< 1 Samuel 4 >

1 Ọ̀rọ̀ Samuẹli tọ gbogbo àwọn ọmọ Israẹli wá. Nísinsin yìí àwọn ọmọ Israẹli jáde láti lọ bá àwọn Filistini jà. Àwọn ọmọ Israẹli sì pàgọ́ sí Ebeneseri àti àwọn Filistini ní Afeki.
And so it was, when the word of Samuel had reached all Israel, that Israel went forth to meet the Philistines in battle, and they encamped near Eben-ezer, while, the Philistines, encamped in Aphek.
2 Àwọn Filistini mú ogun wọn sọ̀kalẹ̀ láti pàdé Israẹli, nígbà tí ogun náà bẹ̀rẹ̀, àwọn Filistini ṣẹ́gun Israẹli wọ́n pa ẹgbàajì ọkùnrin nínú ogun náà.
And the Philistines set themselves in array to meet Israel, and, when the battle spread, then was Israel smitten before the Philistines, —and there were slain of the army in the field about four thousand men.
3 Nígbà tí àwọn ọmọ-ogun náà padà sí ibùdó, àwọn àgbàgbà Israẹli sì béèrè pé, “Èéṣe ti Olúwa fi mú kí àwọn Filistini ṣẹ́gun wa lónìí? Ẹ jẹ́ kí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa láti Ṣilo wá, kí ó ba à le lọ pẹ̀lú wa kí ó sì gbà wá là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa.”
And, when the people came into the camp, the elders of Israel said, Wherefore hath Yahweh smitten us to-day, before the Philistines? Let us fetch unto us, out of Shiloh, the ark of the covenant of Yahweh, that, when it cometh into our midst, it may save us out of the hand of our enemies.
4 Nítorí náà a rán àwọn ènìyàn lọ sí Ṣilo, wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wá, ẹni tí ń wà láàrín àwọn Kérúbù àti àwọn ọmọ Eli méjèèjì Hofini àti Finehasi wà níbẹ̀ pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.
So the people sent to Shiloh, and bare from thence the ark of the covenant of Yahweh of hosts, who inhabiteth the cherubim, —and, there, were the two sons of Eli, with the ark of the covenant of God, namely, Hophni and Phinehas.
5 Nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ibùdó, gbogbo àwọn ọmọ Israẹli sì dìde láti kígbe tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ sì mì tìtì.
And so it was, when the ark of the covenant of Yahweh came into the camp, that all Israel brake out into a loud shout of joy, —so that the earth rang again.
6 Ní ìgbà tí àwọn Filistini gbọ́ ariwo náà wọ́n béèrè pé, “Kí ni gbogbo ariwo yìí ní ibùdó Heberu?” Nígbà tí wọ́n mọ̀ wí pé àpótí ẹ̀rí Olúwa ti wá sí ibùdó,
And, when the Philistines heard the noise of the shout, they said—What meaneth the noise of this loud shout of joy in the camp of the Hebrews? And they learned that, the ark of Yahweh, had come into the camp.
7 àwọn Filistini sì bẹ̀rù pé, Ọlọ́run kékeré ti wọ ibùdó, wọ́n wí pé, “A wọ wàhálà, irú èyí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí.
And the Philistines were afraid, for they said—God hath come into the camp. And they said—Woe to us! for there hath not happened the like of this, heretofore.
8 Àwa gbé! Ta ni yóò gbà wá kúrò lọ́wọ́ Ọlọ́run alágbára yìí? Àwọn ni Ọlọ́run tí ó fi ìpọ́njú pa àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo àjàkálẹ̀-ààrùn ní aginjù.
Woe to us! Who shall rescue us out of the hand of these majestic gods? These, are the gods, who smote the Egyptians with all manner of smiting in the desert!
9 Ẹ jẹ́ alágbára Filistini, ẹ ṣe bí ọkùnrin, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ̀yin yóò di ẹrú àwọn Heberu, bí wọ́n ti jẹ́ sí i yín. Ẹ jẹ́ alágbára ọkùnrin, kí ẹ sì jagun!”
Take courage, and quit yourselves like men, ye Philistines, lest ye come into bondage to the Hebrews, as they have been in bondage unto you, —therefore must ye quit yourselves like men, and fight.
10 Nígbà náà àwọn Filistini jà, wọ́n sì ṣẹ́gun àwọn Israẹli olúkúlùkù sì sá padà sínú àgọ́ rẹ̀, wọ́n pa ọ̀pọ̀ ènìyàn, àwọn ará Israẹli tí ó kú sí ogun sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọmọ-ogun orí ilẹ̀.
So the Philistines fought, and Israel was smitten, and they fled every man to his home; and the slaughter became exceeding great, —and there fell of Israel—thirty thousand footmen.
11 Wọ́n gba àpótí ẹ̀rí Olúwa, àwọn ọmọkùnrin Eli méjèèjì sì kú, Hofini àti Finehasi.
And, the ark of God, was taken, —and, the two sons of Eli, were slain, Hophni and Phinehas.
