< 1 Samuel 30 >
1 Ó sì ṣe nígbà ti Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì bọ̀ sí Siklagi ní ọjọ́ kẹta, àwọn ará Amaleki sì ti kọlu ìhà gúúsù, àti Siklagi, wọ́n sì ti kùn ún ní iná.
Davudıy cun insanar Tsiklag eyhene şahareeqa xhebı'esde yiğıs qabı hiviyxhar. Mane gahıl Amalekbı abı, Negevılqayiy Tsiklagılqa k'yoohar. Manbışe Tsiklag q'əra qav'u, qiyğab gyooxhan haa'a.
2 Wọ́n sì kó àwọn obìnrin tí ń bẹ nínú rẹ̀ ní ìgbèkùn, wọn kò sì pa ẹnìkan, ọmọdé tàbí àgbà, ṣùgbọ́n wọ́n kó wọn lọ, wọ́n sì bá ọ̀nà tiwọn lọ.
Manbışe, maane zəiyfabışda nenacar geek'a deş. Xərıng'ule k'ıning'ulqamee manbışin gırgınbı avqu, cokasana quvkekka.
3 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin sì wọ ìlú Siklagi, sì wò ó, a ti kùn ún ni iná; àti obìnrin wọn, àti ọmọkùnrin wọn àti ọmọbìnrin wọn ni a kó ni ìgbèkùn lọ.
Davud cune insanaaşika şahareeqa ikkeç'umee, mang'uk'le şahar gyooxhan hav'u, con dixbı, yişba, yedar şenbışe cone ögeeqa gyavhu quvku, g'ooce.
4 Dafidi àti àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún títí agbára kò fi sí fún wọn mọ́ láti sọkún.
Man g'acu, Davudıy cun insanar uledın nağbı qeqvasmee gyaaşenbı.
5 A sì kó àwọn aya Dafidi méjèèjì nígbèkùn lọ, Ahinoamu ará Jesreeli àti Abigaili aya Nabali ará Karmeli.
Şenbışe avqu quvkiynbışde yı'q'nee, Davudna q'öyursana xhunaşşe: İzre'elyğançena Axinoamiy Karmelyğançene Navalna sip'ıriy Avigailir yeexhena.
6 Dafidi sì banújẹ́ gidigidi, nítorí pé àwọn ènìyàn náà sì ń sọ̀rọ̀ láti sọ ọ́ lókùúta, nítorí ti inú gbogbo àwọn ènìyàn náà sì bàjẹ́, olúkúlùkù ọkùnrin nítorí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti nítorí ọmọ rẹ̀ obìnrin ṣùgbọ́n Dafidi mú ara rẹ̀ lọ́kàn le nínú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
Davudun yik' qoxa eyxhe, milletın mana g'ayeqqa helesva uvhuva. Maane insanaaşin cone uşaxaaşiqa yik' gyotxhan ıxhayke, məxüd eyhe ıxha. Davudeeyid yı'q' cune Allahılqa Rəbbilqa qiyzar.
7 Dafidi sì wí fún Abiatari àlùfáà, ọmọ Ahimeleki pé, èmí bẹ̀ ọ́, mú efodu fún mi wá níhìn-ín yìí. Abiatari sì mú efodu náà wá fún Dafidi.
Mang'vee, Aximelekne duxayk'le kaahin Evyatarık'le uvhuyn: – Hucoona ixhes, yizdemee kaahinaaşin ileylığ inyaqa alle. Evyatareeyid man kar Davudne k'anyaqa adaylen.
8 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa wí pé, “Kí èmi ó lépa ogun yìí bi? Èmi lè bá wọn?” Ó sì dá a lóhùn pé, “Lépa, nítorí pé ni bíbá ìwọ yóò bá wọn, ni gbígbà ìwọ yóò sì rí wọn gbà.”
