< 1 Samuel 6 >

1 Nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa sì ti wà ní agbègbè Filistini fún oṣù méje,
Kwathi ibhokisi lesivumelwano sikaThixo selihlale elizweni lamaFilistiya izinyanga eziyisikhombisa,
2 àwọn ará Filistini pe àwọn àlùfáà, àti àwọn alásọtẹ́lẹ̀, wọ́n sì sọ pé, “Kí ni kí a ṣe pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Olúwa? Sọ fún wa bí àwa yóò ti dá a padà sí ààyè rẹ̀.”
amaFilistiya abiza abaphristi labahlahluli athi, “Sizakwenzani ngebhokisi lesivumelwano sikaThixo na? Sitsheleni ukuthi singalibuyisela njani emuva endaweni yalo.”
3 Wọ́n dáhùn wí pé, “Tí ẹ bá dá àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ti àwọn ọmọ Israẹli padà, ẹ má ṣe dá a padà ní òfìfo, ṣùgbọ́n bí ó ti wù kí ó rí, ẹ fún un ní ẹbọ ẹ̀bi. Nígbà náà ni a ó mú un yín láradá, ẹ̀yin yóò sì mọ ìdí tí ọwọ́ rẹ̀ kò fi tí ì kúrò lára yín.”
Baphendula bathi, “Nxa libuyisela ibhokisi lesivumelwano sikankulunkulu ka-Israyeli, lingalibuyiseli lingelalutho, kodwa impela thumelani umnikelo wecala kuye. Ngalokho lizasila, njalo lizakwazi ukuthi kungani isandla sakhe singasuswanga kini.”
4 Àwọn ará Filistini béèrè pé, “Irú ẹbọ ẹ̀bi wo ni kí a fi fún un?” Wọ́n dáhùn, “Wúrà oníkókó márùn-ún àti eku ẹ̀lírí wúrà márùn-ún, gẹ́gẹ́ bí iye àwọn aláṣẹ Filistini, nítorí àjàkálẹ̀-ààrùn kan náà ni ó kọlù yín àti olórí yín.
AmaFilistiya abuza athi, “Ngumnikelo bani wecala okumele siwuthumele kuye na?” Baphendula bathi, “Amathumba egolide amahlanu lamagundwane egolide amahlanu, kusiya ngenani lababusi bamaFilistiya, ngoba isifo sinye sihlasele lina kanye lababusi benu.”
5 Mọ àwòrán ààrùn oníkókó àti ti eku ẹ̀lírí yin tí ó ń ba orílẹ̀-èdè náà jẹ́ kí o sì bu ọlá fún Ọlọ́run Israẹli. Bóyá yóò gbé ọwọ́ rẹ̀ kúrò lára yín, lára ọlọ́run yín àti lára ilẹ̀ yín.
Yenzani izifanekiso zamathumba lamagundwane achitha ilizwe, lidumise unkulunkulu ka-Israyeli. Mhlawumbe uzasusa isandla sakhe kini lakubonkulunkulu benu kanye laselizweni lenu.
6 Kí ni ó dé tí ẹ fi ń sé ọkàn yín le gẹ́gẹ́ bí àwọn ará Ejibiti àti Farao ti ṣe? Nígbà tí ó fi ọwọ́ líle mú wọn, ṣé wọn kò rán àwọn ọmọ Israẹli jáde kí wọn kí ó lè lọ ní ọ̀nà wọn?
Kungani lisenza inhliziyo zenu zibe lukhuni njengalokhu okwenziwa ngamaGibhithe loFaro na? Lapho unkulunkulu wama-Israyeli esebaphethe kalukhuni kabawavumelanga ama-Israyeli ukuba ahambe na?
7 “Nísinsin yìí ẹ pèsè kẹ̀kẹ́ ẹrù tuntun sílẹ̀, pẹ̀lú màlúù méjì tí ó ti fi ọmú fún ọmọ, èyí tí a kò tí ì gba àjàgà sí ọrùn rí, kí ẹ sì so ó mọ́ kẹ̀kẹ́ náà, kí ẹ sì mú ọmọ wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn wá sí ilé láti so.
