< 1 Timothy 2 >
1 Nítorí náà mo gbà yín níyànjú ṣáájú ohun gbogbo, pé kí a máa bẹ̀bẹ̀, kí a máa gbàdúrà, kí a máa ṣìpẹ̀, àti kí a máa dúpẹ́ nítorí gbogbo ènìyàn.
ⲁ̅ϯϯϩⲟ ⲟⲩⲛ ⳿ⲛϣⲟⲣⲡ ⳿ⲛϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲉ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲛϩⲁⲛⲧⲱⲃϩ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛ⳿ⲡⲣⲟⲥⲉⲩⲭⲏ ϩⲁⲛⲥⲉⲙⲓ ϩⲁⲛϣⲉⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲣⲱⲙⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ.
2 Fún àwọn ọba, àti gbogbo àwọn tí ó wà ni ipò àṣẹ, kí a lè máa lo ayé wa ní àlàáfíà àti ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ pẹ̀lú nínú gbogbo ìwà-bí-Ọlọ́run àti ìwà mímọ́.
ⲃ̅⳿ⲉϫⲉⲛ ⲛⲓⲟⲩⲣⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧϭⲟⲥⲓ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲟⲩϣⲱⲡⲓ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲱⲛϧ ⲉϥϩⲟⲩⲣⲱⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲣⲉⲙⲣⲁⲩϣ ϧⲉⲛ ⲙⲉⲧⲉⲩⲥⲉⲃⲏⲥ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲛⲉⲙ ⲙⲉⲧⲥⲉⲙⲛⲟⲥ ⲛⲓⲃⲉⲛ.
3 Nítorí èyí dára, ó sì ṣe ìtẹ́wọ́gbà níwájú Ọlọ́run Olùgbàlà wa;
ⲅ̅ⲫⲁⲓ ⲛⲁⲛⲉϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ϥϣⲏⲡ ⳿ⲙⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲙⲫϯ ⲡⲉⲛⲥⲱⲧⲏⲣ.
4 ẹni tí ó fẹ́ kí gbogbo ènìyàn ní ìgbàlà kí wọ́n sì wá sínú ìmọ̀ òtítọ́.
ⲇ̅ⲫⲁⲓ ⲉⲑⲟⲩⲱϣ ⳿ⲛⲧⲉ ⲣⲱⲙⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲛⲟϩⲉⲙ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲥⲉ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ⲡⲥⲟⲩⲉⲛ ϯⲙⲉⲑⲙⲏⲓ.
5 Nítorí Ọlọ́run kan ní ń bẹ, onílàjà kan pẹ̀lú láàrín Ọlọ́run àti ènìyàn, àní Kristi Jesu ọkùnrin náà.
ⲉ̅ⲟⲩⲁⲓ ⲅⲁⲣ ⲡⲉ ⲫϯ ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩⲁⲓ ⲡⲉ ⲡⲓⲙⲉⲥⲓⲧⲏⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲟⲩⲣⲱⲙⲓ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ Ⲓⲏ̅ⲥ̅.
6 Ẹni ti ó fi ara rẹ̀ ṣe ìràpadà fún gbogbo ènìyàn—ẹ̀rí tí a fi fún ni ní àkókò tó yẹ.
ⲋ̅ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲁϥⲧⲏⲓϥ ⳿ⲛⲥⲱϯ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲡⲓⲙⲉⲑⲣⲉ ϧⲉⲛ ⲡⲉϥⲥⲏⲟⲩ.
7 Nítorí èyí tí a yàn mi ṣe oníwàásù, aposteli òtítọ́ ni èmi ń sọ, èmi kò ṣèké olùkọ́ àwọn aláìkọlà nínú ìgbàgbọ́ àti òtítọ́.
ⲍ̅ⲫⲁⲓ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲉⲧⲁⲩⲭⲁⲧ ⲛⲁϥ ⳿ⲛⲣⲉϥϩⲓⲱⲓϣ ⲛⲉⲙ ⲁⲡⲟⲥⲧⲟⲗⲟⲥ ⳿ⲑⲙⲏⲓ ⲡⲉϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⳿ⲛϯ ϫⲉⲙⲉⲑⲛⲟⲩϫ ⲁⲛ ⳿ⲫⲣⲉϥϯ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲛⲧⲉ ϩⲁⲛⲉⲑⲛⲟⲥ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲛⲁϩϯ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲙⲉⲑⲙⲏⲓ.
8 Mo fẹ́ kí àwọn ọkùnrin máa gbàdúrà níbi gbogbo, kí wọ́n máa gbé ọwọ́ mímọ́ sókè, ní àìbínú àti àìjiyàn.
ⲏ̅ϯⲟⲩⲱϣ ⲟⲩⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲣⲱⲙⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲧⲱⲃϩ ϧⲉⲛ ⲙⲁⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲩϥⲁⲓ ⳿ⲛϩⲁⲛϫⲓϫ ⳿ⲉ⳿ⲡϣⲱⲓ ⲉⲩⲟⲩⲁⲃ ⲭⲱⲣⲓⲥ ϫⲱⲛⲧ ⲛⲉⲙ ⲙⲟⲕⲙⲉⲕ.
