< 1 Samuel 31 >

1 Nísinsin yìí, àwọn ará Filistini dojú ìjà kọ Israẹli, àwọn ará Israẹli sì sálọ kúrò níwájú wọn, a sì pa ọ̀pọ̀ wọn sí orí òkè Gilboa.
Hagi Filistia vahe'mo'za eza Israeli vahera hara eme huzmante'za zamarotago hazage'za fre'za vu'naze. Hagi rama'a vahera bainati kazinknonteti zamahage'za Gilboa agonafi fri'naze.
2 Àwọn Filistini sì ń lépa Saulu àti àwọn ọmọ rẹ̀ kíkan; àwọn Filistini sì pa Jonatani àti Abinadabu, àti Malikiṣua, àwọn ọmọ Saulu.
Hagi Soli'ene mofavrezaga'amo'za fre'nazanagi, Filistia vahe'mo'za hanaveti'za zamarotago hu'za, mika Soli mofavrezaga'a Jonatanima Abinadabuma Malkisuanena zamahe'naze.
3 Ìjà náà sì burú fún Saulu gidigidi, àwọn tafàtafà si ta á ní ọfà, o sì fi ara pa púpọ̀ lọ́wọ́ àwọn tafàtafà.
Hagi Solina tusi'a ha' hugagintazageno ha'mo'a hanavetigeno, mago'a vahe'mo'za kevea ahazageno ra hazenke eri'ne.
4 Saulu sì wí fún ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Fa idà rẹ yọ, kí ìwọ sì fi gún mi, kí àwọn aláìkọlà wọ̀nyí má ba à wá gún mi, àti kí wọn kí ó má bá à fi mí ṣe ẹlẹ́yà.” Ṣùgbọ́n ẹni tí ó rú ẹ̀rù ìhámọ́ra rẹ̀ kò fẹ́ ṣe bẹ́ẹ̀, nítorí pé ẹ̀rù bà á gidigidi. Nígbà náà ni Saulu mú idà, ó sì ṣubú lù ú.
Ana'ma higeno'a hankoare'ma eneria nera asamino, Ru oku zamavufaga taga osu Filistia vahe'mo'za esu'za kiza zokago ke eme hunante'za nata nenami'za nahe frisagi, bainati kazinka'a erinka nare frio. Hianagi hazama'are erinentea ne'mo'a tusi koro nehuno, ahe ofrine. Ana higeno Soli'a bainati kazima'a erino ana kazinte agra'a taruheno fri'ne.
5 Nígbà tí ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ si rí i pé Saulu kú, òun náà sì fi idà rẹ̀ pa ara rẹ̀, ó sì kú pẹ̀lú rẹ̀.
Hagi Solina hankoare'ma azerinentea ne'mo'ma keama Soli'ma frigeno'a, agranena kazima'a erino agra'a kazinte taruheno Soli'ene fri'na'e.
6 Saulu sì kú, àti àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́ta, àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀, àti gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà.
Ana higeno Solima, 3'a mofavre'ama, ha'zama'are'ma azerinentea ne'ma, miko Israeli sondia vahe'ma Soli'enema vu'naza vahe'mo'za ana zupage fri vagare'naze.
7 Nígbà ti àwọn ọkùnrin Israẹli tí ó wà lápá kejì àfonífojì náà, àti àwọn ẹni tí ó wà lápá kejì Jordani, rí pé àwọn ọkùnrin Israẹli sá, àti pé Saulu àti àwọn ọmọkùnrin rẹ ti kú, wọ́n sì fi ìlú sílẹ̀, wọ́n sì sá, àwọn Filistini sì wá, wọ́n sì jókòó si ìlú wọn.
Hagi Israeli vahe'ma agupofima nemani'za vahe'mo'zane, Jodanima mani'za vu'naza vahe'mo'zama kazama, Israeli sondia vahe'mo'za frazageno, Soli'ene maka mofavre'aramine, hanko'are'ma azerinentea ne'ma, agranema vu'naza vahetamima fri vagarazage'za, kumazamia atre'za frazageno, Filistia vahe'mo'za ana kuma'zmia eme eri'za mani'naze.
8 Ní ọjọ́ kejì, nígbà tí àwọn Filistini dé láti bọ́ nǹkan tí ń bẹ lára àwọn tí ó kù, wọ́n sì rí pé, Saulu àti àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́ta ṣubú ni òkè Gilboa.
Hagi ha'ma haza knamofo anante knazupa Filistia vahe'mo'za Israeli vahe ha'zane kukenazami zoginaku ha'ma hu'nazafi e'za eme kazana, Soli'ene 3'a mofavre'aramina Gilboa agonafi fri'nage'za eme ke'naze.
9 Wọ́n sì gé orí rẹ̀, wọ́n sì bọ ìhámọ́ra rẹ̀, wọ́n sì ránṣẹ́ lọ ilẹ̀ Filistini káàkiri, láti máa sọ ọ́ ní gbangba ni ilé òrìṣà wọn, àti láàrín àwọn ènìyàn.
Hagi zamagra Solina agenopa nekafri'za ha' kukena'a hate'za eri'naze. Hagi anama nehu'za zamagra ke erino vu vahe huntageno mika Filistia kokampine, havi anumzamofo mono hunentafi Soli'ma fri'nea zamofo musenkea ome hu'ama hu'za zmasami'naze.
10 Wọ́n sì fi ìhámọ́ra rẹ̀ sí ilé Aṣtoreti: wọ́n sì kan òkú rẹ̀ mọ́ odi Beti-Ṣani.
Hagi Solina ha'zama'a Astaroti havi a' anumzamofo mono nompi ome nente'za, avufga'a eri'za Bet-seni rankuma keginare ome hanti'naze.
11 Nígbà tí àwọn ará Jabesi Gileadi sì gbọ́ èyí tí àwọn Filistini ṣe sí Saulu.
Hagi Jabes-giliati kumate'ma nemaniza vahe'mo'zama, Filistia vahe'mo'zama Soline mofavre'amokizmima huzmantaza zamofo ke'ma nentahi'za,
12 Gbogbo àwọn ọkùnrin alágbára sì dìde, wọ́n sì fi gbogbo òru náà rìn, wọ́n sì gbé òkú Saulu, àti òkú àwọn ọmọ bíbí rẹ̀ kúrò lára odi Beti-Ṣani, wọ́n sì wá sí Jabesi, wọ́n sì sun wọ́n níbẹ̀.
maka hanave vahe'amo'za kenage Bet-seni kumate vu'za, Soline mofavre'arami zamavufaga ome eri'za, Jabesi kumate eme krerasage'naze.
13 Wọ́n sì kó egungun wọn, wọ́n sì sin wọ́n lábẹ́ igi tamariski ní Jabesi, wọ́n sì gbààwẹ̀ ní ọjọ́ méje.
Ana'ma hute'za zaferinazami eri'za tamaris zafa agafafi asenente'za, 7ni'a zagegnafi ne'zana a'o hu'za zamasunkura hu'naze.

< 1 Samuel 31 >