< 1 Thessalonians 3 >

1 Nítorí ìdí èyí, nígbà tí ara mi kò gbà á mọ́, mo pinnu láti nìkan dúró ní ìlú Ateni.
Wie wir es vor Sehnsucht nach euch nicht mehr aushalten konnten, deshalb entschlossen wir uns, allein in Athen zurückzubleiben,
2 Awa sì rán Timotiu, arákùnrin àti alábáṣiṣẹ́pọ̀ wa nínú Ọlọ́run nínú ìyìnrere Kristi, láti fi ẹsẹ yín múlẹ̀, àti láti tù yín nínú ní ti ìgbàgbọ́ yín.
und schickten Timotheus, unseren Bruder und Gottes Diener an Christi Froher Botschaft, um euch für euern Glauben Stärkung und Trost zu bringen,
3 Láìsí àní àní, ẹ mọ̀ gbangba pé, irú ìṣòro báwọ̀nyí wà nínú ètò Ọlọ́run fún àwọn tí ó gbàgbọ́, kí a má ba dààmú.
damit niemand in den jetzigen Trübsalen wankend würde. Denn ihr wißt ja selbst, daß wir dazu bestimmt sind (Trübsal durchzumachen).
4 Tó bẹ́ẹ̀ tí a fi kìlọ̀ fún yín pé ìjìyà inúnibíni yóò dé. Ó sì rí bẹ́ẹ̀ nítòótọ́.
Haben wir es euch doch, als wir bei euch waren, vorhergesagt, daß wir Trübsal leiden müssen. Und das ist nun, wie ihr erfahren habt, auch wirklich eingetroffen.
5 Bí mo wí tẹ́lẹ̀, nígbà tí ara mi kò gba á mọ́, mo sì ránṣẹ́ kí èmi kí ó lè mọ́ ìgbàgbọ́ yín, kí olùdánwò nì má ba à dán an yín wò lọ́nàkọnà, kí làálàá wa sì jásí asán.
So schickte ich denn, weil ich es nicht mehr aushielt, zu euch, um zu erfahren, wie es um euern Glauben stehe, ob euch etwa der Versucher verführt habe und unsere Arbeit vergeblich gewesen sei.
6 Nísinsin yìí, Timotiu ti dé pẹ̀lú ìròyìn ayọ̀ wí pé, ìgbàgbọ́ àti ìfẹ́ yín ṣì lágbára bí i ti àtẹ̀yìnwá. Inú wa dùn láti gbọ́ wí pé ẹ ṣì ń rántí ìbágbé wa láàrín yín pẹ̀lú ayọ̀. Timotiu tún fi yé wa pé bí ó ti mú wa lọ́kàn tó láti rí i yín, ni ó ṣe ẹ̀yin pàápàá.
Jetzt aber ist Timotheus von euch zu uns zurückgekehrt mit guter Botschaft über euern Glauben und eure Liebe und mit der Nachricht, daß ihr uns allezeit in gutem Andenken habt und voll Sehnsucht seid, uns wiederzusehen, — wie auch uns nach dem Wiedersehen mit euch verlangt.
7 Nítorí náà, ẹ̀yin ará, inú wá dùn jọjọ nínú gbogbo ìyọnu àti ìjìyà wa níbí nítorí pé àwa mọ̀ nísinsin yìí pé, ẹ̀yin dúró gbọningbọnin fún Olúwa.
Nun sind wir, liebe Brüder, bei all unserer Not und Trübsal durch euern Glauben getröstet worden.
8 Nítorí àwa yè nísinsin yìí, bí ẹ̀yin bá dúró ṣinṣin nínú Olúwa.
Denn jetzt erst haben wir rechten Lebensmut, weil ihr in der Gemeinschaft des Herrn feststeht.
9 Kò ṣe é ṣe fún wa láti dá ọpẹ́ tán lọ́wọ́ Ọlọ́run nítorí ayọ̀ àti ìfẹ́ tí ó máa ń kún ọkàn wa nípa àdúrà wa fún un yín.
Ja wir können Gott nicht genug danken für all die Freude, die wir euretwegen vor unserem Gott empfinden.
10 Nítorí pé àwa ń gbàdúrà fún un yín lọ̀sán-án àti lóru. Èyí yóò ràn wá lọ́wọ́ láti ṣe àtúnṣe ibi tí ìgbàgbọ́ yín bá kù sí.
Tag und Nacht flehen wir ihn innig an, er möge uns euch wiedersehen lassen, damit wir alles, was etwa noch in euerm Glaubensleben mangelt, in rechte Ordnung bringen können.
11 À ń gbàdúrà wí pé, kí ó wu Ọlọ́run pàápàá àti Olúwa wa Jesu Kristi láti rán wa padà sí ọ̀dọ̀ yín lẹ́ẹ̀kan sí í.
Er, unser Gott und Vater, und unser Herr Jesus bahne uns den Weg zu euch!
12 A sì béèrè pé, kí Ọlọ́run ràn yín lọ́wọ́ tó bẹ́ẹ̀ tí ìfẹ́ yín yóò fi gbòòrò tí yóò sì sàn kan olúkúlùkù yín. Èyí yóò jẹ́ àpẹẹrẹ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ àwa náà ṣe sàn kan ẹ̀yin náà.
Euch aber erfülle der Herr mit reicher Liebe zueinander und zu allen Menschen — wie auch wir von Liebe zu euch überfließen.
13 Kí ó lè fi ọkàn yín balẹ̀ ní àìlábùkù nínú ìwà mímọ́ níwájú Ọlọ́run àti Baba wa. Nígbà náà, ẹ ó ní ìgboyà láti dúró níwájú rẹ̀ láìṣẹ̀, ní ọjọ́ tí Olúwa wa Jesu Kristi yóò padà wá pẹ̀lú àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀.
Dann werden eure Herzen fest, und ihr seid unsträflich in Heiligkeit vor unserem Gott und Vater, wenn unser Herr Jesus kommt mit allen seinen Heiligen.

< 1 Thessalonians 3 >