Davudee Rəbbike qiyghan: – Zı ine şaharılqa kyophuriynbışiqa qihna gyurxheene, avayq'aree? Rəbbee mang'uk'le eyhen: – Gixhe qihna. Ğu manbışiqa avaq'arasdar, manbışe avquynbıb g'attivxhan haa'asınbı.
9 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì wá sí ibi àfonífojì Besori, apá kan sì dúró.
Davud cukane yixhıd vəş insanıka Amalekbışiqar qihna gexha. Manbı Besor eyhene qadaalisqa qabı hipxhırmee, q'öd vəş insan maacab aaxva.
10 Ṣùgbọ́n Dafidi àti irinwó ọmọkùnrin lépa wọn: igba ènìyàn tí àárẹ̀ mú, tiwọn kò lè kọjá odò Besori sì dúró lẹ́yìn.
Davudıy manasa cukasanana yoq'ud vəş insanmee maa'ab ulyoozarcab deş, manbı Amalekbışiqab qihna gyabak'a. Manasa q'öd vəş insan manimee obzur vooxhe, Besor eyhene qadaalikecab manbışisse ılğeepç'es vəəxə deş.
11 Wọ́n sì rí ará Ejibiti kan ní oko, wọ́n sì mú un tọ Dafidi wá, wọ́n sì fún un ní oúnjẹ, ó sì jẹ; wọ́n sì fún un ní omi mu.
Çolee manbışisqa sa Misirğançena qızaxxa, mana manbışe Davudusqa arayle. Manbışe mang'us gıneyıd xhyanıd helen.
12 Wọ́n sì fún un ní àkàrà, èso ọ̀pọ̀tọ́ àti síírí àjàrà gbígbẹ́ méjì: nígbà tí ó sì jẹ ẹ́ tán, ẹ̀mí rẹ̀ sì sọjí: nítorí pé kò jẹ oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi ní ọjọ́ mẹ́ta ní ọ̀sán, àti ní òru.
Qiyğa manbışe mang'us qooqqav'una inciliyiy q'öble ts'ets'y t'ımılena hoole. Mang'vee man karbı otxhuniyle qiyğa culqa qarayle. Xhebılle yiğnayiy xheyible xəmna mang'vee mankilqasse gıneyid otxhun ıxha deş, xhyanıd ulyodğu eyxhe deş.
13 Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ? Àti níbo ni ìwọ ti wá?” Òun sì wí pé, “Ọmọ ará Ejibiti ni èmi, ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin kan ará Amaleki. Olúwa mi fi mí sílẹ̀, nítorí pé láti ọjọ́ mẹ́ta ni èmi ti ṣe àìsàn.
Davudee mang'uke qiyghanan: – Ğu vuşune vor, nençena arı? Mang'vee Davuduk'le eyhen: – Amalekbışde sang'una zı nukar vor. İxhesır zı, Misirbışda eyxhe. Hiyyiğna zı ık'iyk'ırna, yizde xərıng'veeyir zı g'alerçuna.
14 Àwa sì gbé ogun lọ sí ìhà gúúsù tí ará Kereti, àti sí ìhà ti Juda, àti sí ìhà gúúsù ti Kalebu; àwa sì kun Siklagi ní iná.”
Şi canubulynang'a, Keretbışde, Yahudayne, Kalevne cigabışeeqa k'yophur. Tsiklagıs ts'a ı'xı', gyooxhan hav'una.
15 Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ìwọ lè mú mí sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun yìí lọ bí?” Òun sì wí pé, “Fi Ọlọ́run búra fún mi pé, ìwọ kì yóò pa mí, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò sì fi mi lé olúwa mi lọ́wọ́; èmi yóò sì mú ọ sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun náà lọ.”
Davudee mang'uk'le eyhen: – Vasse zı, mane şaharbışilqa k'yophuriynbışisqa ıkkees əxəyee? Mane insanee eyhen: – Ğu zı gidek'asvayiy yizde xərng'une xılyaqa qidelesva Allahılqan k'ın g'assıreene, zınar ğu maqa ıkkeesda.
