< 1 Samuel 4 >
1 Ọ̀rọ̀ Samuẹli tọ gbogbo àwọn ọmọ Israẹli wá. Nísinsin yìí àwọn ọmọ Israẹli jáde láti lọ bá àwọn Filistini jà. Àwọn ọmọ Israẹli sì pàgọ́ sí Ebeneseri àti àwọn Filistini ní Afeki.
And it was doon in tho daies Filisteis camen to gidere in to batel; for Israel yede out ayens Filisteis in to batel, and settiden tentis bisidis the stoon of help. Forsothe Filisteis camen in to Aphet,
2 Àwọn Filistini mú ogun wọn sọ̀kalẹ̀ láti pàdé Israẹli, nígbà tí ogun náà bẹ̀rẹ̀, àwọn Filistini ṣẹ́gun Israẹli wọ́n pa ẹgbàajì ọkùnrin nínú ogun náà.
and maden redi scheltrun ayens Israel. Sotheli whanne the batel was bigunnun, Israel turned backis to Filisteis; and as foure thousynde of men weren slayn in that batel `euery where bi feeldis;
3 Nígbà tí àwọn ọmọ-ogun náà padà sí ibùdó, àwọn àgbàgbà Israẹli sì béèrè pé, “Èéṣe ti Olúwa fi mú kí àwọn Filistini ṣẹ́gun wa lónìí? Ẹ jẹ́ kí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa láti Ṣilo wá, kí ó ba à le lọ pẹ̀lú wa kí ó sì gbà wá là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa.”
and the puple of Israel turnede ayen to tentis. And the grettere men in birthe of Israel seiden, Whi hath the Lord smyte vs to dai bifore Filisteis? Brynge we to vs fro Silo the arke of boond of pees of the Lord, and come it in to the myddis of vs, that it saue vs fro the hond of oure enemyes.
4 Nítorí náà a rán àwọn ènìyàn lọ sí Ṣilo, wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wá, ẹni tí ń wà láàrín àwọn Kérúbù àti àwọn ọmọ Eli méjèèjì Hofini àti Finehasi wà níbẹ̀ pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.
Therfor the puple sente in to Silo, and thei token fro thennus the arke of boond of pees of the Lord of oostis, `that sat on cherubyn. And Ophym and Fynees, twei sones of Heli, weren with the arke of boond of pees of the Lord.
5 Nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ibùdó, gbogbo àwọn ọmọ Israẹli sì dìde láti kígbe tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ sì mì tìtì.
And whanne the arke of boond of pees of the Lord hadde come in to the castels, al Israel criede with grete cry, and the erthe sownede.
6 Ní ìgbà tí àwọn Filistini gbọ́ ariwo náà wọ́n béèrè pé, “Kí ni gbogbo ariwo yìí ní ibùdó Heberu?” Nígbà tí wọ́n mọ̀ wí pé àpótí ẹ̀rí Olúwa ti wá sí ibùdó,
And Filisteis herden the vois of cry, and seiden, What is this vois of greet cry in the castels of Ebrews? And thei knewen, that the arke of boond of pees of the Lord hadde come in to castels.
7 àwọn Filistini sì bẹ̀rù pé, Ọlọ́run kékeré ti wọ ibùdó, wọ́n wí pé, “A wọ wàhálà, irú èyí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí.
And Filisteis dredden, and seiden, God is come in to `the castels; and thei weiliden, and seiden, Wo to vs!
8 Àwa gbé! Ta ni yóò gbà wá kúrò lọ́wọ́ Ọlọ́run alágbára yìí? Àwọn ni Ọlọ́run tí ó fi ìpọ́njú pa àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo àjàkálẹ̀-ààrùn ní aginjù.
for so greet ful ioiyng was not yistirdai, and the thridde day passid; wo to vs! who schal kepe vs fro the hond of `these hiye goddis? these ben the goddis, that smytiden Egipt with al veniaunce in deseert.
9 Ẹ jẹ́ alágbára Filistini, ẹ ṣe bí ọkùnrin, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ̀yin yóò di ẹrú àwọn Heberu, bí wọ́n ti jẹ́ sí i yín. Ẹ jẹ́ alágbára ọkùnrin, kí ẹ sì jagun!”
Filisteis, be ye coumfortid, and be ye men, serue ye not Ebrews, as thei serueden vs; be ye coumfortid, and fiyte ye.
10 Nígbà náà àwọn Filistini jà, wọ́n sì ṣẹ́gun àwọn Israẹli olúkúlùkù sì sá padà sínú àgọ́ rẹ̀, wọ́n pa ọ̀pọ̀ ènìyàn, àwọn ará Israẹli tí ó kú sí ogun sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọmọ-ogun orí ilẹ̀.
Therfor Filisteis fouyten, and Israel was slayn, and ech man flei in to his tabernacle; and a ful greet veniaunce was maad, and thretti thousynde of foot men of Israel felden doun.
11 Wọ́n gba àpótí ẹ̀rí Olúwa, àwọn ọmọkùnrin Eli méjèèjì sì kú, Hofini àti Finehasi.
And the arke of God was takun; and, twei sones of Heli, Ophym and Fynees, weren deed.
