< 1 Timothy 4 >

1 Nísinsin yìí, èmi ń tẹnumọ́ ọ́ pé ní ìgbà ìkẹyìn àwọn mìíràn yóò kúrò nínú ìgbàgbọ́, wọn yóò máa fiyèsí àwọn ẹ̀mí tí ń tannijẹ, àti ẹ̀kọ́ àwọn ẹ̀mí èṣù.
Dar Duhul spune în mod expres că, în vremurile de pe urmă, unii se vor depărta de la credință, ascultând de duhuri seducătoare și de învățături ale demonilor,
2 Nípa àgàbàgebè àwọn tí ń ṣèké, àwọn tí ọkàn tìkára wọn dàbí èyí tí a fi irin gbígbóná jó.
prin ipocrizia unor oameni care spun minciuni, care-și lovesc conștiința ca un fier încins,
3 Àwọn tí ń dánilẹ́kun láti gbéyàwó tiwọn si ń pàṣẹ láti ka èèwọ̀ oúnjẹ ti Ọlọ́run ti dá fún ìtẹ́wọ́gbà pẹ̀lú ọpẹ́ àwọn onígbàgbọ́ àti àwọn ti ó mọ òtítọ́.
care interzic căsătoria și poruncesc să se abțină de la mâncărurile pe care Dumnezeu le-a creat pentru a fi primite cu mulțumire de cei ce cred și cunosc adevărul.
4 Nítorí gbogbo ohun ti Ọlọ́run dá ni ó dára, kò sí ọkàn tí ó yẹ kí a kọ̀, bí a bá fi ọpẹ́ gbà á.
Căci orice făptură a lui Dumnezeu este bună și nimic nu este de lepădat, dacă este primit cu mulțumire.
5 Nítorí tí a fi ọ̀rọ̀ Ọlọ́run àti àdúrà yà sí mímọ́.
Căci este sfințită prin cuvântul lui Dumnezeu și prin rugăciune.
6 Bí ìwọ bá ń rán àwọn ará létí nǹkan wọ̀nyí, ìwọ ó jẹ́ ìránṣẹ́ rere ti Kristi Jesu, tí a fi ọ̀rọ̀ ìgbàgbọ́ àti ẹ̀kọ́ rere bọ́, èyí ti ìwọ ti ń tẹ̀lé.
Dacă vei învăța pe frați aceste lucruri, vei fi un bun slujitor al lui Hristos Isus, hrănit cu cuvintele credinței și cu buna învățătură pe care ai urmat-o.
7 Ṣùgbọ́n kọ ọ̀rọ̀ asán àti ìtàn àwọn àgbà obìnrin, sì máa tọ́ ara rẹ sí ìwà-bí-Ọlọ́run.
Dar refuzați fabulele profane și cele ale babelor. Exersează-te spre evlavie.
8 Nítorí ṣíṣe eré-ìdárayá ni èrè fún ohun díẹ̀, ṣùgbọ́n ìwà-bí-Ọlọ́run ni èrè fún ohun gbogbo, ó ní ìlérí ti ìgbé ayé ìsinsin yìí àti ti èyí tí ń bọ̀.
Căci exercițiul trupesc are o anumită valoare, dar evlavia are valoare în toate lucrurile, având făgăduința vieții de acum și a celei viitoare.
9 Òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ náà, ó sì yẹ fún ìtẹ́wọ́gbà gbogbo.
Acest cuvânt este credincios și vrednic de toată acceptarea.
10 Nítorí fún èyí ni àwa ń ṣe làálàá tí a sì ń jìjàkadì, nítorí àwa ní ìrètí nínú Ọlọ́run alààyè, ẹni tí í ṣe Olùgbàlà gbogbo ènìyàn, pẹ̀lúpẹ̀lú ti àwọn ti ó gbàgbọ́.
Căci în acest scop ne străduim și suferim ocara, pentru că ne-am pus încrederea în Dumnezeul cel viu, care este Mântuitorul tuturor oamenilor, mai ales al celor care cred.
11 Nǹkan wọ̀nyí ni kí ó máa paláṣẹ kí ó máa kọ́ni.
Poruncește și învață aceste lucruri.
12 Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni gan ìgbà èwe rẹ; ṣùgbọ́n kì ìwọ jẹ́ àpẹẹrẹ fún àwọn tí ó gbàgbọ́, nínú ọ̀rọ̀, nínú ìwà híhù, nínú ìfẹ́, nínú ẹ̀mí, nínú ìgbàgbọ́, nínú ìwà mímọ́.
Nimeni să nu disprețuiască tinerețea voastră, ci să fiți o pildă pentru cei credincioși, prin cuvânt, prin felul vostru de viață, prin dragoste, prin duh, prin credință și prin curăție.
13 Títí èmi ó fi dé, máa fiyèsí kíkàwé àti ìgbaniníyànjú àti ìkọ́ni.
Până voi veni eu, fiți atenți la citire, la îndemn și la învățătură.
14 Má ṣe àìnání ẹ̀bùn tí ń bẹ lára rẹ, èyí tí a fi fún ọ nípa ìsọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú ìgbọ́wọ́lé àwọn alàgbà.
Nu neglijați darul care este în voi, care v-a fost dat prin profeție, prin punerea mâinilor bătrânilor.
15 Máa fiyèsí nǹkan wọ̀nyí; fi ara rẹ fún wọn pátápátá; kí ìlọsíwájú rẹ lè hàn gbangba fún gbogbo ènìyàn.
Fiți sârguincioși în aceste lucruri. Dăruiește-te cu totul lor, pentru ca progresul tău să fie descoperit tuturor.
16 Máa ṣe ìtọ́jú ará rẹ àti ẹ̀kọ́ rẹ; máa dúró láìyẹsẹ̀ nínú nǹkan wọ̀nyí; nítorí ní ṣíṣe èyí, ìwọ ó gba ara rẹ àti tí àwọn ti ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ là.
Fiți atenți la voi înșivă și la învățătura voastră. Continuați în aceste lucruri, căci, făcând aceasta, vă veți salva atât pe voi înșivă, cât și pe cei care vă ascultă.

< 1 Timothy 4 >