< 2 Chronicles 11 >

1 Nígbà tí Rehoboamu dé Jerusalẹmu, ó kó ilé Juda àti Benjamini jọ, ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ènìyàn tí a yàn, tí wọ́n jẹ́ ológun, láti bá Israẹli jà kí ó lè mú ìjọba náà padà bọ̀ sọ́dọ̀ rẹ̀.
Kiedy Roboam przybył do Jerozolimy, zebrał spośród domu Judy i Beniamina sto osiemdziesiąt tysięcy [mężczyzn] – wyborowych wojowników – aby walczyć z Izraelem i przywrócić królestwo Roboamowi.
2 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Ṣemaiah ènìyàn Ọlọ́run wá wí pé,
Lecz słowo PANA doszło do Szemajasza, męża Bożego:
3 “Wí fún Rehoboamu ọmọ Solomoni ọba Juda, sí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ní Juda àti Benjamini,
Powiedz Roboamowi, synowi Salomona, królowi Judy, i całemu Izraelowi w Judzie i Beniaminie:
4 ‘Èyí ní ohun tí Olúwa wí. Ẹ má ṣe gòkè lọ láti lọ jà pẹ̀lú arákùnrin yín, ẹ lọ sílé, gbogbo yín, nítorí ti ìṣe mi nìyí.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tẹ̀lé ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n sì padà sẹ́yìn láti yan lọ dojúkọ Jeroboamu.
Tak mówi PAN: Nie wyruszajcie ani nie walczcie ze swoimi braćmi. Niech każdy wróci do swego domu, bo ta rzecz wyszła ode mnie. I posłuchali słowa PANA, i zawrócili z drogi przeciw Jeroboamowi.
5 Rehoboamu ń gbe ní Jerusalẹmu ó sì kọ́ àwọn ìlú fún olódi ní Juda.
I Roboam zamieszkał w Jerozolimie, i odbudował miasta obronne w Judzie.
6 Bẹtilẹhẹmu, Etamu, Tekoa,
Odbudował Betlejem, Etam i Tekoa;
7 Beti-Suri, Soko, Adullamu,
Bet-Sur, Soko i Adullam;
8 Gati, Meraṣa Sifi,
Gat, Mareszę i Zif;
9 Adoraimu, Lakiṣi, Aseka
Adoraim, Lakisz i Azekę;
10 Sora, Aijaloni, àti Hebroni. Wọ̀nyí ni àwọn ìlú ìdáàbòbò ní Juda àti Benjamini.
Sorea, Ajjalon i Hebron, warowne miasta w Judzie i Beniaminie.
11 Ó sì mú àwọn ìlú olódi lágbára, ó sì fi àwọn balógun sínú wọn àti àkójọ oúnjẹ, àti òróró àti ọtí wáìnì.
A gdy wzmocnił te twierdze, ustanowił w nich dowódców i [zaopatrzył] w składy zboża, oliwy i wina.
12 Àti ní olúkúlùkù ìlú ni ó fi asà àti ọ̀kọ̀ sí, ó sì mú wọn lágbára gidigidi, ó sì ní Juda àti Benjamini lábẹ́ rẹ̀.
A w każdym mieście [złożył] tarcze i włócznie i bardzo je umocnił. Tak należały do niego Juda i Beniamin.
13 Àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi, láti gbogbo ẹ̀yà wọn jákèjádò Israẹli wà ní ẹ̀bá rẹ̀.
Kapłani też i Lewici, którzy [byli] w całym Izraelu, zebrali się u niego, [przybywszy] ze wszystkich swoich granic.
14 Àwọn ará Lefi fi ìgbèríko sílẹ̀, wọ́n sì wá sí Juda àti Jerusalẹmu nítorí Jeroboamu àti àwọn ọmọ rẹ̀, ti kọ̀ wọ́n sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà Olúwa.
Lewici bowiem opuścili swoje pastwiska i posiadłości i przyszli do Judy i do Jerozolimy, gdyż Jeroboam i jego synowie odsunęli ich od pełnienia służby kapłańskiej dla PANA.
