< 2 Chronicles 10 >
1 Rehoboamu sì lọ sí Ṣekemu nítorí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ti lọ síbẹ̀ láti fi jẹ ọba.
Și Roboam a mers la Sihem, căci la Sihem venise tot Israelul să îl facă împărat.
2 Nígbà tí Jeroboamu ọmọ Nebati gbọ́ ẹni ti ó wà ní Ejibiti, níbi tí ó ti sá kúrò lọ́dọ̀ ọba Solomoni ó sì padà láti Ejibiti.
Și s-a întâmplat, când a auzit aceasta Ieroboam, fiul lui Nebat, care era în Egipt, unde fugise din prezența împăratului Solomon, că Ieroboam s-a întors din Egipt.
3 Bẹ́ẹ̀ ni nígbà náà ó sì ránṣẹ́ sí Jeroboamu àti òun àti gbogbo àwọn Israẹli lọ sí ọ̀dọ̀ Rehoboamu wọ́n sì wí fún pé,
Și au trimis și l-au chemat. Astfel Ieroboam și tot Israelul au venit și au vorbit lui Roboam, spunând:
4 “Baba rẹ gbé àjàgà tí ó wúwo lórí wa, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ mú un fúyẹ́, iṣẹ́ líle àti àjàgà wúwo tí ó gbé ka orí wa, àwa yóò sì sìn ọ́.”
Tatăl tău a făcut jugul nostru apăsător; acum, de aceea, ușurează puțin acest serviciu apăsător al tatălui tău și jugul său greu pe care l-a pus peste noi și îți vom servi.
5 Rehoboamu sì dáhùn pé, “Ẹ padà wá sọ́dọ̀ mi lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn náà sì lọ.
Iar el le-a spus: Veniți din nou la mine după trei zile. Și poporul s-a depărtat.
6 Nígbà náà ni ọba Rehoboamu fi ọ̀ràn lọ̀ àwọn àgbàgbà tí ó ti ń sin baba rẹ̀ Solomoni nígbà ayé rẹ̀, ó sì bi wọ́n léèrè pe, “Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe gbà mí ní ìmọ̀ràn láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”
Și împăratul Roboam a ținut sfat cu bătrânii care au stat în picioare înaintea lui Solomon, tatăl său, în timp ce el încă trăia, spunând: Ce sfat îmi dați ca să mă întorc să răspund acestui popor?
7 Wọ́n sì dáhùn, “Tí ìwọ yóò bá ṣe rere sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kí o sì ṣe ìre fún wọn, kí o sì fún wọn ní ìdáhùn rere, wọn yóò sì máa jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ nígbà gbogbo.”
Iar ei i-au vorbit, spunând: Dacă ești bun cu acest popor și le vei plăcea și le vei vorbi cuvinte bune, ei vor fi servitorii tăi pentru totdeauna.
8 Ṣùgbọ́n Rehoboamu kọ ìmọ̀ràn náà tí àwọn àgbàgbà fi fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn ọmọ ọkùnrin tí ó ti dàgbàsókè pẹ̀lú rẹ̀ tí wọ́n sì ń dúró níwájú rẹ̀.
Dar el a părăsit sfatul pe care bătrânii i l-au dat și a ținut sfat cu tinerii care au crescut cu el, care au stat înaintea lui.
9 Ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni kí a ṣe dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí tí wọ́n wí fún mi pé, ‘Mú kí àjàgà tí baba rẹ gbé lé wa kí ó fúyẹ́ díẹ̀.’”
Și le-a spus: Ce sfat îmi dați ca să mă întorc să răspund acestui popor, care mi-a vorbit, spunând: Ușurează puțin jugul pe care tatăl tău l-a pus peste noi?
10 Àwọn ọ̀dọ́mọdé tí ó ti dàgbà pẹ̀lú rẹ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí ó wí fún ọ wí pé, ‘Baba rẹ gbé àjàgà wúwo lórí wa, ṣùgbọ́n mú àjàgà wa fúyẹ́,’ wí fún wọn pé, ‘Ìka ọwọ́ mi kékeré, ó nípọn ju ìbàdí baba mi lọ.
Și tinerii care au fost crescuți cu el i-au vorbit, spunând: Astfel să răspunzi poporului care ți-a vorbit, zicând: Tatăl tău ne-a făcut jugul greu, dar tu fă-l puțin mai ușor pentru noi; astfel să le spui: Degetul meu mic va fi mai gros decât coapsele tatălui meu.
