< 2 Chronicles 11 >

1 Nígbà tí Rehoboamu dé Jerusalẹmu, ó kó ilé Juda àti Benjamini jọ, ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ènìyàn tí a yàn, tí wọ́n jẹ́ ológun, láti bá Israẹli jà kí ó lè mú ìjọba náà padà bọ̀ sọ́dọ̀ rẹ̀.
Vindo pois Roboão a Jerusalém, ajuntou da casa de Judá e Benjamin cento e oitenta mil escolhidos, dextros na guerra para pelejarem contra Israel, e para restituirem o reino a Roboão.
2 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Ṣemaiah ènìyàn Ọlọ́run wá wí pé,
Porém a palavra do Senhor veio a Semaias, homem de Deus, dizendo:
3 “Wí fún Rehoboamu ọmọ Solomoni ọba Juda, sí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ní Juda àti Benjamini,
Fala a Roboão, filho de Salomão, rei de Judá, e a todo o Israel, em Judá e Benjamin, dizendo:
4 ‘Èyí ní ohun tí Olúwa wí. Ẹ má ṣe gòkè lọ láti lọ jà pẹ̀lú arákùnrin yín, ẹ lọ sílé, gbogbo yín, nítorí ti ìṣe mi nìyí.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tẹ̀lé ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n sì padà sẹ́yìn láti yan lọ dojúkọ Jeroboamu.
Assim diz o Senhor: Não subireis, nem pelejareis contra os vossos irmãos, tornai cada um à sua casa; porque de mim proveiu isto. E ouviram as palavras do Senhor, e tornaram d'irem contra Jeroboão.
5 Rehoboamu ń gbe ní Jerusalẹmu ó sì kọ́ àwọn ìlú fún olódi ní Juda.
E Roboão habitou em Jerusalém: e edificou cidades para fortalezas, em Judá.
6 Bẹtilẹhẹmu, Etamu, Tekoa,
Edificou pois a Belém, e a Etam, e a Tekoa,
7 Beti-Suri, Soko, Adullamu,
E a Beth-zur, e a Soco, e a Adullam,
8 Gati, Meraṣa Sifi,
E a Gath, e a Maresa, e a Ziph,
9 Adoraimu, Lakiṣi, Aseka
E a Adoraim, e a Lachis, e a Azeka,
10 Sora, Aijaloni, àti Hebroni. Wọ̀nyí ni àwọn ìlú ìdáàbòbò ní Juda àti Benjamini.
E a Zora, e a Aijalon, e a Hebron, que estavam em Judá e em Benjamin; cidades fortes.
11 Ó sì mú àwọn ìlú olódi lágbára, ó sì fi àwọn balógun sínú wọn àti àkójọ oúnjẹ, àti òróró àti ọtí wáìnì.
E fortificou estas fortalezas e pôs nelas maiorais, e armazéns de viveres, e de azeite, e de vinho.
12 Àti ní olúkúlùkù ìlú ni ó fi asà àti ọ̀kọ̀ sí, ó sì mú wọn lágbára gidigidi, ó sì ní Juda àti Benjamini lábẹ́ rẹ̀.
E pôs em cada cidade pavezes e lanças; fortificou-as em grande maneira: e Judá e Benjamin foram seus.
13 Àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi, láti gbogbo ẹ̀yà wọn jákèjádò Israẹli wà ní ẹ̀bá rẹ̀.
Também os sacerdotes, e os levitas, que havia em todo o Israel, se ajuntaram a ele de todos os seus termos.
14 Àwọn ará Lefi fi ìgbèríko sílẹ̀, wọ́n sì wá sí Juda àti Jerusalẹmu nítorí Jeroboamu àti àwọn ọmọ rẹ̀, ti kọ̀ wọ́n sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà Olúwa.
Porque os levitas deixaram os seus arrabaldes, e a sua possessão, e vieram a Judá e a Jerusalém (porque Jeroboão e seus filhos os lançaram fora para que não ministrassem ao Senhor.
