< 2 Chronicles 11 >

1 Nígbà tí Rehoboamu dé Jerusalẹmu, ó kó ilé Juda àti Benjamini jọ, ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ènìyàn tí a yàn, tí wọ́n jẹ́ ológun, láti bá Israẹli jà kí ó lè mú ìjọba náà padà bọ̀ sọ́dọ̀ rẹ̀.
Și când Roboam a venit la Ierusalim, a strâns din casa lui Iuda și a lui Beniamin, o sută optzeci de mii de bărbați aleși, care erau războinici, să lupte împotriva lui Israel, ca să aducă împărăția înapoi la Roboam.
2 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Ṣemaiah ènìyàn Ọlọ́run wá wí pé,
Dar cuvântul DOMNULUI a venit la Șemaia, omul lui Dumnezeu, spunând:
3 “Wí fún Rehoboamu ọmọ Solomoni ọba Juda, sí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ní Juda àti Benjamini,
Vorbește lui Roboam, fiul lui Solomon, împăratul lui Iuda, și întregului Israel în Iuda și Beniamin, zicând:
4 ‘Èyí ní ohun tí Olúwa wí. Ẹ má ṣe gòkè lọ láti lọ jà pẹ̀lú arákùnrin yín, ẹ lọ sílé, gbogbo yín, nítorí ti ìṣe mi nìyí.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tẹ̀lé ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n sì padà sẹ́yìn láti yan lọ dojúkọ Jeroboamu.
Astfel spune DOMNUL: Să nu urcați, nici să nu luptați împotriva fraților voștri: întoarceți-vă, fiecare om, la casa lui, fiindcă acest lucru este făcut de mine. Și ei au ascultat de cuvintele DOMNULUI, și s-au întors de la a merge împotriva lui Ieroboam.
5 Rehoboamu ń gbe ní Jerusalẹmu ó sì kọ́ àwọn ìlú fún olódi ní Juda.
Și Roboam a locuit în Ierusalim și a construit cetăți de apărare în Iuda.
6 Bẹtilẹhẹmu, Etamu, Tekoa,
A construit chiar Betleem și Etam și Tecoa,
7 Beti-Suri, Soko, Adullamu,
Și Bet-Țur și Soco și Adulam,
8 Gati, Meraṣa Sifi,
Și Gat și Mareșa și Zif,
9 Adoraimu, Lakiṣi, Aseka
Și Adoraim și Lachis și Azeca,
10 Sora, Aijaloni, àti Hebroni. Wọ̀nyí ni àwọn ìlú ìdáàbòbò ní Juda àti Benjamini.
Și Țoreea și Aialon și Hebron, care sunt în Iuda și Beniamin, cetăți întărite.
11 Ó sì mú àwọn ìlú olódi lágbára, ó sì fi àwọn balógun sínú wọn àti àkójọ oúnjẹ, àti òróró àti ọtí wáìnì.
Și a fortificat întăriturile și a pus căpetenii în ele și provizii de mâncare și de untdelemn și vin.
12 Àti ní olúkúlùkù ìlú ni ó fi asà àti ọ̀kọ̀ sí, ó sì mú wọn lágbára gidigidi, ó sì ní Juda àti Benjamini lábẹ́ rẹ̀.
Și în fiecare cetate a pus scuturi și sulițe și le-a făcut peste măsură de tari, având pe Iuda și pe Beniamin de partea sa.
13 Àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi, láti gbogbo ẹ̀yà wọn jákèjádò Israẹli wà ní ẹ̀bá rẹ̀.
Și preoții și leviții, care erau în tot Israelul, au venit la el din toate hotarele lor,
14 Àwọn ará Lefi fi ìgbèríko sílẹ̀, wọ́n sì wá sí Juda àti Jerusalẹmu nítorí Jeroboamu àti àwọn ọmọ rẹ̀, ti kọ̀ wọ́n sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà Olúwa.
