< 2 Chronicles 1 >

1 Solomoni ọmọ Dafidi fìdí ara rẹ̀ múlẹ̀ ṣinṣin lórí ìjọba rẹ̀. Nítorí tí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú u rẹ̀, ó sì jẹ́ kí ó ga lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Salomon, fils de David, s’affermit sur son trône; l’Eternel, son Dieu, était avec lui et l’éleva à un haut rang.
2 Nígbà náà, Solomoni bá gbogbo Israẹli sọ̀rọ̀ sí àwọn alákòóso ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún, sí àwọn adájọ́ àti sí gbogbo àwọn olórí Israẹli, àwọn olórí ìdílé
Salomon s’adressa à tout Israël, aux chiliarques, aux centurions, aux juges, à tous les princes d’Israël, chefs des familles,
3 pẹ̀lú Solomoni, àti gbogbo àpéjọ lọ sí ibi gíga ní Gibeoni, nítorí àgọ́ Ọlọ́run fún pípàdé wà níbẹ̀, tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti pa ní aginjù.
et, accompagné de toute l’assemblée, il se rendit au haut lieu qui était à Gabaon; car là se trouvait la Tente d’assignation de Dieu, construite par Moïse, serviteur de l’Eternel, dans le désert.
4 Nísinsin yìí, Dafidi ti gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run wá láti Kiriati-Jearimu sí ibi tí ó ti pèsè fún un, nítorí ó ti kọ́ àgọ́ fún un ni Jerusalẹmu.
Toutefois l’arche de Dieu, David l’avait transférée de Kiryat-Yearim dans la résidence qu’il lui avait aménagée: il avait, en effet, dressé pour elle un pavillon à Jérusalem.
5 Ṣùgbọ́n pẹpẹ idẹ tí Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ṣe wà ní Gibeoni níwájú àgọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Solomoni àti gbogbo àpéjọ béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ níbẹ̀.
Quant à l’autel de cuivre, qu’avait confectionné Beçalêl, fils d’Ouri, fils de Hour, on l’avait placé devant le Tabernacle du Seigneur; c’est lui, le Seigneur, que Salomon et l’assemblée allèrent rechercher.
6 Solomoni gòkè lọ sí ibi pẹpẹ idẹ níwájú Olúwa ní ibi àgọ́ ìpàdé, ó sì rú ẹgbẹ̀rún ẹbọ sísun lórí rẹ̀.
Là, sur cet autel de cuivre, placé devant le Seigneur et faisant partie de la Tente d’assignation, Salomon offrit mille holocaustes.
7 Ní òru ọjọ́ náà, Ọlọ́run farahàn Solomoni, ó sì wí fún un pé, “Béèrè fún ohunkóhun tí ìwọ bá fẹ́ kí n fún ọ.”
Cette même nuit, Dieu apparut à Salomon et lui dit: "Demande: que dois-je te donner?"
8 Solomoni dá Ọlọ́run lóhùn pé, “Ìwọ ti fi àánú ńlá han Dafidi baba mi, ìwọ sì ti fi mí jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Salomon répondit à Dieu: "Tu as témoigné à mon père David une grande faveur, en me permettant de lui succéder.
9 Nísinsin yìí Olúwa Ọlọ́run, jẹ́ kí ìlérí rẹ sí baba à mi Dafidi wá sí ìmúṣẹ, nítorí ìwọ ti fi mí jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn tí ó pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀.
Et maintenant, Seigneur Dieu, que se vérifie la promesse faite à mon père David, puisque tu m’as fait régner sur un peuple nombreux comme le sable de la mer.
10 Fún mi ní ọgbọ́n àti ìmọ̀, kí èmi kí ó lè máa wọ ilé kí ń sì máa jáde níwájú ènìyàn wọ̀nyí, nítorí ta ni ó le è ṣàkóso àwọn ènìyàn rẹ tí ó pọ̀ yanturu wọ̀nyí?”
Donne-moi donc de la sagesse et du discernement, afin que je puisse aller et venir à la tête de ce peuple; car autrement, qui pourrait gouverner un peuple aussi considérable que celui-ci?"
