< 1 Samuel 1 >

1 Ọkùnrin kan wà, láti Ramataimu-Sofimu, láti ìlú olókè Efraimu, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Elkana, ọmọ Jerohamu, ọmọ Elihu, ọmọ Tohu, ọmọ Sufu, ará Efrata.
Volt egy ember Rámátájim Czófimból, Efraim hegységéből, neve Elkána, Jeróchám fia, Elíhú fia, Tóchú fia, Czúf fia, Efraimbeli.
2 Ó sì ní ìyàwó méjì, orúkọ wọn ni Hana àti Penina: Penina ní ọmọ, ṣùgbọ́n Hana kò ní.
Annak volt két felesége, az egyiknek neve Channa s a másiknak neve Peninna; Peninnának voltak gyermekei, Channának pedig nem voltak gyermekei.
3 Ní ọdọọdún, ọkùnrin yìí máa ń gòkè láti ìlú rẹ̀ láti lọ sìn àti láti ṣe ìrúbọ sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ ní Ṣilo, níbi tí àwọn ọmọkùnrin Eli méjèèjì, Hofini àti Finehasi ti jẹ́ àlùfáà Olúwa.
Évről-évre ama férfiú fölment a városából, hogy leboruljon és áldozzon az Örökkévalónak, a Seregek urának Sílóban; ott volt Éli két fia, Chofni és Pínechász, mint papjai az Örökkévalónak.
4 Nígbàkígbà tí ó bá kan Elkana láti ṣe ìrúbọ, òun yóò bù lára ẹran fún aya rẹ̀ Penina àti fún gbogbo àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin.
S történt, amely napon áldozott Elkána, adott feleségének, Peninnának és annak minden fiának és leányának részeket;
5 Ṣùgbọ́n ó máa ń pín ìlọ́po fun Hana nítorí pé ó fẹ́ràn rẹ̀ àti pé Olúwa ti sé e nínú.
Channának pedig egy kiváló részt adott, mert Channát szerette; de az Örökkévaló elzárta a méhét.
6 Nítorí pé Olúwa ti sé e nínú, orogún rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní fín níràn láti lè mú kí ó bínú.
Bosszantotta is vetélytársa bosszantással azért, hogy felbőszítse, mivel elzárta az Örökkévaló a méhét.
7 Eléyìí sì máa ń ṣẹlẹ̀ ní ọdọọdún. Nígbàkígbà tí Hana bá gòkè lọ sí ilé Olúwa, orogún rẹ̀ a máa fín níràn títí tí yóò fi máa sọkún tí kò sì ní lè jẹun.
S így tett esztendőről-esztendőre: valahányszor fölment az Örökkévaló házába, megannyiszor bosszantotta; ő meg sírt és nem evett.
8 Elkana ọkọ rẹ̀ yóò sọ fún un pé, “Hana èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún? Èéṣe tí ìwọ kò fi jẹun? Èéṣe tí ìwọ fi ń ba ọkàn jẹ́? Èmi kò ha ju ọmọ mẹ́wàá lọ fún ọ bí?”
Ekkor mondta neki férje Elkána: Channa, miért sírsz és miért nem eszel és miért szomorú a szíved? Nem jobb vagyok-e neked tíz fiúnál is?
9 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti jẹ, tí wọ́n tún mu tán ní Ṣilo, Hana dìde wá síwájú Olúwa. Nígbà náà, Eli àlùfáà wà lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ní ibi tí ó máa ń jókòó.
S fölkelt Channa, miután ettek Sílóban és miután ittak – Éli pap éppen a széken ült az Örökkévaló templomában az ajtófélnél –
10 Pẹ̀lú ẹ̀dùn ọkàn Hana sọkún gidigidi, ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
ő pedig elkeseredett lelkű volt, imádkozott az Örökkévalóhoz és sírva sírt.
11 Ó sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, jùlọ tí ìwọ bá le bojú wo ìránṣẹ́bìnrin rẹ kí ìwọ sì rántí rẹ̀, tí ìwọ kò sì gbàgbé ìránṣẹ́ rẹ ṣùgbọ́n tí ìwọ yóò fún un ní ọmọkùnrin, nígbà náà èmi yóò sì fi fún Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀ a kì yóò sì fi abẹ kàn án ní orí.”
És fogadást tett és mondta: Örökkévaló, seregek ura, ha rátekintesz szolgálód nyomorára, megemlékezel rólam és nem felejted el szolgálódat és majd adsz a szolgálódnak férfimagzatot: akkor odaadom őt az Örökkévalónak életének mindennapjaira, és borotva nem éri fejét.
12 Bí ó sì ṣe ń gbàdúrà sí Olúwa, Eli sì kíyèsi ẹnu rẹ̀.
És történt, midőn sokat imádkozott az Örökkévaló előtt, Éli pedig megfigyelte a száját,
13 Hana ń gbàdúrà láti inú ọkàn rẹ̀, ṣùgbọ́n ètè rẹ̀ ni ó ń mì, a kò gbọ́ ohùn rẹ̀. Eli rò wí pé ó ti mu ọtí yó.
ő meg, Channa, szívében beszélt, csupán ajkai mozogtak, de hangja nem hallatszott, azért Éli részegnek gondolta.
14 Eli sì wí fún un pé, “Yóò ti pẹ́ fún ọ tó tí ìwọ yóò máa yó? Mú ọtí wáìnì rẹ̀ kúrò.”
És szólt hozzá Éli: Meddig fogsz részegeskedni? Távolítsd el magadtól borodat!