12 Lọ́jọ́ kan náà tí ará Benjamini kan sá wá láti ojú ogun tí ó sì lọ sí Ṣilo, aṣọ rẹ̀ sì fàya pẹ̀lú eruku lórí rẹ̀.
And there ran a man of Benjamin out of the army, and entered Shiloh on the same day, —with his clothes rent, and with earth upon his head.
13 Nígbà tí ó sì dé, Eli sì jókòó sórí àga rẹ̀ ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà, ó ń wò, ọkàn rẹ̀ kò balẹ̀ nítorí àpótí ẹ̀rí Olúwa. Nígbà tí ọkùnrin náà wọ ìlú tí ó sì sọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀, gbogbo ìlú bẹ̀rẹ̀ sí sọkún.
And, when he entered, lo! Eli was sitting upon his chair, by the wayside, watching, for his heart was trembling for the ark of God, —and, the man, entered to tell the news in the city, and all the city made outcry.
14 Eli gbọ́ ìró ohùn ẹkún náà ó sì béèrè pé, “Kí ni ìtumọ̀ ariwo yìí?” Ọkùnrin náà sì sáré tọ Eli wá
And, when Eli heard the noise of the outcry, he said—What meaneth the noise of this tumult? And, the man, hasted, and came, and told Eli.
15 Eli sì di ẹni méjìdínlọ́gọ́run ọdún, tí ojú rẹ̀ di bàìbàì, kò sì ríran mọ́.
Now, Eli, was ninety-eight years old; and his eyes were fixed, that he could not see.
16 Ọkùnrin náà sọ fún Eli, “Mo ṣẹ̀ṣẹ̀ dé láti ibi ogun náà ni: mo sá láti ibi ogun náà wá lónìí.” Eli sì béèrè pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀ ọmọ mi?”
So the man said unto Eli, I, am he that came in from the army, yea, I, from the army, fled to-day. And he said—What is the thing that hath happened, my son?
17 Ọkùnrin tí ó mú ìròyìn náà wá dáhùn pé, “Israẹli sá níwájú àwọn Filistini, ìṣubú àwọn ọmọ-ogun náà sì pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ méjèèjì, Hofini àti Finehasi, wọ́n kú, wọ́n sì ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ.”
And the bearer of tidings answered, and said—Israel hath fled before the Philistines, Moreover also, a great smiting, hath taken place among the people, —Moreover also, thy two sons, are slain, Hophni and Phinehas, And, the ark of God, is taken.
18 Nígbà tí ó dárúkọ àpótí ẹ̀rí Olúwa, Eli sì ṣubú sẹ́yìn kúrò lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ bodè, ọrùn rẹ̀ ṣẹ́, ó sì kú, nítorí tí ó jẹ́ arúgbó ọkùnrin, ó sì tóbi, ó ti darí àwọn Israẹli fún ogójì ọdún.
And it came to pass, when he mentioned the ark of God, that he fell from off his seat backwards, at the side of the gate, and his neck brake, and he died, for, old, was the man, and, heavy, —and, he had judged Israel forty years.
19 Aya ọmọ rẹ̀, ìyàwó Finehasi, ó lóyún ó súnmọ́ àkókò àti bí. Nígbà tí ó gbọ́ ìròyìn náà wí pé wọ́n ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ àti wí pé baba ọkọ rẹ̀ àti ọkọ rẹ̀ ti kú, ó rọbí ó sì bímọ, ó sì borí ìrora ìrọbí náà.
Now, his daughter-in-law, wife of Phinehas, was with child, ready to give birth, and, when she heard the tidings, as to the taking of the ark of God, and the death of her father-in-law, and her husband, she bowed herself and gave birth, for her pains had seized her.
20 Bí ó ti ń kú lọ, obìnrin tí ó dúró tì í wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù; nítorí o ti bí ọmọ ọkùnrin.” Ṣùgbọ́n kò sọ̀rọ̀ tàbí kọ ibi ara sí i.
And, about the time of her death, the women that stood by her said: Do not fear, for, to a son, hast thou given birth. But she neither answered nor regarded.
21 Ó sì pe ọmọ náà ní Ikabodu, wí pé, “Kò sí ògo fún Israẹli mọ́,” nítorí tí wọ́n ti gba àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run àti ikú baba ọkọ rẹ̀ àti ti ọkọ rẹ̀.
And she called the boy I-chabod ["Where’s the glory?"]! saying, Exiled is the glory from Israel, —In regard to the taking of the ark of God, and to her father-in-law, and to her husband.
22 Ó si wí pé, “Ògo kò sí fún Israẹli mọ́, nítorí ti a ti gbá àpótí Ọlọ́run.”
So she said—Exiled is the glory from Israel, —For the ark of God hath been taken.

< 1 Samuel 4 >