< 1 Timothy 2 >
1 Nítorí náà mo gbà yín níyànjú ṣáájú ohun gbogbo, pé kí a máa bẹ̀bẹ̀, kí a máa gbàdúrà, kí a máa ṣìpẹ̀, àti kí a máa dúpẹ́ nítorí gbogbo ènìyàn.
Mǝn ⱨǝmmidin awwal, [etiⱪadqilarƣa] pütkül insanlar üqün Hudadin tilǝklǝr tilixini, dua-tilawǝt ⱪilixini, baxⱪilar üqün murajiǝt ⱪilixini wǝ tǝxǝkkürlǝr eytixini,
2 Fún àwọn ọba, àti gbogbo àwọn tí ó wà ni ipò àṣẹ, kí a lè máa lo ayé wa ní àlàáfíà àti ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ pẹ̀lú nínú gbogbo ìwà-bí-Ọlọ́run àti ìwà mímọ́.
bolupmu padixaⱨlar wǝ barliⱪ ǝmǝldarlar üqün dua-tilawǝt ⱪilixini jekilǝymǝn. Xundaⱪ ⱪilƣanda, biz toluⱪ ihlasmǝnlik wǝ salmaⱪliⱪ bilǝn tinq wǝ aman-esǝn ⱨayat kǝqürǝlǝymiz.
3 Nítorí èyí dára, ó sì ṣe ìtẹ́wọ́gbà níwájú Ọlọ́run Olùgbàlà wa;
Bundaⱪ dua-tilawǝt ⱪilix güzǝl ixtur, Ⱪutⱪuzƣuqimiz Hudani hursǝn ⱪilidu.
4 ẹni tí ó fẹ́ kí gbogbo ènìyàn ní ìgbàlà kí wọ́n sì wá sínú ìmọ̀ òtítọ́.
Qünki U pütkül insanning ⱪutⱪuzuluxi wǝ ularning ⱨǝⱪiⱪǝtni tonup yetixini halaydu.
5 Nítorí Ọlọ́run kan ní ń bẹ, onílàjà kan pẹ̀lú láàrín Ọlọ́run àti ènìyàn, àní Kristi Jesu ọkùnrin náà.
Qünki birla Huda bardur, Huda bilǝn insanlar arisida bir kelixtürgüqimu bar, U bolsimu Ɵzi insan bolup kǝlgǝn Mǝsiⱨ Əysadur.
6 Ẹni ti ó fi ara rẹ̀ ṣe ìràpadà fún gbogbo ènìyàn—ẹ̀rí tí a fi fún ni ní àkókò tó yẹ.
U barliⱪ insanlarni ⱨɵr ⱪilix üqün Ɵzini ⱪurban ⱪilip bǝdǝl tɵlidi; xundaⱪ ⱪilip bekitilgǝn waⱪit-saitidǝ Hudaning nijatiƣa guwaⱨliⱪ berildi.
7 Nítorí èyí tí a yàn mi ṣe oníwàásù, aposteli òtítọ́ ni èmi ń sọ, èmi kò ṣèké olùkọ́ àwọn aláìkọlà nínú ìgbàgbọ́ àti òtítọ́.
Mǝn bu guwaⱨliⱪni yǝtküzüx üqün jakarqi wǝ rosul boluxⱪa tǝyinlinip (mening bu sɵzlirimning ⱨǝmmisi rast, mǝn yalƣan gǝp ⱪilmidim), yat ǝlliklǝrgǝ etiⱪad wǝ ⱨǝⱪiⱪǝt yolida ɵgǝtküqi bolup tiklǝndim.
8 Mo fẹ́ kí àwọn ọkùnrin máa gbàdúrà níbi gbogbo, kí wọ́n máa gbé ọwọ́ mímọ́ sókè, ní àìbínú àti àìjiyàn.
Xunga, mǝn xuni halaymǝnki, ǝrlǝr ⱪǝyǝrdǝ bolsun, duaƣa jǝm bolƣanda ƣǝzǝpsiz wǝ dǝtalaxsiz ⱨalda, ⱨalal ǝmǝllik ⱪollirini kɵtürüp dua ⱪilsun.
9 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni kí àwọn obìnrin fi aṣọ ìwọ̀ntúnwọ̀nsì ṣe ara wọn ní ọ̀ṣọ́, ní ìwọ̀ntúnwọ̀nsì àti pẹ̀lú ìwà àìrékọjá; kì í ṣe pẹ̀lú irun dídì, tàbí wúrà, tàbí peali, tàbí aṣọ olówó iyebíye,
Ohxax yolda ayallarmu muwapiⱪ kiyinip, ɵzlirini ar-nomus wǝ salmaⱪliⱪ bilǝn pǝrdaz ⱪilsun. Ularning ɵzlirini pǝrdazlax, qaqlirini alaⱨidǝ yasax wǝ altun, ünqǝ-mǝrwayit wǝ esil ⱪimmǝt kiyim-keqǝklǝr bilǝn ǝmǝs,
10 bí kò ṣe pẹ̀lú iṣẹ́ rere, èyí tí ó yẹ fún àwọn obìnrin tó jẹ́wọ́ pé wọ́n sin Ọlọ́run.
bǝlki güzǝl ǝmǝlliri bilǝn pǝrdazlixini halaymǝn. Bu, Huda yolida tǝⱪwadar bolay degǝn ayallarƣa yarixidu.
11 Jẹ́ kí obìnrin máa fi ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìtẹríba gbogbo kọ́ ẹ̀kọ́.
[Jamaǝt sorunlirida], ayallar tinq olturup, toluⱪ itaǝtmǝnlik bilǝn tǝlim alsun.
12 Ṣùgbọ́n èmi kò fi àṣẹ fún obìnrin láti máa kọ́ni, tàbí láti pàṣẹ lórí ọkùnrin, bí kò ṣe kí ó dákẹ́ jẹ́ẹ́.
Lekin ayallarning ǝrlǝrgǝ tǝlim berixi yaki ular üstidin ⱨɵküm sürüxigǝ yol ⱪoymaymǝn. Əksiqǝ, ular tinq bolsun.
13 Nítorí Adamu ni a kọ́ dá, lẹ́yìn náà, Efa.
Qünki awwal Adǝm’ata, keyin Ⱨawa’ana yaritilƣan.
14 Adamu kọ́ ni a tànjẹ, ṣùgbọ́n obìnrin náà ni a tàn tí ó sì di ẹlẹ́ṣẹ̀.
Awwal aldinip azdurulƣanmu Adǝm’ata ǝmǝs, bǝlki [Ⱨawa’ana] idi. U tolimu aldanƣanliⱪidin ularning itaǝtsizlikigǝ qüxüp ⱪalƣanidi.
15 Ṣùgbọ́n a ó gbà àwọn obìnrin là nípa ìbímọ wọn, bí wọ́n bá dúró nínú ìgbàgbọ́, ìfẹ́, àti ìwà mímọ́ pẹ̀lú ìwà àìrékọjá.
Lekin ayallar etiⱪadta, meⱨir-muⱨǝbbǝt wǝ pak-muⱪǝddǝsliktǝ salmaⱪliⱪ bilǝn turidiƣanla bolsa, ular tuƣutta saⱪ-salamǝt ⱪutulidu.