“Ngakho-ke khathesi, lungisani inqola entsha lamankomokazi amabili azeleyo njalo angakaze afakwe ijogwe. Bophelani amankomokazi enqoleni, kodwa lisuse amankonyane awo liwavalele esibayeni.
8 Kí ẹ sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa sí orí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti kí ẹ̀yin sì kó àwọn ohun èlò wúrà tí ẹ̀yin fi fún un gẹ́gẹ́ bí ti ẹbọ ẹ̀bi sí inú àpótí ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, kí ẹ̀yin kí ó sì rán an lọ,
Thathani ibhokisi lesivumelwano sikaThixo lilibeke enqoleni, kuthi emxhakeni oseceleni kwalo lifake izinto zegolide elizithumela kuye njengomnikelo wecala. Ikhupheni izihambele ngendlela yayo,
9 ṣùgbọ́n kí ẹ sì máa ṣọ́ ọ. Tí ó bá ń lọ sí ilẹ̀ rẹ̀, ìlú rẹ̀, níhà Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà ni Olúwa mú àjálù ńlá yìí bá wa. Ṣùgbọ́n bí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà náà ni a mọ̀ pé kì í ṣe ọwọ́ rẹ̀ ni ó kọlù wá, ṣùgbọ́n ó wá bẹ́ẹ̀ ni.”
kodwa liyiqaphelisise. Ingaya elizweni lakibo, iqonde eBhethi-Shemeshi, kuyabe kunguThixo olethe incithakalo le enkulu phezu kwethu. Kodwa nxa ingenzi njalo, sizakwazi ukuthi kade kungasisosandla sakhe esisitshayileyo kanye lokuthi kuzenzakalele kodwa nje kithi.”
10 Nígbà náà ni wọ́n ṣe èyí. Wọ́n mú abo màlúù méjì, tí ń fi ọmú fún ọmọ, wọn mọ́ ara, wọ́n sì dè é ni ilé kẹ̀kẹ́ ẹrù, wọn sì so àwọn ọmọ wọn mọ́lẹ̀ ni ilé.
Ngakho-ke bakwenza lokhu. Bathatha amankomokazi amabili anjalo bawabophela enqoleni kwathi amankonyane awo bawavalela esibayeni.
11 Wọ́n gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa lé orí kẹ̀kẹ́ ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ni àpótí tí eku ẹ̀lírí wúrà àti àwòrán ààrùn oníkókó wà níbẹ̀.
Babeka ibhokisi lesivumelwano sikaThixo enqoleni ndawonye lomxhaka owawulamagundwane egolide lezifanekiso zamathumba.
12 Nígbà náà; àwọn màlúù lọ tààrà sí ìhà Beti-Ṣemeṣi, wọ́n ń lọ tààrà, wọ́n sì ń dún bí wọ́n ti ń lọ. Wọn kò yà sí ọ̀tún tàbí yà sí òsì. Àwọn aláṣẹ Filistini tẹ̀lé wọn títí dé ibodè Beti-Ṣemeṣi.
Emva kwalokho amankomokazi ahamba eqonde eBhethi-Shemeshi, elokhu esemgwaqweni njalo ebhonsa indlela yonke; kawazange aphambukele kwesokudla kumbe kwesenxele. Ababusi bamaFilistiya bawalandela baze bayafika emngceleni weBhethi Shemeshi.
13 Nísinsin yìí, àwọn ará Beti-Ṣemeṣi ń kórè jéró wọn ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, nígbà tí wọ́n wo òkè tí wọ́n sì rí àpótí ẹ̀rí Olúwa, wọ́n yọ̀ níwájú rẹ̀.
Ngalesosikhathi abantu beBhethi-Shemeshi babevuna ingqoloyi yabo esigodini, njalo bathi lapho bekhangela babona ibhokisi lesivumelwano, bathokoza ukulibona.
14 Kẹ̀kẹ́ ẹrù wá sí pápá Joṣua ti Beti-Ṣemeṣi, níbẹ̀ ni ó ti dúró ní ẹ̀bá àpáta ńlá kan. Àwọn ènìyàn gé igi ara kẹ̀kẹ́ ẹrù sí wẹ́wẹ́ wọ́n sì fi àwọn màlúù náà rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
Inqola yafika ensimini kaJoshuwa waseBhethi-Shemeshi, yasisima khonapho phansi kwedwala elikhulu. Abantu babanda inqola yaba zinkuni basebehlaba amankomokazi ukuba ngumnikelo wokutshiswa kuThixo.
