< 1 Samuel 6 >

1 Nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa sì ti wà ní agbègbè Filistini fún oṣù méje,
The people of Philistia kept God’s sacred chest in their area for seven months.
2 àwọn ará Filistini pe àwọn àlùfáà, àti àwọn alásọtẹ́lẹ̀, wọ́n sì sọ pé, “Kí ni kí a ṣe pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Olúwa? Sọ fún wa bí àwa yóò ti dá a padà sí ààyè rẹ̀.”
Then they summoned their priests and their (diviners/men who practice rituals to find out what would happen in the future). They asked them, “What should we do with the sacred chest of Yahweh? Tell us how we should send it back to its own land.”
3 Wọ́n dáhùn wí pé, “Tí ẹ bá dá àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ti àwọn ọmọ Israẹli padà, ẹ má ṣe dá a padà ní òfìfo, ṣùgbọ́n bí ó ti wù kí ó rí, ẹ fún un ní ẹbọ ẹ̀bi. Nígbà náà ni a ó mú un yín láradá, ẹ̀yin yóò sì mọ ìdí tí ọwọ́ rẹ̀ kò fi tí ì kúrò lára yín.”
Those men replied, “Send with it an offering [to show Yahweh that you know that you are] guilty [for having captured the chest], in order that the plague will stop. If you do that, and then if you are healed, you will know that Yahweh is the one who caused you to experience the plague.”
4 Àwọn ará Filistini béèrè pé, “Irú ẹbọ ẹ̀bi wo ni kí a fi fún un?” Wọ́n dáhùn, “Wúrà oníkókó márùn-ún àti eku ẹ̀lírí wúrà márùn-ún, gẹ́gẹ́ bí iye àwọn aláṣẹ Filistini, nítorí àjàkálẹ̀-ààrùn kan náà ni ó kọlù yín àti olórí yín.
The people of Philistia asked, “What kind of offering should we send?” The men replied, “Make five gold models of the tumors on your skin, and five gold models of rats. Make five of each because that is the same number as the number of your kings, and because the plague has struck both you people and your five kings.
5 Mọ àwòrán ààrùn oníkókó àti ti eku ẹ̀lírí yin tí ó ń ba orílẹ̀-èdè náà jẹ́ kí o sì bu ọlá fún Ọlọ́run Israẹli. Bóyá yóò gbé ọwọ́ rẹ̀ kúrò lára yín, lára ọlọ́run yín àti lára ilẹ̀ yín.
Make models that represent the rats and the tumors that are ruining your land. Make them in order to honor the god of the Israeli people. If you do that, perhaps he will stop punishing [IDM] you, and your gods, and your land.
6 Kí ni ó dé tí ẹ fi ń sé ọkàn yín le gẹ́gẹ́ bí àwọn ará Ejibiti àti Farao ti ṣe? Nígbà tí ó fi ọwọ́ líle mú wọn, ṣé wọn kò rán àwọn ọmọ Israẹli jáde kí wọn kí ó lè lọ ní ọ̀nà wọn?
Do not be [RHQ] stubborn [IDM] like the Egyptians and their king were. [They did not do what the Israelis’ god told them to do, so he punished them]. After the Israelis’ god finished punishing them very severely, they were glad to allow the Israelis to leave their country [RHQ].
7 “Nísinsin yìí ẹ pèsè kẹ̀kẹ́ ẹrù tuntun sílẹ̀, pẹ̀lú màlúù méjì tí ó ti fi ọmú fún ọmọ, èyí tí a kò tí ì gba àjàgà sí ọrùn rí, kí ẹ sì so ó mọ́ kẹ̀kẹ́ náà, kí ẹ sì mú ọmọ wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn wá sí ilé láti so.
“So you must build a new cart. Then get two cows that have very recently given birth to calves. They must be cows that have never been hitched to a cart [MTY]. Hitch those cows to the new cart, and take the calves away from their mothers.
8 Kí ẹ sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa sí orí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti kí ẹ̀yin sì kó àwọn ohun èlò wúrà tí ẹ̀yin fi fún un gẹ́gẹ́ bí ti ẹbọ ẹ̀bi sí inú àpótí ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, kí ẹ̀yin kí ó sì rán an lọ,
Put the Israelis’ god’s sacred chest on the cart. Also put in the cart the five gold models of the tumors on your skin and the five gold models of rats. Put them in a small box alongside the sacred chest. They will be an offering to show that you know that you deserved to be punished [for capturing the sacred chest]. Then send [the cows] down the road, [pulling] the cart.
9 ṣùgbọ́n kí ẹ sì máa ṣọ́ ọ. Tí ó bá ń lọ sí ilẹ̀ rẹ̀, ìlú rẹ̀, níhà Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà ni Olúwa mú àjálù ńlá yìí bá wa. Ṣùgbọ́n bí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà náà ni a mọ̀ pé kì í ṣe ọwọ́ rẹ̀ ni ó kọlù wá, ṣùgbọ́n ó wá bẹ́ẹ̀ ni.”
[Watch the cart as the cows pull it]. If they pull it to Beth-Shemesh [town] in Israel, we will know that it was the Israelis’ god who caused us to experience this plague. But if they do not take it there, we will know that it was not the god [MTY] of the Israelis who has punished us. We will know that it just happened.”
10 Nígbà náà ni wọ́n ṣe èyí. Wọ́n mú abo màlúù méjì, tí ń fi ọmú fún ọmọ, wọn mọ́ ara, wọ́n sì dè é ni ilé kẹ̀kẹ́ ẹrù, wọn sì so àwọn ọmọ wọn mọ́lẹ̀ ni ilé.
So the people did what the priests and men who predicted what would happen in the future told them to do. They [made] a cart [and] hitched two cows to it. They took the calves from their mothers.