Fiindcă leviții și-au părăsit împrejurimile și toate stăpânirile lor și au venit la Iuda și Ierusalim, căci Ieroboam și fiii lui îi alungaseră din îndeplinirea serviciului preoțesc pentru DOMNUL;
15 Ó sì yan àwọn àlùfáà tirẹ̀ fún àwọn ibi gíga wọ̀n-ọn-nì, àti fún àwọn ère òbúkọ, àti fún ẹgbọrọ màlúù tí ó ṣe.
Și a rânduit preoți pentru înălțimi și pentru draci și pentru vițeii pe care i-a făcut.
16 Àwọn tó wá láti gbogbo ẹ̀yà Israẹli tí wọ́n fi ọkàn wọn fún wíwá Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, tẹ̀lé àwọn ará Lefi lọ sí Jerusalẹmu láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run baba a wọn.
Și, după ei, din toate triburile lui Israel, aceia care au pus în inima lor să caute pe DOMNUL Dumnezeul lui Israel, au venit la Ierusalim să sacrifice DOMNULUI Dumnezeului părinților lor.
17 Ó fún ìjọba Juda ní agbára, ó sì ti Rehoboamu ọmọ Solomoni lẹ́yìn fún ọdún mẹ́ta nítorí ọdún mẹ́ta ni wọ́n fi rìn ní ọ̀nà ti Dafidi àti Solomoni ní àkókò yí.
Astfel ei au întărit împărăția lui Iuda și au întărit pe Roboam, fiul lui Solomon, trei ani, căci trei ani au umblat în calea lui David și Solomon.
18 Rehoboamu fẹ́ Mahalati tí ó jẹ́ ọmọbìnrin ti ọmọkùnrin Dafidi Jerimoti bi àti ti Abihaili, ọmọbìnrin ti ọmọkùnrin Jese Eliabu bí.
Și Roboam și-a luat pe Mahalat, fiica lui Ierimot, fiul lui David, ca soție, și pe Abihail, fiica lui Eliab, fiul lui Isai,
19 Ó bí àwọn ọmọ fún un: Jeuṣi, Ṣemariah àti Sahamu.
Care i-a născut copii: pe Ieuș și pe Șemaria și pe Zaham.
20 Nígbà náà, ó fẹ́ Maaka ọmọbìnrin Absalomu, tí ó bí Abijah fún Attai, Sisa àti Ṣelomiti.
Și după ea a luat pe Maaca, fiica lui Absalom, care i-a născut pe Abiia și pe Atai și pe Ziza și pe Șelomit.
21 Rehoboamu fẹ́ràn Maaka ọmọbìnrin Absalomu ju èyíkéyìí nínú àwọn ìyàwó rẹ̀ àti àwọn àlè rẹ̀ lọ. Ní gbogbo rẹ̀, ó ní ìyàwó méjìdínlógún àti ọgọ́ta àlè ọmọkùnrin méjìdínlọ́gbọ̀n àti ọgọ́ta ọmọbìnrin.
Și Roboam a iubit pe Maaca, fiica lui Absalom, mai presus de toate soțiile și concubinele lui (căci a luat optsprezece soții și șaizeci de concubine; și a născut douăzeci și opt de fii și șaizeci de fiice).
22 Rehoboamu yan Abijah ọmọ Maaka láti jẹ́ olóyè ọmọ-aládé láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀, kí ó ba à lè ṣe é ní ọba.
Și Roboam l-a făcut pe Abiia, fiul Maachei, mai marele, să fie conducător între frații lui, căci s-a gândit să îl facă împărat.
23 Ó hùwà ọlọ́gbọ́n, nípa fí fọ́n díẹ̀ nínú àwọn ọmọ rẹ̀ jákèjádò ká àwọn agbègbè Juda àti Benjamini àti sí gbogbo àwọn ìlú ńlá olódi. Ó fún wọn ní ọ̀pọ̀ ohun tí wọ́n fẹ́, ó sì fẹ́ ọ̀pọ̀ ìyàwó fún wọn.
Și s-a purtat cu înțelepciune și a împrăștiat pe toți copiii lui prin toate țările lui Iuda și Beniamin, până la fiecare cetate întărită, și le-a dat hrană din abundență. Și a dorit o mulțime de soții.

< 2 Chronicles 11 >