< 2 Chronicles 12 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí a fi ìjọba Rehoboamu múlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba, tí ó sì ti di alágbára, òun àti gbogbo Israẹli, pẹ̀lú rẹ̀ ni wọ́n pa òfin Olúwa tì.
And it came to pass, when Rehoboam had established the kingdom, and had strengthened himself, he forsook the law of Yahweh, —and all Israel with him.
2 Nítorí tí wọn kò ṣọ òtítọ́ sí Olúwa. Ṣiṣaki ọba Ejibiti dojúkọ Jerusalẹmu ní ọdún karùn-ún ti ọba Rehoboamu.
And so it came to pass, in the fifth year of King Rehoboam, that Shishak king of Egypt came up against Jerusalem, —because they had dealt treacherously against Yahweh; —
3 Pẹ̀lú ẹgbàá mẹ́fà kẹ̀kẹ́ àti ọ̀kẹ́ mẹ́ta àwọn ọkùnrin ẹlẹ́ṣin àti àìníye ọ̀wọ́ ogun ti Libia, Sukki àti Kuṣi, tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ láti Ejibiti.
with twelve hundred chariots, and with sixty thousand horsemen, -and, without number, the people who came with him out of Egypt—Lybians, Sukkiim, and Ethiopians.
4 Ó fi agbára mú àwọn ìlú ààbò ti Juda, pẹ̀lú wá sí Jerusalẹmu bí ó ti jìnnà tó.
And he captured the cities of defence which belonged to Judah, —and came, as far as Jerusalem.
5 Nígbà náà, wòlíì Ṣemaiah wá sí ọ̀dọ̀ Rehoboamu àti sí ọ̀dọ̀ àwọn olórí Juda tí wọ́n ti péjọ ní Jerusalẹmu nítorí ìbẹ̀rù Ṣiṣaki, ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ìwọ ti pa mí tì; nítorí náà èmi náà ti pa yín tì sí ọ̀dọ̀ Ṣiṣaki.”
And, Shemaiah the prophet, came unto Rehoboam, and the rulers of Judah, who had gathered themselves together unto Jerusalem because of Shishak, —and said unto them, Thus, saith Yahweh, Ye, have left, me, Therefore, I also, have left, you, in the hands of Shishak.
6 Àwọn olórí Israẹli àti ọba rẹ̀ ará wọn sílẹ̀, wọ́n sì wí pé, “Olódodo ni Olúwa.”
Then the rulers of Israel and the king humbled themselves, —and said, Righteous, is Yahweh!
7 Nígbà tí Olúwa rí i pé, wọ́n ti rẹ̀ ara wọn sílẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa yí tọ Ṣemaiah lọ pé, “Níwọ́n ìgbà tí wọ́n ti rẹ ara wọn sílẹ̀, Èmi kì yóò pa wọ́n ṣùgbọ́n, yóò fún wọn ní ìtúsílẹ̀ tó bá yá. Ìbínú mi kì yóò dà sórí Jerusalẹmu ní ipasẹ̀ Ṣiṣaki.
And, when Yahweh saw that they humbled themselves, the word of Yahweh came unto Shemaiah, saying—They have humbled themselves, I will not destroy them, —but will grant them, in a little while, to escape, and my wrath shall not be poured out upon Jerusalem, by the hand of Shishak.
8 Bí ó ti wù kí ó rí, wọn yóò sìn ní abẹ́ rẹ̀, kí wọn kí ó lè mọ̀ ìyàtọ̀ láàrín sí sìn mí àti sí sin àwọn ọba ilẹ̀ mìíràn.”
Nevertheless they shall become his servants, that they may know my service, and the service of the kingdoms of the countries.
9 Nígbà tí Ṣiṣaki ọba Ejibiti dojúkọ Jerusalẹmu, ó gbé àwọn ìṣúra ilé Olúwa, àti àwọn ìṣúra ààfin ọba. Ó gbé gbogbo rẹ̀, pẹ̀lú àwọn àpáta wúrà tí Solomoni dá.
So Shishak king of Egypt came up against Jerusalem, and took the treasures of the house of Yahweh, and the treasures of the house of the king, the whole, he took, —and he took the bucklers of gold, which Solomon had made.
10 Bẹ́ẹ̀ ni, ọba Rehoboamu dá àwọn àpáta idẹ láti fi dípò wọn, ó sì fi èyí lé àwọn alákòóso àti olùṣọ́ tí ó wà ní ẹnu iṣẹ́ ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà ààfin ọba lọ́wọ́.
And King Rehoboam made, instead of them, bucklers of bronze, —and committed them unto the hand of the captains of the runners, who kept guard at the entrance of the house of the king.
11 Ìgbàkígbà tí ọba bá lọ sí ilé Olúwa, àwọn olùṣọ́ n lọ pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n ń gbé àwọn àpáta náà àti lẹ́yìn, wọ́n dá wọn padà sí yàrá ìṣọ́.
And so it was, whensoever the king came into the house of Yahweh, the runners came and bare them, and then returned them into the chamber of the runners.
12 Nítorí ti Rehoboamu rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, ìbínú Olúwa yí padà kúrò lórí rẹ̀, a kò sì pa á run pátápátá. Nítòótọ́, ìre díẹ̀ wà ní Juda.
But, when he humbled himself, then turned from him the anger of Yahweh, that he would not destroy, to make an end, —moreover also, in Judah, there were some good things.
13 Ọba Rehoboamu fi ara rẹ̀ lélẹ̀ gidigidi ní Jerusalẹmu, ó sì tẹ̀síwájú gẹ́gẹ́ bí ọba. Ó jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógójì nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba fún ọdún mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu, ìlú ńlá tí Olúwa ti yàn jáde kúrò nínú gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli ní èyí tí ó fẹ́ fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Naama, ará Ammoni.
So King Rehoboam strengthened himself in Jerusalem, and reigned, —because, forty-one years old, was Rehoboam when he began to reign, and, seventeen years, reigned he in Jerusalem, the city which Yahweh had chosen, to set his Name there—from among all the tribes of Israel, and, the name of his mother, was Naamah, the Ammonitess.
14 O sì ṣe búburú, nítorí tí kò múra nínú ọkàn rẹ̀ láti wá Olúwa.
But he did evil, —in that he did not fix his heart to seek Yahweh.
15 Fún tí iṣẹ́ ìjọba Rehoboamu láti ìbẹ̀rẹ̀ dé ìparí, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìrántí ti Ṣemaiah wòlíì àti ti Iddo, aríran tí ó ní ṣe pẹ̀lú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá? Ìtẹ̀síwájú ogun jíjà sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu.
Now, the story of Rehoboam, first and last, is it not written in the story of Shemaiah the prophet and Iddo the seer, for enrolling, -also the wars of Rehoboam and Jeroboam, all the days?
16 Rehoboamu sun pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sin ín sínú ìlú ńlá ti Dafidi. Abijah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
And Rehoboam slept with his fathers, and was buried in the city of David, —and Abijah his son reigned in his stead.

< 2 Chronicles 12 >