11 Ọlọ́run wí fún Solomoni pé, “Níwọ́n ìgbà tí ó jẹ́ pé ìfẹ́ ọkàn rẹ nìyí, tí ìwọ kò sì béèrè, fún ọrọ̀, ọlá tàbí ọ̀wọ̀, tàbí fún ikú àwọn ọ̀tá rẹ, àti nígbà tí ìwọ kò ti béèrè fún ẹ̀mí gígùn, ṣùgbọ́n tí ìwọ béèrè fún ọgbọ́n àti ìmọ̀ láti ṣàkóso àwọn ènìyàn mi tí èmi fi ọ́ jẹ ọba lé lórí.
Dieu répondit à Salomon: "Puisque telle a été l’inspiration de ton cœur, que tu n’as demandé ni des richesses, ni des trésors, ni des honneurs, ni la vie de tes ennemis, ni de longs jours, que tu as seulement demandé pour toi de la sagesse et du discernement pour gouverner mon peuple, sur lequel je t’ai fait régner,
12 Nítorí náà, ọgbọ́n àti ìmọ̀ ni a ó fi fún ọ, Èmi yóò sì fún ọ ní ọrọ̀, ọlá àti ọ̀wọ̀, irú èyí tí ọba ti ó wà ṣáájú rẹ kò ní, tí àwọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn rẹ kò sì ní ní irú rẹ̀.”
la sagesse et le discernement te sont accordés; et je te donnerai par surcroît des richesses, des trésors et de la gloire, tels que n’en ont eus les rois qui t’ont précédé et que n’en aura personne après toi."
13 Nígbà náà ni Solomoni sì ti ibi gíga Gibeoni lọ sí Jerusalẹmu láti iwájú àgọ́ ìpàdé. Ó sì jẹ ọba lórí Israẹli.
Puis, Salomon, s’éloignant du haut lieu de Gabaon, situé devant la Tente d’assignation, revint à Jérusalem et exerça sa royauté sur Israël.
14 Solomoni kó kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin jọ, ó sì ní ẹgbàáje kẹ̀kẹ́ àti ẹgbàá mẹ́fà ẹlẹ́ṣin, tí ó kó pamọ́ sí ìlú kẹ̀kẹ́ ogun àti pẹ̀lú rẹ̀ ni Jerusalẹmu.
Salomon eut une collection de chars et de cavaliers, quatorze cents chars, douze mille cavaliers, les fit stationner dans les dépôts de chars et en garda près de lui à Jérusalem.
15 Ọba náà ṣe fàdákà àti wúrà gẹ́gẹ́ bí ó ti wọ́pọ̀ ní Jerusalẹmu bí òkúta, àti kedari ó pọ̀ bí igi sikamore ní àwọn ẹsẹ̀ òkè.
Le roi rendit l’argent et l’or à Jérusalem aussi communs que les pierres, et les cèdres aussi nombreux que les sycomores dans la Plaine.
16 Àwọn ẹṣin Solomoni ní a gbà láti ìlú òkèrè Ejibiti àti láti kún ọ̀gbọ̀ oníṣòwò ti ọba ni gba okun náà ní iye kan.
C’Était de l’Egypte que provenaient les chevaux de Salomon; un groupe de marchands, sujets du roi, les acquéraient en masse à prix d’argent.
17 Wọ́n ra kẹ̀kẹ́ kan láti Ejibiti. Fún ẹgbẹ̀ta ṣékélì fàdákà àti ẹṣin kan fún ọgọ́rin méjìdínláàádọ́ta. Wọ́n ko wọn lọ sọ́dọ̀ àwọn ọba mìíràn ti Hiti àti ti àwọn ará Aramu.
Tout attelage qu’ils exportaient et amenaient d’Egypte revenait à six cents pièces d’argent, et un cheval à cent cinquante. C’Est dans les mêmes conditions qu’ils les exportaient personnellement pour tous les rois des Héthéens et pour les rois d’Aram.

< 2 Chronicles 1 >