< 1 Thessalonians 3 >
1 Nítorí ìdí èyí, nígbà tí ara mi kò gbà á mọ́, mo pinnu láti nìkan dúró ní ìlú Ateni.
ⲁ̅ⲉⲑⲃⲉⲫⲁⲓ ⳿ⲛⲧⲉⲛ⳿ϣⲟϩⲓ ⲁⲛ ⲁⲛϯⲙⲁϯ ⳿ⲉⲥⲱϫⲡ ⳿ⲙⲙⲁⲩⲁⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ ⲁⲑⲏⲛⲛⲁⲥ.
2 Awa sì rán Timotiu, arákùnrin àti alábáṣiṣẹ́pọ̀ wa nínú Ọlọ́run nínú ìyìnrere Kristi, láti fi ẹsẹ yín múlẹ̀, àti láti tù yín nínú ní ti ìgbàgbọ́ yín.
ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲛⲟⲩⲱⲣⲡ ⳿ⲙⲡⲉⲛⲥⲟⲛ ⲧⲓⲙⲟⲑⲉⲟⲥ ϩⲁⲣⲱⲧⲉⲛ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲇⲓ⳿ⲁⲕⲱⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⳿ⲉⲧⲁϫⲣⲉ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥⲧⲱⲃϩ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲡⲉⲧⲉⲛⲛⲁϩϯ.
3 Láìsí àní àní, ẹ mọ̀ gbangba pé, irú ìṣòro báwọ̀nyí wà nínú ètò Ọlọ́run fún àwọn tí ó gbàgbọ́, kí a má ba dààmú.
ⲅ̅ϫⲉ ⳿ⲛⲧⲉ⳿ϣⲧⲉⲙ ⳿ϩⲗⲓ ⲕⲓⲙ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲁⲓϩⲟϫϩⲉϫ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲅⲁⲣ ⲧⲉⲧⲉⲛⲥⲱⲟⲩⲛ ϫⲉ ⲁⲛⲭⲏ ⳿ⲉⲡⲁⲓϩⲱⲃ.
4 Tó bẹ́ẹ̀ tí a fi kìlọ̀ fún yín pé ìjìyà inúnibíni yóò dé. Ó sì rí bẹ́ẹ̀ nítòótọ́.
ⲇ̅ⲕⲉ ⲅⲁⲣ ⲓⲥϫⲉⲛ ⲉⲛⲭⲏ ϧⲁⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲁⲛⲉⲣϣⲟⲣⲡ ⳿ⲛϫⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⲥⲉⲛⲁϩⲉϫϩⲱϫⲉⲛ ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧⲁⲥϣⲱⲡⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ.
5 Bí mo wí tẹ́lẹ̀, nígbà tí ara mi kò gba á mọ́, mo sì ránṣẹ́ kí èmi kí ó lè mọ́ ìgbàgbọ́ yín, kí olùdánwò nì má ba à dán an yín wò lọ́nàkọnà, kí làálàá wa sì jásí asán.
ⲉ̅ⲉⲑⲃⲉⲫⲁⲓ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ϩⲱ ϯ⳿ϣⲱⲟⲩ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⲁⲛ ⲁⲓⲟⲩⲱⲣⲡ ⳿ⲉ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲉⲡⲉⲧⲉⲛⲛⲁϩϯ ⲙⲏⲡⲱⲥ ⲁⲛ ⲁϥⲉⲣⲡⲓⲣⲁⲍⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛϫⲉ ⲫⲏⲉⲧ ϭⲱⲛⲧ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛϧⲓⲥⲓ ϣⲱⲡⲓ ⲉϥϣⲟⲩⲓⲧ.
6 Nísinsin yìí, Timotiu ti dé pẹ̀lú ìròyìn ayọ̀ wí pé, ìgbàgbọ́ àti ìfẹ́ yín ṣì lágbára bí i ti àtẹ̀yìnwá. Inú wa dùn láti gbọ́ wí pé ẹ ṣì ń rántí ìbágbé wa láàrín yín pẹ̀lú ayọ̀. Timotiu tún fi yé wa pé bí ó ti mú wa lọ́kàn tó láti rí i yín, ni ó ṣe ẹ̀yin pàápàá.
ⲋ̅ϯⲛⲟⲩ ⲇⲉ ⲉⲧⲁϥ⳿ⲓ ϩⲁⲣⲟⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲧⲓⲙⲟⲑⲉⲟⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲁⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧⲁϥϫⲉ ⳿ⲡϣⲉⲛⲛⲟⲩϥⲓ ⲛⲁⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛⲛⲁϩϯ ⲛⲉⲙ ⲧⲉⲧⲉⲛⲁⲅⲁⲡⲏ ⲟⲩⲟϩ ϫⲉ ⲡⲉⲛⲙⲉⲩⲓ ⲉⲑⲛⲁⲛⲉϥ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲙⲉⲓ ⳿ⲛⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟⲛ ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧϣⲟⲡ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ϩⲱⲛ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ.
