< 2 Chronicles 10 >
1 Rehoboamu sì lọ sí Ṣekemu nítorí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ti lọ síbẹ̀ láti fi jẹ ọba.
Elméne Roboám Síkembe; mert Síkembe gyűlt vala az egész Izráel, hogy őt királylyá választanák.
2 Nígbà tí Jeroboamu ọmọ Nebati gbọ́ ẹni ti ó wà ní Ejibiti, níbi tí ó ti sá kúrò lọ́dọ̀ ọba Solomoni ó sì padà láti Ejibiti.
Lőn pedig, mikor ezt meghallotta Jeroboám, a Nébát fia, a ki akkor Égyiptomban vala; mert oda futott volt Salamon király elől, visszatére Jeroboám Égyiptomból.
3 Bẹ́ẹ̀ ni nígbà náà ó sì ránṣẹ́ sí Jeroboamu àti òun àti gbogbo àwọn Israẹli lọ sí ọ̀dọ̀ Rehoboamu wọ́n sì wí fún pé,
És hozzáküldvén, elhivaták őt. Eljöve azért Jeroboám és az egész Izráel, és szólának Roboámnak, mondván:
4 “Baba rẹ gbé àjàgà tí ó wúwo lórí wa, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ mú un fúyẹ́, iṣẹ́ líle àti àjàgà wúwo tí ó gbé ka orí wa, àwa yóò sì sìn ọ́.”
A te atyád igen megnehezítette a mi igánkat, de te most könnyebbítsd meg atyádnak kemény szolgálatát és az ő nehéz igáját, a melyet reánk vetett, és szolgálunk néked.
5 Rehoboamu sì dáhùn pé, “Ẹ padà wá sọ́dọ̀ mi lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn náà sì lọ.
És monda nékik: Harmadnapig gondolkodom róla, azután jőjjetek hozzám. Elméne azért a nép.
6 Nígbà náà ni ọba Rehoboamu fi ọ̀ràn lọ̀ àwọn àgbàgbà tí ó ti ń sin baba rẹ̀ Solomoni nígbà ayé rẹ̀, ó sì bi wọ́n léèrè pe, “Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe gbà mí ní ìmọ̀ràn láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”
És tanácskozék Roboám király a vén emberekkel, a kik Salamon előtt az ő atyja előtt állottak vala életében, mondván: Mit tanácsoltok, mit válaszoljak e népnek?
7 Wọ́n sì dáhùn, “Tí ìwọ yóò bá ṣe rere sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kí o sì ṣe ìre fún wọn, kí o sì fún wọn ní ìdáhùn rere, wọn yóò sì máa jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ nígbà gbogbo.”
És azok ekképen szólának: Ha javára leendesz ennek a népnek, s kedvezel nékik és jó szóval beszélsz hozzájok; akkor te szolgáid lesznek mindenkor.
8 Ṣùgbọ́n Rehoboamu kọ ìmọ̀ràn náà tí àwọn àgbàgbà fi fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn ọmọ ọkùnrin tí ó ti dàgbàsókè pẹ̀lú rẹ̀ tí wọ́n sì ń dúró níwájú rẹ̀.
De ő megvetette a vének tanácsát, a melyet néki tanácsoltak, és tanácsot tarta az ifjakkal, a kik ő vele nevekedtek volt fel és néki udvaroltak.
9 Ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni kí a ṣe dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí tí wọ́n wí fún mi pé, ‘Mú kí àjàgà tí baba rẹ gbé lé wa kí ó fúyẹ́ díẹ̀.’”
És monda azoknak: Ti micsoda tanácsot adtok, hogy választ adjunk e népnek, a kik nékem így szólának: Könnyebbítsd meg az igát, a melyet a te atyád reánk vetett.
10 Àwọn ọ̀dọ́mọdé tí ó ti dàgbà pẹ̀lú rẹ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí ó wí fún ọ wí pé, ‘Baba rẹ gbé àjàgà wúwo lórí wa, ṣùgbọ́n mú àjàgà wa fúyẹ́,’ wí fún wọn pé, ‘Ìka ọwọ́ mi kékeré, ó nípọn ju ìbàdí baba mi lọ.
