< 1 Samuel 30 >

1 Ó sì ṣe nígbà ti Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì bọ̀ sí Siklagi ní ọjọ́ kẹta, àwọn ará Amaleki sì ti kọlu ìhà gúúsù, àti Siklagi, wọ́n sì ti kùn ún ní iná.
Davut'la adamları üçüncü gün Ziklak Kenti'ne vardılar. Bu arada Amalekliler Negev bölgesiyle Ziklak'a baskın yapmış, Ziklak Kenti'ni yakıp yıkmışlardı.
2 Wọ́n sì kó àwọn obìnrin tí ń bẹ nínú rẹ̀ ní ìgbèkùn, wọn kò sì pa ẹnìkan, ọmọdé tàbí àgbà, ṣùgbọ́n wọ́n kó wọn lọ, wọ́n sì bá ọ̀nà tiwọn lọ.
Kimseyi öldürmemişlerdi, ama kadınlarla orada yaşayan genç, yaşlı herkesi tutsak etmişlerdi. Sonra onları da yanlarına alıp yollarına gitmişlerdi.
3 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin sì wọ ìlú Siklagi, sì wò ó, a ti kùn ún ni iná; àti obìnrin wọn, àti ọmọkùnrin wọn àti ọmọbìnrin wọn ni a kó ni ìgbèkùn lọ.
Davut'la adamları oraya varınca kentin ateşe verildiğini, karılarının, oğullarının, kızlarının tutsak alındığını anladılar.
4 Dafidi àti àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún títí agbára kò fi sí fún wọn mọ́ láti sọkún.
Güçleri tükeninceye dek hıçkıra hıçkıra ağladılar.
5 A sì kó àwọn aya Dafidi méjèèjì nígbèkùn lọ, Ahinoamu ará Jesreeli àti Abigaili aya Nabali ará Karmeli.
Davut'un iki karısı, Yizreelli Ahinoam ile Karmelli Naval'ın dulu Avigayil de tutsak edilmişti.
6 Dafidi sì banújẹ́ gidigidi, nítorí pé àwọn ènìyàn náà sì ń sọ̀rọ̀ láti sọ ọ́ lókùúta, nítorí ti inú gbogbo àwọn ènìyàn náà sì bàjẹ́, olúkúlùkù ọkùnrin nítorí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti nítorí ọmọ rẹ̀ obìnrin ṣùgbọ́n Dafidi mú ara rẹ̀ lọ́kàn le nínú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
Davut büyük sıkıntı içindeydi. Çünkü herkes oğulları, kızları için acı çekiyor ve, “Davut'u taşlayalım” diyordu. Ama Davut, Tanrısı RAB'de güç bularak,
7 Dafidi sì wí fún Abiatari àlùfáà, ọmọ Ahimeleki pé, èmí bẹ̀ ọ́, mú efodu fún mi wá níhìn-ín yìí. Abiatari sì mú efodu náà wá fún Dafidi.
Ahimelek oğlu Kâhin Aviyatar'a, “Bana efodu getir” dedi. Aviyatar efodu getirdi.
8 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa wí pé, “Kí èmi ó lépa ogun yìí bi? Èmi lè bá wọn?” Ó sì dá a lóhùn pé, “Lépa, nítorí pé ni bíbá ìwọ yóò bá wọn, ni gbígbà ìwọ yóò sì rí wọn gbà.”
Davut RAB'be danışarak, “Bu akıncıların ardına düşersem, onlara yetişir miyim?” diye sordu. RAB, “Artlarına düş, kesinlikle onlara yetişip tutsakları kurtaracaksın” diye yanıtladı.
9 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì wá sí ibi àfonífojì Besori, apá kan sì dúró.
Bunun üzerine Davut yanındaki altı yüz kişiyle yola çıktı. Besor Vadisi'ne geldiler. Vadiyi geçemeyecek kadar bitkin düşen iki yüz kişi orada kaldı. Davut dört yüz kişiyle akıncıları kovalamayı sürdürdü.
10 Ṣùgbọ́n Dafidi àti irinwó ọmọkùnrin lépa wọn: igba ènìyàn tí àárẹ̀ mú, tiwọn kò lè kọjá odò Besori sì dúró lẹ́yìn.
11 Wọ́n sì rí ará Ejibiti kan ní oko, wọ́n sì mú un tọ Dafidi wá, wọ́n sì fún un ní oúnjẹ, ó sì jẹ; wọ́n sì fún un ní omi mu.
Kırda bir Mısırlı bulup Davut'a getirdiler. Yiyip içmesi için ona yiyecek, içecek verdiler.
