< 2 Chronicles 16 >

1 Ní ọdún kẹrìndínlógójì ìjọba Asa, Baaṣa ọba Israẹli gòkè wá sí Juda ó sì kọlu Rama, láti ma bá a jẹ́ kí ẹnikẹ́ni lè jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba Juda lọ.
In the six-and-thirtieth year of the reign of Assa, came up Ba'sha the king of Israel against Judah, and built Kamah, in order not to suffer any one to go out or come in to Assa the king of Judah.
2 Nígbà náà ni Asa mú wúrà àti fàdákà jáde nínú ilé ìṣúra ilé Olúwa àti ààfin ọba ó sì ránṣẹ́ sí Beni-Hadadi ọba Siria, ẹni tí ń gbé ní Damasku, ó wí pé,
Then did Assa bring out silver and gold out of the treasuries of the house of the Lord and of the king's house, and sent [them] to Ben-hadad the king of Syria, who dwelt at Damascus, saying,
3 “Májẹ̀mú kan wà láàrín èmi àti ìrẹ, bí ó ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Ẹ wò ó, mo fi wúrà àti fàdákà ránṣẹ́ sí ọ; lọ, ba májẹ̀mú tí o bá Baaṣa ọba Israẹli dá jẹ́, kí ó lè lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.”
A covenant is between me and thee, as between my father and thy father: behold, I have sent unto thee silver and gold; go, break thy covenant with Ba'sha the king of Israel, that he may withdraw from me.
4 Beni-Hadadi sì gbọ́ ti Asa ọba, ó sì rán àwọn olórí ogun rẹ̀ lọ sí àwọn ìlú Israẹli, wọ́n sì kọlu Ijoni, Dani, Abeli-Maimu, àti gbogbo ìlú ìṣúra Naftali.
And Ben-hadad hearkened unto king Assa, and sent the captains of the armies that he had against the cities of Israel, and they smote 'Iyon, and Dan, and Abel-mayim, and all the treasure-cities of Naphtali.
5 Nígbà tí Baaṣa gbọ́ èyí, ó sì dá kíkọ́ Rama dúró, ó sì dá iṣẹ́ rẹ̀ dúró.
And it came to pass, when Ba'sha heard this, that he left off the building of Ramah, and stopped his work.
6 Nígbà náà ní ọba Asa kó gbogbo àwọn ènìyàn Juda jọ, wọ́n sì kó òkúta àti igi Rama lọ èyí ti Baaṣa ń fi kọ́lé; ó sì fi kọ́ Geba àti Mispa.
And king Assa took then all Judah; and they carried away the stones of Ramah, and its timber, wherewith Ba'sha had built; and he built therewith Geba' and Mizpah.
7 Ní àkókò náà wòlíì Hanani wá sí ọ̀dọ̀ Asa ọba Juda, ó sì wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ọba Siria, ìwọ kò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run rẹ, nítorí náà ni ogún ọba Siria ṣe bọ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ.
And at that time came Chanani the seer to Assa the king of Judah, and said unto him, Because thou hast relied on the king of Syria, and hast not relied on the Lord thy God: therefore is the army of the king of Syria escaped out of thy hands.
8 Àwa kì í ṣe ará Etiopia àti àwọn ará Libia àwọn alágbára ogun pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹlẹ́ṣin? Síbẹ̀ nígbà tí ìwọ bá gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò sì fi wọ́n lé ọwọ́ rẹ.
Were not the Ethiopians and the Lubim a numerous army, with chariots and horsemen in great abundance? yet, because thou didst rely on the Lord, he gave them up into thy hand.
9 Nítorí ojú Olúwa yí gbogbo ayé ká láti fi agbára fún àwọn ẹni tí ó ní ọkàn pípé sí i. Ìwọ ti ṣe ohun aṣiwèrè, láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ yóò wà lójú ogun.”
For as regardeth the Lord, his eyes roam throughout the whole earth, to hold strongly with those whose heart is entire toward him: thou hast done foolishly for this reason; because from this time forth there will be wars with thee.
10 Asa sì bínú pẹ̀lú sí wòlíì nítorí èyí, ó sì mú un bínú gidigidi tí ó sì fi mú un sínú túbú. Ní àkókò náà Asa sì ni díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn náà lára.
Then became Assa incensed toward the seer, and put him in a prison-house; for he was in a rage with him because of this. And Assa oppressed some of the people at the same time.
11 Àwọn iṣẹ́ ìjọba Asa, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni akọ sínú ìwé ọba Juda àti Israẹli.
And, behold, the acts of Assa, the first and the last, lo, they are written in the book of the kings of Judah and Israel.
12 Ní ọdún kọkàndínlógójì ìjọba rẹ̀, Asa sì ṣe àìsàn pẹ̀lú ààrùn nínú ẹsẹ̀ rẹ̀. Bi ó tilẹ̀ jẹ pé ààrùn rẹ̀ lágbára, síbẹ̀ kódà nínú àìsàn rẹ̀ kò wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ àwọn oníṣègùn nìkan.
And Assa became sick in the thirty-and-ninth year of his reign in his feet, his disease being exceedingly severe: yet even in his disease he sought not to the Lord, but [applied] to the physicians.
13 Nígbà náà tí ó pé ọdún kọ́kànlélógójì rẹ̀, Asa kú, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn ìjọba baba rẹ̀,
And Assa slept with his fathers, and died in the one-and-fortieth year of his reign.
14 wọ́n sì sin ín sínú isà òkú tí ó ti gbẹ́ jáde fún ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi. Wọ́n sì tẹ sí orí àkéte tí ó fi òórùn dídùn kún, àti onírúurú tùràrí tí a fi ọgbọ́n pèsè, wọ́n sì da iná ńlá nítorí rẹ̀.
And they buried him in his own sepulchres, which he had dug for himself in the city of David, and they laid him in the couch which was filled with sweet odors and divers kinds of spices mixed by the apothecary's art; and they made for him a burning uncommonly great.

< 2 Chronicles 16 >