Juda konung.
2 Nígbà náà ni Asa mú wúrà àti fàdákà jáde nínú ilé ìṣúra ilé Olúwa àti ààfin ọba ó sì ránṣẹ́ sí Beni-Hadadi ọba Siria, ẹni tí ń gbé ní Damasku, ó wí pé,
Då tog Asa silver och guld ur skattkamrarna i HERRENS hus och i konungshuset, och sände det till Ben-Hadad, konungen i Aram, som bodde i Damaskus, och lät säga:
3 “Májẹ̀mú kan wà láàrín èmi àti ìrẹ, bí ó ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Ẹ wò ó, mo fi wúrà àti fàdákà ránṣẹ́ sí ọ; lọ, ba májẹ̀mú tí o bá Baaṣa ọba Israẹli dá jẹ́, kí ó lè lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.”
"Ett förbund består ju mellan mig och dig, såsom det var mellan min fader och din fader. Se, här sänder jag dig silver och guld; så bryt då ditt förbund med Baesa, Israels konung, för att han må lämna mig i fred."
4 Beni-Hadadi sì gbọ́ ti Asa ọba, ó sì rán àwọn olórí ogun rẹ̀ lọ sí àwọn ìlú Israẹli, wọ́n sì kọlu Ijoni, Dani, Abeli-Maimu, àti gbogbo ìlú ìṣúra Naftali.
Och Ben-Hadad lyssnade till konung Asa och sände sina krigshövitsmän mot Israels städer, och de förhärjade Ijon, Dan och Abel-Maim samt alla förrådshus i Naftali städer.
5 Nígbà tí Baaṣa gbọ́ èyí, ó sì dá kíkọ́ Rama dúró, ó sì dá iṣẹ́ rẹ̀ dúró.
När Baesa hörde detta, avstod han från att befästa Rama och lät sina arbeten där upphöra.
6 Nígbà náà ní ọba Asa kó gbogbo àwọn ènìyàn Juda jọ, wọ́n sì kó òkúta àti igi Rama lọ èyí ti Baaṣa ń fi kọ́lé; ó sì fi kọ́ Geba àti Mispa.
Men konung Asa tog med sig hela Juda, och de förde bort ifrån Rama stenar och trävirke som Baesa använde till att befästa det. Därmed befäste han så Geba och Mispa.
7 Ní àkókò náà wòlíì Hanani wá sí ọ̀dọ̀ Asa ọba Juda, ó sì wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ọba Siria, ìwọ kò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run rẹ, nítorí náà ni ogún ọba Siria ṣe bọ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ.
Vid samma tid kom siaren Hanani till Asa, Juda konung, och sade till honom: "Eftersom du stödde dig på konungen i Aram och icke stödde dig på HERREN, din Gud, därför har den arameiske konungens här sluppit undan din hand.
8 Àwa kì í ṣe ará Etiopia àti àwọn ará Libia àwọn alágbára ogun pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹlẹ́ṣin? Síbẹ̀ nígbà tí ìwọ bá gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò sì fi wọ́n lé ọwọ́ rẹ.
Voro icke etiopierna och libyerna en väldig här, med vagnar och ryttare i stor myckenhet? Men därför att du då stödde dig på HERREN, gav han dem i din hand.
9 Nítorí ojú Olúwa yí gbogbo ayé ká láti fi agbára fún àwọn ẹni tí ó ní ọkàn pípé sí i. Ìwọ ti ṣe ohun aṣiwèrè, láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ yóò wà lójú ogun.”
TY HERRENS ögon överfara hela jorden, för att han med sin kraft skall bistå dem som med sina hjärtan hängiva sig åt honom. Härutinnan har du handlat dåraktigt. Därför skall du hädanefter hava ständiga strider."
10 Asa sì bínú pẹ̀lú sí wòlíì nítorí èyí, ó sì mú un bínú gidigidi tí ó sì fi mú un sínú túbú. Ní àkókò náà Asa sì ni díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn náà lára.
Men Asa blev förtörnad på siaren och satte honom i stockhuset; så förbittrad var han på honom för vad han hade sagt. Vid samma tid förfor Asa ock våldsamt mot andra av folket.
11 Àwọn iṣẹ́ ìjọba Asa, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni akọ sínú ìwé ọba Juda àti Israẹli.
Men vad som är att säga om Asa, om hans första tid såväl som om hans sista, det finnes upptecknat i boken om Judas och Israels konungar.
12 Ní ọdún kọkàndínlógójì ìjọba rẹ̀, Asa sì ṣe àìsàn pẹ̀lú ààrùn nínú ẹsẹ̀ rẹ̀. Bi ó tilẹ̀ jẹ pé ààrùn rẹ̀ lágbára, síbẹ̀ kódà nínú àìsàn rẹ̀ kò wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ àwọn oníṣègùn nìkan.
Och i sitt trettionionde regeringsår fick Asa en sjukdom i sina fötter, och sjukdomen blev övermåttan svår; men oaktat sin sjukdom sökte han icke HERREN, utan allenast läkares hjälp.
13 Nígbà náà tí ó pé ọdún kọ́kànlélógójì rẹ̀, Asa kú, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn ìjọba baba rẹ̀,
Och Asa gick till vila hos sina fäder och dog i sitt fyrtioförsta regeringsår.
14 wọ́n sì sin ín sínú isà òkú tí ó ti gbẹ́ jáde fún ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi. Wọ́n sì tẹ sí orí àkéte tí ó fi òórùn dídùn kún, àti onírúurú tùràrí tí a fi ọgbọ́n pèsè, wọ́n sì da iná ńlá nítorí rẹ̀.
Och man begrov honom i den grav som han hade låtit hugga ut åt sig i Davids stad; och man lade honom på en bädd som man hade fyllt med vällukter och kryddor av olika slag, konstmässigt beredda, och anställde till hans ära en mycket stor förbränning.

< 2 Chronicles 16 >