< 1 Samuel 4 >

1 Ọ̀rọ̀ Samuẹli tọ gbogbo àwọn ọmọ Israẹli wá. Nísinsin yìí àwọn ọmọ Israẹli jáde láti lọ bá àwọn Filistini jà. Àwọn ọmọ Israẹli sì pàgọ́ sí Ebeneseri àti àwọn Filistini ní Afeki.
I słowo Samuela dotarło do całego Izraela. W tym czasie Izrael wyruszył przeciwko Filistynom do walki i rozbili obóz koło Ebenezer. Filistyni zaś rozbili obóz w Afek.
2 Àwọn Filistini mú ogun wọn sọ̀kalẹ̀ láti pàdé Israẹli, nígbà tí ogun náà bẹ̀rẹ̀, àwọn Filistini ṣẹ́gun Israẹli wọ́n pa ẹgbàajì ọkùnrin nínú ogun náà.
Wtedy Filistyni ustawili się w szyku bojowym przeciwko Izraelowi. Gdy walka rozgorzała, Izrael został pobity przez Filistynów, którzy zabili na polu bitwy około czterech tysięcy ludzi.
3 Nígbà tí àwọn ọmọ-ogun náà padà sí ibùdó, àwọn àgbàgbà Israẹli sì béèrè pé, “Èéṣe ti Olúwa fi mú kí àwọn Filistini ṣẹ́gun wa lónìí? Ẹ jẹ́ kí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa láti Ṣilo wá, kí ó ba à le lọ pẹ̀lú wa kí ó sì gbà wá là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa.”
I kiedy lud wrócił do obozu, starsi Izraela powiedzieli: Dlaczego PAN pobił nas dziś przed Filistynami? Sprowadźmy do siebie z Szilo arkę przymierza PANA, by weszła między nas i wybawiła nas z rąk naszych wrogów.
4 Nítorí náà a rán àwọn ènìyàn lọ sí Ṣilo, wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wá, ẹni tí ń wà láàrín àwọn Kérúbù àti àwọn ọmọ Eli méjèèjì Hofini àti Finehasi wà níbẹ̀ pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.
Posłał więc lud do Szilo, by sprowadzić stamtąd arkę przymierza PANA zastępów, który zasiada między cherubinami. Byli tam też z arką przymierza Boga dwaj synowie Helego, Chofni i Pinchas.
5 Nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ibùdó, gbogbo àwọn ọmọ Israẹli sì dìde láti kígbe tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ sì mì tìtì.
A gdy arka przymierza PANA przybyła do obozu, cały Izrael zawołał wielkim głosem, że aż ziemia zadrżała.
6 Ní ìgbà tí àwọn Filistini gbọ́ ariwo náà wọ́n béèrè pé, “Kí ni gbogbo ariwo yìí ní ibùdó Heberu?” Nígbà tí wọ́n mọ̀ wí pé àpótí ẹ̀rí Olúwa ti wá sí ibùdó,
Kiedy Filistyni usłyszeli ten okrzyk, pytali: Cóż to za wielki okrzyk w obozie Hebrajczyków? I dowiedzieli się, że arka PANA przybyła do obozu.
7 àwọn Filistini sì bẹ̀rù pé, Ọlọ́run kékeré ti wọ ibùdó, wọ́n wí pé, “A wọ wàhálà, irú èyí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí.
I Filistyni zlękli się, gdyż mówiono: Bóg przybył do ich obozu. I mówili: Biada nam, bo czegoś takiego nigdy przedtem nie było.
8 Àwa gbé! Ta ni yóò gbà wá kúrò lọ́wọ́ Ọlọ́run alágbára yìí? Àwọn ni Ọlọ́run tí ó fi ìpọ́njú pa àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo àjàkálẹ̀-ààrùn ní aginjù.
Biada nam! Któż nas wybawi z rąk tych potężnych bogów? To są ci bogowie, którzy porazili Egipt wszelką plagą na pustyni.
9 Ẹ jẹ́ alágbára Filistini, ẹ ṣe bí ọkùnrin, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ̀yin yóò di ẹrú àwọn Heberu, bí wọ́n ti jẹ́ sí i yín. Ẹ jẹ́ alágbára ọkùnrin, kí ẹ sì jagun!”
Umacniajcie się i bądźcie mężni, o Filistyni, abyście nie służyli Hebrajczykom, tak jak [oni] wam służyli. Bądźcie więc mężni i walczcie!
10 Nígbà náà àwọn Filistini jà, wọ́n sì ṣẹ́gun àwọn Israẹli olúkúlùkù sì sá padà sínú àgọ́ rẹ̀, wọ́n pa ọ̀pọ̀ ènìyàn, àwọn ará Israẹli tí ó kú sí ogun sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọmọ-ogun orí ilẹ̀.
Wtedy Filistyni walczyli, a Izrael został pokonany i każdy uciekał do swego namiotu. Była to wielka klęska, gdyż poległo trzydzieści tysięcy z piechoty Izraela.
11 Wọ́n gba àpótí ẹ̀rí Olúwa, àwọn ọmọkùnrin Eli méjèèjì sì kú, Hofini àti Finehasi.
I arka Boga została zabrana, a dwaj synowie Heliego, Chofni i Pinchas, polegli.