16 Ó sì mú un sọ̀kalẹ̀, sì wò ó, wọ́n sì tàn ká ilẹ̀, wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n sì ń jó, nítorí ìkógun púpọ̀ tí wọ́n kó láti ilẹ̀ àwọn Filistini wá, àti láti ilẹ̀ Juda.
Mang'vee Davud mane insanaaşisqa qarayle. Mane gahıl şaharbışilqa k'yophuriynbı inyaa-şaa opt'ul vuxha. Manbışe Filiştğançeyiy Yahudeençe geed kar qıkkı. Qiyğad inyaa-şaa otxhan-ulyoğa, mık'ar ha'a, cos ıkkananbı ha'a vuxha.
17 Dafidi sì pa wọ́n láti àfẹ̀mọ́júmọ́ títí ó fi di àṣálẹ́ ọjọ́ kejì: kò sí ẹnìkan tí ó là nínú wọn, bí kọ̀ ṣe irinwó ọmọkùnrin tí wọ́n gun ìbákasẹ tí wọ́n sì sá.
Davud verığ k'yooçuyle qiyğa, qinne yiğıl exhalilyqamee manbı gyabat'a ıxha. Devabışilqa aleepxı, hepxıyne yoq'ud vəş mek'vung'ule ğayrı, mançe şavussecar hixu g'attixhanas əxı' deş.
18 Dafidi sì gbà gbogbo nǹkan tí àwọn ará Amaleki ti kó: Dafidi sì gba àwọn obìnrin rẹ̀ méjèèjì.
Mang'vee Amalekbışe qıkkiyn gırgın karıd, cuna q'öyursana xhunaşşer yı'q'əlqa siyeek'al hee'ena.
19 Kò sì ṣí nǹkan tí ó kù fún wọn, kékeré tàbí ńlá, ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin, tàbí ìkógun, tàbí gbogbo nǹkan tí wọ́n ti kó: Dafidi sì gba gbogbo wọn.
Ç'ak'ınbı, k'ıninbı, gırgın dixbıyiy yişba, şenbışe cone xılelqa qı'iyn gırgın kar Davudee yı'q'əlqa sak'al ha'an. Mançike vuççud inyaqa-şaqa ıxha deş.
20 Dafidi sì kó gbogbo àgùntàn, àti màlúù tí àwọn ènìyàn rẹ̀ dà ṣáájú àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn tí wọ́n gbà, wọ́n sì wí pé, “Èyí yìí ni ìkógun ti Dafidi.”
Davudee manbışisse gırgın çavra-vəq'ə g'eşşen. Çavra-vəq'ə ha'aykı qıkkekkamee «İnbıd Davudee g'ayşunbı vodva» eyhe ıxha.
21 Dafidi sì wá sọ́dọ̀ igba ọkùnrin tí àárẹ̀ ti mú jú, tiwọn kò lè tọ́ Dafidi lẹ́yìn mọ́, ti òun ti fi sílẹ̀, ni àfonífojì Besori: wọ́n sì lọ pàdé Dafidi, àti láti pàdé àwọn ènìyàn tí ó lọ pẹ̀lú rẹ̀: Dafidi sì pàdé àwọn ènìyàn náà, ó sì kí wọn.
Davud, obzurva coqab qihna qavaales dəvxüyne, Besorne qadaalil avxuyne q'öd vəş insanısqa siyk'al. Man insanar Davudneyiy cukane insanaaşine ögilqa qığeebaç'e. Davudee cosqana qabıyne insanaaşis salam hoole.
22 Gbogbo àwọn ènìyàn búburú àti àwọn ọmọ Beliali nínú àwọn tí o bá Dafidi lọ sì dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Bí wọn kò ti bá wa lọ, àwa ki yóò fi nǹkan kan fún wọn nínú ìkógun ti àwa rí gbà bí kò ṣe obìnrin olúkúlùkù wọn, àti ọmọ wọn; ki wọn sì mú wọn, ki wọn sì máa lọ.”