Akkor felelének az ifjak, a kik ő vele együtt nevekedtek vala, mondván: Így szólj a népnek, a mely szólván néked, azt mondja: A te atyád megnehezítette a mi igánkat, te pedig könnyebbítsd meg nékünk; így szólj nékik: Az én legkisebb ujjam erősebb atyám derekánál;
11 Baba mi gbé àjàgà wúwo ka orí yín; èmi yóò sì tún mú kí ó wúwo sì í. Baba mi fi pàṣán nà yín; èmi yóò sì nà yín pẹ̀lú àkéekèe.’”
Most azért, ha az én atyám nehéz igát vetett reátok, én még nehezebbé teszem igátokat; ha az én atyám ostorral vert titeket, én skorpiókkal.
12 Ní ọjọ́ kẹta Jeroboamu àti gbogbo ènìyàn sì padà sí ọ̀dọ̀ Rehoboamu, gẹ́gẹ́ bí ọba ti sọ, “Ẹ padà wá sọ́dọ̀ mi ní ọjọ́ kẹta.”
És elméne Jeroboám és az egész nép Roboámhoz harmadnap, a mint a király meghagyta, ezt mondván: Jőjjetek hozzám harmadnapon.
13 Nígbà náà ni ọba dá wọn lóhùn ní ọ̀nà líle. Rehoboamu ọba sì kọ̀ ìmọ̀ràn àwọn àgbàgbà sílẹ̀,
És a király kemény választ adott nékik, megvetve Roboám király a vének tanácsát.
14 Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọ̀dọ́mọdé, ó sì wí pé, “Baba mi mú kí àjàgà yín wúwo; èmi yóò sì mú kí ó wúwo jù bẹ́ẹ̀ lọ. Baba mi nà yín pẹ̀lú pàṣán; èmi yóò sì nà yín pẹ̀lú àkéekèe.”
És az ifjak tanácsa szerint szóla nékik, mondván: Ha az én atyám megnehezítette a ti igátokat, én még nehezebbé teszem azt; ha az én atyám ostorral vert titeket, én skorpiókkal.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fetísí àwọn ènìyàn, nítorí ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí wá láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni. Láti mú ọ̀rọ̀ Olúwa ṣẹ tí a ti sọ fún Jeroboamu ọmọ Nebati nípasẹ̀ Ahijah ará Ṣilo.
És a király nem hallgatá meg a népet; mert ezt az Úr fordította ekként, hogy megerősítené az Úr az ő beszédét, a melyet szólott vala a Silóbeli Ahija által Jeroboámnak, a Nébát fiának.
16 Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i wí pé ọba kọ̀ láti gbọ́ tiwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn wí pé, “Ìpín kí ní a ní nínú Dafidi, ìní wo ni a ní nínú ọmọ Jese? Ẹ lọ sí àgọ́ yín, ẹ̀yin Israẹli! Bojútó ilé rẹ, ìwọ Dafidi!” Bẹ́ẹ̀ ní gbogbo àwọn ọmọ Israẹli lọ sí ilé wọn.
Mikor pedig az egész Izráel látta, hogy nem hallgatá meg őket a király, felele a nép a királynak, mondván: Micsoda részünk van nékünk Dávidban? Nincsen nékünk örökségünk az Isai fiában! Menj el a te hajlékidba, oh Izráel! Ám viseld gondját a te házadnak, oh Dávid! Elméne azért hajlékiba az egész Izráel;
17 Ṣùgbọ́n ní ti àwọn ọmọ Israẹli tí ń gbé ní ìlú Juda, Rehoboamu ń jẹ ọba lórí wọn.
Úgy, hogy Roboám csak azokon az Izráel fiain uralkodék, a kik Júda városaiban laktak.
18 Ọba Rehoboamu rán Adoniramu jáde, ẹni tí ó wà ní ìkáwọ́ iṣẹ́ onírúurú, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa. Ọba Rehoboamu, gbìyànjú láti dé inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì sálọ sí Jerusalẹmu.
És mikor elküldé Roboám Adorámot, az adószedőt, megkövezék őt Izráel fiai, és meghala; Roboám király pedig siete szekerébe ülni, hogy Jeruzsálembe szaladjon.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Israẹli sì wà ní ìṣọ̀tẹ̀ lórí ilé Dafidi títí fi di òní yìí.
Így szakada el az Izráel népe a Dávid házától, mind e mai napig.