< 1 Timothy 5 >
1 Má ṣe bá àgbàlagbà ọkùnrin wí, ṣùgbọ́n kí ó máa gbà á níyànjú bí i baba; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin bí arákùnrin.
Starszemu nie łaj, ale jako ojca napominaj, młodszych jako braci,
2 Àwọn àgbàlagbà obìnrin bí ìyá; àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin bí arábìnrin nínú ìwà mímọ́.
Starsze niewiasty jako matki, młodsze jako siostry, ze wszelaką czystością.
3 Bọ̀wọ̀ fún àwọn opó ti í ṣe opó nítòótọ́.
Wdowy miej w uczciwości, które prawdziwie są wdowami.
4 Ṣùgbọ́n bí opó kan bá ni ọmọ tàbí ọmọ ọmọ, jẹ́ kí wọn kọ́kọ́ kọ́ bí a ti ń ṣe ìtọ́jú ilé àwọn tìkára wọn, kí wọn sì san oore àwọn òbí wọn padà; nítorí pé èyí ni ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà níwájú Ọlọ́run.
A jeźli która wdowa dzieci albo wnuczęta ma, niech się uczą pierwej przeciwko domowi własnemu być pobożnemi i wzajem oddawać rodzicom; albowiem to jest rzecz chwalebna i przyjemna przed obliczem Bożem.
5 Ǹjẹ́ ẹni ti í ṣe opó nítòótọ́, ti ó ṣe òun nìkan, a máa gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run, a sì máa dúró nínú ẹ̀bẹ̀ àti nínú àdúrà lọ́sàn àti lóru.
A która jest prawdziwie wdowa i osierociała, ma nadzieję w Bogu i trwa w prośbach i w modlitwach w nocy i we dnie.
6 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá fi ara rẹ fún ayé jíjẹ, ó kú nígbà tí ó wà láààyè.
Ale która w rozkoszach żyje, ta żyjąc umarłą jest.
7 Nǹkan wọ̀nyí ni kí wọn máa paláṣẹ, kí wọn lè wà láìlẹ́gàn.
To tedy rozkazuj, żeby były nienaganione.
8 Ṣùgbọ́n bí ẹnikẹ́ni kò bá pèsè fún àwọn tirẹ̀, pàápàá fún àwọn ará ilé rẹ̀, ó ti sẹ́ ìgbàgbọ́, ó burú ju aláìgbàgbọ́ lọ.
A jeźli kto o swoich, a najwięcej o domowych starania nie ma, wiary się zaprzał i gorszy jest niż niewierny.
9 Kọ orúkọ ẹni tí kò bá dín ni ọgọ́ta ọdún sílẹ̀ bí opó, lẹ́yìn ti ó ti jẹ́ aya ọkọ kan.
Wdowa niech będzie obrana, która by nie miała mniej niż sześćdziesiąt lat, która była żoną jednego męża,
10 Ẹni ti a jẹ́rìí rẹ̀ fún iṣẹ́ rere; bí ẹni ti ó ti tọ́ ọmọ dàgbà, ti ó ń ṣe ìtọ́jú àlejò, tí ó sì ń wẹ ẹsẹ̀ àwọn ènìyàn mímọ́, tí ó ti ran àwọn olùpọ́njú lọ́wọ́, tí ó sì ń lépa iṣẹ́ rere gbogbo.
Mająca świadectwo w dobrych uczynkach, jeźli dzieci wychowała, jeźli gości przyjmowała, jeźli świętych nogi umywała, jeźli utrapionych wspomagała, jeźli każdego uczynku dobrego naśladowała.
11 Ṣùgbọ́n ma ṣe kọ orúkọ àwọn opó tí kò dàgbà; nítorí pé nígbà tiwọn bá ti ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ lòdì sí Kristi, wọn á tún fẹ́ láti gbéyàwó.
Wdów zasię młodszych chroń się; bo gdyby się zbestwiły przeciw Chrystusowi, chcą za mąż iść,
12 Wọn á di ẹlẹ́bi, nítorí tí wọn ti kọ ìgbàgbọ́ wọn ìṣáájú sílẹ̀.
Mając osądzenie, iż pierwszą wiarę odrzuciły;
13 Àti pẹ̀lú wọn ń kọ́ láti ṣe ọ̀lẹ, láti máa kiri láti ilédélé, kì í ṣe ọ̀lẹ nìkan, ṣùgbọ́n onísọkúsọ àti olófòófó pẹ̀lú, wọn a máa sọ ohun tí kò yẹ.