12 Lọ́jọ́ kan náà tí ará Benjamini kan sá wá láti ojú ogun tí ó sì lọ sí Ṣilo, aṣọ rẹ̀ sì fàya pẹ̀lú eruku lórí rẹ̀.
A pewien Beniaminita uciekł z bitwy i przyszedł do Szilo tego samego dnia w podartej szacie i z prochem na swojej głowie.
13 Nígbà tí ó sì dé, Eli sì jókòó sórí àga rẹ̀ ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà, ó ń wò, ọkàn rẹ̀ kò balẹ̀ nítorí àpótí ẹ̀rí Olúwa. Nígbà tí ọkùnrin náà wọ ìlú tí ó sì sọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀, gbogbo ìlú bẹ̀rẹ̀ sí sọkún.
Kiedy przyszedł, oto Heli siedział na krześle przy drodze i wyczekiwał, bo jego serce drżało o arkę Boga. Gdy ten człowiek przyszedł do miasta i opowiedział o tym, całe miasto podniosło krzyk.
14 Eli gbọ́ ìró ohùn ẹkún náà ó sì béèrè pé, “Kí ni ìtumọ̀ ariwo yìí?” Ọkùnrin náà sì sáré tọ Eli wá
I kiedy Heli usłyszał ten krzyk, powiedział: Cóż to za zgiełk? A ten człowiek śpiesznie przyszedł i oznajmił o tym Heliemu.
15 Eli sì di ẹni méjìdínlọ́gọ́run ọdún, tí ojú rẹ̀ di bàìbàì, kò sì ríran mọ́.
A Heli miał już dziewięćdziesiąt osiem lat i jego oczy tak zasłabły, że nie mógł [nic] widzieć.
16 Ọkùnrin náà sọ fún Eli, “Mo ṣẹ̀ṣẹ̀ dé láti ibi ogun náà ni: mo sá láti ibi ogun náà wá lónìí.” Eli sì béèrè pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀ ọmọ mi?”
Człowiek ten powiedział do Heliego: Przychodzę z bitwy, bo dziś z niej uciekłem. On zaś zapytał: Cóż [tam] się stało, mój synu?
17 Ọkùnrin tí ó mú ìròyìn náà wá dáhùn pé, “Israẹli sá níwájú àwọn Filistini, ìṣubú àwọn ọmọ-ogun náà sì pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ méjèèjì, Hofini àti Finehasi, wọ́n kú, wọ́n sì ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ.”
Posłaniec odpowiedział: Izrael uciekł przed Filistynami i lud poniósł wielką klęskę. Zginęli także twoi dwaj synowie, Chofni i Pinchas, a arka Boga została zabrana.
18 Nígbà tí ó dárúkọ àpótí ẹ̀rí Olúwa, Eli sì ṣubú sẹ́yìn kúrò lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ bodè, ọrùn rẹ̀ ṣẹ́, ó sì kú, nítorí tí ó jẹ́ arúgbó ọkùnrin, ó sì tóbi, ó ti darí àwọn Israẹli fún ogójì ọdún.
A gdy wspomniał o arce Boga, [Heli] spadł z krzesła na wznak obok bramy, złamał sobie kark i umarł. [Był] bowiem człowiekiem starym i ociężałym, a sądził Izraela przez czterdzieści lat.
19 Aya ọmọ rẹ̀, ìyàwó Finehasi, ó lóyún ó súnmọ́ àkókò àti bí. Nígbà tí ó gbọ́ ìròyìn náà wí pé wọ́n ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ àti wí pé baba ọkọ rẹ̀ àti ọkọ rẹ̀ ti kú, ó rọbí ó sì bímọ, ó sì borí ìrora ìrọbí náà.
Jego synowa, żona Pinchasa, była brzemienna i bliska porodu, a gdy usłyszała wieści o zabraniu arki Bożej i o śmierci jej teścia i męża, skuliła się i urodziła. Dosięgły ją bowiem bóle [porodowe].
20 Bí ó ti ń kú lọ, obìnrin tí ó dúró tì í wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù; nítorí o ti bí ọmọ ọkùnrin.” Ṣùgbọ́n kò sọ̀rọ̀ tàbí kọ ibi ara sí i.
Gdy umierała, [kobiety], które były przy niej, powiedziały: Nie bój się, bo urodziłaś syna. Lecz ona nic nie odpowiedziała ani nie zwróciła [na to] uwagi.
21 Ó sì pe ọmọ náà ní Ikabodu, wí pé, “Kò sí ògo fún Israẹli mọ́,” nítorí tí wọ́n ti gba àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run àti ikú baba ọkọ rẹ̀ àti ti ọkọ rẹ̀.
I nazwała dziecko Ikabod, mówiąc: Odeszła chwała od Izraela – z powodu zabrania arki Boga i z powodu jej teścia i męża.
22 Ó si wí pé, “Ògo kò sí fún Israẹli mọ́, nítorí ti a ti gbá àpótí Ọlọ́run.”
Dlatego powiedziała: Odeszła chwała od Izraela, gdyż arka Boga została zabrana.

< 1 Samuel 4 >