7 Nítorí náà, ẹ̀yin ará, inú wá dùn jọjọ nínú gbogbo ìyọnu àti ìjìyà wa níbí nítorí pé àwa mọ̀ nísinsin yìí pé, ẹ̀yin dúró gbọningbọnin fún Olúwa.
ⲍ̅ⲉⲑⲃⲉⲫⲁⲓ ⲁ ⲡⲉⲛϩⲏⲧ ⲑⲱⲧ ⲉϫⲉⲛ ⲑⲏ ⲛⲟⲩ ⲛⲉⲛ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛⲁⲛⲁⲅⲕⲏ ⲧⲏⲣⲥ ⲛⲉⲙ ⲡⲉⲧⲉⲛϩⲟϫϩⲉϫ ⲧⲏⲣϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲡⲉⲧⲉⲛⲛⲁϩϯ.
8 Nítorí àwa yè nísinsin yìí, bí ẹ̀yin bá dúró ṣinṣin nínú Olúwa.
ⲏ̅ϫⲉ ϯⲛⲟⲩ ⲧⲉⲛⲟⲛϧ ⲁⲣⲉⲧⲉⲛϣⲁⲛⲟϩⲓ ⳿ⲉⲣⲁⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ϧⲉⲛ Ⲡ⳪.
9 Kò ṣe é ṣe fún wa láti dá ọpẹ́ tán lọ́wọ́ Ọlọ́run nítorí ayọ̀ àti ìfẹ́ tí ó máa ń kún ọkàn wa nípa àdúrà wa fún un yín.
ⲑ̅ⲟⲩ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛϣⲉⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ⲉⲧⲏⲓϥ ⳿ⲛ⳿ⲧϣⲉⲃⲓⲱ ⳿ⲙⲠ⳪ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲡⲓⲣⲁϣⲓ ⲧⲏⲣϥ ⲉⲧⲉⲛⲣⲁϣⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲙⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲙⲡⲉⲛⲛⲟⲩϯ.
10 Nítorí pé àwa ń gbàdúrà fún un yín lọ̀sán-án àti lóru. Èyí yóò ràn wá lọ́wọ́ láti ṣe àtúnṣe ibi tí ìgbàgbọ́ yín bá kù sí.
ⲓ̅⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲡⲓ⳿ⲉϫⲱⲣϩ ⳿ⲛϩⲟⲩ⳿ⲟ ⳿ⲛϩⲟⲩ⳿ⲟ ⲉⲛⲧⲱⲃϩ ⳿ⲉ⳿ⲡϫⲓⲛⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲡⲉⲧⲉⲛϩⲟ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲥⲉⲃⲧⲉ ⲛⲓϭⲣⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛⲛⲁϩϯ.
11 À ń gbàdúrà wí pé, kí ó wu Ọlọ́run pàápàá àti Olúwa wa Jesu Kristi láti rán wa padà sí ọ̀dọ̀ yín lẹ́ẹ̀kan sí í.
ⲓ̅ⲁ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲫϯ ⲡⲉⲛⲓⲱⲧ ⲛⲉⲙ ⲡⲉⲛ⳪ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲉϥ⳿ⲉⲥⲉⲃⲧⲉ ⲡⲉⲛⲙⲱⲓⲧ ϩⲁⲣⲱⲧⲉⲛ.
12 A sì béèrè pé, kí Ọlọ́run ràn yín lọ́wọ́ tó bẹ́ẹ̀ tí ìfẹ́ yín yóò fi gbòòrò tí yóò sì sàn kan olúkúlùkù yín. Èyí yóò jẹ́ àpẹẹrẹ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ àwa náà ṣe sàn kan ẹ̀yin náà.
ⲓ̅ⲃ̅⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲇⲉ ⲉⲣⲉ Ⲡ⳪ ⳿ⲑⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲁϣⲁⲓ ⲛⲉⲙ ⳿ⲉⲉⲣϩⲟⲩ⳿ⲟ ϧⲉⲛ ϯⲁⲅⲁⲡⲏ ⳿ⲉⲛⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲏⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧϣⲟⲡ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ϩⲱⲛ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ.
13 Kí ó lè fi ọkàn yín balẹ̀ ní àìlábùkù nínú ìwà mímọ́ níwájú Ọlọ́run àti Baba wa. Nígbà náà, ẹ ó ní ìgboyà láti dúró níwájú rẹ̀ láìṣẹ̀, ní ọjọ́ tí Olúwa wa Jesu Kristi yóò padà wá pẹ̀lú àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀.
ⲓ̅ⲅ̅⳿ⲉ⳿ⲡϫⲓⲛⲧⲁϫⲣⲉ ⲛⲉⲧⲉⲛϩⲏⲧ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲉⲧⲁⲧⲁⲣⲓⲕⲓ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲧⲟⲩⲃⲟ ⳿ⲙⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲙⲫϯ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉⲛⲓⲱⲧ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲡⲁⲣⲟⲩⲥⲓⲁ ⳿ⲙⲡⲉⲛϭ̅ ⲥ̅ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲁⲅⲓⲟⲥ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲁϥ ⲁⲙⲏⲛ