Owszem też próżnując uczą się chodzić od domu do domu; a nie tylko są próżnujące, ale też świegotliwe, niepotrzebnemi rzeczami się bawiące, mówiąc, co nie przystoi.
14 Nítorí náà, mo fẹ́ kí àwọn opó tí kò dàgbà máa gbéyàwó, kí wọn máa bímọ, kí wọn máa ṣe alábojútó ilé, kí wọn má ṣe fi ààyè sílẹ̀ rárá fún ọ̀tá náà láti sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn.
Chcę tedy, aby młodsze szły za mąż, dzieci rodziły, gospodyniami były; przeciwnikowi żadnej przyczyny nie dawały ku obmowisku;
15 Nítorí àwọn mìíràn ti yípadà kúrò sí ẹ̀yìn Satani.
Albowiem się już niektóre obróciły za szatanem.
16 Bí ọkùnrin tàbí obìnrin kan tí ó gbàgbọ́ bá ní àwọn opó, kí ó máa ràn wọ́n lọ́wọ́, kí a má sì di ẹrù lé ìjọ, kí wọn lè máa ran àwọn ti í ṣe opó nítòótọ́ lọ́wọ́.
Przetoż, jeźli który wierny albo która wierna ma wdowy, niechże je opatruje, a niech zbór nie będzie obciążony, aby tym, które są prawdziwie wdowami, starczyło.
17 Àwọn alàgbà ti ó ṣe àkóso dáradára ni kí a kà yẹ sí ọlá ìlọ́po méjì, pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ti ó ṣe làálàá ni ọ̀rọ̀ àti ni kíkọ́ni.
Starsi, którzy się w przełożeństwie dobrze sprawują, niech będą mieni za godnych dwojakiej czci, a zwłaszcza ci, którzy pracują w słowie i w nauce.
18 Nítorí tí Ìwé Mímọ́ wí pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ di màlúù ti ń tẹ ọkà lẹ́nu,” àti pé, “Ọ̀yà alágbàṣe tọ́ sí i.”
Albowiem Pismo mówi: Wołowi młócącemu nie zawiążesz gęby; i: Godzien jest robotnik zapłaty swojej.
19 Má ṣe gba ẹ̀sùn sí alàgbà kan, bí kò ṣe láti ẹnu ẹlẹ́rìí méjì mẹ́ta.
Przeciwko starszemu nie przyjmuj skargi, chyba za dwoma albo trzema świadkami.
20 Bá àwọn tí ó ṣẹ̀ wí níwájú gbogbo ènìyàn, kí àwọn ìyókù pẹ̀lú bà á lè bẹ̀rù.
A tych, którzy grzeszą, strofuj przed wszystkimi, aby i drudzy bojaźń mieli.
21 Mo pàṣẹ fún ọ níwájú Ọlọ́run, àti Kristi Jesu, àti àwọn angẹli àyànfẹ́ kí ìwọ máa ṣàkíyèsí nǹkan wọ̀nyí, láìṣe ojúsàájú, láti fi ègbè ṣe ohunkóhun.
Oświadczam się przed Bogiem i Panem Jezusem Chrystusem, i przed Anioły wybranymi, abyś tych rzeczy przestrzegał, w osobach nie brakując, nic nie czyniąc z przychylności.
22 Má ṣe fi ìkánjú gbe ọwọ́ lé ẹnikẹ́ni, bẹ́ẹ̀ ni kí ó má sì ṣe jẹ́ alábápín nínú ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ẹlòmíràn, pa ara rẹ mọ́ ní ìwà mímọ́.
Rąk z prędka na nikogo nie wkładaj, ani bądź uczestnikiem cudzych grzechów: samego siebie czystym zachowaj.
23 Ma ṣe máa mu omi nìkan, ṣùgbọ́n máa lo wáìnì díẹ̀ nítorí inú rẹ, àti nítorí àìlera ìgbàkúgbà.
Samej wody więcej nie pijaj, ale używaj po trosze wina dla żołądka twego i częstych chorób twoich.
24 Ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ẹlòmíràn a máa hàn gbangba, a máa lọ ṣáájú sí ìdájọ́; tí àwọn ẹlòmíràn pẹ̀lú a sì máa tẹ̀lé wọn.
Grzechy niektórych ludzi przedtem są jawne i uprzedzają na sąd, a za niektórymi idą pozad.
25 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ pẹ̀lú ni iṣẹ́ rere wa máa ń hàn gbangba; bí wọn kò tilẹ̀ tí ì hàn, wọn kò lè fi ara sin títí.
Także też dobre uczynki przedtem są jawne; ale które są insze, utaić się nie mogą.