11 Baba mi gbé àjàgà wúwo ka orí yín; èmi yóò sì tún mú kí ó wúwo sì í. Baba mi fi pàṣán nà yín; èmi yóò sì nà yín pẹ̀lú àkéekèe.’”
Și acum, dacă tatăl meu a pus un jug greu peste voi, eu voi pune mai mult peste jugul vostru; tatăl meu v-a pedepsit cu bice, dar eu vă voi pedepsi cu scorpioni.
12 Ní ọjọ́ kẹta Jeroboamu àti gbogbo ènìyàn sì padà sí ọ̀dọ̀ Rehoboamu, gẹ́gẹ́ bí ọba ti sọ, “Ẹ padà wá sọ́dọ̀ mi ní ọjọ́ kẹta.”
Astfel Ieroboam și tot poporul au venit la Roboam în a treia zi, precum a cerut împăratul, spunând: Veniți din nou la mine în a treia zi.
13 Nígbà náà ni ọba dá wọn lóhùn ní ọ̀nà líle. Rehoboamu ọba sì kọ̀ ìmọ̀ràn àwọn àgbàgbà sílẹ̀,
Și împăratul le-a răspuns cu asprime; și împăratul Roboam a părăsit sfatul bătrânilor,
14 Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọ̀dọ́mọdé, ó sì wí pé, “Baba mi mú kí àjàgà yín wúwo; èmi yóò sì mú kí ó wúwo jù bẹ́ẹ̀ lọ. Baba mi nà yín pẹ̀lú pàṣán; èmi yóò sì nà yín pẹ̀lú àkéekèe.”
Și le-a răspuns după sfatul tinerilor, spunând: Tatăl meu v-a făcut jugul greu, dar eu voi adăuga la acesta; tatăl meu v-a pedepsit cu bice, dar eu vă voi pedepsi cu scorpioni.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fetísí àwọn ènìyàn, nítorí ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí wá láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni. Láti mú ọ̀rọ̀ Olúwa ṣẹ tí a ti sọ fún Jeroboamu ọmọ Nebati nípasẹ̀ Ahijah ará Ṣilo.
Astfel împăratul nu a dat ascultare poporului, căci răzvrătirea era de la Dumnezeu, ca să își împlinească DOMNUL cuvântul pe care l-a vorbit prin mâna lui Ahiia șilonitul, lui Ieroboam, fiul lui Nebat.
16 Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i wí pé ọba kọ̀ láti gbọ́ tiwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn wí pé, “Ìpín kí ní a ní nínú Dafidi, ìní wo ni a ní nínú ọmọ Jese? Ẹ lọ sí àgọ́ yín, ẹ̀yin Israẹli! Bojútó ilé rẹ, ìwọ Dafidi!” Bẹ́ẹ̀ ní gbogbo àwọn ọmọ Israẹli lọ sí ilé wọn.
Și când tot Israelul a văzut că împăratul a refuzat să le dea ascultare, poporul a răspuns împăratului, spunând: Ce parte avem noi în David? Și nu avem nicio moștenire în fiul lui Isai; fiecare bărbat la corturile voastre, Israele; și acum, David, vezi-ți de propria ta casă. Astfel tot Israelul a mers la corturile lor.
17 Ṣùgbọ́n ní ti àwọn ọmọ Israẹli tí ń gbé ní ìlú Juda, Rehoboamu ń jẹ ọba lórí wọn.
Dar cât despre copiii lui Israel care au locuit în cetățile lui Iuda, Roboam a domnit peste ei.
18 Ọba Rehoboamu rán Adoniramu jáde, ẹni tí ó wà ní ìkáwọ́ iṣẹ́ onírúurú, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa. Ọba Rehoboamu, gbìyànjú láti dé inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì sálọ sí Jerusalẹmu.
Atunci împăratul Roboam a trimis pe Hadoram, care era peste taxă; și copiii lui Israel l-au împroșcat cu pietre, încât a murit. Dar împăratul Roboam s-a grăbit să îl i-a în carul său, să fugă la Ierusalim.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Israẹli sì wà ní ìṣọ̀tẹ̀ lórí ilé Dafidi títí fi di òní yìí.
Și Israel s-a răzvrătit împotriva casei lui David până în această zi.