< 1 Timothy 2 >

1 Nítorí náà mo gbà yín níyànjú ṣáájú ohun gbogbo, pé kí a máa bẹ̀bẹ̀, kí a máa gbàdúrà, kí a máa ṣìpẹ̀, àti kí a máa dúpẹ́ nítorí gbogbo ènìyàn.
De aceea [vă] îndemn ca, înainte de toate, să se facă cereri, rugăciuni, mijlociri și mulțumiri pentru toți oamenii;
2 Fún àwọn ọba, àti gbogbo àwọn tí ó wà ni ipò àṣẹ, kí a lè máa lo ayé wa ní àlàáfíà àti ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ pẹ̀lú nínú gbogbo ìwà-bí-Ọlọ́run àti ìwà mímọ́.
Pentru împărați și pentru toți cei ce sunt în autoritate; ca să putem duce o viață liniștită și pașnică în toată evlavia și onestitatea.
3 Nítorí èyí dára, ó sì ṣe ìtẹ́wọ́gbà níwájú Ọlọ́run Olùgbàlà wa;
Fiindcă acest [lucru] este bun și bine primit înaintea lui Dumnezeu, Salvatorul nostru;
4 ẹni tí ó fẹ́ kí gbogbo ènìyàn ní ìgbàlà kí wọ́n sì wá sínú ìmọ̀ òtítọ́.
Care dorește ca toți oamenii să fie salvați și să vină la cunoașterea adevărului.
5 Nítorí Ọlọ́run kan ní ń bẹ, onílàjà kan pẹ̀lú láàrín Ọlọ́run àti ènìyàn, àní Kristi Jesu ọkùnrin náà.
Fiindcă este un singur Dumnezeu și un singur mijlocitor între Dumnezeu și oameni, omul Cristos Isus,
6 Ẹni ti ó fi ara rẹ̀ ṣe ìràpadà fún gbogbo ènìyàn—ẹ̀rí tí a fi fún ni ní àkókò tó yẹ.
Care s-a dat pe sine însuși răscumpărare pentru toți, ca să fie mărturisit la timpul cuvenit.
7 Nítorí èyí tí a yàn mi ṣe oníwàásù, aposteli òtítọ́ ni èmi ń sọ, èmi kò ṣèké olùkọ́ àwọn aláìkọlà nínú ìgbàgbọ́ àti òtítọ́.
Pentru care eu sunt rânduit predicator și apostol (spun adevărul în Cristos, nu mint), învățător al neamurilor în credință și adevăr.
8 Mo fẹ́ kí àwọn ọkùnrin máa gbàdúrà níbi gbogbo, kí wọ́n máa gbé ọwọ́ mímọ́ sókè, ní àìbínú àti àìjiyàn.
De aceea doresc ca bărbații să se roage în tot locul, ridicând mâini sfinte, fără furie și fără îndoială.
9 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni kí àwọn obìnrin fi aṣọ ìwọ̀ntúnwọ̀nsì ṣe ara wọn ní ọ̀ṣọ́, ní ìwọ̀ntúnwọ̀nsì àti pẹ̀lú ìwà àìrékọjá; kì í ṣe pẹ̀lú irun dídì, tàbí wúrà, tàbí peali, tàbí aṣọ olówó iyebíye,
Și în același fel, rânduiesc ca femeile să se înfrumusețeze ordonat, în haine decente, cu sfială și sobrietate, nu cu păr împletit, sau cu aur sau cu perle sau cu haine scumpe,
10 bí kò ṣe pẹ̀lú iṣẹ́ rere, èyí tí ó yẹ fún àwọn obìnrin tó jẹ́wọ́ pé wọ́n sin Ọlọ́run.
Ci cu fapte bune (ceea ce se cuvine femeilor care susțin că sunt evlavioase).
11 Jẹ́ kí obìnrin máa fi ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìtẹríba gbogbo kọ́ ẹ̀kọ́.
Femeia să învețe în tăcere, cu toată supunerea.
12 Ṣùgbọ́n èmi kò fi àṣẹ fún obìnrin láti máa kọ́ni, tàbí láti pàṣẹ lórí ọkùnrin, bí kò ṣe kí ó dákẹ́ jẹ́ẹ́.
Dar nu permit femeii să învețe pe altul, nici să exercite autoritate asupra bărbatului, ci să stea în tăcere.
13 Nítorí Adamu ni a kọ́ dá, lẹ́yìn náà, Efa.
Fiindcă întâi a fost format Adam, apoi Eva.
14 Adamu kọ́ ni a tànjẹ, ṣùgbọ́n obìnrin náà ni a tàn tí ó sì di ẹlẹ́ṣẹ̀.
Și nu Adam a fost înșelat; ci femeia, fiind înșelată, a ajuns la încălcarea poruncii.
15 Ṣùgbọ́n a ó gbà àwọn obìnrin là nípa ìbímọ wọn, bí wọ́n bá dúró nínú ìgbàgbọ́, ìfẹ́, àti ìwà mímọ́ pẹ̀lú ìwà àìrékọjá.
Totuși ea va fi salvată prin nașterea de copii, dacă vor stărui în credință și dragoste creștină și sfințenie cu sobrietate.

< 1 Timothy 2 >