< 1 Thessalonians 5 >

1 Nísinsin yìí, ará, a kò nílò láti kọ ìwé sí i yín mọ́ nípa àkókò àti ìgbà,
Pero sobre los tiempos y su orden, mis hermanos, no hay necesidad de que les diga nada.
2 nítorí ẹ̀yin pàápàá mọ̀ wí pé ọjọ́ Olúwa yóò wá bí olè lóru.
Porque ustedes saben que el día del Señor vendrá como ladrón en la noche.
3 Ní àkókò gan an tí àwọn ènìyàn yóò máa wí pé, “Àlàáfíà àti ààbò,” nígbà náà ni ìparun òjijì yóò dé sórí wọn gẹ́gẹ́ bí ìrọbí obìnrin tí ó lóyún, wọn kò sí ni rí ibi ààbò láti sá sí.
Cuando dicen: Hay paz y no peligro, vendrá sobre ellos destrucción repentina, como dolores de parto en una mujer encinta; y no podrán escapar de eso.
4 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ará, kò sí nínú òkùnkùn nípa nǹkan wọ̀nyí tí ọjọ́ Olúwa yóò fi dé bá yín bí olè.
Pero ustedes, mis hermanos, no están a oscuras, para que ese día los alcance como a un ladrón.
5 Nítorí gbogbo yín ni ọmọ ìmọ́lẹ̀ àti ọmọ ọ̀sán gangan. Ẹ kì í ṣe tí òru tàbí tí òkùnkùn mọ́.
Porque todos ustedes son hijos de la luz y del día; no somos de la noche ni de la oscuridad.
6 Nítorí náà, ẹ kíyèsára yín kí ẹ má ṣe sùn bí àwọn ẹlòmíràn. Ẹ máa ṣọ́nà kí ẹ sì máa pa ara yín mọ́.
Entonces, no descansemos como lo hacen los demás, pero seamos alertas y sobrios.
7 Nítorí àwọn tí wọ́n ń sùn, a máa sùn ní òru, àwọn ẹni tí ń mu àmupara, a máa mú un ní òru.
Porque los que duermen lo hacen en la noche; y los que se emborrachan, se emborrachan de noche;
8 Ṣùgbọ́n àwa jẹ́ ti ìmọ́lẹ̀, ẹ jẹ́ kí a pa ara wa mọ́, ní gbígbé ìgbàgbọ́ wọ̀ àti ìfẹ́ bí ìgbàyà ni òru àti ìrètí ìgbàlà bí àṣíborí.
Pero nosotros, que somos del día, seamos serios, poniéndonos la coraza de la fe y el amor, y sobre nuestras cabezas, como un casco la esperanza de la salvación.
9 Nítorí pé, Ọlọ́run kò yàn wa láti da ìbínú rẹ̀ gbígbóná sí orí wa, ṣùgbọ́n ó yàn láti gbà wá là nípasẹ̀ Olúwa wa, Jesu Kristi.
Porque el propósito de Dios para nosotros no es la ira, sino la salvación por medio de nuestro Señor Jesucristo,
10 Jesu kú fún wa kí a lè ba à gbé títí láéláé. Èyí yóò rí bẹ́ẹ̀ yálà a sùn tàbí a wà láààyè pẹ̀lú rẹ̀.
Quien murió por nosotros, para que, despierto o durmiendo, tengamos parte en su vida.
11 Nítorí náà, ẹ máa gba ara yín níyànjú, kí ẹ sì máa gbé ara yín ró, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ń ṣe.
Entonces, continúen consolando y edificándose unos a otros, como lo han estado haciendo.
12 Ẹ̀yin ará, ẹ fi ọlá fún àwọn olórí tí ń ṣe iṣẹ́ àṣekára láàrín yín tí wọn ń kìlọ̀ fún yín nínú Olúwa.
