< 2 Chronicles 10 >

1 Rehoboamu sì lọ sí Ṣekemu nítorí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ti lọ síbẹ̀ láti fi jẹ ọba.
És elment Rechabeám Sekhémbe; mert Sekhémbe gyűlt egész Izrael, hogy őt királlyá tegyék.
2 Nígbà tí Jeroboamu ọmọ Nebati gbọ́ ẹni ti ó wà ní Ejibiti, níbi tí ó ti sá kúrò lọ́dọ̀ ọba Solomoni ó sì padà láti Ejibiti.
És volt midőn hallotta Járobeám, Nebát fia – ő ugyanis Egyiptomban volt, ahová megszökött Salamon király elől – visszatért Járobeám Egyiptomból.
3 Bẹ́ẹ̀ ni nígbà náà ó sì ránṣẹ́ sí Jeroboamu àti òun àti gbogbo àwọn Israẹli lọ sí ọ̀dọ̀ Rehoboamu wọ́n sì wí fún pé,
És küldtek s hivatták őt, s odament Járobeám meg egész Izrael, s beszéltek Rechabéámhoz, mondván:
4 “Baba rẹ gbé àjàgà tí ó wúwo lórí wa, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ mú un fúyẹ́, iṣẹ́ líle àti àjàgà wúwo tí ó gbé ka orí wa, àwa yóò sì sìn ọ́.”
Atyád keménnyé tette jármunkat, most tehát könnyíts atyád kemény szolgálatán és azon nehéz jármán, melyet ránk vetett, és szolgálunk neked.
5 Rehoboamu sì dáhùn pé, “Ẹ padà wá sọ́dọ̀ mi lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn náà sì lọ.
Erre szólt hozzájuk: Még három napot, akkor jöjjetek vissza hozzám. S elment a nép.
6 Nígbà náà ni ọba Rehoboamu fi ọ̀ràn lọ̀ àwọn àgbàgbà tí ó ti ń sin baba rẹ̀ Solomoni nígbà ayé rẹ̀, ó sì bi wọ́n léèrè pe, “Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe gbà mí ní ìmọ̀ràn láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”
Akkor tanácskozott Rechabeám király az öregekkel, kik atyja Salamon előtt álltak, amíg élt, mondván: Miféle tanácsot adtok, hogy választ adjak e népnek?
7 Wọ́n sì dáhùn, “Tí ìwọ yóò bá ṣe rere sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kí o sì ṣe ìre fún wọn, kí o sì fún wọn ní ìdáhùn rere, wọn yóò sì máa jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ nígbà gbogbo.”
Beszéltek hozzá, mondván: Ha jó lesz e nép iránt s kedveled őket s beszélsz hozzájuk jó szavakkal, akkor szolgáid lesznek neked minden időben.
8 Ṣùgbọ́n Rehoboamu kọ ìmọ̀ràn náà tí àwọn àgbàgbà fi fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn ọmọ ọkùnrin tí ó ti dàgbàsókè pẹ̀lú rẹ̀ tí wọ́n sì ń dúró níwájú rẹ̀.
De elhagyta az öregek tanácsát, melyet tanácsoltak neki és tanácskozott az ifjakkal, kik vele nőttek föl, kik őelőtte álltak.
9 Ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni kí a ṣe dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí tí wọ́n wí fún mi pé, ‘Mú kí àjàgà tí baba rẹ gbé lé wa kí ó fúyẹ́ díẹ̀.’”
És szólt hozzájuk: Mi tanácsot adtok, hogy választ adjunk e népnek, akik így szóltak hozzám, mondván: könnyíts a jármon, amelyet ránk vetett atyád?
10 Àwọn ọ̀dọ́mọdé tí ó ti dàgbà pẹ̀lú rẹ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí ó wí fún ọ wí pé, ‘Baba rẹ gbé àjàgà wúwo lórí wa, ṣùgbọ́n mú àjàgà wa fúyẹ́,’ wí fún wọn pé, ‘Ìka ọwọ́ mi kékeré, ó nípọn ju ìbàdí baba mi lọ.
