< 1 Samuel 9 >

1 Ará Benjamini kan wà, ẹni tí ó jẹ́ aláàánú ọlọ́rọ̀, orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Kiṣi, ọmọ Abieli, ọmọ Serori, ọmọ Bekorati, ọmọ Afiah ti Benjamini.
Byl pak muž z pokolení Beniamin, jménem Cis, syn Abiele syna Seror, syna Bechorat, syna Afia, syna muže Jemini, muž udatný.
2 Ó ní ọmọkùnrin kan tí à ń pè ní Saulu, ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó yanjú, tí ó jẹ́ arẹwà, tí kò sí ẹni tó ní ẹwà jù ú lọ láàrín gbogbo àwọn ọmọ Israẹli—láti èjìká rẹ̀ lọ sí òkè, ó ga ju gbogbo àwọn ènìyàn tókù lọ.
Ten měl syna jménem Saule, mládence krásného, tak že žádného z synů Izraelských nebylo pěknějšího nad něj; od ramene svého vzhůru převyšoval všecken lid.
3 Nísinsin yìí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó jẹ́ ti Kiṣi baba Saulu sì sọnù. Nígbà náà, Kiṣi sọ fún Saulu ọmọ rẹ̀ pé, “Mú ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́ pẹ̀lú rẹ kí ẹ lọ láti wá àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà.”
Byly se pak ztratily oslice Cis, otce Saulova. I řekl Cis Saulovi synu svému: Vezmi i hned s sebou jednoho z služebníků, a vstana, jdi, hledej oslic.
4 Bẹ́ẹ̀ ní ó kọjá láàrín àwọn ìlú olókè Efraimu, ó sì kọjá ní àyíká ilẹ̀ Ṣaliṣa, ṣùgbọ́n wọn kò rí wọn. Wọ́n sì kọjá lọ sí òpópó Ṣaalimu, ṣùgbọ́n àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kò sí níbẹ̀. Nígbà náà, ó kọjá ní agbègbè Benjamini, wọn kò sì rí wọn.
A tak šel přes horu Efraim, a prošel až do země Salisa, a nic nenalezli; prošli také zemi Sálim, a nic nenalezli. Ještě přešli i zemi Jemini, a nenalezli.
5 Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Sufu, Saulu sọ fún ìránṣẹ́ tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí á padà sẹ́yìn, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, baba mi yóò dá ìrònú rẹ̀ dúró nípa àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ yóò sì bẹ̀rẹ̀ àníyàn nípa wa.”
Když pak přišli do země Zuf, řekl Saul služebníku svému, kterýž byl s ním: Poď, a navraťme se, aby otec můj nechaje těch oslic, neměl starosti o nás.
6 Ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ náà fún un ní èsì pé, “Wò ó, ní inú ìlú yìí ọkùnrin ènìyàn Ọlọ́run kan wà; ó jẹ́ ẹni tí wọ́n ń bu ọlá fún, àti gbogbo ohun tí ó bá sọ ní ó máa ń jẹ́ òtítọ́. Jẹ́ kí á lọ síbẹ̀ nísinsin yìí, bóyá yóò sọ fún wá ọ̀nà tí a yóò gbà.”
Kterýž řekl jemu: Aj, nyní muž Boží jest v městě tomto, a muž ten jest znamenitý; cožkoli praví, všecko se tak stává. Medle, jděme tam, zdali by oznámil nám cestu naši, kterouž bychom jíti měli.
7 Saulu sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀, “Tí àwa bá lọ, kín ni àwa lè fún ọkùnrin náà? Oúnjẹ inú àpò wa ti tán. A kò sì ní ẹ̀bùn láti mú lọ sọ́dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run. Kí ni a ní?”
Odpověděl Saul služebníku svému: Aj, půjdeme. Co pak přineseme muži tomu? Nebo jsme chléb vytrávili z pytlíků našich, ani daru nemáme, kterýž bychom přinesli muži Božímu. Což máme?
8 Ìránṣẹ́ sì dá a lóhùn lẹ́ẹ̀kan sí i. “Wò ó,” ó wí pé, “Mo ní ìdámẹ́rin ṣékélì fàdákà lọ́wọ́. Èmi yóò fún ènìyàn Ọlọ́run náà kí ó lè fi ọ̀nà hàn wá.”
I doložil služebník, odpovídaje Saulovi, a řekl: Hle, nalezl jsem u sebe čtvrt lotu stříbra; to dám muži Božímu, aby nám oznámil cestu naši.
9 (Tẹ́lẹ̀ ní Israẹli tí ọkùnrin kan bá lọ béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run, yóò wí pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì náà,” nítorí àwọn alásọtẹ́lẹ̀ ìsinsin yìí ni wọ́n ń pè ní wòlíì).
