< 1 Timothy 2 >
1 Nítorí náà mo gbà yín níyànjú ṣáájú ohun gbogbo, pé kí a máa bẹ̀bẹ̀, kí a máa gbàdúrà, kí a máa ṣìpẹ̀, àti kí a máa dúpẹ́ nítorí gbogbo ènìyàn.
Je recommande donc, avant toutes choses, qu'on fasse des requêtes, des prières, des supplications, des actions de grâces pour tous les hommes,
2 Fún àwọn ọba, àti gbogbo àwọn tí ó wà ni ipò àṣẹ, kí a lè máa lo ayé wa ní àlàáfíà àti ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ pẹ̀lú nínú gbogbo ìwà-bí-Ọlọ́run àti ìwà mímọ́.
pour les rois et pour tous ceux qui sont élevés en dignité, afin que nous passions une vie paisible et tranquille en toute piété et en toute honnêteté:
3 Nítorí èyí dára, ó sì ṣe ìtẹ́wọ́gbà níwájú Ọlọ́run Olùgbàlà wa;
cela est bon et agréable à Dieu, notre Sauveur,
4 ẹni tí ó fẹ́ kí gbogbo ènìyàn ní ìgbàlà kí wọ́n sì wá sínú ìmọ̀ òtítọ́.
qui veut que tous les hommes soient sauvés, et parviennent à la connaissance de la vérité.
5 Nítorí Ọlọ́run kan ní ń bẹ, onílàjà kan pẹ̀lú láàrín Ọlọ́run àti ènìyàn, àní Kristi Jesu ọkùnrin náà.
Car il n'y a qu'un seul Dieu; il n'y a aussi qu'un seul médiateur entre Dieu et les hommes, savoir un homme, Jésus-Christ,
6 Ẹni ti ó fi ara rẹ̀ ṣe ìràpadà fún gbogbo ènìyàn—ẹ̀rí tí a fi fún ni ní àkókò tó yẹ.
qui s'est donné lui-même en rançon pour tous, fait attesté en son temps.
7 Nítorí èyí tí a yàn mi ṣe oníwàásù, aposteli òtítọ́ ni èmi ń sọ, èmi kò ṣèké olùkọ́ àwọn aláìkọlà nínú ìgbàgbọ́ àti òtítọ́.
C'est afin d'en témoigner que j'ai été établi prédicateur, apôtre (je dis la vérité, je ne mens point) et docteur des Gentils pour ce qui a trait à la foi et à la vérité.
8 Mo fẹ́ kí àwọn ọkùnrin máa gbàdúrà níbi gbogbo, kí wọ́n máa gbé ọwọ́ mímọ́ sókè, ní àìbínú àti àìjiyàn.
Je veux donc que les hommes prient en tout lieu, levant au ciel des mains pures, et n'ayant ni colère, ni arrière-pensée.
9 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni kí àwọn obìnrin fi aṣọ ìwọ̀ntúnwọ̀nsì ṣe ara wọn ní ọ̀ṣọ́, ní ìwọ̀ntúnwọ̀nsì àti pẹ̀lú ìwà àìrékọjá; kì í ṣe pẹ̀lú irun dídì, tàbí wúrà, tàbí peali, tàbí aṣọ olówó iyebíye,
Je veux pareillement, que les femmes soient vêtues d'une manière convenable, avec pudeur et modestie; qu'elles se parent, non de tresses et de bijoux, de perles ou d'habits somptueux,
10 bí kò ṣe pẹ̀lú iṣẹ́ rere, èyí tí ó yẹ fún àwọn obìnrin tó jẹ́wọ́ pé wọ́n sin Ọlọ́run.
mais de bonnes oeuvres, comme il sied à des femmes qui font profession de piété.
11 Jẹ́ kí obìnrin máa fi ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìtẹríba gbogbo kọ́ ẹ̀kọ́.
Que la femme écoute l'instruction en silence, avec une parfaite soumission.
12 Ṣùgbọ́n èmi kò fi àṣẹ fún obìnrin láti máa kọ́ni, tàbí láti pàṣẹ lórí ọkùnrin, bí kò ṣe kí ó dákẹ́ jẹ́ẹ́.
Je ne permets pas à la femme d'enseigner, ni même de prendre aucune autorité sur l'homme, mais je veux qu'elle se tienne dans le silence;
13 Nítorí Adamu ni a kọ́ dá, lẹ́yìn náà, Efa.
car Adam a été formé le premier, Eve ensuite,
14 Adamu kọ́ ni a tànjẹ, ṣùgbọ́n obìnrin náà ni a tàn tí ó sì di ẹlẹ́ṣẹ̀.
et ce n'est pas Adam qui a été séduit, mais la femme s'étant laissé séduire, s'est rendue coupable de transgression.
15 Ṣùgbọ́n a ó gbà àwọn obìnrin là nípa ìbímọ wọn, bí wọ́n bá dúró nínú ìgbàgbọ́, ìfẹ́, àti ìwà mímọ́ pẹ̀lú ìwà àìrékọjá.
Néanmoins, la femme sera sauvée en devenant mère, pourvu qu'elle demeure dans la foi, dans la charité et dans la sainteté unies à la modestie.