Davuduka sacigee hapk'ınne qüvçüneyiy karaı'dəəne insanaaşe eyhen: – Manbı şaka hidyapk'ıninçil-alla, şi Amalekbışike g'ayşuyne karan manbışis vuççud heles deş. Manbışde gırgıng'usqa saccu con yedariy uşaxar qevles. Hasre manbıb alyapt'ı, inençe hudooracen.
23 Dafidi sì wí pé, “Ẹ má ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin ara mi: Olúwa ni ó fi nǹkan yìí fún wa, òun ni ó sì pa wá mọ́, òun ni ó sì fi ẹgbẹ́ ogun ti ó dìde sí wa lé wa lọ́wọ́.
Davudeeme manbışik'le eyhen: – De'eş, yizın çocar! Rəbbee şas huvuyne karak, şosse man ha'as əxəs deş. Şi Rəbbee havaacı. Mang'vee, yişin cigabı q'əra qı'iynbıb yişde xılyaqa quvu.
24 Ta ni yóò gbọ́ tiyín nínú ọ̀ràn yìí? Ṣùgbọ́n bi ìpín ẹni tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ si ìjà ti rí, bẹ́ẹ̀ ni ìpín ẹni ti ó dúró ti ẹrù; wọn ó sì pín in bákan náà.”
Şavaa vuşde mane cuvabıl k'ırı iliyxheyee? Dəv'eeqa hark'ıning'uqab, yişde karane k'ane axuyng'uqab akaranacab pay vuxhes vukkan. Gırgıng'us akaraba bit'al haa'as vukkan.
25 Láti ọjọ́ náà lọ, ó sì pàṣẹ, ó sì sọ ọ di òfin fún Israẹli títí di òní yìí.
Mane yiğıle, Davudee mana q'aanun bıkırne İzrailynemee haa'a. Mana q'aanun İzrailil g'iyniyne yiğılqameeyib avxuna.
26 Dafidi sì padà sí Siklagi, ó sì rán nínú ìkógun náà si àwọn àgbàgbà Juda, àti sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ni ẹ̀bùn fún un yín, láti inú ìkógun àwọn ọ̀tá Olúwa wa.”
Davud Tsiklageeqa qarımee, mang'vee Amalekbışike g'ayşuyne karbışin sık'ıninbı, cus hambazar vooxhene Yahudayne ağsaqqalaaşis g'axuvu, eyhen: – Hayna Rəbbine duşmanaaşike g'ayşunçike, şos hav'una pay vobna.
27 Ó sì rán an sí àwọn tí ó wà ni Beteli àti sí àwọn tí ó wà ní gúúsù tí Ramoti, àti sí àwọn tí ó wà ní Jattiri.
Mang'vee man paybı g'ıxelenbı Bet-Elee, canubul Ramoteeyiy Yattiree,
28 Àti sí àwọn tí ó wà ní Aroeri, àti sí àwọn tí ó wà ní Sifimoti, àti sí àwọn tí ó wà ni Eṣitemoa.
Aroeree, Sifmotee, Eştemoayee,
29 Àti si àwọn tí ó wà ni Rakeli, àti sí àwọn tí ó wà ní ìlú àwọn Jerahmeeli, àti sí àwọn tí ó wà ni ìlú àwọn ará Keni,
Rakalee, Yeraxmelybışdeyiy Genbışisde şaharbışee,
30 àti sí àwọn tí ó wà ni Horma, àti sí àwọn ti ó wà ní Bori-Aṣani, àti sí àwọn tí ó wà ni Ataki.
Xormayee, Bor-Aşanee, Ataxee,
31 Àti àwọn tí ó wà ni Hebroni, àti sí gbogbo àwọn ìlú ti Dafidi tìkára rẹ̀ àti tí àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ máa ń rìn ká.
Xevronee vooxhenbışisiy vuciy cun insanar nyaabiy vuxha mane cigaynbışis.