< 2 Chronicles 10 >

1 Rehoboamu sì lọ sí Ṣekemu nítorí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ti lọ síbẹ̀ láti fi jẹ ọba.
Tedy jechał Roboam do Sychem; bo w Sychem zebrał się był wszystek Izrael, aby go postanowił królem.
2 Nígbà tí Jeroboamu ọmọ Nebati gbọ́ ẹni ti ó wà ní Ejibiti, níbi tí ó ti sá kúrò lọ́dọ̀ ọba Solomoni ó sì padà láti Ejibiti.
A gdy to usłyszał Jeroboam, syn Nabatowy, który był w Egipcie, gdzie był uciekł przed królem Salomonem, wrócił się Jeroboam z Egiptu;
3 Bẹ́ẹ̀ ni nígbà náà ó sì ránṣẹ́ sí Jeroboamu àti òun àti gbogbo àwọn Israẹli lọ sí ọ̀dọ̀ Rehoboamu wọ́n sì wí fún pé,
Bo posłali i wezwali go. Tedy przyszedł Jeroboam i wszystek Izrael, i rzekli do Roboama, mówiąc:
4 “Baba rẹ gbé àjàgà tí ó wúwo lórí wa, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ mú un fúyẹ́, iṣẹ́ líle àti àjàgà wúwo tí ó gbé ka orí wa, àwa yóò sì sìn ọ́.”
Ojciec twój włożył na nas jarzmo ciężkie; ale ty teraz ulżyj nam niewoli srogiej ojca twego, i jarzma ciężkiego, które włożył na nas, a będziemyć służyli.
5 Rehoboamu sì dáhùn pé, “Ẹ padà wá sọ́dọ̀ mi lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn náà sì lọ.
Który im rzekł: Po trzech dniach wróćcie się do mnie. I odszedł lud.
6 Nígbà náà ni ọba Rehoboamu fi ọ̀ràn lọ̀ àwọn àgbàgbà tí ó ti ń sin baba rẹ̀ Solomoni nígbà ayé rẹ̀, ó sì bi wọ́n léèrè pe, “Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe gbà mí ní ìmọ̀ràn láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”
Międzytem wszedł król Roboam w radę z starszymi, którzy stawali przed Salomonem, ojcem jego, za żywota jego, mówiąc: Co wy radzicie? Jakąbym miał dać odpowiedź ludowi temu?
7 Wọ́n sì dáhùn, “Tí ìwọ yóò bá ṣe rere sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kí o sì ṣe ìre fún wọn, kí o sì fún wọn ní ìdáhùn rere, wọn yóò sì máa jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ nígbà gbogbo.”
Którzy mu odpowiedzieli, mówiąc: Jeźli dziś powolny będziesz ludowi temu, a uczynisz im kwoli, i będziesz mówił do nich słowa łagodne, będą sługami twymi po wszystkie dni.
8 Ṣùgbọ́n Rehoboamu kọ ìmọ̀ràn náà tí àwọn àgbàgbà fi fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn ọmọ ọkùnrin tí ó ti dàgbàsókè pẹ̀lú rẹ̀ tí wọ́n sì ń dúró níwájú rẹ̀.
Ale on opuściwszy radę starszych, którą mu podali, wszedł w radę z młodzieńcami, którzy z nim wzrośli i stawali przed nim.
9 Ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni kí a ṣe dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí tí wọ́n wí fún mi pé, ‘Mú kí àjàgà tí baba rẹ gbé lé wa kí ó fúyẹ́ díẹ̀.’”
I rzekł do nich: Cóż wy radzicie, abyśmy odpowiedzieli ludowi temu, którzy rzekli do mnie, mówiąc: Ulżyj tego jarzma, które włożył ojciec twój na nas?
10 Àwọn ọ̀dọ́mọdé tí ó ti dàgbà pẹ̀lú rẹ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí ó wí fún ọ wí pé, ‘Baba rẹ gbé àjàgà wúwo lórí wa, ṣùgbọ́n mú àjàgà wa fúyẹ́,’ wí fún wọn pé, ‘Ìka ọwọ́ mi kékeré, ó nípọn ju ìbàdí baba mi lọ.