15 Hana dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, Olúwa mi, èmi ni obìnrin oníròbìnújẹ́. Èmi kò mu ọtí wáìnì tàbí ọtí líle; èmi ń tú ọkàn mi jáde sí Olúwa ni.
Felelt Channa és mondta: Nem, uram, nehéz lelkű asszony vagyok én, bort pedig meg részegítő italt nem ittam, hanem kiöntöttem lelkemet az Örökkévaló előtt.
16 Má ṣe mú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí obìnrin búburú. Èmi ti ń gbàdúrà níhìn-ín nínú ìrora ọkàn àti ìbànújẹ́ mi.”
Ne tartsd szolgálódat alávaló nőnek, mert panaszom és bánatom teljéből beszéltem idáig.
17 Eli dáhùn pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, kí Ọlọ́run Israẹli fi ohun tí ìwọ ti béèrè ní ọwọ́ rẹ̀ fún ọ.”
Felelt Éli és mondta: Menj békével! Izrael Istene pedig adja meg kérésedet, melyet kértél tőle.
18 Ó wí pé, “Kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà bá tirẹ̀ lọ, ó sì jẹun, kò sì fa ojú ro mọ́.
Mondta: Találjon szolgálód kegyet szemeidben! Erre elment az asszony az útjára, evett és nem volt többé bánatos arca.
19 Wọ́n sì dìde ni kùtùkùtù òwúrọ̀, wọn wólẹ̀ sìn níwájú Olúwa, wọn padà wa sí ilé wọn ni Rama: Elkana si mọ Hana aya rẹ̀: Olúwa sì rántí rẹ̀.
Fölkeltek korán reggel és leborultak az Örökkévaló előtt, erre visszatértek és megtértek házukba Rámába. Megismerte Elkána a feleségét, Channát, és megemlékezett róla az Örökkévaló.
20 Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ rẹ̀ pé, lẹ́yìn ìgbà tí Hana lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Samuẹli, pé, “Nítorí tí mo béèrè rẹ̀ lọ́wọ́ Olúwa.”
És volt a napok fordultakor, várandós lett Channa és szült fiút; s nevezte őt Sámuelnek: mert az Örökkévalótól kértem őt.
21 Ọkùnrin náà Elkana, àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, gòkè lọ láti rú ẹbọ ọdún sí Olúwa, àti láti sán ẹ̀jẹ́ rẹ̀.
S fölment a férfi Elkána meg az egész háza, hogy áldozza az Örökkévalónak az évi áldozatot és fogadását.
22 Ṣùgbọ́n Hana kò gòkè lọ; nítorí tí ó sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ó di ìgbà tí mo bá gba ọmú lẹ́nu ọmọ náà, nígbà náà ni èmi yóò mú un lọ, kí òun lè fi ara hàn níwájú Olúwa, kí ó sí máa gbé ibẹ̀ títí láé.”
Channa pedig nem ment föl, mert mondta férjének: Míg elválasztatik a fiú, akkor majd elviszem, hogy megjelenjék az Örökkévaló színe előtt és ott maradjon örökre.
23 Elkana ọkọ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ. Dúró títí ìwọ yóò fi gba ọmú lẹ́nu rẹ̀; ṣùgbọ́n kí Olúwa sá à mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà sì jókòó, ó sì fi ọmú fún ọmọ rẹ̀ títí ó fi gbà á lẹ́nu rẹ̀.
Mondta neki férje Elkána: Tedd, ami jónak tetszik szemeidben, maradj, míg őt elválasztottad, csakhogy megtartsa az Örökkévaló az igéjét. És maradt az asszony és szoptatta az ő fiát, míg elválasztotta.
24 Nígbà tí ó sì gba ọmú lẹ́nu rẹ̀, ó sì mú un gòkè lọ pẹ̀lú ara rẹ̀. Pẹ̀lú ẹgbọrọ màlúù mẹ́ta, àti ìyẹ̀fun efa kan, àti ìgò ọtí wáìnì kan, ó sì mú un wá sí ilé Olúwa ní Ṣilo: ọmọ náà sì wà ní ọmọdé.
S fölvitte magával, miután elválasztotta, három tulokkal, egy éfa liszttel és egy tömlő borral, és bevitte őt az Örökkévaló házába Sílóba; a fiú még fiatal volt.
25 Wọ́n pa ẹgbọrọ màlúù, wọ́n sì mú ọmọ náà tọ Eli wá.
Levágták a tulkot és bevitték a fiút Élihez.
26 Hana sì wí pé, “Olúwa mi, bí ọkàn rẹ ti wà láààyè, Olúwa mi, èmi ni obìnrin náà tí ó dúró lẹ́bàá ọ̀dọ̀ rẹ níhìn-ín tí ń tọrọ lọ́dọ̀ Olúwa.
Mondta: Kérem uram, lelked életére, uram, én vagyok az asszony, aki állt melletted e helyütt, imádkozva az Örökkévalóhoz.
27 Ọmọ yìí ni mo ń tọrọ; Olúwa sì fi ìdáhùn ìbéèrè tí mo béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ fún mi.
Ezért a fiúért imádkoztam: megadta nekem az Örökkévaló kérésemet, melyet tőle kértem.
28 Nítorí náà pẹ̀lú, èmi fi í fún Olúwa; ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀: nítorí tí mo ti béèrè rẹ̀ fún Olúwa.” Wọn si wólẹ̀ sin Olúwa níbẹ̀.
Tehát én is felajánlottam őt az Örökkévalónak: mind a napokon, amíg csak lesz, fel van ő ajánlva az Örökkévalónak. És leborult ott az Örökkévaló előtt.

< 1 Samuel 1 >