9 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni kí àwọn obìnrin fi aṣọ ìwọ̀ntúnwọ̀nsì ṣe ara wọn ní ọ̀ṣọ́, ní ìwọ̀ntúnwọ̀nsì àti pẹ̀lú ìwà àìrékọjá; kì í ṣe pẹ̀lú irun dídì, tàbí wúrà, tàbí peali, tàbí aṣọ olówó iyebíye,
ⲑ̅ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲟⲛ ⲛⲓϩⲓ⳿ⲟⲙⲓ ⲉⲩϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲉⲧⲥⲁⲓ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⲉⲥⲟⲣϥ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲙⲉⲧ⳿ϫⲫⲓⲏϯ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲥⲁⲃⲉ ⲉⲩⲥⲟⲗⲥⲉⲗ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛϩⲱⲗⲕ ⲁⲛ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛⲛⲟⲩⲃ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛⲁⲛⲁⲙⲏⲓ ⲓⲉ ϧⲉⲛ ⲟⲩϭⲓ⳿ϩⲃⲱⲥ ⳿ⲉⲛⲁϣⲉⲛⲥⲟⲩⲉⲛϥ.
10 bí kò ṣe pẹ̀lú iṣẹ́ rere, èyí tí ó yẹ fún àwọn obìnrin tó jẹ́wọ́ pé wọ́n sin Ọlọ́run.
ⲓ̅ⲁⲗⲗⲁ ⲡⲉⲧ⳿ϩⲣⲁⲩ ⳿ⲛⲛⲓϩⲓ⳿ⲟⲙⲓ ϭⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲉⲩⲱϣ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲉⲧⲑⲉⲟⲥⲉⲃⲏⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛ⳿ϩⲃⲏⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲛⲁⲛⲉⲩ.
11 Jẹ́ kí obìnrin máa fi ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìtẹríba gbogbo kọ́ ẹ̀kọ́.
ⲓ̅ⲁ̅ⲟⲩ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲙⲁⲣⲉⲥϭⲓ⳿ⲥⲃⲱ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲉⲧⲣⲉⲙⲣⲁⲩϣ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ϧⲉⲛ ϭⲛⲉϫⲱϥ ⲛⲓⲃⲉⲛ.
12 Ṣùgbọ́n èmi kò fi àṣẹ fún obìnrin láti máa kọ́ni, tàbí láti pàṣẹ lórí ọkùnrin, bí kò ṣe kí ó dákẹ́ jẹ́ẹ́.
ⲓ̅ⲃ̅ϯⲟⲩⲁϩⲥⲁϩⲛⲓ ⲇⲉ ⲁⲛ ⳿ⲛ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⳿ⲉϯ⳿ⲥⲃⲱ ⲟⲩⲇⲉ ⲉⲑⲣⲉⲥⲉⲣϫⲱϫ ⳿ⲉⲡⲉⲥϩⲁⲓ ⲁⲗⲗⲁ ⲙⲁⲣⲉⲥ ϭⲓ⳿ⲥⲃⲱ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲉⲧⲣⲉⲙⲣⲁⲩϣ.
13 Nítorí Adamu ni a kọ́ dá, lẹ́yìn náà, Efa.
ⲓ̅ⲅ̅ⲁⲇⲁⲙ ⲅⲁⲣ ⲁⲩⲉⲣ⳿ⲡⲗⲁⲍⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲛϣⲟⲣⲡ ⳿ⲓⲧⲁ ⲉⲩ⳿ⲁ.
14 Adamu kọ́ ni a tànjẹ, ṣùgbọ́n obìnrin náà ni a tàn tí ó sì di ẹlẹ́ṣẹ̀.
ⲓ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲇⲁⲙ ⳿ⲙⲡⲟⲩ⳿ϣⲉⲣϩⲁⲗ ⳿ⲙⲙⲟϥ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲇⲉ ⳿ⲛⲑⲟⲥ ⲉⲧⲁⲩⲉⲣϩⲁⲗ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲁⲥϣⲱⲡⲓ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲡⲁⲣⲁⲃⲁⲥⲓⲥ.
15 Ṣùgbọ́n a ó gbà àwọn obìnrin là nípa ìbímọ wọn, bí wọ́n bá dúró nínú ìgbàgbọ́, ìfẹ́, àti ìwà mímọ́ pẹ̀lú ìwà àìrékọjá.
ⲓ̅ⲉ̅ⲉⲥ⳿ⲉⲛⲟϩⲉⲙ ⲇⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲧⲉⲥⲙⲉⲧⲣⲉϥ⳿ϫⲫⲉ ϣⲏⲣⲓ ⲉϣⲱⲡ ⲁⲩϣⲁⲛⲟϩⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲛⲁϩϯ ⲛⲉⲙ ϯⲁⲅⲁⲡⲏ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲧⲟⲩⲃⲟ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲉⲧⲥⲁⲃⲉ