< 2 Chronicles 13 >
1 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Jeroboamu, Abijah di ọba Juda.
When Jeroboam had been ruling [Israel] for almost 18 years, Abijah became the king of Judah.
2 Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Mikaiah, ọmọbìnrin Urieli ti Gibeah. Ogun wà láàrín Abijah àti Jeroboamu.
He ruled in Jerusalem for three years. His mother was Micaiah (OR, Maacah), the daughter of Uriel from Gibeah [town]. There was a war between [the armies of] Abijah and Jeroboam.
3 Abijah lọ sí ojú ogun pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun ogún ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára, Jeroboamu kó ogun jọ pẹ̀lú ogójì ọ̀kẹ́ ọ̀wọ́ ogun tí ó lágbára.
Abijah went into the battle, taking 400,000 of his capable soldiers, and Jeroboam prepared to fight them, taking 800,000 of his capable troops.
4 Abijah dúró lórí òkè Semaraimu ní òkè orílẹ̀-èdè Efraimu, ó sì wí pé, Jeroboamu àti gbogbo Israẹli, ẹ gbọ́ mi!
Abijah stood on the top of Zemaraim Mountain, which is in the hilly area that belonged to the tribe of Ephraim, and he shouted, “Jeroboam and all you other people of Israel, listen to me!
5 Ṣé ẹ̀yin kò mọ̀ pé Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti fún Dafidi àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ ni oyè ọba títí láé nípasẹ̀ májẹ̀mú iyọ̀?
You should know that Yahweh, the God to whom all we Israelis belong, has appointed David and his descendants to be the kings of Israel forever. He has confirmed that by making a permanent agreement.
6 Síbẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, oníṣẹ́ Solomoni ọmọ Dafidi, ṣọ̀tẹ̀ sí ọ̀gá rẹ̀.
But Jeroboam, who was [only] an official of David’s son King Solomon, rebelled against his king.
7 Àwọn ènìyàn lásán sì kó ara wọn jọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, àwọn ọmọ ẹni búburú, wọ́n sì kẹ̀yìn sí Rehoboamu ọmọ Solomoni ní ìgbà tí ó sì kéré tí kò lè pinnu fúnra rẹ̀, tí kò lágbára tó láti takò wọ́n.
And when Solomon’s son Rehoboam became king and was still young and inexperienced, a group of worthless scoundrels gathered around you, Jeroboam, and rebelled against Rehoboam.
8 “Nísinsin yìí, ìwọ ṣètò láti kọ́ ìjọba Olúwa, tí ó wà lọ́wọ́ àwọn àtẹ̀lé Dafidi. Ìwọ jẹ́ ọmọ-ogun tí ó gbilẹ̀, ìwọ sì ní pẹ̀lú rẹ ẹgbọrọ màlúù wúrà ti Jeroboamu dà láti fi ṣe Ọlọ́run yín.
“And now you are planning to fight against the kingdom that Yahweh established to be governed by David’s descendants. It is true that you have a huge army, and you and your soldiers have brought with you the golden [statues of] calves that Jeroboam’s workers made to be gods for all of you.
9 Ṣùgbọ́n ṣé ìwọ kò lé àwọn àlùfáà Olúwa jáde, àwọn ọmọ Aaroni àti àwọn ará Lefi. Tí ó sì ṣe àwọn àlùfáà ti ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn ti ṣe? Ẹnikẹ́ni tí ó bá wá láti ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ pẹ̀lú ọ̀dọ́ akọ màlúù àti àgbò méjì lè jẹ́ àlùfáà ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run.
But you expelled the priests that Yahweh [appointed], men who are descendants of Aaron [the first Supreme Priest], and you expelled the descendants of Levi, and you appointed the priests that you wanted, like the people of other countries do. You allow anyone to become a priest of idols that are not gods if he comes to dedicate himself to be a priest by sacrificing a young bull and seven rams.
10 “Ní ti àwa, Olúwa ni Ọlọ́run wa, àwa kò sì ti ì kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Àwọn àlùfáà tí ó ń sin Olúwa jẹ́ àwọn ọmọ Aaroni àwọn ará Lefi sì ń ràn wọ́n lọ́wọ́.
“As for us, Yahweh is our God, and we have not abandoned him. Our priests who serve Yahweh are descendants of Aaron, and the descendants of Levi assist them.