15 Ó sì yan àwọn àlùfáà tirẹ̀ fún àwọn ibi gíga wọ̀n-ọn-nì, àti fún àwọn ère òbúkọ, àti fún ẹgbọrọ màlúù tí ó ṣe.
I ustanowił sobie kapłanów na wyżynach dla [kultu] demonów i cielców, które sporządził.
16 Àwọn tó wá láti gbogbo ẹ̀yà Israẹli tí wọ́n fi ọkàn wọn fún wíwá Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, tẹ̀lé àwọn ará Lefi lọ sí Jerusalẹmu láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run baba a wọn.
A za nimi przybywali do Jerozolimy ze wszystkich pokoleń Izraela ci, którzy zwrócili swoje serca ku szukaniu PANA, Boga Izraela, aby składać ofiary PANU, Bogu swoich ojców.
17 Ó fún ìjọba Juda ní agbára, ó sì ti Rehoboamu ọmọ Solomoni lẹ́yìn fún ọdún mẹ́ta nítorí ọdún mẹ́ta ni wọ́n fi rìn ní ọ̀nà ti Dafidi àti Solomoni ní àkókò yí.
I tak przez trzy lata umocnili królestwo Judy, i utwierdzili Roboama, syna Salomona. Trzy lata bowiem chodzili drogą Dawida i Salomona.
18 Rehoboamu fẹ́ Mahalati tí ó jẹ́ ọmọbìnrin ti ọmọkùnrin Dafidi Jerimoti bi àti ti Abihaili, ọmọbìnrin ti ọmọkùnrin Jese Eliabu bí.
Potem Roboam wziął sobie za żonę Machalat, córkę Jerimota, syna Dawida, [oraz] Abihail, córkę Eliaba, syna Jessego;
19 Ó bí àwọn ọmọ fún un: Jeuṣi, Ṣemariah àti Sahamu.
Która mu urodziła synów: Jeusza, Szemariasza i Zahama.
20 Nígbà náà, ó fẹ́ Maaka ọmọbìnrin Absalomu, tí ó bí Abijah fún Attai, Sisa àti Ṣelomiti.
A po niej wziął za żonę Maakę, córkę Absaloma, która urodziła mu Abiasza, Attaja, Zizę i Szelomita.
21 Rehoboamu fẹ́ràn Maaka ọmọbìnrin Absalomu ju èyíkéyìí nínú àwọn ìyàwó rẹ̀ àti àwọn àlè rẹ̀ lọ. Ní gbogbo rẹ̀, ó ní ìyàwó méjìdínlógún àti ọgọ́ta àlè ọmọkùnrin méjìdínlọ́gbọ̀n àti ọgọ́ta ọmọbìnrin.
Roboam ukochał Maakę, córkę Absaloma, najbardziej ze wszystkich swoich żon i nałożnic. Pojął bowiem osiemnaście żon i sześćdziesiąt nałożnic i spłodził dwudziestu ośmiu synów i sześćdziesiąt córek.
22 Rehoboamu yan Abijah ọmọ Maaka láti jẹ́ olóyè ọmọ-aládé láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀, kí ó ba à lè ṣe é ní ọba.
I Roboam ustanowił na czele Abiasza, syna Maaki, aby był wodzem wśród jego braci. [Zamierzał] bowiem uczynić go królem.
23 Ó hùwà ọlọ́gbọ́n, nípa fí fọ́n díẹ̀ nínú àwọn ọmọ rẹ̀ jákèjádò ká àwọn agbègbè Juda àti Benjamini àti sí gbogbo àwọn ìlú ńlá olódi. Ó fún wọn ní ọ̀pọ̀ ohun tí wọ́n fẹ́, ó sì fẹ́ ọ̀pọ̀ ìyàwó fún wọn.
A postępując roztropnie, rozesłał wszystkich [pozostałych] swoich synów po wszystkich krainach Judy i Beniamina, po wszystkich miastach warownych, i zaopatrzył ich w zapasy żywności. I pragnął wielu żon.

< 2 Chronicles 11 >