< 2 Chronicles 13 >

1 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Jeroboamu, Abijah di ọba Juda.
Jeroboam singpahrang ah ohhaih saning hatlaitazetto naah, Abijah Judah siangpahrang ah oh amtong.
2 Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Mikaiah, ọmọbìnrin Urieli ti Gibeah. Ogun wà láàrín Abijah àti Jeroboamu.
Anih mah Jerusalem to saning thumto thung uk. Anih ih amno loe Gibeah kami, Uriel ih canu, Mikhaiah. To naah Abijah hoi Jeroboem loe misa ah oh hoi.
3 Abijah lọ sí ojú ogun pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun ogún ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára, Jeroboamu kó ogun jọ pẹ̀lú ogójì ọ̀kẹ́ ọ̀wọ́ ogun tí ó lágbára.
Abijah loe a qoih ih misatuh kami sang cumvai palito hoiah misa tuk, Jeroboam doeh a qoih ih misatuh thaih kami sang cumvai tazetto hoiah misa tuk toeng.
4 Abijah dúró lórí òkè Semaraimu ní òkè orílẹ̀-èdè Efraimu, ó sì wí pé, Jeroboamu àti gbogbo Israẹli, ẹ gbọ́ mi!
Abijah loe Ephraim mae ah kaom, Zemaraim mae nuiah angdoet moe, Jeroboam hoi Israel kaminawk boih, ka lok hae tahngai oh!
5 Ṣé ẹ̀yin kò mọ̀ pé Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti fún Dafidi àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ ni oyè ọba títí láé nípasẹ̀ májẹ̀mú iyọ̀?
Israel Angraeng Sithaw mah paloi hoi lokkamhaih sak baktih toengah, Israel prae to David hoi a caanawk hanah dungzan khoek to paek boeh, tiah na panoek o ai maw?
6 Síbẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, oníṣẹ́ Solomoni ọmọ Dafidi, ṣọ̀tẹ̀ sí ọ̀gá rẹ̀.
Toe David capa Solomon ih tamna, Nebat capa Jeroboam loe angthawk moe, angmah ih angraeng to tuk.
7 Àwọn ènìyàn lásán sì kó ara wọn jọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, àwọn ọmọ ẹni búburú, wọ́n sì kẹ̀yìn sí Rehoboamu ọmọ Solomoni ní ìgbà tí ó sì kéré tí kò lè pinnu fúnra rẹ̀, tí kò lágbára tó láti takò wọ́n.
Solomon capa Rehoboam loe poekhaih nawkta moe, misatuh thai ai naah, tidoeh avang ai kami hnukbang kaminawk mah amkhueng o moe, Rehoboam to tuk o.
8 “Nísinsin yìí, ìwọ ṣètò láti kọ́ ìjọba Olúwa, tí ó wà lọ́wọ́ àwọn àtẹ̀lé Dafidi. Ìwọ jẹ́ ọmọ-ogun tí ó gbilẹ̀, ìwọ sì ní pẹ̀lú rẹ ẹgbọrọ màlúù wúrà ti Jeroboamu dà láti fi ṣe Ọlọ́run yín.
Vaihi David ih caanawk ban ah kaom, Angraeng ih prae to tuk hanah nam sak o; misatuh kami paroeai na tawnh o, Jeroboam mah sithawnawk hanah, sui hoiah ang sak pae o ih, maitawnawk doeh na tawnh o.
9 Ṣùgbọ́n ṣé ìwọ kò lé àwọn àlùfáà Olúwa jáde, àwọn ọmọ Aaroni àti àwọn ará Lefi. Tí ó sì ṣe àwọn àlùfáà ti ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn ti ṣe? Ẹnikẹ́ni tí ó bá wá láti ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ pẹ̀lú ọ̀dọ́ akọ màlúù àti àgbò méjì lè jẹ́ àlùfáà ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run.
Angraeng ih qaimanawk, Aaron ih capanawk hoi Levinawk to na haek o moe, prae kalah kaminawk mah sak o ih hmuen baktih toengah, nangmacae hanah qaima na suek o na ai maw? Saning kanawk maitaw tae maeto, tuucaa sarihto hoiah angbawnhaih sak han angzo kami to, sithaw ah kaom ai hmuennawk khaeah qaima tok to na sak o sak.
10 “Ní ti àwa, Olúwa ni Ọlọ́run wa, àwa kò sì ti ì kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Àwọn àlùfáà tí ó ń sin Olúwa jẹ́ àwọn ọmọ Aaroni àwọn ará Lefi sì ń ràn wọ́n lọ́wọ́.
Angraeng loe kaicae hanah Sithaw ah oh pongah, kaicae loe Anih to ka pahnawt o ai; Aaron ih capanawk loe Angraeng toksah qaima ah oh o, Levinawk doeh angmacae ih tok to sak o.