12 Wọ́n sì fún un ní àkàrà, èso ọ̀pọ̀tọ́ àti síírí àjàrà gbígbẹ́ méjì: nígbà tí ó sì jẹ ẹ́ tán, ẹ̀mí rẹ̀ sì sọjí: nítorí pé kò jẹ oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi ní ọjọ́ mẹ́ta ní ọ̀sán, àti ní òru.
Bir parça incir pestili ile iki salkım kuru üzüm de verdiler. Adam yiyince canlandı. Üç gün üç gecedir yiyip içmemişti.
13 Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ? Àti níbo ni ìwọ ti wá?” Òun sì wí pé, “Ọmọ ará Ejibiti ni èmi, ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin kan ará Amaleki. Olúwa mi fi mí sílẹ̀, nítorí pé láti ọjọ́ mẹ́ta ni èmi ti ṣe àìsàn.
Davut ona, “Kime bağlısın? Nerelisin?” diye sordu. Genç adam, “Mısırlı'yım, bir Amalekli'nin kölesiyim” diye yanıtladı, “Üç gün önce hastalanınca, efendim beni bıraktı.
14 Àwa sì gbé ogun lọ sí ìhà gúúsù tí ará Kereti, àti sí ìhà ti Juda, àti sí ìhà gúúsù ti Kalebu; àwa sì kun Siklagi ní iná.”
Keretliler'in güney sınırlarına, Yahuda topraklarına, Kalev'in güneyine baskınlar düzenlemiş, Ziklak Kenti'ni de ateşe vermiştik.”
15 Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ìwọ lè mú mí sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun yìí lọ bí?” Òun sì wí pé, “Fi Ọlọ́run búra fún mi pé, ìwọ kì yóò pa mí, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò sì fi mi lé olúwa mi lọ́wọ́; èmi yóò sì mú ọ sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun náà lọ.”
Davut, “Beni bu akıncılara götürebilir misin?” diye sordu. Mısırlı genç, “Beni öldürmeyeceğine ya da efendimin eline teslim etmeyeceğine dair Tanrı'nın önünde ant içersen, seni akıncıların olduğu yere götürürüm” diye karşılık verdi.
16 Ó sì mú un sọ̀kalẹ̀, sì wò ó, wọ́n sì tàn ká ilẹ̀, wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n sì ń jó, nítorí ìkógun púpọ̀ tí wọ́n kó láti ilẹ̀ àwọn Filistini wá, àti láti ilẹ̀ Juda.
Böylece Mısırlı Davut'u götürdü. Akıncılar dört bir yana dağılmışlardı. Filist ve Yahuda topraklarından topladıkları büyük yağmadan yiyip içiyor, eğlenip oynuyorlardı.
17 Dafidi sì pa wọ́n láti àfẹ̀mọ́júmọ́ títí ó fi di àṣálẹ́ ọjọ́ kejì: kò sí ẹnìkan tí ó là nínú wọn, bí kọ̀ ṣe irinwó ọmọkùnrin tí wọ́n gun ìbákasẹ tí wọ́n sì sá.
Davut ertesi gün tan vaktinden akşama dek onları öldürdü. Develere binip kaçan dört yüz genç dışında içlerinden kurtulan olmadı.
18 Dafidi sì gbà gbogbo nǹkan tí àwọn ará Amaleki ti kó: Dafidi sì gba àwọn obìnrin rẹ̀ méjèèjì.
Davut Amalekliler'in ele geçirdiği her şeyi, bu arada da iki karısını kurtardı.
19 Kò sì ṣí nǹkan tí ó kù fún wọn, kékeré tàbí ńlá, ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin, tàbí ìkógun, tàbí gbogbo nǹkan tí wọ́n ti kó: Dafidi sì gba gbogbo wọn.
Gençler, yaşlılar, oğullar, kızlar, yağmalanan mallar, kısacası Amalekliler'in aldıklarından hiçbir şey eksik kalmadı. Davut tümünü geri aldı.
20 Dafidi sì kó gbogbo àgùntàn, àti màlúù tí àwọn ènìyàn rẹ̀ dà ṣáájú àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn tí wọ́n gbà, wọ́n sì wí pé, “Èyí yìí ni ìkógun ti Dafidi.”
Bütün koyunlarla sığırları da aldı. Adamları, bunları öbür hayvanların önünden sürerek, “Bunlar Davut'un yağmaladıkları” diyorlardı.