Tedy mu odpowiedzieli oni młodzieńcy, którzy z nim wzrośli, mówiąc: Tak odpowiesz temu ludowi, którzy do ciebie rzekli, mówiąc: Ojciec twój włożył na nas ciężkie jarzmo, ale ty ulżyj go nam. Tak rzeczesz do nich: Najmniejszy palec mój mięższy niż biodra ojca mego.
11 Baba mi gbé àjàgà wúwo ka orí yín; èmi yóò sì tún mú kí ó wúwo sì í. Baba mi fi pàṣán nà yín; èmi yóò sì nà yín pẹ̀lú àkéekèe.’”
Przetoż teraz, ojciec mój kładł na was jarzmo ciężkie, ale ja przydam do jarzma waszego; ojciec mój karał was biczykami, a ja was będę karał korbaczami.
12 Ní ọjọ́ kẹta Jeroboamu àti gbogbo ènìyàn sì padà sí ọ̀dọ̀ Rehoboamu, gẹ́gẹ́ bí ọba ti sọ, “Ẹ padà wá sọ́dọ̀ mi ní ọjọ́ kẹta.”
Przyszedł tedy Jeroboam i wszystek lud do Roboama dnia trzeciego, jako był im rozkazał król, mówiąc: Wróćcie się do mnie dnia trzeciego.
13 Nígbà náà ni ọba dá wọn lóhùn ní ọ̀nà líle. Rehoboamu ọba sì kọ̀ ìmọ̀ràn àwọn àgbàgbà sílẹ̀,
I odpowiedział im król surowie, bo opuścił król Roboam radę starców.
14 Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọ̀dọ́mọdé, ó sì wí pé, “Baba mi mú kí àjàgà yín wúwo; èmi yóò sì mú kí ó wúwo jù bẹ́ẹ̀ lọ. Baba mi nà yín pẹ̀lú pàṣán; èmi yóò sì nà yín pẹ̀lú àkéekèe.”
A rzekł do nich według rady młodzieńców, mówiąc: Ojciec mój obciążył was jarzmem ciężkiem, ale ja przydam do niego; ojciec mój karał was biczykami, ale ja was będę karał korbaczami.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fetísí àwọn ènìyàn, nítorí ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí wá láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni. Láti mú ọ̀rọ̀ Olúwa ṣẹ tí a ti sọ fún Jeroboamu ọmọ Nebati nípasẹ̀ Ahijah ará Ṣilo.
I nie usłuchał król ludu: (bo była przyczyna od Boga, aby dosyć uczynił Pan słowu swemu, które był powiedział przez Achyjasza Sylonitczyka do Jeroboama, syna Nabatowego.)
16 Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i wí pé ọba kọ̀ láti gbọ́ tiwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn wí pé, “Ìpín kí ní a ní nínú Dafidi, ìní wo ni a ní nínú ọmọ Jese? Ẹ lọ sí àgọ́ yín, ẹ̀yin Israẹli! Bojútó ilé rẹ, ìwọ Dafidi!” Bẹ́ẹ̀ ní gbogbo àwọn ọmọ Israẹli lọ sí ilé wọn.
Przetoż widząc wszystek Izrael, że ich król nie usłuchał, odpowiedział lud królowi, mówiąc: Cóż mamy za dział w Dawidzie? a co za dziedzictwo w synu Isajowym? Każdy idź do namiotów swych, o Izraelu! a ty Dawidzie! opatrz teraz dom swój. I rozeszli się wszyscy Izraelczycy do namiotów swoich.
17 Ṣùgbọ́n ní ti àwọn ọmọ Israẹli tí ń gbé ní ìlú Juda, Rehoboamu ń jẹ ọba lórí wọn.
A tak tylko nad synami Izraelskimi, którzy mieszkali w miastach Judzkich, królował Roboam.
18 Ọba Rehoboamu rán Adoniramu jáde, ẹni tí ó wà ní ìkáwọ́ iṣẹ́ onírúurú, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa. Ọba Rehoboamu, gbìyànjú láti dé inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì sálọ sí Jerusalẹmu.
I posłał król Roboam Adorama, który był poborcą, i ukamionowali go synowie Izraelscy, że umarł; przetoż król Roboam wsiadłszy co rychlej na wóz, uciekł do Jeruzalemu.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Israẹli sì wà ní ìṣọ̀tẹ̀ lórí ilé Dafidi títí fi di òní yìí.
A tak odstąpili Izraelczycy od domu Dawidowego, aż do dnia tego.

< 2 Chronicles 10 >