< 2 Chronicles 16 >
1 Ní ọdún kẹrìndínlógójì ìjọba Asa, Baaṣa ọba Israẹli gòkè wá sí Juda ó sì kọlu Rama, láti ma bá a jẹ́ kí ẹnikẹ́ni lè jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba Juda lọ.
Године тридесет шесте царовања Асиног изиђе Васа, цар Израиљев, на Јуду, и стаде зидати Раму да не да никоме отићи к Аси, цару Јудином, ни од њега доћи.
2 Nígbà náà ni Asa mú wúrà àti fàdákà jáde nínú ilé ìṣúra ilé Olúwa àti ààfin ọba ó sì ránṣẹ́ sí Beni-Hadadi ọba Siria, ẹni tí ń gbé ní Damasku, ó wí pé,
Тада узе Аса сребро и злато из ризница дома Господњег и дома царевог, и посла Вен-Ададу цару сирском, који живљаше у Дамаску, и поручи:
3 “Májẹ̀mú kan wà láàrín èmi àti ìrẹ, bí ó ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Ẹ wò ó, mo fi wúrà àti fàdákà ránṣẹ́ sí ọ; lọ, ba májẹ̀mú tí o bá Baaṣa ọba Israẹli dá jẹ́, kí ó lè lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.”
Вера је између мене и тебе, између оца мог и оца твог, ево шаљем ти сребра и злата, хајде поквари веру коју имаш са Васом царем Израиљевим, еда би отишао од мене.
4 Beni-Hadadi sì gbọ́ ti Asa ọba, ó sì rán àwọn olórí ogun rẹ̀ lọ sí àwọn ìlú Israẹli, wọ́n sì kọlu Ijoni, Dani, Abeli-Maimu, àti gbogbo ìlú ìṣúra Naftali.
И послуша Вен-Адад цара Асу, и посла војводе своје на градове Израиљеве, и освојише Ијон и Дан и Авел-Мајим и све градове Нефталимове у којима беху житнице.
5 Nígbà tí Baaṣa gbọ́ èyí, ó sì dá kíkọ́ Rama dúró, ó sì dá iṣẹ́ rẹ̀ dúró.
А кад Васа то чу, преста зидати Раму и остави дело своје.
6 Nígbà náà ní ọba Asa kó gbogbo àwọn ènìyàn Juda jọ, wọ́n sì kó òkúta àti igi Rama lọ èyí ti Baaṣa ń fi kọ́lé; ó sì fi kọ́ Geba àti Mispa.
Тада цар Аса узе сав народ Јудин, те однесоше камење из Раме и дрво, чим зидаше Васа, и од њега сазида Гавају и Миспу.
7 Ní àkókò náà wòlíì Hanani wá sí ọ̀dọ̀ Asa ọba Juda, ó sì wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ọba Siria, ìwọ kò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run rẹ, nítorí náà ni ogún ọba Siria ṣe bọ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ.
А у то време дође Ананије виделац к Аси, цару Јудином, и рече му: Што си се поуздао у цара сирског а ниси се поуздао у Господа Бога свог, зато се војска цара сирског измаче из твојих руку.
8 Àwa kì í ṣe ará Etiopia àti àwọn ará Libia àwọn alágbára ogun pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹlẹ́ṣin? Síbẹ̀ nígbà tí ìwọ bá gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò sì fi wọ́n lé ọwọ́ rẹ.
Нису ли Етиопљани и Лувеји имали велике војске с врло много кола и коњика? Па кад си се поуздао у Господа, даде ти их у руке.
9 Nítorí ojú Olúwa yí gbogbo ayé ká láti fi agbára fún àwọn ẹni tí ó ní ọkàn pípé sí i. Ìwọ ti ṣe ohun aṣiwèrè, láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ yóò wà lójú ogun.”
Јер очи Господње гледају по свој земљи да би показивао силу своју према онима којима је срце цело према Њему. Лудо си у том радио; зато ће одсада бити ратови на те.
10 Asa sì bínú pẹ̀lú sí wòlíì nítorí èyí, ó sì mú un bínú gidigidi tí ó sì fi mú un sínú túbú. Ní àkókò náà Asa sì ni díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn náà lára.
Тада се Аса разгневи на пророка, и стави га у тамницу, јер се расрди на њ за то; и потлачи Аса неке из народа у то време.
11 Àwọn iṣẹ́ ìjọba Asa, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni akọ sínú ìwé ọba Juda àti Israẹli.
Али гле, дела Асина, прва и последња, ено записана су у књизи о царевима Јудиним и Израиљевим.
12 Ní ọdún kọkàndínlógójì ìjọba rẹ̀, Asa sì ṣe àìsàn pẹ̀lú ààrùn nínú ẹsẹ̀ rẹ̀. Bi ó tilẹ̀ jẹ pé ààrùn rẹ̀ lágbára, síbẹ̀ kódà nínú àìsàn rẹ̀ kò wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ àwọn oníṣègùn nìkan.
И разболе се Аса тридесет девете године царовања свог од ногу, и болест његова би врло тешка, али ни у болести својој не тражи Господа него лекаре.
13 Nígbà náà tí ó pé ọdún kọ́kànlélógójì rẹ̀, Asa kú, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn ìjọba baba rẹ̀,
И тако почину Аса код отаца својих, и умре четрдесет прве године царовања свог.
14 wọ́n sì sin ín sínú isà òkú tí ó ti gbẹ́ jáde fún ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi. Wọ́n sì tẹ sí orí àkéte tí ó fi òórùn dídùn kún, àti onírúurú tùràrí tí a fi ọgbọ́n pèsè, wọ́n sì da iná ńlá nítorí rẹ̀.
И погребоше га у гробу његовом, који ископа себи у граду Давидовом, и метнуше га на постељу коју беше напунио мирисавих ствари и масти зготовљених вештином апотекарском, и спалише му их врло много.