11 Ní àràárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́, wọ́n gbé ẹbọ sísun àti tùràrí olóòórùn dídùn síwájú Olúwa. Wọ́n gbé àkàrà jáde sórí tábìlì àsè mímọ́, wọ́n sì tan iná sí àwọn fìtílà lórí ìdúró ọ̀pá fìtílà wúrà ní gbogbo ìrọ̀lẹ́. A ń pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa mọ́. Ṣùgbọ́n ìwọ ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
Every morning and every evening they present to Yahweh offerings to be completely burned [on the altar], and they burn fragrant incense. [Each week] they place the sacred bread on the sacred table, and each morning they light the lamps that are on the gold lampstand. We are obeying what Yahweh our God requires us to do. But you have abandoned him.
12 Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa; òun ni olórí wa. Àwọn àlùfáà rẹ̀ pẹ̀lú fèrè wọn yóò fọn ìpè ogun sí i yín. Ẹyin ọkùnrin Israẹli, ẹ má ṣe dojú ìjà kọ Olúwa Ọlọ́run baba yín nítorí ẹ̀yin kì yóò yege.”
Yahweh is with us; he is our leader. The priests whom he has appointed will blow their trumpets to signal [that we are ready] to fight a battle against you. You Israeli men, do not fight against Yahweh, the God to whom your ancestors belonged, because you will not be successful and win the battle against him.”
13 Nísinsin yìí, Jeroboamu ti rán àwọn ọ̀wọ́ ogun lọ yíká láti jagun ẹ̀yìn. Kí ó lè jẹ́ pé, tí òun bá wà níwájú Juda, bíba ní bùba á wà ní ẹ̀yìn wọn.
[While he was speaking, ] Jeroboam sent some of his troops around the army of Judah. So while the soldiers who were with Jeroboam were in front of the army of Judah, the other soldiers of Israel were behind the army of Judah.
14 Nígbà tí Juda sì bojú wo ẹ̀yìn, sì kíyèsi i, ogun ń bẹ níwájú àti lẹ́yìn, wọn sì ké pe Olúwa, àwọn àlùfáà sì fun ìpè.
When the soldiers of Judah turned and saw that they were going to be attacked from the front and from the rear, they cried out to Yahweh. The priests blew their trumpets,
15 Olúkúlùkù, ọkùnrin Juda sì fún ìpè ogun, ó sì ṣe, bí àwọn ọkùnrin Juda sì ti fun ìpè ogun, ni Ọlọ́run kọlu Jeroboamu àti gbogbo Israẹli níwájú Abijah àti Juda.
and the men of Judah shouted a loud battle-cry. Then Yahweh [enabled Abijah and the army of Judah to] defeat Jeroboam and [the army of] Israel.
16 Àwọn ọmọ Israẹli sálọ kúrò níwájú Juda, Ọlọ́run sì fi wọ́n lé wọn lọ́wọ́.
The soldiers of Israel fled from the soldiers of Judah, and God enabled the army of Judah to defeat them.
17 Abijah àti àwọn arákùnrin rẹ̀ fi ìdààmú ńlá jẹ wọ́n ní ìyà, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ọkùnrin tí a yàn ṣubú ní pípa nínú Israẹli.
Abijah and his troops struck the capable soldiers of Israel and killed 500,000 of them.
18 Báyìí ni a rẹ àwọn ọmọ Israẹli sílẹ̀ ní àkókò náà, àwọn ọmọ Juda sì borí nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn.
So the soldiers of Israel were defeated, and the soldiers of Judah won the battle because they trusted in Yahweh, the God to whom their ancestors belonged.
19 Abijah sì lépa Jeroboamu, ó sì gba ìlú lọ́wọ́ rẹ̀, Beteli pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀, àti Jeṣana pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀, àti Efroni pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀.
Abijah’s army pursued the army of Jeroboam, and they captured from the people of Israel the cities of Bethel, Jeshanah, and Ephron, and the surrounding villages.
20 Bẹ́ẹ̀ ní Jeroboamu kò sì tún ní agbára mọ́ ní ọjọ́ Abijah. Olúwa sì lù ú ó sì kú.
During the remaining time that Abijah ruled, Jeroboam did not become powerful again. Then Yahweh caused him to become very ill, and he died.
21 Abijah sì di alágbára, ó sì gbé obìnrin mẹ́tàlá ní ìyàwó, ó sì bi ọmọkùnrin méjìlélógún, àti ọmọbìnrin mẹ́rìndínlógún.
But Abijah became more powerful. He married 14 wives and had 22 sons and 16 daughters.
22 Àti ìyókù ìṣe Abijah, àti ìwà rẹ̀, àti iṣẹ́ rẹ̀, a kọ wọ́n sínú ìwé ìtumọ̀, wòlíì Iddo.
An account of the other things that Abijah did while he was the king, including what he said and what he did, is in the scroll written by the prophet Iddo.