< 1 Thessalonians 3 >
1 Nítorí ìdí èyí, nígbà tí ara mi kò gbà á mọ́, mo pinnu láti nìkan dúró ní ìlú Ateni.
Przeto nie mogąc dłużej znosić, upodobało się nam, abyśmy sami w Atenach zostali.
2 Awa sì rán Timotiu, arákùnrin àti alábáṣiṣẹ́pọ̀ wa nínú Ọlọ́run nínú ìyìnrere Kristi, láti fi ẹsẹ yín múlẹ̀, àti láti tù yín nínú ní ti ìgbàgbọ́ yín.
I posłaliśmy Tymoteusza, brata naszego i sługę Bożego, i pomocnika naszego w Ewangielii Chrystusowej, aby was utwierdził i napominał z strony wiary waszej.
3 Láìsí àní àní, ẹ mọ̀ gbangba pé, irú ìṣòro báwọ̀nyí wà nínú ètò Ọlọ́run fún àwọn tí ó gbàgbọ́, kí a má ba dààmú.
Aby się żaden nie poruszał w tych uciskach; gdyż sami wiecie, żeśmy na to wystawieni.
4 Tó bẹ́ẹ̀ tí a fi kìlọ̀ fún yín pé ìjìyà inúnibíni yóò dé. Ó sì rí bẹ́ẹ̀ nítòótọ́.
Albowiem gdyśmy byli u was, opowiadaliśmy wam, żeśmy mieli być uciśnieni, jakoż się też to stało, i wiecie o tem.
5 Bí mo wí tẹ́lẹ̀, nígbà tí ara mi kò gba á mọ́, mo sì ránṣẹ́ kí èmi kí ó lè mọ́ ìgbàgbọ́ yín, kí olùdánwò nì má ba à dán an yín wò lọ́nàkọnà, kí làálàá wa sì jásí asán.
Dlatego i ja, nie mogąc tego dłużej znosić, posłałem go, abym się dowiedział o wierze waszej, by was snać nie kusił ten, co kusi, a nie była daremna praca nasza.
6 Nísinsin yìí, Timotiu ti dé pẹ̀lú ìròyìn ayọ̀ wí pé, ìgbàgbọ́ àti ìfẹ́ yín ṣì lágbára bí i ti àtẹ̀yìnwá. Inú wa dùn láti gbọ́ wí pé ẹ ṣì ń rántí ìbágbé wa láàrín yín pẹ̀lú ayọ̀. Timotiu tún fi yé wa pé bí ó ti mú wa lọ́kàn tó láti rí i yín, ni ó ṣe ẹ̀yin pàápàá.
Lecz teraz Tymoteusz od was do nas przyszedł i zwiastował nam wesołą nowinę o wierze i miłości waszej, a iż nas zawsze dobrze wspominacie, żądając nas widzieć, tak jako i my was.
7 Nítorí náà, ẹ̀yin ará, inú wá dùn jọjọ nínú gbogbo ìyọnu àti ìjìyà wa níbí nítorí pé àwa mọ̀ nísinsin yìí pé, ẹ̀yin dúró gbọningbọnin fún Olúwa.
Dlatego pocieszeni jesteśmy, bracia! z was w każdym utrapieniu i potrzebie naszej przez wiarę waszę;
8 Nítorí àwa yè nísinsin yìí, bí ẹ̀yin bá dúró ṣinṣin nínú Olúwa.
Bo teraz my żyjemy, jeźli wy stoicie w Panu.
9 Kò ṣe é ṣe fún wa láti dá ọpẹ́ tán lọ́wọ́ Ọlọ́run nítorí ayọ̀ àti ìfẹ́ tí ó máa ń kún ọkàn wa nípa àdúrà wa fún un yín.
Albowiem jakież dziękowanie możemy Bogu oddać za was za wszelkie wesele, którem się weselimy dla was przed Bogiem naszym?
10 Nítorí pé àwa ń gbàdúrà fún un yín lọ̀sán-án àti lóru. Èyí yóò ràn wá lọ́wọ́ láti ṣe àtúnṣe ibi tí ìgbàgbọ́ yín bá kù sí.
W nocy i we dnie bardzo się gorliwie modląc, abyśmy oglądali oblicze wasze i dopełnili niedostatków wiary waszej.
11 À ń gbàdúrà wí pé, kí ó wu Ọlọ́run pàápàá àti Olúwa wa Jesu Kristi láti rán wa padà sí ọ̀dọ̀ yín lẹ́ẹ̀kan sí í.
Lecz sam Bóg i Ojciec nasz, i Pan nasz, Jezus Chrystus, niech wyprostuje drogę naszę do was;
12 A sì béèrè pé, kí Ọlọ́run ràn yín lọ́wọ́ tó bẹ́ẹ̀ tí ìfẹ́ yín yóò fi gbòòrò tí yóò sì sàn kan olúkúlùkù yín. Èyí yóò jẹ́ àpẹẹrẹ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ àwa náà ṣe sàn kan ẹ̀yin náà.
A was Pan niech pomnoży i obfitującymi uczyni w miłości jednego ku drugiemu, i ku wszystkim, jako i nas ku wam,
13 Kí ó lè fi ọkàn yín balẹ̀ ní àìlábùkù nínú ìwà mímọ́ níwájú Ọlọ́run àti Baba wa. Nígbà náà, ẹ ó ní ìgboyà láti dúró níwájú rẹ̀ láìṣẹ̀, ní ọjọ́ tí Olúwa wa Jesu Kristi yóò padà wá pẹ̀lú àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀.
Aby utwierdzone były serca wasze nienaganione w świętobliwości przed Bogiem i Ojcem naszym, na przyjście Pana naszego, Jezusa Chrystusa, ze wszystkimi świętymi jego.