< 2 Chronicles 15 >

1 Ẹ̀mí Ọlọ́run wá sórí Asariah ọmọ Odedi.
Now, as for Azariah son of Oded, there came upon him, the spirit of God.
2 Ó jáde lọ bá Asa, ó sì wí fún un pé, “Tẹ́tí si mi Asa, àti gbogbo Juda àti Benjamini. Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, nígbà tí ìwọ bá wà pẹ̀lú rẹ̀. Ti ìwọ bá wá a, ìwọ yóò rí i ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ rẹ ṣùgbọ́n tí ìwọ bá kọ̀ ọ́ sílẹ̀, òun yóò kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
So he went forth to meet Asa, and said unto him, Hear me, O Asa, and all Judah and Benjamin, —Yahweh, is with you, so long as ye are with him, and, if ye seek him, he will be found of you, but, if ye forsake him, he will forsake you.
3 Fún ọjọ́ pípẹ́ ni Israẹli ti wà láì sin Ọlọ́run òtítọ́, àti láìní àlùfáà ti ń kọ́ ni, àti láìní òfin.
Now, many days, had Israel been, —without the faithful God, and without a teaching priest, and without the law;
4 Ṣùgbọ́n nínú ìpọ́njú wọn, wọ́n yí padà si Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wọ́n sì wa kiri. Wọ́n sì ri i ní ẹ̀gbẹ́ wọn.
But they turned, in their distress, unto Yahweh God of Israel, —and sought him, and he was found of them.
5 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ó léwu kí ènìyàn máa rìn ìrìnàjò kiri, nítorí tí gbogbo àwọn olùgbé ilẹ̀ náà wà nínú làálàá ńlá.
And, in those times, there had been no prosperity, to him that went out nor to him that came in, —for, great consternations, were upon all the inhabitants of the lands;
6 Orílẹ̀-èdè kan ń run èkejì àti ìlú kan sí òmíràn nítorí Ọlọ́run ń yọ wọ́n lẹ́nu pẹ̀lú oríṣìíríṣìí ìpọ́njú.
and they were beaten in pieces-nation against nation, and city against city, —for, God, discomfited them with all manner of distress.
7 Ṣùgbọ́n fun ìwọ, jẹ́ alágbára, kí ó má sì ṣe ṣàárẹ̀. Nítorí tí a ó fi èrè sí iṣẹ́ ẹ̀ rẹ.”
Ye, therefore, be strong, and let not your hands be slack, —for there is a reward for your work!
8 Nígbà tí Asa gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí àti àsọtẹ́lẹ̀ Asariah ọmọ Odedi wòlíì, ó mú àyà rẹ̀ le. Ó sì mú gbogbo ohun ìríra kúrò ní gbogbo ilẹ̀ Juda àti Benjamini àti kúrò nínú àwọn ìlú tí ó ti fi agbára mú ní orí òkè Efraimu. Ó tún pẹpẹ Olúwa ṣe tí ó wà ní iwájú portiko ti ilé Olúwa.
And, when Asa heard these words and the prophecy of Oded the prophet, he strengthened himself, and put away the abominations out of all the land of Judah and Benjamin, and out of the cities which he had captured out of the hill country of Ephraim, —and renewed the altar of Yahweh, that was before the porch of Yahweh.
9 Nígbà náà, ó pe gbogbo Juda àti Benjamini jọ àti àwọn ènìyàn láti Efraimu, Manase àti Simeoni tí ó ti ṣe àtìpó ní àárín wọn. Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn ti wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti Israẹli nígbà tí wọ́n rí i wí pé Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
And he gathered together all Judah and Benjamin, and the sojourners with them, out of Ephraim and out of Manasseh, and out of Simeon, —for they fell unto him out of Israel, in great numbers, because they saw that, Yahweh his God, was with him.
10 Wọ́n péjọ sí Jerusalẹmu ní oṣù kẹta ọdún kẹ́ẹ̀dógún ti ìjọba Asa.
So they gathered themselves together unto Jerusalem, in the third month of the fifteenth year of the reign of Asa.
11 Ní àkókò yìí, wọ́n rú ẹbọ sí Olúwa ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin akọ màlúù àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn àti àwọn ewúrẹ́ láti ibi ìkógun tí wọ́n ti kó padà.
And they sacrificed unto Yahweh, on that day, out of the spoil they had brought in, —oxen, seven hundred, and sheep, seven thousand.
12 Wọ́n sì tún dá májẹ̀mú láti wá Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn tinútinú wọn àti tọkàntọkàn wọn.
And they entered into a covenant, to seek Yahweh, God of their fathers, —with all their heart, and with all their soul;
13 Pé ẹnikẹ́ni tí kò bá wá Olúwa Ọlọ́run Israẹli, pípa ni á ó pa á láti ẹni kékeré dé orí ẹni ńlá àti ọkùnrin àti obìnrin.
and, whosoever would not seek unto Yahweh God of Israel, should be put to death, —whether small or great, whether man or woman.
14 Wọ́n sì búra ní ohùn rara fún Olúwa àti pẹ̀lú ìhó ńlá àti pẹ̀lú ìpè àti pẹ̀lú fèrè.
So they bound themselves by oath unto Yahweh, with a loud voice, and with shouting, —and with trumpets and with horns.
15 Gbogbo Juda yọ̀ nípa ìbúra náà nítorí wọ́n ti búra tinútinú wọn wọ́n sì fi gbogbo ìfẹ́ inú wọn wá a, wọ́n sì rí i, Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi yí káàkiri.
And all Judah rejoiced over the oath, for, with all their heart, had they sworn, and, with all their good will, had they sought him, and he was found of them, —and Yahweh gave them rest round about.
16 Ọba Asa sì mú Maaka ìyá ńlá rẹ̀ kúrò láti máa ṣe ayaba, nítorí tí ó yá ère kan fún Aṣerah òrìṣà rẹ̀. Asa sì ké ère náà lulẹ̀, ó sì jó o ní àfonífojì Kidironi.
Moreover also, as touching Maacah mother of Asa the king, he removed her from being queen, because she had made, unto the Sacred Stem, a monstrous thing, —so Asa cut down her monstrous thing, and reduced it to dust, and burnt it up, in the Kidron ravine.
17 Ṣùgbọ́n a kò mú àwọn ibi gíga náà kúrò ní Israẹli; síbẹ̀síbẹ̀ ọkàn Asa wà ní pípé ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo.
But, the high places, were not taken away out of Israel, —only, the heart of Asa, was perfect, all his days.
18 Ó sì mú àwọn ohun mímọ́ náà ti baba rẹ̀ àti àwọn ohun mímọ́ ti òun tìkára rẹ̀ tirẹ̀ wá sínú ilé Ọlọ́run, wúrà àti fàdákà àti àwọn ohun èlò náà.
And he brought the hallowed things of his father and his own hallowed things, into the house of God, —silver and gold, and utensils.
19 Kò sí ogun mọ́ títí fún ọdún márùndínlógójì ti ìjọba Asa.
And, war, was there none, —until the thirty-fifth year of the reign of Asa.

< 2 Chronicles 15 >