< 2 Chronicles 13 >
1 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Jeroboamu, Abijah di ọba Juda.
En la dix-huitième année du règne de Jéroboam, Abias commença à régner sur Juda.
2 Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Mikaiah, ọmọbìnrin Urieli ti Gibeah. Ogun wà láàrín Abijah àti Jeroboamu.
Il régna trois ans à Jérusalem; et le nom de sa mère était Maacha, fille d'Uriel de Gabaon. Abias ne cessa pas d'être en guerre avec Jéroboam.
3 Abijah lọ sí ojú ogun pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun ogún ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára, Jeroboamu kó ogun jọ pẹ̀lú ogójì ọ̀kẹ́ ọ̀wọ́ ogun tí ó lágbára.
Et il rangea en bataille une armée de quatre cent mille hommes vaillants, et Jéroboam lui en opposa huit cent mille, vaillants aussi.
4 Abijah dúró lórí òkè Semaraimu ní òkè orílẹ̀-èdè Efraimu, ó sì wí pé, Jeroboamu àti gbogbo Israẹli, ẹ gbọ́ mi!
Alors Abias monta sur la colline de Salomon qui est dans les montagnes d'Ephraïm, et il dit: Jéroboam, écoute-moi ainsi que tout Israël.
5 Ṣé ẹ̀yin kò mọ̀ pé Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti fún Dafidi àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ ni oyè ọba títí láé nípasẹ̀ májẹ̀mú iyọ̀?
Ne devez-vous pas savoir que par une alliance sacrée, le Seigneur notre Dieu a donné pour toujours le royaume d'Israël à David et à ses fils.
6 Síbẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, oníṣẹ́ Solomoni ọmọ Dafidi, ṣọ̀tẹ̀ sí ọ̀gá rẹ̀.
Mais, Jéroboam, fils de Nabat, serviteur de Salomon, fils de David, s'est levé et s'est révolté contre son maître.
7 Àwọn ènìyàn lásán sì kó ara wọn jọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, àwọn ọmọ ẹni búburú, wọ́n sì kẹ̀yìn sí Rehoboamu ọmọ Solomoni ní ìgbà tí ó sì kéré tí kò lè pinnu fúnra rẹ̀, tí kò lágbára tó láti takò wọ́n.
Et des hommes de pestilence, fils du péché, se sont joints à lui, qui s'est révolté contre Roboam, fils de Salomon, et Roboam, qui était jeune et d'un cœur craintif, n'osa lui tenir tête.
8 “Nísinsin yìí, ìwọ ṣètò láti kọ́ ìjọba Olúwa, tí ó wà lọ́wọ́ àwọn àtẹ̀lé Dafidi. Ìwọ jẹ́ ọmọ-ogun tí ó gbilẹ̀, ìwọ sì ní pẹ̀lú rẹ ẹgbọrọ màlúù wúrà ti Jeroboamu dà láti fi ṣe Ọlọ́run yín.
Et vous maintenant, vous dites que vous résisterez au royaume du Seigneur que possèdent les fils de David; et vous êtes nombreux, et vous avez avec vous les veaux d'or qu'a faits Jéroboam, pour qu'ils soient vos dieux.
9 Ṣùgbọ́n ṣé ìwọ kò lé àwọn àlùfáà Olúwa jáde, àwọn ọmọ Aaroni àti àwọn ará Lefi. Tí ó sì ṣe àwọn àlùfáà ti ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn ti ṣe? Ẹnikẹ́ni tí ó bá wá láti ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ pẹ̀lú ọ̀dọ́ akọ màlúù àti àgbò méjì lè jẹ́ àlùfáà ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run.
N'avez-vous pas chassé les prêtres du Seigneur, les fils d'Aaron et les lévites? Ne vous êtes-vous point fait des prêtres parmi le peuple de toute la terre? Quiconque arrive, pour se consacrer, avec un bœuf du troupeau et sept béliers, le voilà prêtre de ce qui n'est point dieu.
10 “Ní ti àwa, Olúwa ni Ọlọ́run wa, àwa kò sì ti ì kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Àwọn àlùfáà tí ó ń sin Olúwa jẹ́ àwọn ọmọ Aaroni àwọn ará Lefi sì ń ràn wọ́n lọ́wọ́.