(Za starodávna v Izraeli tak říkával každý, kdož jíti měl raditi se s Bohem: Poďte, a půjdeme až k vidoucímu. Nebo ten, kterýž nyní slove prorok, za starodávna sloul vidoucí.)
10 Saulu sọ fún ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀ pé ó dára, “Jẹ́ kí a lọ.” Wọ́n jáde lọ sí ìlú tí ènìyàn Ọlọ́run náà ń gbé.
Řekl tedy Saul služebníku svému: Dobrá jest řeč tvá, nu, jděmež. I šli do města, v kterémž byl muž Boží.
11 Bí wọ́n ṣe ń lọ ní orí òkè sí ìlú náà, wọ́n pàdé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin tí ó ń jáde í bọ̀ láti wá pọn omí. Wọ́n sì bi wọ́n, “Ṣé wòlíì náà wà níbí?”
A když vcházeli na horu města, potkali se s děvečkami, vycházejícími vážit vody. I řekli jim: Jest-li zde vidoucí?
12 “Ó wà,” wọ́n dáhùn. “Ó ń bẹ níwájú u yín, múra nísinsin yìí, ó ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ wa lónìí ni, nítorí àwọn ènìyàn ní ẹbọ rírú ni ibi gíga.
Kteréž odpověděly jim a řekly: Jest. Hle, a on před tebou, pospěš tedy; nebo dnes přišel do města, proto že obětuje dnes lid na té hoře.
13 Kété tí ẹ bá ti wọ ìlú, ẹ ó rí i kí ó tó lọ sí ibi gíga láti lọ jẹun. Àwọn ènìyàn kò sì ní bẹ̀rẹ̀ sí jẹun títí tí yóò fi dé. Torí ó gbọdọ̀ bùkún ẹbọ náà; lẹ́yìn náà, àwọn tí a pè yóò jẹun. Gòkè lọ nísinsin yìí, ó yẹ kí ẹ rí i ní àkókò yìí.”
Hned jakž vejdete do města, tedy naleznete ho, prvé než vstoupí na horu k jídlu. Lid zajisté nebude jísti, dokudž on nepřijde, nebo on požehná obětí, a potom pozvaní jísti budou. A protož jděte, nebo v tuto chvíli naleznete ho.
14 Wọ́n gòkè lọ sí ìlú náà, bí wọ́n ti ń wọlé, níbẹ̀ ni Samuẹli, ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ wọn bí ó ti ń lọ ibi gíga náà.
I šli do města. A když vcházeli do prostřed města, aj, Samuel vycházel proti nim, aby vstoupil na tu horu.
15 Olúwa ti sọ létí Samuẹli ní ọjọ́ kan kí Saulu ó tó dé pé,
Hospodin pak zjevil Samuelovi o jeden den prvé, nežli přišel Saul, řka:
16 “Ní ìwòyí ọ̀la, èmi yóò ran ọmọkùnrin kan sí ọ láti ilẹ̀ Benjamini. Fi òróró yàn án gẹ́gẹ́ bí olórí lórí àwọn ọmọ Israẹli, yóò gba àwọn ènìyàn mi kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Filistini. Mo ti bojú wo àwọn ènìyàn mi, nítorí igbe wọn ti dé ọ̀dọ̀ mi.”
V tuto chvíli zítra pošli k tobě muže z země Beniamin, kteréhož pomažeš, aby byl vůdce lidu mého Izraelského, a vysvobodíť lid můj z ruky Filistinských; vzhlédlť jsem zajisté na lid svůj, nebo přišlo volání jeho ke mně.
17 Nígbà tí Samuẹli fojúrí Saulu, Olúwa sọ fún un pé, “Èyí ni ọkùnrin tí mo sọ fún ọ nípa rẹ̀, yóò darí àwọn ènìyàn mi.”
A když Samuel uzřel Saule, řekl jemu Hospodin: Aj, teď ten muž, o kterémž pravil jsem tobě: tenť spravovati bude lid můj.
18 Saulu sì súnmọ́ Samuẹli ní ẹnu-ọ̀nà ìlú, ó sì wí pé, “Sọ fún mi èmi ń bẹ̀ ọ́ níbo ni ilé wòlíì náà wà.”
Tedy přistoupil Saul k Samuelovi v bráně, a řekl: Ukaž mi, prosím, kde jest tuto dům vidoucího?
19 Samuẹli dáhùn pé, “Èmi ni wòlíì náà. Ẹ máa gòkè lọ ṣáájú mi, ní ibi gíga, ẹ ó sì bá mi jẹun lónìí. Ní òwúrọ̀ ni èmi yóò tó jẹ́ kí ẹ lọ, gbogbo ohun tí ó wà ní ọkàn rẹ ní èmi yóò sọ fún ọ.