11 Ní àràárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́, wọ́n gbé ẹbọ sísun àti tùràrí olóòórùn dídùn síwájú Olúwa. Wọ́n gbé àkàrà jáde sórí tábìlì àsè mímọ́, wọ́n sì tan iná sí àwọn fìtílà lórí ìdúró ọ̀pá fìtílà wúrà ní gbogbo ìrọ̀lẹ́. A ń pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa mọ́. Ṣùgbọ́n ìwọ ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
Aduem akhawn angbawnhaih sak o moe, Angraeng hmaa ah hmuihoih tui to a thlaek o; kaciim caboi nuiah takaw a suek o moe, aduem kruek hmai pa-aanghaih sui tung pongah hmai-im to paaang o; kaicae ih Angraeng Sithaw mah hnik ih hmuennawk to ka sak o boih; toe nangcae loe Angraeng to na pahnawt o ving boeh.
12 Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa; òun ni olórí wa. Àwọn àlùfáà rẹ̀ pẹ̀lú fèrè wọn yóò fọn ìpè ogun sí i yín. Ẹyin ọkùnrin Israẹli, ẹ má ṣe dojú ìjà kọ Olúwa Ọlọ́run baba yín nítorí ẹ̀yin kì yóò yege.”
Khenah, kaicae khaeah Sithaw oh moe, anih loe kaicae zaehoikung ah oh; anih ih qaimanawk loe nangcae tuk hanah mongkah to ueng o tih; Aw Israel caanawk, nam panawk ih Angraeng Sithaw to tuh o hmah; na pazawk o mak ai, tiah a naa.
13 Nísinsin yìí, Jeroboamu ti rán àwọn ọ̀wọ́ ogun lọ yíká láti jagun ẹ̀yìn. Kí ó lè jẹ́ pé, tí òun bá wà níwájú Juda, bíba ní bùba á wà ní ẹ̀yìn wọn.
Toe Jeroboam mah Judah kaminawk to ahnukbang hoiah takui hanah angmah ih misatuh kaminawk to patoeh boeh; anih loe Judahnawk hmaa ah oh nathuem ah, nihcae to a hnuk bang hoiah ven o khoep boeh.
14 Nígbà tí Juda sì bojú wo ẹ̀yìn, sì kíyèsi i, ogun ń bẹ níwájú àti lẹ́yìn, wọn sì ké pe Olúwa, àwọn àlùfáà sì fun ìpè.
Judahnawk hnukbang angqoi o naah, khenah, misanawk mah ahnuk ahmaa takui khoep boeh, tiah panoek o; to naah Angraeng khaeah hang o, qaimanawk mah mongkah to uengh o.
15 Olúkúlùkù, ọkùnrin Juda sì fún ìpè ogun, ó sì ṣe, bí àwọn ọkùnrin Juda sì ti fun ìpè ogun, ni Ọlọ́run kọlu Jeroboamu àti gbogbo Israẹli níwájú Abijah àti Juda.
Judah kaminawk hangh o; tha hoi a hangh o naah, Sithaw mah Jeroboam hoi Israelnawk to Abijah hoi Judahnawk hmaa hoiah cawnsak boih.
16 Àwọn ọmọ Israẹli sálọ kúrò níwájú Juda, Ọlọ́run sì fi wọ́n lé wọn lọ́wọ́.
Israelnawk loe Judahnawk hmaa ah cawnh o; Sithaw mah nihcae to Judahnawk ban ah paek.
17 Abijah àti àwọn arákùnrin rẹ̀ fi ìdààmú ńlá jẹ wọ́n ní ìyà, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ọkùnrin tí a yàn ṣubú ní pípa nínú Israẹli.
Abijah hoi anih ih kaminawk mah nihcae to hum o moe, paroeai duek o; qoih ih Israelcaanawk sang cumvai pangato duek o.
18 Báyìí ni a rẹ àwọn ọmọ Israẹli sílẹ̀ ní àkókò náà, àwọn ọmọ Juda sì borí nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn.
Misa angtuk naah Israel kaminawk to sung o; Judahnawk loe angmacae ampanawk ih, Angraeng Sithaw nuiah amha o pongah misa pazawk o.
19 Abijah sì lépa Jeroboamu, ó sì gba ìlú lọ́wọ́ rẹ̀, Beteli pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀, àti Jeṣana pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀, àti Efroni pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀.
Abijah mah Jeroboam to patom moe, Bethel, Jeshanah hoi Ephraim vangpuinawk to lak pae.
20 Bẹ́ẹ̀ ní Jeroboamu kò sì tún ní agbára mọ́ ní ọjọ́ Abijah. Olúwa sì lù ú ó sì kú.
Jeroboam loe Abijah dung thungah thacak thai ai boeh; Angraeng mah anih to hum moe, duek.
21 Abijah sì di alágbára, ó sì gbé obìnrin mẹ́tàlá ní ìyàwó, ó sì bi ọmọkùnrin méjìlélógún, àti ọmọbìnrin mẹ́rìndínlógún.
Toe Abijah loe thacak aep aep; zu hatlai palito a lak moe, capa pumphae hnetto hoi canu hatlai tarukto sak.
22 Àti ìyókù ìṣe Abijah, àti ìwà rẹ̀, àti iṣẹ́ rẹ̀, a kọ wọ́n sínú ìwé ìtumọ̀, wòlíì Iddo.
Abijah siangpahrang toksakhaihnawk, a sak ih hmuennawk hoi a thuih ih loknawk boih loe tahmaa Iddo ih ruici cabu thungah tarik o.

< 2 Chronicles 13 >