< 2 Chronicles 15 >
1 Ẹ̀mí Ọlọ́run wá sórí Asariah ọmọ Odedi.
Tada duh Božji dođe na Odedova sina Azarju.
2 Ó jáde lọ bá Asa, ó sì wí fún un pé, “Tẹ́tí si mi Asa, àti gbogbo Juda àti Benjamini. Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, nígbà tí ìwọ bá wà pẹ̀lú rẹ̀. Ti ìwọ bá wá a, ìwọ yóò rí i ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ rẹ ṣùgbọ́n tí ìwọ bá kọ̀ ọ́ sílẹ̀, òun yóò kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
On je izišao pred Asu i rekao mu: “Čujte me, Asa i sve Judino i Benjaminovo pleme! Jahve je s vama jer ste vi s njime; i ako ga budete tražili, naći ćete ga; ako li ga ostavite, i on će ostaviti vas.
3 Fún ọjọ́ pípẹ́ ni Israẹli ti wà láì sin Ọlọ́run òtítọ́, àti láìní àlùfáà ti ń kọ́ ni, àti láìní òfin.
Dugo su Izraelci bili bez pravoga Boga i bez svećenika-učitelja i bez Zakona.
4 Ṣùgbọ́n nínú ìpọ́njú wọn, wọ́n yí padà si Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wọ́n sì wa kiri. Wọ́n sì ri i ní ẹ̀gbẹ́ wọn.
Kad su se u nevolji obratili Jahvi, Bogu Izraelovu, i stali ga tražiti, našli su ga.
5 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ó léwu kí ènìyàn máa rìn ìrìnàjò kiri, nítorí tí gbogbo àwọn olùgbé ilẹ̀ náà wà nínú làálàá ńlá.
U ona vremena nitko nije mogao na miru ni izlaziti ni dolaziti, jer su veliki nemiri vladali među svim zemaljskim stanovnicima.
6 Orílẹ̀-èdè kan ń run èkejì àti ìlú kan sí òmíràn nítorí Ọlọ́run ń yọ wọ́n lẹ́nu pẹ̀lú oríṣìíríṣìí ìpọ́njú.
Udarao je narod na narod, grad na grad, jer ih je Jahve smeo svakojakom nevoljom.
7 Ṣùgbọ́n fun ìwọ, jẹ́ alágbára, kí ó má sì ṣe ṣàárẹ̀. Nítorí tí a ó fi èrè sí iṣẹ́ ẹ̀ rẹ.”
Ali vi budite hrabri i neka vam ne klonu ruke, jer ima nagrada za vaša djela.”
8 Nígbà tí Asa gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí àti àsọtẹ́lẹ̀ Asariah ọmọ Odedi wòlíì, ó mú àyà rẹ̀ le. Ó sì mú gbogbo ohun ìríra kúrò ní gbogbo ilẹ̀ Juda àti Benjamini àti kúrò nínú àwọn ìlú tí ó ti fi agbára mú ní orí òkè Efraimu. Ó tún pẹpẹ Olúwa ṣe tí ó wà ní iwájú portiko ti ilé Olúwa.
Čuvši te riječi i proročku besjedu proroka Odeda, Asa se ohrabri i ukloni idolske gadove iz cijele Judine i Benjaminove zemlje i iz gradova koje je bio osvojio u Efrajimovoj gori. Obnovio je i Jahvin žrtvenik koji je bio pred Jahvinim trijemom.
9 Nígbà náà, ó pe gbogbo Juda àti Benjamini jọ àti àwọn ènìyàn láti Efraimu, Manase àti Simeoni tí ó ti ṣe àtìpó ní àárín wọn. Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn ti wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti Israẹli nígbà tí wọ́n rí i wí pé Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
Onda je skupio sve Judino i Benjaminovo pleme i došljake koji su bili kod njih od Efrajimova, Manašeova i Šimunova plemena, jer ih je mnogo prebjeglo k njemu od Izraelaca kad su vidjeli da je s njim Jahve, njegov Bog.
10 Wọ́n péjọ sí Jerusalẹmu ní oṣù kẹta ọdún kẹ́ẹ̀dógún ti ìjọba Asa.
I skupili su se u Jeruzalemu trećega mjeseca petnaeste godine Asina kraljevanja.
11 Ní àkókò yìí, wọ́n rú ẹbọ sí Olúwa ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin akọ màlúù àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn àti àwọn ewúrẹ́ láti ibi ìkógun tí wọ́n ti kó padà.
Onoga su dana prinijeli Jahvi žrtve od plijena koji su dognali, sedam stotina goveda i sedam tisuća sitne stoke.
12 Wọ́n sì tún dá májẹ̀mú láti wá Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn tinútinú wọn àti tọkàntọkàn wọn.
Zavjetovaše se da će tražiti Jahvu, Boga svojih otaca, svim srcem i svom dušom.
13 Pé ẹnikẹ́ni tí kò bá wá Olúwa Ọlọ́run Israẹli, pípa ni á ó pa á láti ẹni kékeré dé orí ẹni ńlá àti ọkùnrin àti obìnrin.
A tko god ne bi tražio Jahvu, Izraelova Boga, da se pogubi, bio malen ili velik, čovjek ili žena.
14 Wọ́n sì búra ní ohùn rara fún Olúwa àti pẹ̀lú ìhó ńlá àti pẹ̀lú ìpè àti pẹ̀lú fèrè.
Zakleli su se Jahvi iza glasa i uz gromki poklik, uz trube i rogove.
15 Gbogbo Juda yọ̀ nípa ìbúra náà nítorí wọ́n ti búra tinútinú wọn wọ́n sì fi gbogbo ìfẹ́ inú wọn wá a, wọ́n sì rí i, Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi yí káàkiri.
Svi su se Judejci radovali zbog te zakletve jer su se iz svega srca zakleli i od sve su ga svoje volje tražili i našli ga. Jahve im je dao mir odasvud uokolo.
16 Ọba Asa sì mú Maaka ìyá ńlá rẹ̀ kúrò láti máa ṣe ayaba, nítorí tí ó yá ère kan fún Aṣerah òrìṣà rẹ̀. Asa sì ké ère náà lulẹ̀, ó sì jó o ní àfonífojì Kidironi.
I svoju mater Maaku ukloni kralj Asa s vlasti jer je bila načinila gada Ašeri. Asa je sasjekao njezina gada, satro ga i spalio u potoku Kidronu.
17 Ṣùgbọ́n a kò mú àwọn ibi gíga náà kúrò ní Israẹli; síbẹ̀síbẹ̀ ọkàn Asa wà ní pípé ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo.
Ali uzvišice nisu bile uklonjene iz Izraela. Ipak je Asino srce bilo privrženo Jahvi svega njegova života.
18 Ó sì mú àwọn ohun mímọ́ náà ti baba rẹ̀ àti àwọn ohun mímọ́ ti òun tìkára rẹ̀ tirẹ̀ wá sínú ilé Ọlọ́run, wúrà àti fàdákà àti àwọn ohun èlò náà.
Unio je u Dom Božji posvećene darove svoga oca i svoje: srebro i zlato i posuđe.
19 Kò sí ogun mọ́ títí fún ọdún márùndínlógójì ti ìjọba Asa.
Nije bilo rata sve do trideset i pete godine Asina kraljevanja.