< 2 Chronicles 12 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí a fi ìjọba Rehoboamu múlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba, tí ó sì ti di alágbára, òun àti gbogbo Israẹli, pẹ̀lú rẹ̀ ni wọ́n pa òfin Olúwa tì.
Or il arriva qu'aussitôt que le Royaume de Roboam fut établi et fortifié, [Roboam] abandonna la Loi de l'Eternel, et tout Israël [l'abandonna aussi] avec lui.
2 Nítorí tí wọn kò ṣọ òtítọ́ sí Olúwa. Ṣiṣaki ọba Ejibiti dojúkọ Jerusalẹmu ní ọdún karùn-ún ti ọba Rehoboamu.
C'est pourquoi il arriva que la cinquième année du Roi Roboam, Sisak Roi d'Egypte monta contre Jérusalem, parce qu'ils avaient péché contre l'Eternel.
3 Pẹ̀lú ẹgbàá mẹ́fà kẹ̀kẹ́ àti ọ̀kẹ́ mẹ́ta àwọn ọkùnrin ẹlẹ́ṣin àti àìníye ọ̀wọ́ ogun ti Libia, Sukki àti Kuṣi, tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ láti Ejibiti.
Il avait avec lui mille deux cents chariots, et soixante mille hommes de cheval, et le peuple qui était venu avec lui d'Egypte, [savoir], les Libyens, les Sukiens, et les Ethiopiens, était sans nombre.
4 Ó fi agbára mú àwọn ìlú ààbò ti Juda, pẹ̀lú wá sí Jerusalẹmu bí ó ti jìnnà tó.
Et il prit les villes fortes qui appartenaient à Juda, et vint jusqu'à Jérusalem.
5 Nígbà náà, wòlíì Ṣemaiah wá sí ọ̀dọ̀ Rehoboamu àti sí ọ̀dọ̀ àwọn olórí Juda tí wọ́n ti péjọ ní Jerusalẹmu nítorí ìbẹ̀rù Ṣiṣaki, ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ìwọ ti pa mí tì; nítorí náà èmi náà ti pa yín tì sí ọ̀dọ̀ Ṣiṣaki.”
Alors Sémahia le Prophète vint vers Roboam, et vers les principaux de Juda qui s'étaient assemblés à Jérusalem à cause de Sisak, et leur dit: Ainsi a dit l'Eternel: Vous m'avez abandonné, c'est pourquoi je vous ai aussi abandonnés entre les mains de Sisak.
6 Àwọn olórí Israẹli àti ọba rẹ̀ ará wọn sílẹ̀, wọ́n sì wí pé, “Olódodo ni Olúwa.”
Alors les principaux d'Israël et le Roi s'humilièrent, et dirent: L'Eternel est juste.
7 Nígbà tí Olúwa rí i pé, wọ́n ti rẹ̀ ara wọn sílẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa yí tọ Ṣemaiah lọ pé, “Níwọ́n ìgbà tí wọ́n ti rẹ ara wọn sílẹ̀, Èmi kì yóò pa wọ́n ṣùgbọ́n, yóò fún wọn ní ìtúsílẹ̀ tó bá yá. Ìbínú mi kì yóò dà sórí Jerusalẹmu ní ipasẹ̀ Ṣiṣaki.
Et quand l'Eternel eut vu qu'ils s'étaient humiliés, la parole de l'Eternel fut adressée à Sémahia, en disant: Ils se sont humiliés, je ne les détruirai point, mais je leur donnerai dans peu de temps quelque moyen d'échapper, et ma fureur ne se répandra point sur Jérusalem par le moyen de Sisak.
8 Bí ó ti wù kí ó rí, wọn yóò sìn ní abẹ́ rẹ̀, kí wọn kí ó lè mọ̀ ìyàtọ̀ láàrín sí sìn mí àti sí sin àwọn ọba ilẹ̀ mìíràn.”