Pero les pedimos esto, hermanos míos: respeten y valoren a los que trabajan entre ustedes, que están sobre ustedes en el Señor para mantener el orden entre ustedes;
13 Ẹ bu ọlá fún wọn gidigidi nínú ìfẹ́, nítorí iṣẹ́ wọn. Ẹ sì máa wà ní àlàáfíà láàrín ara yín.
Y tengan una alta opinión y amor a causa de su trabajo. Estén en paz entre ustedes mismos,
14 Ẹ̀yin ará mi, ẹ kìlọ̀ fún àwọn ọ̀lẹ ti ó wà láàrín yín, ẹ gba àwọn tí ẹ̀rù ń bà ní ìyànjú, ẹ tọ́jú àwọn aláìlera pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́, kí ẹ sì ní sùúrù pẹ̀lú gbogbo ènìyàn.
Y nuestro deseo es que mantengan el control sobre aquellos cuyas vidas no están bien ordenadas, dando consuelo a los débiles de corazón, apoyando a aquellos con poca fuerza y Sean pacientes con todos.
15 Ẹ rí i pé kò sí ẹni tí ó fi búburú san búburú, ṣùgbọ́n ẹ máa lépa èyí tí í ṣe rere láàrín ara yín àti sí ènìyàn gbogbo.
Que nadie dé mal por mal; pero siempre vean lo que es bueno, el uno para el otro y para todos.
16 Ẹ máa yọ̀ nígbà gbogbo.
Tener alegría en todo momento.
17 Ẹ máa gbàdúrà nígbà gbogbo.
Oren sin cesar.
18 Ẹ máa dúpẹ́ nígbà gbogbo nínú ipòkípò tí o wù kí ẹ wà; nítorí pé, èyí ni ìfẹ́ Ọlọ́run fún yin nínú Kristi Jesu nítòótọ́.
En todo da gloria, porque este es el propósito de Dios en Cristo Jesús para ustedes.
19 Ẹ má ṣe pa iná Ẹ̀mí Mímọ́.
No apagues el fuego del Espíritu;
20 Ẹ má ṣe kẹ́gàn àwọn ti ń sọtẹ́lẹ̀.
No menosprecies las profecías;
21 Ṣùgbọ́n ẹ dán gbogbo nǹkan wò. Ẹ di èyí tí ṣe òtítọ́ mú.
Someterlo todo a prueba; mantener lo que es bueno;
22 Ẹ yẹra fún ohunkóhun tí í ṣe ibi.
Absténganse de toda apariencia de maldad.
23 Kí Ọlọ́run fúnra rẹ̀, Ọlọ́run àlàáfíà, sọ yín di mímọ́ pátápátá. Kí Ọlọ́run pa ẹ̀mí àti ọkàn pẹ̀lú ara yín mọ́ pátápátá ní àìlábùkù, títí di ìgbà wíwá Jesu Kristi Olúwa wa.
Y que el Dios de la paz los santifique a todos; y que su espíritu y alma y cuerpo sean libres de todo pecado en la venida de nuestro Señor Jesucristo.
24 Olóòtítọ́ ni ẹni tí ó pè yín, yóò sì ṣe.
Él que los ha llamado es fiel, es fiel y cumplirá todo esto.
25 Ẹ̀yin ará, ẹ gbàdúrà fún wa.
Hermanos, oren por nosotros.
26 Ẹ fi ìfẹ́nukonu mímọ́ ki ara yin.
Dale a todos los hermanos un beso santo.
27 Mo pàṣẹ fún yín níwájú Olúwa pé, kí ẹ ka lẹ́tà yìí fún gbogbo àwọn ará.
Doy órdenes en el nombre del Señor de que todos los hermanos estén presentes en la lectura de esta carta.
28 Ki oore-ọ̀fẹ́ Jesu Kristi Olúwa wa, wà pẹ̀lú yín.
La gracia de nuestro Señor Jesucristo sea con ustedes. Amén.

< 1 Thessalonians 5 >