< 2 Chronicles 13 >
1 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Jeroboamu, Abijah di ọba Juda.
In the eighteenth year of King Jeroboam, began Abijah to reign over Judah:
2 Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Mikaiah, ọmọbìnrin Urieli ti Gibeah. Ogun wà láàrín Abijah àti Jeroboamu.
three years, reigned he in Jerusalem, and, the name of his mother, was Maacah, daughter of Uriel of Gibeah, —and there was, war, between Abijah and Jeroboam.
3 Abijah lọ sí ojú ogun pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun ogún ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára, Jeroboamu kó ogun jọ pẹ̀lú ogójì ọ̀kẹ́ ọ̀wọ́ ogun tí ó lágbára.
And Abijah began the war with a force of heroes of war, four hundred thousand chosen men, —and, Jeroboam, set in array against him to battle, with eight hundred thousand chosen men, heroes of valour.
4 Abijah dúró lórí òkè Semaraimu ní òkè orílẹ̀-èdè Efraimu, ó sì wí pé, Jeroboamu àti gbogbo Israẹli, ẹ gbọ́ mi!
And Abijah stood up upon Mount Zemaraim, which is in the hill country of Ephraim, —and said, Hear me, O Jeroboam and all Israel!
5 Ṣé ẹ̀yin kò mọ̀ pé Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti fún Dafidi àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ ni oyè ọba títí láé nípasẹ̀ májẹ̀mú iyọ̀?
Is it not yours to know, that, Yahweh God of Israel gave the kingdom to David, over Israel, unto times age-abiding, —to him and to his sons, by a covenant of salt?
6 Síbẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, oníṣẹ́ Solomoni ọmọ Dafidi, ṣọ̀tẹ̀ sí ọ̀gá rẹ̀.
Yet hath Jeroboam son of Nebat, servant of Solomon son of David, risen up, —and rebelled against his lord.
7 Àwọn ènìyàn lásán sì kó ara wọn jọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, àwọn ọmọ ẹni búburú, wọ́n sì kẹ̀yìn sí Rehoboamu ọmọ Solomoni ní ìgbà tí ó sì kéré tí kò lè pinnu fúnra rẹ̀, tí kò lágbára tó láti takò wọ́n.
And there are gathered unto him vain men, sons of the Abandoned One, who emboldened themselves against Rehoboam son of Solomon, -when, Rehoboam, was young and tender of heart, and had not strengthened himself to meet them.
8 “Nísinsin yìí, ìwọ ṣètò láti kọ́ ìjọba Olúwa, tí ó wà lọ́wọ́ àwọn àtẹ̀lé Dafidi. Ìwọ jẹ́ ọmọ-ogun tí ó gbilẹ̀, ìwọ sì ní pẹ̀lú rẹ ẹgbọrọ màlúù wúrà ti Jeroboamu dà láti fi ṣe Ọlọ́run yín.
Now, therefore, ye, are thinking to strengthen yourselves against the kingdom of Yahweh, in the hand of the sons of David, —and, ye, are a great multitude, and, with you, are calves of gold, which Jeroboam hath made you for gods.
9 Ṣùgbọ́n ṣé ìwọ kò lé àwọn àlùfáà Olúwa jáde, àwọn ọmọ Aaroni àti àwọn ará Lefi. Tí ó sì ṣe àwọn àlùfáà ti ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn ti ṣe? Ẹnikẹ́ni tí ó bá wá láti ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ pẹ̀lú ọ̀dọ́ akọ màlúù àti àgbò méjì lè jẹ́ àlùfáà ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run.
Have ye not driven out the priests of Yahweh, the sons of Aaron, and the Levites, —and made for yourselves priests like the peoples of the countries? Whosoever cometh to install himself with a young bullock, and seven rams, then becometh he a priest unto the, no-gods.
10 “Ní ti àwa, Olúwa ni Ọlọ́run wa, àwa kò sì ti ì kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Àwọn àlùfáà tí ó ń sin Olúwa jẹ́ àwọn ọmọ Aaroni àwọn ará Lefi sì ń ràn wọ́n lọ́wọ́.