Toutefois ils lui seront asservis, afin qu'ils sachent ce que c'est que de ma servitude, et de la servitude des Royaumes de la terre.
9 Nígbà tí Ṣiṣaki ọba Ejibiti dojúkọ Jerusalẹmu, ó gbé àwọn ìṣúra ilé Olúwa, àti àwọn ìṣúra ààfin ọba. Ó gbé gbogbo rẹ̀, pẹ̀lú àwọn àpáta wúrà tí Solomoni dá.
Sisak donc Roi d'Egypte monta contre Jérusalem, et prit les trésors de la maison de l'Eternel, et les trésors de la Maison Royale, il prit tout; il prit aussi les boucliers d'or que Salomon avait faits.
10 Bẹ́ẹ̀ ni, ọba Rehoboamu dá àwọn àpáta idẹ láti fi dípò wọn, ó sì fi èyí lé àwọn alákòóso àti olùṣọ́ tí ó wà ní ẹnu iṣẹ́ ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà ààfin ọba lọ́wọ́.
Et le Roi Roboam fit des boucliers d'airain au lieu de ceux-là, et les mit entre les mains des capitaines des archers qui gardaient la porte de la maison du Roi.
11 Ìgbàkígbà tí ọba bá lọ sí ilé Olúwa, àwọn olùṣọ́ n lọ pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n ń gbé àwọn àpáta náà àti lẹ́yìn, wọ́n dá wọn padà sí yàrá ìṣọ́.
Et quand le Roi entrait dans la maison de l'Eternel, les archers venaient, et les portaient, puis ils les rapportaient dans la chambre des archers.
12 Nítorí ti Rehoboamu rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, ìbínú Olúwa yí padà kúrò lórí rẹ̀, a kò sì pa á run pátápátá. Nítòótọ́, ìre díẹ̀ wà ní Juda.
Parce donc qu'il s'humilia, la colère de l'Eternel se détourna de lui, en sorte qu'il ne les détruisit point entièrement; car aussi il y avait de bonnes choses en Juda.
13 Ọba Rehoboamu fi ara rẹ̀ lélẹ̀ gidigidi ní Jerusalẹmu, ó sì tẹ̀síwájú gẹ́gẹ́ bí ọba. Ó jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógójì nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba fún ọdún mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu, ìlú ńlá tí Olúwa ti yàn jáde kúrò nínú gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli ní èyí tí ó fẹ́ fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Naama, ará Ammoni.
Ainsi le Roi Roboam se fortifia dans Jérusalem, et régna. Or Roboam était âgé de quarante et un ans, quand il commença à régner, et il régna dix-sept ans à Jérusalem, la ville que l'Eternel avait choisie d'entre toutes les Tribus d'Israël pour y mettre son Nom; et sa mère avait nom Nahama, et était Hammonite.
14 O sì ṣe búburú, nítorí tí kò múra nínú ọkàn rẹ̀ láti wá Olúwa.
Mais il fit ce qui est déplaisant à [l'Eternel]; car il ne disposa point son cœur pour chercher l'Eternel.
15 Fún tí iṣẹ́ ìjọba Rehoboamu láti ìbẹ̀rẹ̀ dé ìparí, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìrántí ti Ṣemaiah wòlíì àti ti Iddo, aríran tí ó ní ṣe pẹ̀lú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá? Ìtẹ̀síwájú ogun jíjà sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu.
Or les faits de Roboam, tant les premiers que les derniers, ne sont-ils pas écrits dans les Livres de Sémahia le Prophète, et de Hiddo le Voyant, dans le récit des généalogies; avec les guerres que Roboam et Jéroboam ont eues tout le temps qu'ils ont vécu?
16 Rehoboamu sun pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sin ín sínú ìlú ńlá ti Dafidi. Abijah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Et Roboam s'endormit avec ses pères, et fut enseveli en la Cité de David; et Abija son fils régna en sa place.

< 2 Chronicles 12 >