< 1 Timothy 6 >

1 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí i ṣe ẹrú lábẹ́ ìsìnrú máa ka àwọn olówó tí ó ni wọ́n yẹ sí ọlá gbogbo, kí a má bà á sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Ọlọ́run àti ẹ̀kọ́ rẹ̀.
Którzykolwiek słudzy są pod jarzmem, niech rozumieją panów swych godnych być wszelakiej czci, aby imię Boże i nauka nie była bluźniona.
2 Àwọn ti ó ní ọ̀gá onígbàgbọ́, kí wọn má ṣe ṣàìbọ̀wọ̀ fún wọn nítorí tí wọn jẹ́ arákùnrin; ṣùgbọ́n kí wọn túbọ̀ máa sìn wọ́n, nítorí àwọn tí í ṣe alábápín iṣẹ́ rere wọn jẹ́ onígbàgbọ́ àti olùfẹ́. Nǹkan wọ̀nyí ni kí ó máa kọ́ ni, kí o sì máa fi gbani níyànjú.
A którzy mają panów wiernych, niech nimi nie gardzą, dlatego iż są braćmi, ale tem raczej niech służą, iż są wierni i mili, dobrodziejstwa Bożego uczestnicy. Tego nauczaj i do tego upominaj.
3 Bí ẹnikẹ́ni bá ń kọ́ni ní ẹ̀kọ́ mìíràn, ti kò sì gba ọ̀rọ̀ ti ó yè kooro, ti Jesu Kristi Olúwa wa, àti ẹ̀kọ́ ti ó bá ìwà-bí-Ọlọ́run mu,
Jeźli kto inaczej uczy, a nie przystępuje do zdrowych mów Pana naszego, Jezusa Chrystusa, i do tej nauki, która jest według pobożności,
4 Ó gbéraga, kò mọ̀ nǹkan kan, bí kò ṣe ìyànjú àti ìjà nípa ọ̀rọ̀ èyí tí ó ń mú ìlara, ìjà, ọ̀rọ̀ búburú wá,
Taki nadęty jest i nic nie umie, ale szaleje około gadek i sporów o słowa, z których pochodzi zazdrość, swar, złorzeczenia, złe podejrzenia,
5 àti ọ̀rọ̀ àríyànjiyàn àwọn ènìyàn ọlọ́kàn èérí ti kò sí òtítọ́ nínú wọn, tiwọn ṣe bí ọ̀nà sí èrè ni ìwà-bí-Ọlọ́run; yẹra lọ́dọ̀ irú àwọn wọ̀nyí.
Przewrotne ćwiczenia ludzi umysłu skażonego i którzy pozbawieni są prawdy, którzy rozumieją, że pobożność jest zyskiem cielesnym; odstąpże od takich.
6 Ṣùgbọ́n ìwà-bí-Ọlọ́run pẹ̀lú ìtẹ́lọ́rùn èrè ńlá ni.
A jestci wielki zysk pobożność z przestawaniem na swem;
7 Nítorí a kò mú ohun kan wá sí ayé, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì lè mu ohunkóhun jáde lọ.
Albowiem niceśmy nie przynieśli na ten świat, bez pochyby że też wynieść nic nie możemy;
8 Bí a sì ni oúnjẹ àti aṣọ, ìwọ̀nyí yẹ́ kí ó tẹ́ wa lọ́rùn.
Ale mając żywność i odzienie, na tem przestawać mamy.
9 Ṣùgbọ́n àwọn tí ń fẹ́ di ọlọ́rọ̀ a máa bọ́ sínú ìdánwò àti ìdẹ̀kùn, àti sínú òmùgọ̀ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ púpọ̀ tí í pa ni lára, irú èyí tí ó máa ń ri ènìyàn sínú ìparun àti ègbé.
Bo którzy chcą bogatymi być, wpadają w pokuszenie i w sidło, i w wiele głupich i szkodliwych pożądliwości, które pogrążają ludzi na zatracenie i zginienie.
10 Nítorí ìfẹ́ owó ni gbòǹgbò ohun búburú gbogbo; èyí tí àwọn mìíràn ń lépa tí a sì mú wọn ṣìnà kúrò nínú ìgbàgbọ́, wọ́n sì fi ọ̀pọ̀ ìbànújẹ́ gún ara wọn lọ́kọ̀.
Albowiem korzeń wszystkiego złego jest miłość pieniędzy, których niektórzy pragnąc, pobłądzili od wiary i poprzebijali się wieloma boleściami.
11 Ṣùgbọ́n ìwọ ènìyàn Ọlọ́run, sá fún nǹkan wọ̀nyí; kí ó sì máa lépa òdodo, ìwà-bí-Ọlọ́run, ìgbàgbọ́, ìfẹ́ sùúrù, ìwà tútù.