11 Wọ́n gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa lé orí kẹ̀kẹ́ ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ni àpótí tí eku ẹ̀lírí wúrà àti àwòrán ààrùn oníkókó wà níbẹ̀.
They put in the cart Yahweh’s sacred chest and the box with the models of the gold rats and the tumors.
12 Nígbà náà; àwọn màlúù lọ tààrà sí ìhà Beti-Ṣemeṣi, wọ́n ń lọ tààrà, wọ́n sì ń dún bí wọ́n ti ń lọ. Wọn kò yà sí ọ̀tún tàbí yà sí òsì. Àwọn aláṣẹ Filistini tẹ̀lé wọn títí dé ibodè Beti-Ṣemeṣi.
Then the cows started walking, and they went straight toward Beth-Shemesh. They stayed on the road, and were mooing all the time. They did not turn to the left or to the right. The five kings of the Philistia area followed the cows until they reached the edge of Beth-Shemesh.
13 Nísinsin yìí, àwọn ará Beti-Ṣemeṣi ń kórè jéró wọn ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, nígbà tí wọ́n wo òkè tí wọ́n sì rí àpótí ẹ̀rí Olúwa, wọ́n yọ̀ níwájú rẹ̀.
At that time, the people of Beth-Shemesh were harvesting wheat in the valley [outside the city]. [When the cows came along the road], they looked up and saw the sacred chest. They were extremely happy to see it.
14 Kẹ̀kẹ́ ẹrù wá sí pápá Joṣua ti Beti-Ṣemeṣi, níbẹ̀ ni ó ti dúró ní ẹ̀bá àpáta ńlá kan. Àwọn ènìyàn gé igi ara kẹ̀kẹ́ ẹrù sí wẹ́wẹ́ wọ́n sì fi àwọn màlúù náà rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
The cows pulled the cart into the field of a man named Joshua, and they stopped alongside a large rock. Several men from the tribe of Levi lifted from the cart the sacred chest and the box containing the gold models of the rats and the tumors, and they put them all on the large rock. Then the people smashed the cart and kindled a fire with the wood [from which the cart had been made]. They slaughtered the cows and burned their bodies/carcasses on the fire to be an offering for Yahweh that would be completely burned. That day the people of Beth-Shemesh offered to Yahweh [many] sacrifices that were completely burned, and [other] sacrifices.
15 Àwọn ará Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ìsàlẹ̀ pẹ̀lú àpótí tí ohun èlò wúrà wà níbẹ̀, wọ́n sì gbé wọn ka orí àpáta ńlá náà. Ní ọjọ́ náà, àwọn ará Beti-Ṣemeṣi rú ẹbọ sísun, wọ́n sì ṣe ìrúbọ sí Olúwa.
16 Àwọn aláṣẹ Filistini márààrún rí gbogbo èyí, wọ́n sì padà ní ọjọ́ náà sí Ekroni.
The five kings from the Philistia area watched all this, and then they returned to Ekron, that same day.
17 Èyí ni kókó wúrà tí àwọn Filistini fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀bi ọ̀kọ̀ọ̀kan fún Aṣdodu, ọ̀kan ti Gasa, ọ̀kan ti Aṣkeloni, ọ̀kan ti Gati, ọ̀kan ti Ekroni.
The five gold models of tumors that they sent to be an offering to Yahweh to show that they knew that they deserved to be punished were gifts from [those five kings who were rulers of] Ashdod, Gaza, Ashkelon, Gath, and Ekron [cities].
18 Wúrà eku ẹ̀lírí jẹ́ iye ìlú tí àwọn aláṣẹ Filistini márààrún ti wá, ìlú olódi pẹ̀lú ìletò wọn. Àpáta ńlá náà, lórí èyí tí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa lé jẹ́ ẹ̀rí títí di òní ní oko Joṣua ará Beti-Ṣemeṣi.
The models of the five gold rats were gifts from the people of those five cities and the surrounding towns. The large rock at Beth-Shemesh, on which the [men of the tribe of Levi] set the sacred chest, is still there in the field that belonged to Joshua. When people see it, they remember [what happened there].
19 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kọlu díẹ̀ lára àwọn ọkùnrin Beti-Ṣemeṣi, ó pa àádọ́rin wọn, nítorí wọ́n ti wo inú àpótí ẹ̀rí Olúwa. Àwọn ènìyàn ṣọ̀fọ̀ nítorí àjálù ńlá tí Olúwa fi bá ọ̀pọ̀ wọn jà.
But seventy men from Beth-Shemesh looked into Yahweh’s sacred chest, and because of that, Yahweh caused them to die. Then the people mourned very much because Yahweh punished [IDM] those men like that.
20 Àwọn ọkùnrin ará Beti-Ṣemeṣi béèrè pé, “Ta ni ó le è dúró ní iwájú Olúwa Ọlọ́run mímọ́ yìí? Ọ̀dọ̀ ta ni àpótí ẹ̀rí Olúwa yóò gbà gòkè lọ láti ibí yìí?”
They said, “No one [RHQ] can (resist the power of/stand in the presence of) Yahweh, our holy God, [and remain alive]! Where can we send the sacred chest?”
21 Nígbà náà, wọ́n rán àwọn ìránṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí Kiriati-Jearimu wí pé, “Àwọn Filistini ti dá àpótí ẹ̀rí Olúwa padà. Ẹ sọ̀kalẹ̀ wá, kí ẹ gbé e gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ yín.”
They sent messengers to the people of Kiriath-Jearim [city] to tell them, “The people of Philistia have returned Yahweh’s sacred chest to us! Come here and take it away!”

< 1 Samuel 6 >