< 2 Chronicles 14 >

1 Abijah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi. Asa ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Ní àwọn ọjọ́ rẹ̀, orílẹ̀-èdè wà ní àlàáfíà fún ọdún mẹ́wàá.
A gdy Abiasz zasnął ze swoimi ojcami, pogrzebano go w mieście Dawida. Wtedy jego syn Asa królował w jego miejsce. Za jego dni w ziemi panował pokój przez dziesięć lat.
2 Asa ṣe ohun tí ó dára, tí ó sì tọ́ ní ojú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
Asa czynił to, co [było] dobre i prawe w oczach PANA, jego Boga.
3 Ó gbé àwọn pẹpẹ àjèjì kúrò àti àwọn ibi gíga. Ó fọ́ àwọn òkúta tí a yà sọ́tọ̀, ó sì gé àwọn ère Aṣerah bolẹ̀.
Usunął bowiem ołtarze obcych bogów i wyżyny, pokruszył posągi i wyrąbał gaje.
4 Ó pa á láṣẹ fún Juda láti wá Olúwa Ọlọ́run àwọn baba a wọn àti láti tẹ̀lé àwọn òfin rẹ̀ àti àṣẹ.
Nakazał Judzie szukać PANA, Boga swoich ojców, i przestrzegać prawa i przykazań.
5 Ó gbé àwọn ibi gíga kúrò àti àwọn pẹpẹ tùràrí ní gbogbo ìlú ní Juda. Ìjọba sì wà ní àlàáfíà ní abẹ́ rẹ̀.
Zniósł też ze wszystkich miast Judy wyżyny i posągi, a królestwo za jego czasów zaznało pokoju.
6 Ó mọ àwọn ìlú ààbò ti Juda, níwọ̀n ìgbà tí ìlú ti wà ní àlàáfíà. Kò sí ẹnikẹ́ni ti o jagun pẹ̀lú rẹ̀ nígbà náà, nítorí Olúwa fún un ní ìsinmi.
Ponadto zbudował miasta warowne w Judzie, ponieważ w ziemi panował pokój i nie było wojny przeciwko niemu w tych latach. PAN bowiem dał mu odpoczynek.
7 “Ẹ jẹ́ kí a kọ́ àwọn ìlú wọ̀nyí,” ó wí fún Juda, “kí ẹ sì mọ odi yí wọn ká pẹ̀lú àwọn ilé ìṣọ́ gíga, àwọn ẹnu-ọ̀nà òde, àti àwọn ìpẹ́ẹ̀rẹ̀. Ilé náà ti wà, nítorí a ti béèrè lọ́wọ́ Olúwa Ọlọ́run wa; a béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, ó sì ti fún wa ní ìsinmi ní gbogbo ọ̀nà.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kọ́ ọ, wọn sì ṣe rere.
I powiedział do Judy: Zbudujmy te miasta i otoczmy [je] murami, wieżami, bramami i ryglami, póki ziemia jest w naszej mocy. Szukaliśmy bowiem PANA, naszego Boga, szukaliśmy go i dał nam zewsząd odpoczynek. Budowali więc i powodziło się im.
8 Asa ní àwọn ọmọ-ogun ti ó jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọkùnrin láti Juda. Pẹ̀lú àwọn ohun èlò àwọn àpáta ńlá àti ọ̀kọ̀ àti ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlá láti Benjamini wọ́n dira pẹ̀lú àwọn àpáta kéékèèké àti àwọn ọrun. Gbogbo àwọn wọ̀nyí jẹ́ ògbójú jagunjagun ọkùnrin.
I Asa miał wojsko z Judy – trzysta tysięcy noszących tarcze i włócznie, i z Beniamina – dwieście osiemdziesiąt tysięcy noszących puklerz i napinających łuk. Wszyscy oni [byli] bardzo dzielni.
9 Sera ará Etiopia yàn láti dojúkọ wọ́n, pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ọmọ-ogun pẹ̀lú ọ̀ọ́dúnrún kẹ̀kẹ́, wọ́n sì wá láti jìnnà réré bí Meraṣa.
Wtedy przeciwko nim nadciągnął Zerach Etiopczyk z wojskiem [liczącym] tysiąc tysięcy oraz trzystu rydwanami i dotarł aż do Mareszy.
10 Asa jáde lọ láti lọ bá a. Wọ́n sì mú ibi ogun ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Sefata lẹ́bàá Meraṣa.
Nadciągnął też i Asa przeciw niemu i stanęli w szyku bojowym w Dolinie Sefaty w Mareszy.
11 Nígbà náà, Asa ké pe Olúwa Ọlọ́run baba a rẹ̀, ó sì wí pé “Olúwa kò sí ẹnìkan bí rẹ láti rán aláìlágbára lọ́wọ́ láti dójú kọ alágbára. Ràn wá lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run wa, nítorí tí àwa gbẹ́kẹ̀lé ọ àti ní orúkọ rẹ ni àwa fi wá láti dojúkọ àwọn ọ̀pọ̀ ọmọ-ogun yìí. Olúwa, ìwọ ni Ọlọ́run wa; má ṣe jẹ́ kí ènìyàn kó ṣẹ́gun rẹ.”
Wtedy Asa zawołał do PANA, swego Boga, i powiedział: PANIE, ty nie potrzebujesz wielu, aby uratować tego, który nie ma siły. Ratuj nas, PANIE, nasz Boże, gdyż na tobie polegamy i w twoje imię idziemy przeciwko temu mnóstwu. Ty jesteś PANEM, naszym Bogiem. Niech człowiek nie zyska przewagi nad tobą.
12 Olúwa lu àwọn ará Kuṣi bolẹ̀ níwájú Asa àti Juda. Àwọn ará Kuṣi sálọ.
A PAN poraził Etiopczyków przed Asą i Judą tak, że Etiopczycy uciekli.
13 Asa àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sá tẹ̀lé wọn ní jìnnà réré sí Gerari. Ọ̀pọ̀lọpọ̀, àwọn ará Kuṣi ṣubú, wọn kò sì le sán padà mọ́. Wọn rún wọn mọ́lẹ̀ níwájú Olúwa àti ọmọ-ogun rẹ̀. Àwọn ọkùnrin Juda kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkógun.
I Asa wraz z ludem, który był z nim, ścigał ich aż do Gerary. I polegli Etiopczycy tak, że nikt się nie uratował, bo zostali starci przed PANEM i jego wojskiem. I nabrano bardzo dużo łupów.
14 Wọ́n pa gbogbo àwọn ìletò tí ó wà ní ẹ̀bá Gerari, nítorí tí ìpayà Olúwa ti sọ̀kalẹ̀ sórí wọn. Wọ́n kó gbogbo ìkógun àwọn ìletò yìí lọ, níwọ̀n ìgbà tí ọ̀pọ̀ ìkógun ti wà níbẹ̀.
Ponadto pobili wszystkie miasta dokoła Gerary, bo padł na nie strach PANA i złupili wszystkie miasta. Była bowiem w nich wielka zdobycz.
15 Wọ́n kọlu àwọn ibùdó àwọn darandaran, wọ́n sì gbé àwọn ọ̀wọ́ ẹran àgùntàn àti àwọn ewúrẹ́ àti àwọn ìbákasẹ. Nígbà náà wọ́n padà sí Jerusalẹmu.
Napadli także na namioty trzód, uprowadzając wiele owiec i wielbłądów i wrócili do Jerozolimy.

< 2 Chronicles 14 >