Ale ty, człowiecze Boży! chroń się takich rzeczy, a naśladuj sprawiedliwości, pobożności, wiary, miłości, cierpliwości, cichości.
12 Máa ja ìjà rere ti ìgbàgbọ́, di ìyè àìnípẹ̀kun mú nínú èyí tí a pè ọ sí, ti ìwọ sì ṣe ìjẹ́wọ́ rere níwájú ẹlẹ́rìí púpọ̀. (aiōnios g166)
Bojuj on dobry bój wiary, chwyć się żywota wiecznego, do któregoś też powołany, i wyznałeś dobre wyznanie przed wieloma świadkami. (aiōnios g166)
13 Mo pàṣẹ fún ọ níwájú Ọlọ́run, tí ń sọ ohun gbogbo di ààyè, àti níwájú Jesu Kristi, ẹni tí ó jẹ́rìí níwájú Pọntiu Pilatu,
Rozkazuję ci przed Bogiem, który wszystko ożywia i przed Chrystusem Jezusem, który oświadczył przed Ponckim Piłatem dobre wyznanie,
14 kí ìwọ pa àṣẹ wọ̀nyí mọ́ ní àìlábàwọ́n, ní àìlẹ́gàn, títí di ìfarahàn Olúwa wa Jesu Kristi.
Abyś zachował to przykazanie, będąc bez zmazy, bez nagany, aż do objawienia Pana naszego, Jezusa Chrystusa,
15 Èyí ti yóò fihàn ní ìgbà tirẹ̀, Ẹni tí í ṣe Olùbùkún àti Alágbára kan ṣoṣo náà, ọba àwọn ọba, àti Olúwa àwọn Olúwa.
Które czasów swoich okaże on błogosławiony i sam możny król królujących i Pan panujących;
16 Ẹnìkan ṣoṣo tí ó jẹ àìkú, tí ń gbé inú ìmọ́lẹ̀ tí a kò lè súnmọ́, ẹni tí ènìyàn kan kò rí rí, tí a kò sì lè rí: ẹni tí ọlá àti agbára títí láé ń ṣe tirẹ̀. Àmín. (aiōnios g166)
Który sam ma nieśmiertelność i mieszka w światłości nieprzystępnej, którego nie widział żaden z ludzi, ani widzieć może; któremu niech będzie cześć i moc wieczna. Amen. (aiōnios g166)
17 Kìlọ̀ fún àwọn tí ó lọ́rọ̀ ní ayé ìsinsin yìí kí wọn ma ṣe gbéraga, bẹ́ẹ̀ ni kí wọn má ṣe gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ àìdánilójú, bí kò ṣe lé Ọlọ́run alààyè, tí ń fi ohun gbogbo fún wa lọ́pọ̀lọ́pọ̀ láti lò; (aiōn g165)
Bogaczom w tym teraźniejszym wieku rozkaż, aby nie byli wysokomyślnymi, ani nadziei pokładali w bogactwie niepewnem, ale w Bogu żywym, który nam wszystkiego obficie ku używaniu dodaje: (aiōn g165)
18 kí wọn máa ṣoore, kí wọn máa pọ̀ ní iṣẹ́ rere, kí wọn múra láti pín fún ni, kí wọn ni ẹ̀mí ìbá kẹ́dùn;
Aby innym dobrze czynili, w uczynki dobre bogatymi byli, radzi dawali, a radzi udzielali,
19 kí wọn máa to ìṣúra ìpìlẹ̀ rere jọ fún ara wọn dé ìgbà tí ń bọ̀, kí wọn lè di ìyè tòótọ́ mú.
Skarbiąc sami sobie grunt dobry na przyszły czas, aby otrzymali żywot wieczny.
20 Timotiu, máa ṣọ ohun tí a fi sí ìkáwọ́ rẹ, yà kúrò nínú ọ̀rọ̀ asán àti ìjiyàn ohun tí a ń fi èké pè ni ìmọ̀;
O Tymoteuszu! strzeż tego, czegoć się powierzono, a brzydź się świecką próżnomównością i sprzeczaniem około fałszywie nazwanej umiejętności,
21 èyí tí àwọn ẹlòmíràn jẹ́wọ́ rẹ̀ tí wọ́n sì ṣìnà ìgbàgbọ́. Kí oore-ọ̀fẹ́ wà pẹ̀lú rẹ.
Którą się niektórzy szczycąc z strony wiary, celu uchybili. Łaska niech będzie z tobą. Amen.

< 1 Timothy 6 >