< 1 Samuel 31 >

1 Nísinsin yìí, àwọn ará Filistini dojú ìjà kọ Israẹli, àwọn ará Israẹli sì sálọ kúrò níwájú wọn, a sì pa ọ̀pọ̀ wọn sí orí òkè Gilboa.
Na rĩrĩ, Afilisti makĩhũũrana na Isiraeli; nao andũ a Isiraeli makĩmoorĩra, na aingĩ ao makĩũragĩrwo kũu Kĩrĩma-inĩ kĩa Giliboa.
2 Àwọn Filistini sì ń lépa Saulu àti àwọn ọmọ rẹ̀ kíkan; àwọn Filistini sì pa Jonatani àti Abinadabu, àti Malikiṣua, àwọn ọmọ Saulu.
Afilisti makĩhatĩrĩria Saũlũ na ariũ ake mũno, na makĩũraga ariũ acio ake, Jonathani, na Abinadabu, na Malikishua.
3 Ìjà náà sì burú fún Saulu gidigidi, àwọn tafàtafà si ta á ní ọfà, o sì fi ara pa púpọ̀ lọ́wọ́ àwọn tafàtafà.
Na rĩrĩ, mbaara nĩyaneneheire Saũlũ mũno mũno, na rĩrĩa aikia a mĩguĩ maamũkinyĩrire, makĩmũguraria mũno.
4 Saulu sì wí fún ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Fa idà rẹ yọ, kí ìwọ sì fi gún mi, kí àwọn aláìkọlà wọ̀nyí má ba à wá gún mi, àti kí wọn kí ó má bá à fi mí ṣe ẹlẹ́yà.” Ṣùgbọ́n ẹni tí ó rú ẹ̀rù ìhámọ́ra rẹ̀ kò fẹ́ ṣe bẹ́ẹ̀, nítorí pé ẹ̀rù bà á gidigidi. Nígbà náà ni Saulu mú idà, ó sì ṣubú lù ú.
Nake Saũlũ akĩĩra mũkuui wake wa indo cia mbaara atĩrĩ, “Comora rũhiũ rwaku rwa njora ũũthece naruo, nĩguo andũ aya mataruaga matigooke maatheece na maanyararithie.” No rĩrĩ, mũkuui ũcio wake wa indo cia mbaara agĩĩtigĩra mũno, akĩrega gwĩka ũguo; nĩ ũndũ ũcio Saũlũ akĩoya rũhiũ rwake rwa njora, akĩrũgwĩra.
5 Nígbà tí ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ si rí i pé Saulu kú, òun náà sì fi idà rẹ̀ pa ara rẹ̀, ó sì kú pẹ̀lú rẹ̀.
Rĩrĩa mũkuui wake wa indo cia mbaara onire atĩ Saũlũ nĩakua-rĩ, o nake akĩgwĩra rũhiũ rwake rwa njora, agĩkua.
6 Saulu sì kú, àti àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́ta, àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀, àti gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà.
Nĩ ũndũ ũcio Saũlũ, na ariũ ake atatũ, na mukuui wake wa indo cia mbaara, na andũ ake othe magĩkua hamwe mũthenya o ro ũcio.
7 Nígbà ti àwọn ọkùnrin Israẹli tí ó wà lápá kejì àfonífojì náà, àti àwọn ẹni tí ó wà lápá kejì Jordani, rí pé àwọn ọkùnrin Israẹli sá, àti pé Saulu àti àwọn ọmọkùnrin rẹ ti kú, wọ́n sì fi ìlú sílẹ̀, wọ́n sì sá, àwọn Filistini sì wá, wọ́n sì jókòó si ìlú wọn.
Rĩrĩa andũ a Isiraeli arĩa maarĩ mwena ũcio ũngĩ wa kĩanda na arĩa maarĩ mũrĩmo wa Jorodani moonire atĩ mbũtũ ya ita ya Isiraeli nĩyoora, na atĩ Saũlũ na ariũ ake nĩmakuĩte-rĩ, magĩtiganĩria matũũra mao makĩũra. Nao Afilisti magĩthiĩ magĩtũũra kuo.
8 Ní ọjọ́ kejì, nígbà tí àwọn Filistini dé láti bọ́ nǹkan tí ń bẹ lára àwọn tí ó kù, wọ́n sì rí pé, Saulu àti àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́ta ṣubú ni òkè Gilboa.
Mũthenya ũyũ ũngĩ, Afilisti magĩthiĩ kũbora ciimba, magĩkora Saũlũ na ariũ ake atatũ makuĩte kũu Kĩrĩma-inĩ kĩa Giliboa.
9 Wọ́n sì gé orí rẹ̀, wọ́n sì bọ ìhámọ́ra rẹ̀, wọ́n sì ránṣẹ́ lọ ilẹ̀ Filistini káàkiri, láti máa sọ ọ́ ní gbangba ni ilé òrìṣà wọn, àti láàrín àwọn ènìyàn.
Nao makĩmũtinia mũtwe na makĩoya indo ciake cia mbaara, magĩcooka magĩtũma andũ mathiĩ bũrũri wothe wa Afilisti makaanĩrĩre ũhoro ũcio thĩinĩ wa hekarũ ya mĩhianano yao ya kũhooywo, na kũrĩ andũ ao.
10 Wọ́n sì fi ìhámọ́ra rẹ̀ sí ilé Aṣtoreti: wọ́n sì kan òkú rẹ̀ mọ́ odi Beti-Ṣani.
Makĩiga indo cia Saũlũ cia mbaara thĩinĩ wa hekarũ ya Ashitarothu, na mwĩrĩ wake makĩwoherera rũthingo-inĩ rwa Bethi-Shani.
11 Nígbà tí àwọn ará Jabesi Gileadi sì gbọ́ èyí tí àwọn Filistini ṣe sí Saulu.
No rĩrĩa andũ a Jabeshi-Gileadi maaiguire ũrĩa Afilisti meekĩte Saũlũ-rĩ,
12 Gbogbo àwọn ọkùnrin alágbára sì dìde, wọ́n sì fi gbogbo òru náà rìn, wọ́n sì gbé òkú Saulu, àti òkú àwọn ọmọ bíbí rẹ̀ kúrò lára odi Beti-Ṣani, wọ́n sì wá sí Jabesi, wọ́n sì sun wọ́n níbẹ̀.
njamba ciao cia ita igĩthiĩ ũtukũ wothe nginya Bethi-Shani. Makĩruta mwĩrĩ wa Saũlũ na ya ariũ ake atatũ kuuma rũthingo-inĩ rwa Bethi-Shani, na magĩthiĩ nayo Jabeshi, magĩcooka makĩmĩcinĩra kuo.
13 Wọ́n sì kó egungun wọn, wọ́n sì sin wọ́n lábẹ́ igi tamariski ní Jabesi, wọ́n sì gbààwẹ̀ ní ọjọ́ méje.
Magĩcooka makĩoya mahĩndĩ macio mao na makĩmathika gĩtina-inĩ kĩa mũtĩ wa mũbinde kũu Jabeshi, na makĩĩhinga kũrĩa irio mĩthenya mũgwanja.

< 1 Samuel 31 >