I odpověděl Samuel Saulovi: Já jsem vidoucí. Vstupiž přede mnou na horu, a budete dnes jísti se mnou; potom ráno propustím tě, a cožkoli jest v srdci tvém, oznámím tobě.
20 Fún ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó sọnù fún ọjọ́ mẹ́ta sẹ́yìn, má ṣe dààmú nípa wọ́n: a ti rí wọn. Sí ta ni gbogbo ìfẹ́ Israẹli wà? Bí kì í ṣe sí ìwọ àti sí gbogbo ilé baba à rẹ.”
O oslice pak, kteréžť se ztratily dnes třetí den, nic se nestarej, nebo nalezeny jsou. Ale na koho žádost všeho Izraele? Zdali ne na tebe a na všecken dům otce tvého?
21 Saulu dáhùn pé, “Ṣùgbọ́n èmi kì í há ṣe ẹ̀yà Benjamini? Kékeré nínú ẹ̀yà Israẹli. Ìdílé mi kò ha rẹ̀yìn jùlọ nínú gbogbo ẹ̀yà Benjamini? Èéṣì ti ṣe tí ìwọ sọ̀rọ̀ yìí sí mi?”
I odpověděl Saul a řekl: Zdaliž já nejsem syn Jemini, z nejmenšího pokolení Izraelského? Ano i čeled má jest nejchaternejší ze všech čeledí pokolení Beniaminova. Pročež jsi tedy ke mně mluvil taková slova?
22 Nígbà náà ni Samuẹli mú Saulu pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ̀ wọ inú gbọ̀ngán, ó sì mú wọn jókòó sí iwájú àwọn tí a pè—tí wọn tó ọgbọ̀n.
A pojav Samuel Saule i služebníka jeho, uvedl je do pokoje, a dal jim místo nejpřednější mezi pozvanými, jichž bylo okolo třidcíti mužů.
23 Samuẹli sọ fún alásè pé, “Mú ìpín ẹran tí mo fún ọ wá, èyí tí mo sọ fún ọ pé kí o yà sọ́tọ̀.”
I řekl Samuel kuchaři: Dej sem ten díl, kterýž jsem dal tobě, o kterémžť jsem řekl: Schovej jej obzvláštně.
24 Alásè náà sì gbé ẹsẹ̀ náà pẹ̀lú ohun tí ó wà lórí i rẹ̀, ó sì gbé e síwájú Saulu. Samuẹli wí pé, “Èyí ni ohun tí a fi pamọ́ fún ọ. Jẹ, nítorí a yà á sọ́tọ̀ fún ọ, fún ìdí yìí, láti ìgbà tí mo ti wí pé, ‘Mo ní àlejò tí a pè.’” Saulu sì jẹun pẹ̀lú Samuẹli ní ọjọ́ náà.
Když tedy přinesl kuchař plece i s tím, což se ho přídrželo, položil Samuel před Saule, a řekl: Teď, což pozůstalo, vezmi sobě, jez; až k této chvíli zajisté zachováno jest to pro tebe, jakž jsem řekl: Lidu jsem pozval. I jedl Saul s Samuelem v ten den.
25 Lẹ́yìn ìgbà tí wọn ti sọ̀kalẹ̀ láti ibí gíga náà wá sí inú ìlú, Samuẹli sì bá Saulu sọ̀rọ̀ lórí òrùlé ilé e rẹ̀.
A když sešli s hory do města, mluvil s Saulem na vrchní podlaze.
26 Wọ́n sì dìde ní àfẹ̀mọ́júmọ́, ó pe Saulu sórí òrùlé pé, “Múra, èmi yóò rán ọ lọ.” Nígbà tí Saulu múra tán òun àti Samuẹli jọ jáde lọ síta.
Potom vstali velmi ráno. I stalo se, když záře vzcházela, že zavolal Samuel Saule na hůru, řka: Vstaň, a propustím tě. Vstal tedy Saul, a vyšli oba ven, on i Samuel.
27 Bí wọ́n ti ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìpẹ̀kun ìlú náà, Samuẹli wí fún Saulu pé, “Sọ fún ìránṣẹ́ náà kí ó máa lọ ṣáájú u wa,” ìránṣẹ́ náà sì ṣe bẹ́ẹ̀, “Ṣùgbọ́n kí ìwọ kí ó dúró díẹ̀, kí èmi kí ó lè sọ ọrọ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run fún ọ.”
A když přicházeli na konec města, řekl Samuel Saulovi: Rci služebníku, ať jde napřed, (i šel); ty pak pozastav se málo, ažť oznámím řeč Boží.

< 1 Samuel 9 >