21 Dafidi sì wá sọ́dọ̀ igba ọkùnrin tí àárẹ̀ ti mú jú, tiwọn kò lè tọ́ Dafidi lẹ́yìn mọ́, ti òun ti fi sílẹ̀, ni àfonífojì Besori: wọ́n sì lọ pàdé Dafidi, àti láti pàdé àwọn ènìyàn tí ó lọ pẹ̀lú rẹ̀: Dafidi sì pàdé àwọn ènìyàn náà, ó sì kí wọn.
Bundan sonra Davut, daha ileriye gidemeyecek kadar bitkin düşüp Besor Vadisi'nde kalan iki yüz kişinin bulunduğu yere vardı. Onlar da Davut'la yanındakileri karşılamaya çıktılar. Davut yaklaşınca onlara esenlik diledi.
22 Gbogbo àwọn ènìyàn búburú àti àwọn ọmọ Beliali nínú àwọn tí o bá Dafidi lọ sì dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Bí wọn kò ti bá wa lọ, àwa ki yóò fi nǹkan kan fún wọn nínú ìkógun ti àwa rí gbà bí kò ṣe obìnrin olúkúlùkù wọn, àti ọmọ wọn; ki wọn sì mú wọn, ki wọn sì máa lọ.”
Ama Davut'la giden adamlardan kötü ve değersiz olanların tümü, “Madem bizimle birlikte gitmediler, geri aldığımız yağmadan onlara hiçbir pay vermeyeceğiz” dediler, “Her biri yalnız karısıyla çocuklarını alıp gitsin.”
23 Dafidi sì wí pé, “Ẹ má ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin ara mi: Olúwa ni ó fi nǹkan yìí fún wa, òun ni ó sì pa wá mọ́, òun ni ó sì fi ẹgbẹ́ ogun ti ó dìde sí wa lé wa lọ́wọ́.
Ama Davut, “Hayır, kardeşlerim!” dedi, “RAB'bin bize verdikleri konusunda böyle davranamayız! O bizi korudu ve bize saldıran akıncıları elimize teslim etti.
24 Ta ni yóò gbọ́ tiyín nínú ọ̀ràn yìí? Ṣùgbọ́n bi ìpín ẹni tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ si ìjà ti rí, bẹ́ẹ̀ ni ìpín ẹni ti ó dúró ti ẹrù; wọn ó sì pín in bákan náà.”
Sizin bu söylediklerinizi kim kabul eder? Savaşa gidenle eşyanın yanında kalanın payı aynıdır. Her şey eşit paylaşılacak!”
25 Láti ọjọ́ náà lọ, ó sì pàṣẹ, ó sì sọ ọ di òfin fún Israẹli títí di òní yìí.
O günden sonra Davut bunu İsrail için bugüne dek geçerli bir kural ve ilke haline getirdi.
26 Dafidi sì padà sí Siklagi, ó sì rán nínú ìkógun náà si àwọn àgbàgbà Juda, àti sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ni ẹ̀bùn fún un yín, láti inú ìkógun àwọn ọ̀tá Olúwa wa.”
Davut Ziklak'a dönünce, dostları olan Yahuda ileri gelenlerine yağma mallardan göndererek, “İşte RAB'bin düşmanlarından yağmalanan mallardan size bir armağan” dedi.
27 Ó sì rán an sí àwọn tí ó wà ni Beteli àti sí àwọn tí ó wà ní gúúsù tí Ramoti, àti sí àwọn tí ó wà ní Jattiri.
Sonra Beytel, Negev'deki Ramot, Yattir,
28 Àti sí àwọn tí ó wà ní Aroeri, àti sí àwọn tí ó wà ní Sifimoti, àti sí àwọn tí ó wà ni Eṣitemoa.
Aroer, Sifmot, Eştemoa,
29 Àti si àwọn tí ó wà ni Rakeli, àti sí àwọn tí ó wà ní ìlú àwọn Jerahmeeli, àti sí àwọn tí ó wà ni ìlú àwọn ará Keni,
Rakal, Yerahmeelliler'in, Kenliler'in kentlerinde,
30 àti sí àwọn tí ó wà ni Horma, àti sí àwọn ti ó wà ní Bori-Aṣani, àti sí àwọn tí ó wà ni Ataki.
Horma, Bor-Aşan, Atak,
31 Àti àwọn tí ó wà ni Hebroni, àti sí gbogbo àwọn ìlú ti Dafidi tìkára rẹ̀ àti tí àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ máa ń rìn ká.
Hevron'da oturanlara ve adamlarıyla birlikte sık sık uğradığı yerlerin tümüne yağmalanan mallardan gönderdi.

< 1 Samuel 30 >