12 Lọ́jọ́ kan náà tí ará Benjamini kan sá wá láti ojú ogun tí ó sì lọ sí Ṣilo, aṣọ rẹ̀ sì fàya pẹ̀lú eruku lórí rẹ̀.
Sotheli a man of Beniamyn ran fro the scheltrun, and cam in to Silo in that dai, with his cloth torent and his heed bispreynt with dust; and whanne he was comen,
13 Nígbà tí ó sì dé, Eli sì jókòó sórí àga rẹ̀ ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà, ó ń wò, ọkàn rẹ̀ kò balẹ̀ nítorí àpótí ẹ̀rí Olúwa. Nígbà tí ọkùnrin náà wọ ìlú tí ó sì sọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀, gbogbo ìlú bẹ̀rẹ̀ sí sọkún.
Heli sat `on an hiye seete, `and bihelde ayens the weie; for his herte was dredyng for the arke of the Lord. Sotheli aftir that thilke man entride, he telde to the citee, and al the citee yellide.
14 Eli gbọ́ ìró ohùn ẹkún náà ó sì béèrè pé, “Kí ni ìtumọ̀ ariwo yìí?” Ọkùnrin náà sì sáré tọ Eli wá
And Heli herde the soun of cry, and seide, What is this sown of this noise? And he hastide, and cam, and telde to Heli.
15 Eli sì di ẹni méjìdínlọ́gọ́run ọdún, tí ojú rẹ̀ di bàìbàì, kò sì ríran mọ́.
Forsothe Heli was of foure score yeer and eiytene, and hise iyen dasiwiden, and he myyte not se.
16 Ọkùnrin náà sọ fún Eli, “Mo ṣẹ̀ṣẹ̀ dé láti ibi ogun náà ni: mo sá láti ibi ogun náà wá lónìí.” Eli sì béèrè pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀ ọmọ mi?”
And he seide to Heli, Y am that cam fro batel, and Y am that flei to dai fro the scheltrun. To whom Ely seide, My sone, what is doon?
17 Ọkùnrin tí ó mú ìròyìn náà wá dáhùn pé, “Israẹli sá níwájú àwọn Filistini, ìṣubú àwọn ọmọ-ogun náà sì pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ méjèèjì, Hofini àti Finehasi, wọ́n kú, wọ́n sì ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ.”
Forsothe he that telde answeride, and seide, Israel flei bifor Filisteis, and a greet fal is maad in the puple; ferthermore and thi twey sones, Ophym and Fynees, ben deed, and the arke of God is takun.
18 Nígbà tí ó dárúkọ àpótí ẹ̀rí Olúwa, Eli sì ṣubú sẹ́yìn kúrò lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ bodè, ọrùn rẹ̀ ṣẹ́, ó sì kú, nítorí tí ó jẹ́ arúgbó ọkùnrin, ó sì tóbi, ó ti darí àwọn Israẹli fún ogójì ọdún.
And whanne he hadde nemyd the arke of God, Hely felde fro `the hiye seete bacward bisidis the dore, and `was deed; for the nollis weren brokun. For he was an eld man, and of greet age; and he demyde Israel bi fourti yeer.
19 Aya ọmọ rẹ̀, ìyàwó Finehasi, ó lóyún ó súnmọ́ àkókò àti bí. Nígbà tí ó gbọ́ ìròyìn náà wí pé wọ́n ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ àti wí pé baba ọkọ rẹ̀ àti ọkọ rẹ̀ ti kú, ó rọbí ó sì bímọ, ó sì borí ìrora ìrọbí náà.
Forsothe his douyter in lawe, `the wijf of Finees, was with childe, and niy the child bering; and whanne `the message was herd that the arke of God was takun, and that hir fadir in lawe was deed, and hir hosebonde, sche bowide hir silf, and childide; for sodeyn sorewis felden in to hir.
20 Bí ó ti ń kú lọ, obìnrin tí ó dúró tì í wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù; nítorí o ti bí ọmọ ọkùnrin.” Ṣùgbọ́n kò sọ̀rọ̀ tàbí kọ ibi ara sí i.
Sotheli in that moment of hir deeth, wymmen that stoden aboute hir, seiden to hir, Drede thou not, for thou hast childid a sone. And sche answeride not to hem, for nether `sche perseyuede.
21 Ó sì pe ọmọ náà ní Ikabodu, wí pé, “Kò sí ògo fún Israẹli mọ́,” nítorí tí wọ́n ti gba àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run àti ikú baba ọkọ rẹ̀ àti ti ọkọ rẹ̀.
And sche clepide the child Ichaboth, and seide, The glorie of the Lord is translatid fro Israel, for the arke of God is takun; and for hir fadir in lawe and for hir hosebonde sche seide,
22 Ó si wí pé, “Ògo kò sí fún Israẹli mọ́, nítorí ti a ti gbá àpótí Ọlọ́run.”
The glorie of God is translatid fro Israel, for the arke of God is takun.