Beszéltek vele az ifjak, akik vele nőttek föl mondván: Így mondjad a népnek, akik beszéltek hozzád, mondván: atyád nehézzé tette jármunkat, te pedig könnyíts rajtunk; így szólj hozzájuk: kis ujjam vastagabb atyám derekánál;
11 Baba mi gbé àjàgà wúwo ka orí yín; èmi yóò sì tún mú kí ó wúwo sì í. Baba mi fi pàṣán nà yín; èmi yóò sì nà yín pẹ̀lú àkéekèe.’”
most tehát atyám nehéz jármot rakott rátok, én pedig súlyosbítom majd jármotokat; atyám ostorokkal fenyített benneteket, én pedig skorpiókkal!
12 Ní ọjọ́ kẹta Jeroboamu àti gbogbo ènìyàn sì padà sí ọ̀dọ̀ Rehoboamu, gẹ́gẹ́ bí ọba ti sọ, “Ẹ padà wá sọ́dọ̀ mi ní ọjọ́ kẹta.”
És odament Járobeám meg az egész nép Rechabeámhoz harmadnapon, ahogy szólt a király, mondván: jöjjetek vissza hozzám harmadnapon.
13 Nígbà náà ni ọba dá wọn lóhùn ní ọ̀nà líle. Rehoboamu ọba sì kọ̀ ìmọ̀ràn àwọn àgbàgbà sílẹ̀,
Keményen felelt nekik a király; elhagyta Rechabeám király az öregek tanácsát,
14 Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọ̀dọ́mọdé, ó sì wí pé, “Baba mi mú kí àjàgà yín wúwo; èmi yóò sì mú kí ó wúwo jù bẹ́ẹ̀ lọ. Baba mi nà yín pẹ̀lú pàṣán; èmi yóò sì nà yín pẹ̀lú àkéekèe.”
és beszélt hozzájuk az ifjak tanácsa szerint, mondván: Atyám nehézzé tette jármotokat, én pedig majd súlyosbítom azt; atyám ostorokkal fenyített benneteket, én pedig skorpiókkal.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fetísí àwọn ènìyàn, nítorí ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí wá láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni. Láti mú ọ̀rọ̀ Olúwa ṣẹ tí a ti sọ fún Jeroboamu ọmọ Nebati nípasẹ̀ Ahijah ará Ṣilo.
A király azért nem hallgatott a népre, mert így volt okozva Isten részéről, azért hogy az Örökkévaló fenntartsa szavát, amelyet szólt a Silóbeli Achijáhú által Járobeámhoz, Nebát fiához.
16 Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i wí pé ọba kọ̀ láti gbọ́ tiwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn wí pé, “Ìpín kí ní a ní nínú Dafidi, ìní wo ni a ní nínú ọmọ Jese? Ẹ lọ sí àgọ́ yín, ẹ̀yin Israẹli! Bojútó ilé rẹ, ìwọ Dafidi!” Bẹ́ẹ̀ ní gbogbo àwọn ọmọ Israẹli lọ sí ilé wọn.
Látta tehát egész Izrael, hogy nem hallgatott rájuk a király, s válaszolt a nép a királynak, mondván: Mi részünk van Dávidban? Nincs örökségünk Jísaj fiában! Kiki sátraidhoz, Izrael! Most nézz házad után, Dávid! S elment egész Izrael a sátraihoz.
17 Ṣùgbọ́n ní ti àwọn ọmọ Israẹli tí ń gbé ní ìlú Juda, Rehoboamu ń jẹ ọba lórí wọn.
A Jehúda városaiban lakó Izrael fiai azok fölött király volt Rechabeám.
18 Ọba Rehoboamu rán Adoniramu jáde, ẹni tí ó wà ní ìkáwọ́ iṣẹ́ onírúurú, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa. Ọba Rehoboamu, gbìyànjú láti dé inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì sálọ sí Jerusalẹmu.
Küldte Rechabeám király Hadórámot, aki a robot fölött volt és meghajigálták őt kővel Izrael fiai, úgy hogy meghalt; Rechabeám király pedig erőlködött, hogy kocsira szálljon, hogy megfutamodjék Jeruzsálembe.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Israẹli sì wà ní ìṣọ̀tẹ̀ lórí ilé Dafidi títí fi di òní yìí.
Így pártolt el Izrael Dávid házától mind e mai napig.

< 2 Chronicles 10 >