Quant à nous, nous n'avons point abandonné le Seigneur; ce sont ses prêtres, fils d'Aaron, et ses lévites qui le servent, et qui journellement
11 Ní àràárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́, wọ́n gbé ẹbọ sísun àti tùràrí olóòórùn dídùn síwájú Olúwa. Wọ́n gbé àkàrà jáde sórí tábìlì àsè mímọ́, wọ́n sì tan iná sí àwọn fìtílà lórí ìdúró ọ̀pá fìtílà wúrà ní gbogbo ìrọ̀lẹ́. A ń pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa mọ́. Ṣùgbọ́n ìwọ ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
Offrent des holocaustes au Seigneur, matin et soir, brûlent les parfums composés, déposent sur la table pure les pains de proposition, allument à la nuit le chandelier d'or et les lampes qui doivent brûler; car, nous observons les préceptes du Seigneur Dieu de nos pères, que vous avez abandonné.
12 Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa; òun ni olórí wa. Àwọn àlùfáà rẹ̀ pẹ̀lú fèrè wọn yóò fọn ìpè ogun sí i yín. Ẹyin ọkùnrin Israẹli, ẹ má ṣe dojú ìjà kọ Olúwa Ọlọ́run baba yín nítorí ẹ̀yin kì yóò yege.”
Voyez, le Seigneur et ses prêtres sont avec nous à notre tête; ce sont les trompettes sacrées qui nous donnent les signaux; fils d'Israël, gardez- vous de combattre le Seigneur, car vous ne réussirez à rien.
13 Nísinsin yìí, Jeroboamu ti rán àwọn ọ̀wọ́ ogun lọ yíká láti jagun ẹ̀yìn. Kí ó lè jẹ́ pé, tí òun bá wà níwájú Juda, bíba ní bùba á wà ní ẹ̀yìn wọn.
Cependant, Jéroboam ramena sur les derrières de Juda une embuscade qu'il avait dressée; il fut ainsi lui-même devant Juda, et son embuscade derrière.
14 Nígbà tí Juda sì bojú wo ẹ̀yìn, sì kíyèsi i, ogun ń bẹ níwájú àti lẹ́yìn, wọn sì ké pe Olúwa, àwọn àlùfáà sì fun ìpè.
Et Juda se retournant regarda, et voilà que la bataille était devant et derrière lui; alors, il cria au Seigneur, et les prêtres sonnèrent de la trompette.
15 Olúkúlùkù, ọkùnrin Juda sì fún ìpè ogun, ó sì ṣe, bí àwọn ọkùnrin Juda sì ti fun ìpè ogun, ni Ọlọ́run kọlu Jeroboamu àti gbogbo Israẹli níwájú Abijah àti Juda.
Et les hommes de Juda crièrent, et il advint, pendant qu'ils jetaient de grands cris, que le Seigneur frappa Jéroboam et Israël devant Abias et Juda.
16 Àwọn ọmọ Israẹli sálọ kúrò níwájú Juda, Ọlọ́run sì fi wọ́n lé wọn lọ́wọ́.
Et les fils d'Israël s'enfuirent devant Juda, et le Seigneur les livra au roi de Juda.
17 Abijah àti àwọn arákùnrin rẹ̀ fi ìdààmú ńlá jẹ wọ́n ní ìyà, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ọkùnrin tí a yàn ṣubú ní pípa nínú Israẹli.
Abias et son peuple les frappèrent d'une grande plaie, et cinq cent mille hommes vaillants succombèrent du côté d'Israël.
18 Báyìí ni a rẹ àwọn ọmọ Israẹli sílẹ̀ ní àkókò náà, àwọn ọmọ Juda sì borí nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn.
Et, en ce jour-là, les fils d'Israël furent humiliés, et les fils de Juda prévalurent, parce qu'ils avaient espéré en Dieu.
19 Abijah sì lépa Jeroboamu, ó sì gba ìlú lọ́wọ́ rẹ̀, Beteli pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀, àti Jeṣana pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀, àti Efroni pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀.
Abias poursuivit Jéroboam, il lui prit des villes: Béthel et ses bourgs, Mayne et ses bourgs, Ephron et ses bourgs.
20 Bẹ́ẹ̀ ní Jeroboamu kò sì tún ní agbára mọ́ ní ọjọ́ Abijah. Olúwa sì lù ú ó sì kú.
Et Jéroboam fut sans force sous le règne d'Abias; enfin, le Seigneur le frappa, et il mourut.
21 Abijah sì di alágbára, ó sì gbé obìnrin mẹ́tàlá ní ìyàwó, ó sì bi ọmọkùnrin méjìlélógún, àti ọmọbìnrin mẹ́rìndínlógún.
Et Abias s'affermit, et il épousa quatorze femmes, dont il eut vingt-deux fils et seize filles.
22 Àti ìyókù ìṣe Abijah, àti ìwà rẹ̀, àti iṣẹ́ rẹ̀, a kọ wọ́n sínú ìwé ìtumọ̀, wòlíì Iddo.
Le reste de l'histoire d'Abias, ses actions et ses discours, sont écrits au livre du prophète Addo.