< 1 Timothy 3 >
1 Òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ náà, bí ẹnìkan bá fẹ́ ipò alábojútó, iṣẹ́ rere ni ó ń fẹ́.
Wierna jest ta mowa: Jeźli kto biskupstwa żąda, dobrej pracy żąda.
2 Ǹjẹ́ alábojútó yẹ kí ó jẹ́ aláìlẹ́gàn, ọkọ aya kan, olùṣọ̀ràn, aláìrékọjá, oníwà rere, olùfẹ́ àlejò ṣíṣe, ẹni tí ó lè ṣe olùkọ́.
Ale biskup ma być nienaganiony, mąż jednej żony, czuły, trzeźwy, poważny, gościnny, ku nauczaniu sposobny;
3 Kí ó má jẹ́ ọ̀mùtí, tàbí oníjàgídíjàgan, tàbí olójúkòkòrò, bí kò ṣe onísùúrù, kí ó má jẹ́ oníjà, tàbí olùfẹ́ owó.
Nie pijanica wina, nie bitny, nie sprośnego zysku chciwy, ale słuszność miłujący, nieswarliwy, niełakomy;
4 Ẹni tí ó káwọ́ ilé ara rẹ̀ gírígírí, tí ó mú àwọn ọmọ rẹ̀ tẹríba pẹ̀lú ìwà àgbà gbogbo.
Który by dom swój dobrze rządził, który by dziatki miał w posłuszeństwie ze wszelaką uczciwością;
5 Ṣùgbọ́n bí ènìyàn kò bá mọ̀ bí a ti ń ṣe ìkáwọ́ ilé ara rẹ̀, òun ó ha ti ṣe lè tọ́jú ìjọ Ọlọ́run?
(Bo jeźliby kto nie umiał swego własnego domu rządzić, jakoż pieczę będzie miał o kościele Bożym?)
6 Kí ó má jẹ́ ẹni tuntun ti ó ṣẹ̀ṣẹ̀ gbàgbọ́, kí ó má ba à gbéraga, a sì ṣubú sínú ẹ̀bi èṣù.
Nie nowotny, aby będąc nadęty, nie wpadł w sąd potwarcy.
7 Ó sì yẹ kí ó ni ẹ̀rí rere pẹ̀lú lọ́dọ̀ àwọn tí ń bẹ lóde; kí ó má ba à bọ́ sínú ẹ̀gàn àti sínú ìdẹ̀kùn èṣù.
Musi też mieć świadectwo dobre od obcych, aby nie wpadł w hańbę i w sidło potwarcy.
8 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ó yẹ fún àwọn Díákónì láti ní ìwà àgbà, kí wọ́n máa jẹ́ ẹlẹ́nu méjì, kí wọ́n máa fi ara wọn fún wáìnì púpọ̀, kí wọ́n má jẹ́ olójúkòkòrò.
Dyjakonowie także mają być poważni, nie dwoistego słowa, nie pijanicy wielu wina, nie chciwi sprośnego zysku,
9 Kí wọn máa di ohun ìjìnlẹ̀ ìgbàgbọ́ mú pẹ̀lú ọkàn funfun.
Mający tajemnicę wiary w czystem sumieniu.
10 Kí a kọ́kọ́ wádìí àwọn wọ̀nyí dájú pẹ̀lú; nígbà náà ni kí a jẹ́ kí wọn ó ṣiṣẹ́ díákónì, bí wọn bá jẹ́ aláìlẹ́gàn.
A ci też niech będą pierwej doświadczeni, zatem niech służą, jeźli są bez nagany;
11 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ó yẹ fún àwọn obìnrin láti ni ìwà àgbà, kí wọn má jẹ́ asọ̀rọ̀ ẹni lẹ́yìn bí kò ṣe aláìrékọjá, olóòtítọ́ ní ohun gbogbo.
Żony także niech mają poważne, nie potwarliwe, trzeźwe, wierne we wszystkiem.
12 Kí àwọn díákónì jẹ́ ọkọ obìnrin kan, kí wọn káwọ́ àwọn ọmọ àti ilé ara wọn dáradára.
Dyjakonowie niech będą mężami jednej żony, którzy by dziatki dobrze rządzili i własne domy.
13 Nítorí àwọn tí ó lo ipò díákónì dáradára ra ipò rere fún ara wọn, àti ìgboyà púpọ̀ nínú ìgbàgbọ́ tí ń bẹ nínú Kristi Jesu.
Albowiem którzy by dobrze służyli, stopień sobie dobry zjednają i wielkie bezpieczeństwo w wierze, która jest w Chrystusie Jezusie.
14 Ìwé nǹkan wọ̀nyí ni mo kọ sí ọ, mo sì ń retí àti tọ̀ ọ́ wá ní lọ́ọ́lọ́ọ́.
Toć tobie piszę, mając nadzieję, że w rychle przyjdę do ciebie;
15 Ṣùgbọ́n bí mo bá pẹ́, kí ìwọ lè mọ̀ bí ó ti yẹ fún àwọn ènìyàn láti máa hùwà nínú ilé Ọlọ́run, tì í ṣe ìjọ Ọlọ́run alààyè, ọ̀wọ́n àti ìpìlẹ̀ òtítọ́.
A jeźlibym omieszkał, abyś wiedział, jako się masz w domu Bożym sprawować, który jest kościołem Boga żywego, filarem i utwierdzeniem prawdy.
16 Láìṣiyèméjì, títóbi ní ohun ìjìnlẹ̀ ìwà-bí-Ọlọ́run: ẹni tí a fihàn nínú ara, tí a dá láre nínú Ẹ̀mí, ti àwọn angẹli rí, tí a wàásù rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, tí a gbàgbọ́ nínú ayé, tí a sì gbà sókè sínú ògo.
A zaprawdę wielka jest tajemnica pobożności, że Bóg objawiony jest w ciele, usprawiedliwiony jest w duchu, widziany jest od Aniołów, kazany jest poganom, uwierzono mu na świecie, wzięty jest w górę do chwały.