15 Ó sì yan àwọn àlùfáà tirẹ̀ fún àwọn ibi gíga wọ̀n-ọn-nì, àti fún àwọn ère òbúkọ, àti fún ẹgbọrọ màlúù tí ó ṣe.
E ele constituiu para si sacerdotes, para os altos, e para os demônios, e para os bezerros, que fizera.)
16 Àwọn tó wá láti gbogbo ẹ̀yà Israẹli tí wọ́n fi ọkàn wọn fún wíwá Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, tẹ̀lé àwọn ará Lefi lọ sí Jerusalẹmu láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run baba a wọn.
Depois desses também de todas as tribos de Israel, os que deram o seu coração a buscarem ao Senhor Deus de Israel, vieram a Jerusalém, para offerecerem sacrifícios ao Senhor Deus de seus pais.
17 Ó fún ìjọba Juda ní agbára, ó sì ti Rehoboamu ọmọ Solomoni lẹ́yìn fún ọdún mẹ́ta nítorí ọdún mẹ́ta ni wọ́n fi rìn ní ọ̀nà ti Dafidi àti Solomoni ní àkókò yí.
Assim fortaleceram o reino de Judá e corroboraram a Roboão, filho de Salomão, por três anos: porque três anos andaram no caminho de David e Salomão.
18 Rehoboamu fẹ́ Mahalati tí ó jẹ́ ọmọbìnrin ti ọmọkùnrin Dafidi Jerimoti bi àti ti Abihaili, ọmọbìnrin ti ọmọkùnrin Jese Eliabu bí.
E Roboão tomou para si, por mulher, a Mahalat, filha de Jerimoth, filho de David; e a Abihail, filha de Eliab, filho de Jessé.
19 Ó bí àwọn ọmọ fún un: Jeuṣi, Ṣemariah àti Sahamu.
A qual lhe pariu filhos, a Jeus, e a Samarias, e a Zaham.
20 Nígbà náà, ó fẹ́ Maaka ọmọbìnrin Absalomu, tí ó bí Abijah fún Attai, Sisa àti Ṣelomiti.
E depois dela tomou a Maaca, filha de Absalão; esta lhe pariu a Abias, e a Atthai, e a Ziza, e a Selomith.
21 Rehoboamu fẹ́ràn Maaka ọmọbìnrin Absalomu ju èyíkéyìí nínú àwọn ìyàwó rẹ̀ àti àwọn àlè rẹ̀ lọ. Ní gbogbo rẹ̀, ó ní ìyàwó méjìdínlógún àti ọgọ́ta àlè ọmọkùnrin méjìdínlọ́gbọ̀n àti ọgọ́ta ọmọbìnrin.
E amava Roboão mais a Maaca, filha de Absalão, do que a todas as suas outras mulheres e concubinas; porque ele tinha tomado dezoito mulheres, e sessenta concubinas; e gerou vinte e oito filhos, e sessenta filhas.
22 Rehoboamu yan Abijah ọmọ Maaka láti jẹ́ olóyè ọmọ-aládé láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀, kí ó ba à lè ṣe é ní ọba.
E Roboão pôs por cabeça a Abias, filho de Maaca, para ser maioral entre os seus irmãos; porque o queria fazer rei.
23 Ó hùwà ọlọ́gbọ́n, nípa fí fọ́n díẹ̀ nínú àwọn ọmọ rẹ̀ jákèjádò ká àwọn agbègbè Juda àti Benjamini àti sí gbogbo àwọn ìlú ńlá olódi. Ó fún wọn ní ọ̀pọ̀ ohun tí wọ́n fẹ́, ó sì fẹ́ ọ̀pọ̀ ìyàwó fún wọn.
E usou de prudência, e de todos os seus filhos alguns espalhou por todas as terras de Judá e Benjamin, por todas as cidades fortes; e deu-lhes viveres em abundância: e lhes desejou uma multidão de mulheres.

< 2 Chronicles 11 >