15 Àwọn ará Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ìsàlẹ̀ pẹ̀lú àpótí tí ohun èlò wúrà wà níbẹ̀, wọ́n sì gbé wọn ka orí àpáta ńlá náà. Ní ọjọ́ náà, àwọn ará Beti-Ṣemeṣi rú ẹbọ sísun, wọ́n sì ṣe ìrúbọ sí Olúwa.
AbaLevi bethula ibhokisi lesivumelwano sikaThixo, kanye lomxhaka owawulezinto zegolide, bakubeka phezu kwedwala elikhulu. Ngalelolanga abantu baseBhethi-Shemeshi banikela iminikelo yokutshiswa benza lemihlatshelo kuThixo.
16 Àwọn aláṣẹ Filistini márààrún rí gbogbo èyí, wọ́n sì padà ní ọjọ́ náà sí Ekroni.
Ababusi abahlanu bamaFilistiya bakubona konke lokhu basebebuyela e-Ekroni ngalelolanga.
17 Èyí ni kókó wúrà tí àwọn Filistini fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀bi ọ̀kọ̀ọ̀kan fún Aṣdodu, ọ̀kan ti Gasa, ọ̀kan ti Aṣkeloni, ọ̀kan ti Gati, ọ̀kan ti Ekroni.
Amathumba egolide amaFilistiya awathumela kuThixo njengomnikelo wecala yila, elilodwa ele-Ashidodi, leleGaza, lele-Ashikheloni, leleGathi kanye lele-Ekroni.
18 Wúrà eku ẹ̀lírí jẹ́ iye ìlú tí àwọn aláṣẹ Filistini márààrún ti wá, ìlú olódi pẹ̀lú ìletò wọn. Àpáta ńlá náà, lórí èyí tí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa lé jẹ́ ẹ̀rí títí di òní ní oko Joṣua ará Beti-Ṣemeṣi.
Lenani lamagundwane egolide lalisiya ngenani lamadolobho amaFilistiya ayengawababusi abahlanu, amadolobho ayevikelwe alemizi yawo yasemaphandleni. Idwala elikhulu ababebeke ibhokisi lesivumelwano sikaThixo phezu kwalo, liyibufakazi lalamhlanje ensimini kaJoshuwa waseBhethi-Shemeshi.
19 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kọlu díẹ̀ lára àwọn ọkùnrin Beti-Ṣemeṣi, ó pa àádọ́rin wọn, nítorí wọ́n ti wo inú àpótí ẹ̀rí Olúwa. Àwọn ènìyàn ṣọ̀fọ̀ nítorí àjálù ńlá tí Olúwa fi bá ọ̀pọ̀ wọn jà.
Kodwa uNkulunkulu watshaya abanye babantu baseBhethi-Shemeshi, wabulala abangamatshumi ayisikhombisa babo ngoba babelunguze phakathi kwebhokisi lesivumelwano sikaNkulunkulu. Abantu balila ngenxa yokugadla okunzima uThixo ayekwenze kubo,
20 Àwọn ọkùnrin ará Beti-Ṣemeṣi béèrè pé, “Ta ni ó le è dúró ní iwájú Olúwa Ọlọ́run mímọ́ yìí? Ọ̀dọ̀ ta ni àpótí ẹ̀rí Olúwa yóò gbà gòkè lọ láti ibí yìí?”
njalo abantu baseBhethi-Shemeshi babuza bathi, “Pho ngubani ongema phambi kukaThixo, uNkulunkulu lo ongcwele na?”
21 Nígbà náà, wọ́n rán àwọn ìránṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí Kiriati-Jearimu wí pé, “Àwọn Filistini ti dá àpótí ẹ̀rí Olúwa padà. Ẹ sọ̀kalẹ̀ wá, kí ẹ gbé e gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ yín.”
Emva kwalokho bathumela izithunywa ebantwini baseKhiriyathi-Jeyarimi, besithi, “AmaFilistiya aselibuyisile ibhokisi lesivumelwano sikaThixo. Wozani lizolithatha lilise endaweni yenu.”

< 1 Samuel 6 >