But, as for us, Yahweh, is our God, and we have not forsaken him, —and, the priests who are waiting upon Yahweh, are sons of Aaron, with Levites in the work;
11 Ní àràárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́, wọ́n gbé ẹbọ sísun àti tùràrí olóòórùn dídùn síwájú Olúwa. Wọ́n gbé àkàrà jáde sórí tábìlì àsè mímọ́, wọ́n sì tan iná sí àwọn fìtílà lórí ìdúró ọ̀pá fìtílà wúrà ní gbogbo ìrọ̀lẹ́. A ń pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa mọ́. Ṣùgbọ́n ìwọ ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
and they are making a perfume unto Yahweh, with ascending-sacrifices morning by morning, and evening by evening and an incense of sweet spices, and are putting in order bread upon the pure table, and the lampstand of gold with the lamps thereof, for lighting up evening by evening, for, observant, are we of the charge of Yahweh our God, —whereas, ye, have forsaken him.
12 Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa; òun ni olórí wa. Àwọn àlùfáà rẹ̀ pẹ̀lú fèrè wọn yóò fọn ìpè ogun sí i yín. Ẹyin ọkùnrin Israẹli, ẹ má ṣe dojú ìjà kọ Olúwa Ọlọ́run baba yín nítorí ẹ̀yin kì yóò yege.”
And lo! with us as Head, is God himself, and his priests, and the trumpets of alarm, to sound an alarm against you, —O sons of Israel! do not fight against Yahweh God of your fathers, for ye shall not prosper.
13 Nísinsin yìí, Jeroboamu ti rán àwọn ọ̀wọ́ ogun lọ yíká láti jagun ẹ̀yìn. Kí ó lè jẹ́ pé, tí òun bá wà níwájú Juda, bíba ní bùba á wà ní ẹ̀yìn wọn.
But, Jeroboam, sent round an ambush, to come up from behind them, —so they were before Judah and, the ambush, did come up from behind them.
14 Nígbà tí Juda sì bojú wo ẹ̀yìn, sì kíyèsi i, ogun ń bẹ níwájú àti lẹ́yìn, wọn sì ké pe Olúwa, àwọn àlùfáà sì fun ìpè.
And, when Judah turned and lo! as for them, the battle was before and behind, then made they outcry unto Yahweh, —and, the priests, kept on blowing with the trumpets.
15 Olúkúlùkù, ọkùnrin Juda sì fún ìpè ogun, ó sì ṣe, bí àwọn ọkùnrin Juda sì ti fun ìpè ogun, ni Ọlọ́run kọlu Jeroboamu àti gbogbo Israẹli níwájú Abijah àti Juda.
Then the men of Judah gave a shout, —and it came to pass, when the men of Judah shouted, then, God himself, smote Jeroboam and all Israel, before Abijah and Judah.
16 Àwọn ọmọ Israẹli sálọ kúrò níwájú Juda, Ọlọ́run sì fi wọ́n lé wọn lọ́wọ́.
And the sons of Israel fled from before Judah, —and God delivered them into their hand.
17 Abijah àti àwọn arákùnrin rẹ̀ fi ìdààmú ńlá jẹ wọ́n ní ìyà, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ọkùnrin tí a yàn ṣubú ní pípa nínú Israẹli.
And Abijah and his people smote among them with a great smiting, —and there fell down slain, of Israel, five hundred thousand chosen men.
18 Báyìí ni a rẹ àwọn ọmọ Israẹli sílẹ̀ ní àkókò náà, àwọn ọmọ Juda sì borí nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn.
Thus were the sons of Israel subdued at that time, —and the sons of Judah prevailed, because they leaned upon Yahweh the God of their fathers.
19 Abijah sì lépa Jeroboamu, ó sì gba ìlú lọ́wọ́ rẹ̀, Beteli pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀, àti Jeṣana pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀, àti Efroni pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀.
And Abijah pursued after Jeroboam, and captured from him, cities, even Bethel, with the villages thereof, and Jeshanah, with the villages thereof, —and Ephron, with the villages thereof;
20 Bẹ́ẹ̀ ní Jeroboamu kò sì tún ní agbára mọ́ ní ọjọ́ Abijah. Olúwa sì lù ú ó sì kú.
neither was Jeroboam strong any more, in the days of Abijah, —and Yahweh smote him that he died.
21 Abijah sì di alágbára, ó sì gbé obìnrin mẹ́tàlá ní ìyàwó, ó sì bi ọmọkùnrin méjìlélógún, àti ọmọbìnrin mẹ́rìndínlógún.
And Abijah strengthened himself, and took him, fourteen wives, —and begat twenty-two sons, and sixteen daughters.
22 Àti ìyókù ìṣe Abijah, àti ìwà rẹ̀, àti iṣẹ́ rẹ̀, a kọ wọ́n sínú ìwé ìtumọ̀, wòlíì Iddo.
And, the rest of the story of Abijah, both his ways and his words, —are written, in the commentary of the prophet Iddo.